< Ieremia 32 >
1 KA olelo i hiki mai io Ieremia la mai o Iehova mai la, i ka umi o ka makahiki o Zedekia ke alii o ka Iuda, oia ka makahiki umikumamawalu o Nebukaneza.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa ní ọdún kẹwàá Sedekiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kejìdínlógún ti Nebukadnessari.
2 Ia manawa, hoopilikia mai la ka poe kaua o ke alii o Babulona ia Ierusalema: a ua hoopaaia o Ieremia ke kaula ma kahi paa o ka halepaahao iloko o ka hale o ke alii o Iuda.
Àwọn ogun ọba Babeli ìgbà náà há Jerusalẹmu mọ́. A sì sé wòlíì Jeremiah mọ́ inú túbú tí wọ́n ń ṣọ́ ní àgbàlá ilé ọba Juda.
3 No ka mea, hoopaa iho la o Zedekia ke alii o Iuda ia ia, e olelo mai ana, No ke aha la oe e wanana mai nei, i ka i ana mai, Penei ka olelo a Iehova, Aia hoi e haawi aku no au i keia kulanakauhale iloko o ka lima o ke alii o Babulona, a nana ia e hoopio:
Nítorí Sedekiah ọba Juda ti há a mọ́lé síbẹ̀; pé, “Kí ló dé tí ìwọ fi ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀? Tí o sì wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Èmi ń bọ̀ wá fi ìlú yìí fún ọba Babeli, tí yóò sì gbà á.
4 Aole hoi e pakele o Zedekia ke alii o Iuda mai ka lima aku o ka poe Kaledea; he oiaio e haawiia oia iloko o ka lima o ke alii o Babulona, a e kamailio oia me ia he waha he waha, a e ike auanei kona mau maka i ko ia la mau maka;
Sedekiah ọba Juda kò lè bọ́ lọ́wọ́ àwọn Kaldea, ṣùgbọ́n à ó mú fún ọba Babeli, yóò sì bá sọ̀rọ̀ ní ojúkojú; yóò sì rí pẹ̀lú ojú rẹ̀.
5 A e kai aku oia ia Zedekia i Babulona, a ilaila oia e noho ai a ike hou au ia ia, wahi a Iehova: ina e kaua aku oukou me ka poe Kaledea, aole oukou e pomaikai.
Yóò mú Sedekiah lọ sí Babeli tí yóò wà títí èmi yóò fi bẹ̀ ọ́ wò ni Olúwa wí. Tí ẹ̀yin bá bá àwọn ará Kaldea jà, ẹ̀yin kì yóò borí wọn.’”
6 Olelo ae la o Ieremia, Hiki mai la ka olelo a ke Akua io'u nei, i mai,
Jeremiah wí pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
7 Aia hoi, e hele mai ana iou la o Hanameela ke keiki a Saluma kekahi makuakane ou, e i mai ana, E kuai oe nou i kuu aina ma Anatota; no ka mea, o ka pono no ka hoopanai, nou no ia e kuai.
Hanameli ọmọkùnrin Ṣallumu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ yóò tọ̀ ọ́ wá pé, ‘Ra pápá mi tí ó wà ní Anatoti; nítorí gẹ́gẹ́ bí ẹni tó súnmọ́ wọn, ẹ̀tọ́ àti ìṣe rẹ ní láti rà á.’
8 A hele mai la io'u nei o Hanameela ke keiki a kekahi makuakane o'u, iloko o ka pahale o ka halepaahao, e like me ka olelo a ke Akua; i mai la ia ia'u, Ke noi aku nei au ia oe, e kuai oe i kuu aina ma Anatota ma ka moku o ka Beniamina; no ka mea, nou no ka hooili ana, a nou hoi ka hoopanai ana; e kuai oe nou. Alaila, ike iho la au o ka olelo ia a ke Akua.
“Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ, Hanameli ọmọ ẹ̀gbọ́n mi tọ̀ mí wá ní àgbàlá túbú wí pé, ‘Ra pápá mi tí ó wà ní Anatoti tí ó wà ní ilẹ̀ Benjamini, èyí tí ó jẹ́ pé ẹ̀tọ́ rẹ ni láti gbà á àti láti ni, rà á fún ara rẹ.’ “Nígbà náà ni èmi mọ̀ wí pé ọ̀rọ̀ Olúwa ni èyí.
9 A kuai iho la au i ka aina me Hanameela ke keiki a kekahi makuakane o'u, ka mea i noho ma Anatota, a kaupaona iho nona i ke kala, i na sekela kala he umikumamahiku.
