< Ieremia 30 >

1 KA olelo i hiki mai io Ieremia la, mai o Iehova mai, i mai la,
Ọ̀rọ̀ tí ó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, wí pé:
2 Ke olelo mai nei o Iehova, ke Akua o ka Iseraela penei, i mai, E kakau oe i na olelo a pau a'u i olelo ai ia oe iloko o ka buke.
“Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, pé: ‘Ìwọ kọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti bá ọ sọ sínú ìwé kan.
3 No ka mea, aia hoi, e hiki mai ana na la, wahi a Iehova, e hoihoi no wau i ke pio ana o ko'u poe kanaka, o ka Iseraela, a me ka Iuda, wahi a Iehova; a e hoihoi aku wau ia lakou i ka aina a'u i haawi aku ai i ko lakou poe makua, a e noho lakou ia aina.
Ọjọ́ ń bọ̀ nígbà tí ń ó mú àwọn ènìyàn mi, àwọn ọmọ Israẹli àti Juda kúrò nínú ìgbèkùn, tí n ó sì dá wọn padà sí orí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá wọn láti ní,’ ni Olúwa Ọlọ́run wí.”
4 Eia no na olelo a Iehova i olelo ai no ka Iseraela, a no ka Iuda.
Ìwọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run sí Israẹli àti Juda:
5 No ka mea, ke olelo mai nei o Iehova penei; Ua lohe no makou i ka leo o ka pihoihoi, a me ka makau, aole o ka maluhia.
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Igbe ẹ̀rù àti ìwárìrì ni a gbọ́ láìṣe igbe àlàáfíà.
6 E ninau hoi oukou, i ike oukou, ina paha e hanau ai ke kane i keiki No ke aha la wau e ike nei i kela kanaka i keia kanaka, e kau ana kona mau lima ma kona puhaka, e like me ka wahine e haakohi ana, a ua nananakea hoi na maka a pau?
Béèrè kí o sì rí. Ǹjẹ́ ọkùnrin le dá ọmọ bí? Èéṣe tí mo fi ń rí àwọn alágbára ọkùnrin tí wọ́n fi ọwọ́ wọn mú inú wọn bí obìnrin tó ń rọbí, tí ojú gbogbo wọ́n sì fàro fún ìrora?
7 Auwe! no ka mea, he la nui ia, aohe mea e like mea ia, o ka manawa no ia o ka popilikia o ka Iakoba; aka, e hoolaia no oia, mailoko mai o ia.
Ọjọ́ náà yóò ha ti burú tó! Kò sí ọjọ́ tí yóò dàbí rẹ̀, Ọjọ́ náà yóò jẹ́ àkókò ìdààmú fún Jakọbu ṣùgbọ́n yóò rí ìgbàlà kúrò nínú ìdààmú náà.
8 No ka mea, a hiki i kela la, wahi a Iehova o na kaua, e uhai no wau i kona auamo, mai kou a-i aku, a e moku hoi ia'u kou mau mea i paa ai, aole hoi ia e hookauwa hou na na malihini:
“‘Ní ọjọ́ náà,’ Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Èmi yóò gbé àjàgà kúrò lọ́rùn wọn, Èmi yóò sì tú ìdè wọn sọnù. Àwọn àjèjì kì yóò sì mú ọ sìn wọ́n mọ́.
9 Aka, e hookauwa no lakou na Iehova, ko lakou Akua, a na Davida ko lakou alii, ka mea a'u e hoala'i no lakou.
Dípò bẹ́ẹ̀ wọn yóò máa sin Olúwa Ọlọ́run wọn àti Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba wọn, ẹni tí èmi yóò gbé dìde fún wọn.
10 Nolaila, mai makau oe, e kuu kauwa, e Iakoba, wahi a Iehova, mai weliweli hoi, e ka Iseraela; no ka mea, aia hoi, e hoola no wau ia oe, mai kahi loihi aku, a i kau hua hoi, mai ka aina o ko lakou pio ana; a e hoi mai no o Iakoba, a e hoomaha no, a e maluhia, aohe mea e hoomakau ia ia.