Bẹ́ẹ̀ ni; èmi ra pápá náà ní Anatoti láti ọwọ́ Hanameli ọmọ ẹ̀gbọ́n mi. Mo sì wọn ìwọ̀n ṣékélì àti fàdákà mẹ́tàdínlógún fún un.
10 Kakau iho la au ma ka palapala, a hoopaa iho la i ka wepa, a lawe iho la na mea ike maka, a kau iho la i ke kala ma na mea kaupaona.
Mo fọwọ́ sínú ìwé, mo sì dì í pa. Mo pe ẹlẹ́rìí sí i, mo sì wọn fàdákà náà lórí òsùwọ̀n.
11 Lawe ae la au i ka palapala hoike i ke kuai ana, i ka mea i paa i ka wepa, a me ka mea i hoopaa ole ia, mamuli o ke kanawai a me ka oihana;
Mo mú ìwé tí mo fi rà á, èyí tí a di pa nípa àṣẹ àti òfin wa, àti èyí tí a kò lẹ̀.
12 A haawi aku la au i ka palapala hoike i ke kuai ana ia Baruka ke keiki a Neria, ke keiki a Maaseia, ma ke alo o Hanameela ke keiki a kekahi makuakane o'u, a ma ke alo hoi o na mea hoike, o ka poe i kakau inoa ma ka palapala o ke kuai ana, imua hoi o ka poe Iudaio a pau e noho ana ma ka pahale o ka halepaahao.
Èmi sì fi èyí fún Baruku, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, ní ojú Hanameli, ọmọ ẹ̀gbọ́n mi àti níwájú àwọn ẹlẹ́rìí tí ó ti fi ọwọ́ sí ìwé àti ní ojú àwọn Júù gbogbo tí wọ́n jókòó ní àgbàlá ilé túbú.
13 Kauoha aku la au ia Baruka imua o lakou, i aku la,
“Ní ojú wọn ni èmi ti pàṣẹ fún Baruku pé,
14 Ke olelo mai nei o Iehova o na kaua ke Akua o ka Iseraela penei; E lawe i keia mau palapala hoike, o ka palapala no ke kuai ana i paa i ka wepa, a me keia palapala hoike aole i paa, a e hahao iloko o ka ipu lepo, i malamaia'i ia mau mea i na la he nui.
èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí; mú àwọn ìwé tí a fi rà á wọ̀nyí, àti èyí tí a lẹ̀ àti èyí tí a kò lẹ̀, kí o wá gbé wọn sínú ìkòkò amọ̀, kí wọn ó lè wà ní ọjọ́ púpọ̀.
15 No ka mea, ke olelo mai nei o Iehova o na kaua, ke Akua o ka Iseraela, penei; E komo hou ia na hale, na aina a me na pawaina ma keia aina.
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí; àwọn ilẹ̀, pápá àti ọgbà àjàrà ni à ó tún rà padà nílẹ̀ yìí.
16 A pau ae la i ka haawiia o ka palapala hoike ia Baruka ke keiki a Neria, pule aku la au ia Iehova, i ka i ana aku,
“Lẹ́yìn tí mo ti fi ìwé rírà náà fún Baruku ọmọkùnrin Neriah, mo gbàdúrà sí Olúwa wí pé:
17 Auwe, e ka Haku, e Iehova e! aia hoi, nau no i hana ka lani a me ka honua, ma kou mana nui, a me ka lima kakauha, aohe mea i hiki ole ia oe.
“Háà! Olúwa Olódùmarè, ìwọ tí o dá ọ̀run àti ayé pẹ̀lú títóbi agbára rẹ àti gbogbo ọ̀rọ̀ apá rẹ. Kò sí ohun tí ó ṣòro fún ọ láti ṣe.
18 Ke hoike mai nei oe i ka lokomaikai i na tausani, a ke hoopai nei hoi i ka hala o na makua maloko o ka poli o ka lakou mau keiki mahope o lakou; ke Akua nui a me ka mana, o Iehova Sabaota kona inoa.
O fi ìfẹ́ hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n o gbé ìyà ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba lé àwọn ọmọ lẹ́yìn wọn. Ọlọ́run títóbi àti alágbára, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ.