“‘Nítorí náà, má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, má sì ṣe jẹ́ kí ẹ̀rù bà ọ́, ìwọ Israẹli,’ ni Olúwa wí. ‘Èmi yóò gbà ọ́ kúrò láti ọ̀nà jíjìn wá, àní àwọn ìran rẹ láti ilẹ̀ àtìpó wọn. Jakọbu yóò sì tún ní àlàáfíà àti ààbò rẹ̀ padà, kò sì ṣí ẹni tí yóò ṣẹ̀rù bà á mọ́.
11 No ka mea, owau pu no me oe, wahi a Iehova, e hoola ia oe. A ina e hooki loa paha wau i ko na aina a pau, kahi a'u i hoopuehu aku ia oukou, aole wau e hooki loa ia oe; aka, e hoopai no wau ia oe ma ka pono, aole wau e kuu wale aku ia oe.
Èmi wà pẹ̀lú rẹ, n ó sì gbà ọ́,’ ni Olúwa wí. ‘Bí mo tilẹ̀ pa gbogbo orílẹ̀-èdè run, nínú èyí tí mo ti fọ́n ọn yín ká, síbẹ̀ èmi kì yóò pa yín run pátápátá. Èmi yóò bá yín wí pẹ̀lú ìdájọ́ òdodo nìkan; Èmi kò ní fi yín sílẹ̀ láìjìyà.’
12 No ka mea, ke olelo mai nei o Iehova penei, He mea ola ole kou palapu, ua nui loa hoi kou eha.
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Ọgbẹ́ yín kò gbóògùn, bẹ́ẹ̀ ni egbò yín kọjá ìwòsàn.
13 Aohe mea hooponopono i kou hihia, e wahi ana, aole ou laau e ola'i.
Kò sí ẹnìkan tí yóò bẹ̀bẹ̀ fún àìṣedéédéé yín, kò sí ètùtù fún ọgbẹ́ yín, a kò sì mú yín láradá.
14 Ua poina kou mau mea aloha a pau ia oe, aole lakou imi ia oe; no ka mea, ua hooeha aku au ia oe i ka eha o ka enemi, me ka paipai ana hoi o ka mea lokoino, no ka nui loa o kou hewa; ua mahuahua no kou hala.
Gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ ti gbàgbé rẹ, wọn kò sì náání rẹ mọ́ pẹ̀lú. Mo ti nà ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀tá rẹ yóò ti nà ọ, mo sì bá a ọ wí gẹ́gẹ́ bí ìkà, nítorí tí ẹ̀bi rẹ pọ̀ púpọ̀, ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kò sì lóǹkà.
15 No keaha la oe i kahea aku ai no kou palapu? He mea ola ole kou eha, no ka mai loa o kou hewa; i ka mahuahua ana o kou mau hala, ua hana no wau i keia mau mea ia oe.
Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń kígbe nítorí ọgbẹ́ yín, ìrora yín èyí tí kò ní oògùn? Nítorí ọ̀pọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ yín àti ẹ̀bi yín tó ga ni mo fi ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí sí i yín.
16 Nolaila, o ka poe a pau i hoopau ia oe, e hoopauia lakou; a e hele no kela mea, keia mea o kou poe enemi a iloko o ke pio ana; a o ka poe i lawe pio i kau, e lilo lakou i waiwai pio, a o ka poe i hao i kau, e haawi no wau ia lakou i ka haoia.
“‘Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ṣe yín ní ibi ni ibi yóò bá, àní gbogbo àwọn ọ̀tá yín ni a ó sọ di àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì; gbogbo àwọn tí wọ́n bà yín jẹ́ ni a ó bàjẹ́.
17 No ka mea, e hoihoi aku au i ke ola ia oe, a e hoola no wau ia oe i kou mau eha, wahi a Iehova: no ka mea, kapa aku lakou ia oe, he Kuewa, o Ziona hoi keia, ka mea imi ole ia e kekahi.
Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìlera fún yín, èmi yóò sì wo ọ̀gbẹ́ yín sàn,’ ni Olúwa wí, ‘nítorí tí a pè yín ní alárìnkiri, Sioni tí gbogbo ènìyàn dágunlá sí.’
18 Ke olelo mai nei o Iehova penei; Aia hoi, e hoihoi no wau i ke pio ana o na halelewa o Iakoba, a e lokomaikai aku au i kona mau wahi e noho ai; a e hana hou ia ke kulanakauhale maluna o kona puu iho, a e koe no ka halealii ma kona pono.
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Èmi yóò dá gbogbo ìre àgọ́ Jakọbu padà, èmi yóò sì ṣe àánú fún olùgbé àgọ́ rẹ̀; ìlú náà yóò sì di títúnṣe tí ààfin ìlú náà yóò sì wà ní ipò rẹ̀.
19 A mailoko aku o ia e puka aku ai ka hoomaikai, a me ka leo o ka poe olioli; a e hoomahuahua wau ia lakou, aole lakou e lilo i uuku, a e hoonani wau ia lakou, aole lakou e liilii ana.
Láti ẹnu wọn ni orin ọpẹ́ àti ìyìn yóò sì ti máa jáde. Èmi yóò sọ wọ́n di púpọ̀, wọn kì yóò sì dínkù ní iye, Èmi yóò fi ọlá fún wọn, wọn kò sì ní di ẹni àbùkù.
20 A e like auanei ka lakou poe keiki me ka wa mamua, a e hookupaaia ko lakou anaina imua o'u, a e hoopai no wau i ka poe a pau e hookaumaha ia lakou.
Ọmọ ọmọ wọn yóò wà bí i ti ìgbàanì níwájú mi ni wọn yóò sì tẹ àwùjọ wọn dúró sí. Gbogbo ẹni tó bá ni wọ́n lára, ni èmi yóò fì ìyà jẹ.
21 A no lakou iho auanei ko lakou poe luna, a e laha aku no ko lakou kiaaina mailoko aku o lakou; a e lawe mai no wau ia ia a kokoke, a e hookokoke mai no oia ia'u; no ka mea, owai keia i hooikaika i kona naau e hookokoke mai ia'u? wahi a Iehova.
Ọ̀kan nínú wọn ni yóò jẹ́ olórí wọn, ọba wọn yóò dìde láti àárín wọn. Èmi yóò mú un wá sí ọ̀dọ̀ mi, òun yóò sì súnmọ́ mi, nítorí ta ni ẹni náà tí yóò fi ara rẹ̀ jì láti súnmọ́ mi?’ ni Olúwa wí.
22 A o oukou auanei ko'u poe kanaka, a owau auanei ko oukou Akua.
‘Nítorí náà, ẹ̀yin yóò jẹ́ ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín.’”
23 Aia hoi, ke puka aku nei ka puahiohio o Iehova me ka huhu, he puahiohio e hoopau ana; me ka eha no ia e kau ai maluna o ke poo o ka poe hewa.
Wò ó, ìbínú Olúwa yóò tú jáde, ìjì líle yóò sì sọ̀kalẹ̀ sórí àwọn ènìyàn búburú.
24 Aole e hoi hou ka huhu nui o Iehova, a hana oia, a hooko oia i ka makemake o kona naau. I na la mahope, e noonoo no oukou ia.
Ìbínú ńlá Olúwa kò ní dẹ̀yìn lẹ́yìn àwọn ìkà títí yóò fi mú èrò ọkàn rẹ̀ ṣẹ. Ní àìpẹ́ ọjọ́, òye rẹ̀ yóò yé e yín.

< Ieremia 30 >