19 He nui ka naauao, he mana hoi i ka hana: no ka mea, e kaakaa ana kou mau maka maluna iho o na aoao a pau o na keiki a kanaka; e uku mai i kela mea i keia mea e like me kona mau aoao, a e like hoi me ka hua o kana hana ana;
Títóbi ni ìgbìmọ̀, àti alágbára ní í ṣe, ojú rẹ̀ ṣì sí gbogbo ọ̀nà àwọn ọmọ ènìyàn; láti fi fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ ọ̀nà rẹ̀ àti gẹ́gẹ́ bí èso iṣẹ́ rẹ̀.
20 Ka mea nana i hoonoho i na hoailona a me na mea kupaianaha ma ka aina o Aigupita, a hiki i neia la, iloko hoi o ka Iseraela, a iwaena o kanaka; a i hookaulana i kou inoa, me ia i keia la;
O ṣe iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá ní Ejibiti. O sì ń ṣe é títí di òní ní Israẹli àti lára ọmọ ènìyàn tí ó sì ti gba òkìkí tí ó jẹ́ tìrẹ.
21 A i lawe mai i kou poe kanaka o ka Iseraela mai ka aina o Aigupita mai me na hoailona, a me na mea kupaianaha, a me ka lima ikaika, a me ka lima kakauha, a me ka weliweli nui;
O kó àwọn Israẹli ènìyàn rẹ jáde láti Ejibiti pẹ̀lú iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu nínú ọwọ́ agbára àti nína apá rẹ pẹ̀lú ẹ̀rù ńlá.
22 A haawi mai la no lakou i keia aina, au i hoohiki ai i ko lakou poe kupuna e haawi mai no lakou, he aina e kahe ana ka waiu a me ka meli;
Ìwọ fún wọn nílẹ̀ yìí, èyí tí o ti ṣèlérí fún àwọn baba ńlá wọn; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.
23 A komo mai la lakou a noho iho la; aka, aole lakou i hoolohe i kou leo, aole hoi i hele ma kou kanawai: aole lakou i hana iki i ka mea a pau au i kauoha mai ai ia lakou e hana; nolaila ua kau mai ai oe i keia popilikia a pau maluna iho o lakou.
Wọ́n wá, wọ́n sì gba ilẹ̀ náà ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ tàbí tẹ̀lé òfin rẹ. Wọn kò ṣe ohun tí o pàṣẹ fún wọn, nítorí náà ìwọ mú àwọn ibi yìí wá sórí wọn.
24 Aia hoi na puu kaua, ua hiki mai i ke kulanakauhale e lawepio ia ia, a ua haawiia ke kulanakauhale iloko o ka lima o ka poe Kaledea e kaua ku e mai ana, no ka pahikaua, a me ka wi, a me ka ahulau: a ua ko io no ka mea au i olelo mai ai; aia hoi, ke ike mai nei oe.
“Wò ó, bí àwọn ìdọ̀tí ṣe kórajọ láti gba ìlú. Nítorí idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, sì fi ìlú lé ọwọ́ àwọn ará Kaldea tí ń gbóguntì wọ́n. Ohun tí ìwọ sọ ṣẹ gẹ́gẹ́ bí o ṣe rí i.
25 E ka Haku, Iehova e, ua olelo mai oe ia'u, E kuai i ka aina me ke kala, a e lalau i na mea ike maka; aka, ua lilo ke kulanakauhale iloko o ka lima o ka poe Kaledea.
Síbẹ̀ a ó fi ìlú náà fún àwọn ará Babeli, ìwọ Olúwa Olódùmarè sọ fún mi pé, ‘Ra pápá náà pẹ̀lú owó fàdákà, kí o sì pe ẹlẹ́rìí.’”
26 Alaila hiki mai ka olelo a Iehova io Ieremia la, i mai la,
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá pé:
27 Aia hoi, owau no o Iehova, ke Akua o na mea io a pau: e hiki ole anei kekahi mea ia u?
“Èmi ni Olúwa Ọlọ́run gbogbo ẹran-ara. Ǹjẹ́ ohun kan ha a ṣòro fún mi bí?
28 Nolaila, ke olelo nei o Iehova; Aia hoi, e haawi no wau i keia kulanakauhale iloko o ka lima o ka poe Kaledea, a iloko o ka lima o Nebukaneza ke alii o Babulona, a e hoopio auanei oia ia.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí, Èmi ṣetán láti fi ìlú yìí fún àwọn ará Kaldea àti fún Nebukadnessari ọba Babeli ẹni tí yóò kó o.
29 A o ka poe Kaledea e kaua mai ana i keia kulanakauhale, e hele mai lakou, a e puhi i keia kulanakauhale, a e hoopau lakou ia i ke ahi, me na hale hoi, maluna olaila kahi i puhi ai lakou nei i ka mea ala na Baala, a ninini iho ai i na mohaiinu no na akua e, i mea e hoonaukiuki mai ai ia'u.
Àwọn ará Kaldea tí ó ń gbógun tí ìlú yóò wọ ìlú. Wọn ó sì fi iná sí ìlú; wọn ó jó o palẹ̀ pẹ̀lú ilé tí àwọn ènìyàn ti ń mú mi bínú, tí wọ́n ń rú ẹbọ tùràrí lórí pẹpẹ fún Baali tiwọn sì ń da ẹbọ ohun mímu fún àwọn ọlọ́run mìíràn.
30 No ka mea, ua hana hewa wale no na mamo a Iseraela a me na mamo a Iuda imua o'u mai ko lakou wa kamalii mai: no ka mea, ua hoonaukiuki wale mai no na mamo a Iseraela ia'u, i ka hana a ko lakou mau lima, wahi a Iehova.
“Àwọn ènìyàn Israẹli àti Juda kò ṣe ohun kankan bí kò ṣe ibi lójú mi láti ìgbà èwe wọn. Nítorí àwọn ọmọ Israẹli ti fi kìkì iṣẹ́ ọwọ́ wọ́n mú mi bínú ni Olúwa wí.
31 No ka mea, he mea hoonaukiuki. a me ka hooinaina ia'u keia kulanakauhale, mai ka la mai i kukulu ai lakou ia a hiki i keia la, i mea e hoonee aku ai au ia mai ko'u alo aku;
Láti ọjọ́ tí wọ́n ti kọ́ ọ, títí di àkókò yìí ni ìlú yìí ti jẹ́ ohun ìbínú àti ìyọnu fún mi tó bẹ́ẹ̀ tí èmi yóò fà á tu kúrò níwájú mi.
32 No ka hewa a pau o na mamo a Iseraela, a o na mamo a Iuda, ka mea a lakou i hana'i e hoonaukiuki mai ia'u, o lakou, o ko lakou poe alii, a me na luna o lakou, a me ko lakou poe kahuna, a me ko lakou poe kaula, a me na kanaka o ka Iuda, a me ka poe e noho ana ma Ierusalema.
Àwọn ènìyàn Israẹli àti àwọn ènìyàn Juda ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ìbàjẹ́ tí wọ́n ṣe. Àwọn Israẹli, ọba wọn àti gbogbo ìjòyè, àlùfáà àti wòlíì, àwọn ọkùnrin Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu.
33 A ua huli lakou i ke kua ia'u, aole i ka maka: owau nae ka mea nana lakou i ao aku e ala ana i ka wanaao e ao aku; aole nae lakou i hoolohe mai, i loaa ia lakou ke akamai.
Wọ́n kọ ẹ̀yìn sí mi, wọ́n sì yí ojú wọn padà. Èmi kọ wọ́n, síbẹ̀ wọn kò fetísílẹ̀ láti gbọ́ ẹ̀kọ́ tàbí kọbi ara sí ìwà ìbàjẹ́.
34 A kau no lakou i ko lakou mea haumia iloko o ka hale i kapaia ma ko'u inoa, e hoohaumia ia.
Wọ́n kó òrìṣà ìríra wọn jọ sí inú ilé tí wọ́n fi orúkọ mi pè, wọ́n sì ṣọ́ di àìmọ́.
35 A hana no hoi lakou i na wahi kiekie o Baala, na mea ma ke awawa o ke keiki a Hinoma, i mea e hele ai ka lakou keikikane a me ka lakou kaikamahine i Moleka, ka mea a'u i kauoha ole aku ai ia lakou, aole hoi ia i komo iloko o ko'u manao e hana lakou i keia mea haumia e hewa'i o ka Iuda.
Wọ́n kọ́ ibi gíga fún Baali ní àfonífojì Hinnomu láti fi ọmọ wọn ọkùnrin àti obìnrin rú ẹbọ sí Moleki. Èmi kò pàṣẹ, fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò wá sí ọkàn mi pé kí wọ́n ṣe ohun ìríra wọ̀nyí tí ó sì mú Juda dẹ́ṣẹ̀.
36 Nolaila, ke olelo mai nei o Iehova, ke Akua o ka Iseraela no keia kulanakauhale, ka mea a oukou i olelo ai, E haawiia oia iloko o ka lima o ke alii o Babulona, no ka pahikaua, a no ka wi, a no ka mai ahulau; peneia,
“Ìwọ ń sọ̀rọ̀ nípa ti ìlú yìí pé, ‘Pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn ni à ó fi wọ́n fún ọba Babeli,’ ṣùgbọ́n ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ nìyìí,
37 Aia hoi, e hoiliili mai nei au ia lakou mai loko mai o na aina a pau, kahi a'u i kipaku aku ai ia lakou i ko'u huhu, a i ko'u ukiuki, a me ka inaina nui; a e hoihoi hou mai au ia lakou i keia wahi, a e hoonoho au ia lakou i ka maluhia.
Èmi ó kó wọn jọ láti gbogbo ilẹ̀ tí mo ti lé wọn kúrò ní ìgbà ìbínú àti ìkáàánú ńlá mi. Èmi yóò mú wọn padà wá sí ilẹ̀ yìí; èmi ó sì jẹ́ kí wọn ó máa gbé láìléwu.
38 A e lilo mai lakou i poe kanaka no'u, a owau auanei ko lakou Akua.
Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
39 A e haawi aku no wau ia lakou i hookahi naau, a i hookahi aoao, i makau mau lakou ia'u, i mea e pono ai lakou, a me ka lakou poe keiki mahope iho o lakou.
Èmi ó fún wọn ní ọkàn kan àti ìṣe kí wọn kí ó lè máa bẹ̀rù mi fún rere wọn àti fún rere àwọn ọmọ wọn tí ó tẹ̀lé wọn.
40 A e hana wau i berita mau loa me lakou, aole hoi au o huli ae mai o lakou aku, me ka hana ia lakou i ka maikai, a e kau no au i ka makau ia'u iloko o ko lakou naau, aole hoi lakou e haalele mai ia'u.
Èmi ò bá wọn dá májẹ̀mú ayérayé, èmi kò ní dúró láti ṣe rere fún wọn, Èmi ó sì jẹ́ kí wọ́n bẹ̀rù mi, wọn kì yóò sì padà lẹ́yìn mi.
41 E olioli no wau ia lakou, e hana maikai ia lakou, a e hoonoho paa ia lakou ma keia aina, mo ko'u naau a pau, a me ko'u uhane a pau.
Lóòtítọ́, èmi ó yọ̀ nípa ṣíṣe wọ́n ní rere, èmi ó sì fi dá wọn lójú nípa gbígbìn wọ́n sí ilẹ̀ yìí tọkàntọkàn mi.
42 No ka mea, ke olelo mai nei o Iehova penei; E like me ko'u lawe ana i keia hewa nui a pau maluna o keia poe kanaka, pela no wau e lawe maluna o lakou i ka maikai a pau a'u i olelo aku ai ia lakau.
“Nítorí báyìí ni Olúwa wí, gẹ́gẹ́ bí èmi ti mú gbogbo ibi ńlá yìí wá sórí àwọn ènìyàn yìí, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó mú gbogbo rere tí èmi ti sọ nípa tiwọn wá sórí wọn.
43 E kuaiia auanei na mahinaai ma keia aina, kahi a oukou i olelo ai, Ua mehameha, aohe kanaka, aohe holoholona; ua haawiia iloko o ka lima o ko Kaledea.
Lẹ́ẹ̀kan sí i, pápá yóò di rírà ní ilẹ̀ yìí tí ìwọ ti sọ pé, ‘Ohun òfò ni tí kò bá sí ọkùnrin tàbí àwọn ẹran, nítorí tí a ti fi fún àwọn ará Babeli.’
44 E kuai no na kanaka i na mahinaai i ke kala, a kakau i palapala e akaka'i, a hoopaa i ka wepa, a e lawe i poe ike, ma ka aina o ka Beniamina a ma na wahi e puni ana ia Ierusalema, a ma na kulanakauhale o ka Iuda, a ma na kulanakauhale o na mauna, a ma na kulanakauhale o ke awawa, a ma na kulanakauhale o ke kukuluhema; no ka mea, e hoihoi mai au i ko lakou pio ana, wahi a Iehova.
Wọn ó fi owó fàdákà ra oko, wọn yóò fi ọwọ́ sí ìwé, wọn ó dí pa pẹ̀lú ẹlẹ́rìí láti ilẹ̀ Benjamini àti ní ìlú kéékèèké tí ó yí Jerusalẹmu ká, àti ní ìlú Juda àti ní ìlú àwọn ìlú orí òkè, àti ni àwọn ẹsẹ̀ òkè, àti ní gúúsù, èmi ó mú ìgbèkùn wọn padà wá, ni Olúwa wí.”