< Ieremia 3 >

1 KE olelo nei lakou, Iua kipaku ke kane i kana wahine, a hele aku oia, mai ona aku la, a lilo na ke kanaka e, e hoi hou anei kela ia ia? Aole anei e hoohaumia loa ia kela aina? Ua moe kolohe no nae oe me na ipo he nui loa: aka, e hoi hou mai oe ia'u, wahi a Iehova.
“Bí ọkùnrin kan bá sì kọ ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀ tí obìnrin náà sì lọ fẹ́ ọkọ mìíràn, ǹjẹ́ ọkùnrin náà tún lè tọ̀ ọ́ wá? Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kò ní di aláìmọ́ bí? Ṣùgbọ́n ìwọ ti gbé pẹ̀lú onírúurú panṣágà gẹ́gẹ́ bí olùfẹ́, ṣé ìwọ yóò tún padà sọ́dọ̀ mi bí?” ni Olúwa wí.
2 E alawa oe i kou mau maka iluna, a i na wahi kiekie. a e nana hoi i kahi i moe ole ia'i oe. Ma na alanui, ua noho kakali oe ia lakou, e like me ko Arabia ma ka waunahele; a ua hoohaumia oe i ka aina, i kou moe kolohe ana, a i kou haua hewa ana.
“Gbé ojú rẹ sókè sí ibi gíga wọ̀n-ọn-nì, kí o sì wò ó ibi kan ha wà tí a kò bà ọ́ jẹ́? Ní ojú ọ̀nà, ìwọ jókòó de àwọn olólùfẹ́, bí i ará Arabia kan nínú aginjù, ìwọ sì ti ba ilẹ̀ náà jẹ́ pẹ̀lú ìwà àgbèrè àti ìwà búburú rẹ.
3 Noliala, ua kaohiia ka ua, aole hoi i hiki mai ka ua hope ana. Aia no ia oe ka maka o ka wahine hookamakama; hoole no oe, aole oe e hoopalaimaka.
Nítorí náà, a ti fa ọ̀wààrà òjò sẹ́yìn, kò sì ṣí òjò àrọ̀kúrò. Síbẹ̀ ìwọ ní ojú líle ti panṣágà, ìwọ sì kọ̀ láti ní ìtìjú.
4 Mai keia manawa aku, aole anei oe e hea mai ia'u, E kuu makua, o oe no ke alakai o ko'u wa opiopio?
Ǹjẹ́ ìwọ kò ha a pè mí láìpẹ́ yìí pé, ‘Baba mi, ìwọ ọ̀rẹ́ mi láti ìgbà èwe mi.
5 E hoomauhala mau loa anei oia? E hoomauhala anei oia, a hiki i ka hopena? Aia hoi, ua olelo oe a ua hana hoi oe i na mea hewa me kou ikaika a pau.
Ìwọ yóò ha máa bínú títí? Ìbínú rẹ yóò ha máa lọ títí láé?’ Báyìí ni o ṣe ń sọ̀rọ̀ ìwọ ṣe gbogbo ibi tí ìwọ le ṣe.”
6 Olelo mai no hoi o Iehova ia'u, i na la ia Iosia, i ke alii, Ua ike anei oe i ka mea a ka Iseraela hoihope i hana'i? Ua hele no oia maluna o na mauna kiekie a pau, a malalo o na laau uliuli a paa, a malaila i moe kolohe ai.
Ní àkókò ìjọba Josiah ọba, Olúwa wí fún mi pé, “Ṣé o ti rí nǹkan tí àwọn Israẹli aláìnígbàgbọ́ ti ṣe? Wọ́n ti lọ sí àwọn òkè gíga àti sí abẹ́ àwọn igi, wọ́n sì ti ṣe àgbèrè níbẹ̀.
7 A i aku la au, mahope o kana hana ana i keia mau mea a pau, E hali mai oe. ia'u. Aole ia i huli mai, Ike ae la kona kaikuaana kipi, o ka Iuda.
Mo rò pé nígbà tí wọ́n ti ṣe èyí wọn yóò padà, wọn kò padà, Juda aláìgbàgbọ́ arábìnrin rẹ̀ náà sì rí i.
8 A ike aku la au, a kipaku aku au i ka Iseraela no ka moe kolohe aua, a haawi ia ia i ka palapala hoohemo; alaila, aole i makau kona kaikuaana kipi, o ka Iuda, hele aku no hoi ia, a moe kolohe iho la.
Mo fún Israẹli aláìnígbàgbọ́ ní ìwé ìkọ̀sílẹ̀, mo sì ké wọn kúrò nítorí gbogbo àgbèrè wọn. Síbẹ̀ mo rí pé Juda tí ó jẹ́ arábìnrin rẹ̀ kò bẹ̀rù, òun náà sì jáde lọ láti lọ ṣe àgbèrè.
9 A no ka kaulana o kona moe kolohe ana, hoohaumia iho la oia i ka aina, a moe kolohe no me ka pohaku, a me ka laau.
Nítorí ìwà èérí Israẹli kò jọ ọ́ lójú, ó ti ba ilẹ̀ jẹ́, ó sì ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú òkúta àti igi.
10 Aka, no keia mau mea a pau, aole i huli mai kona kaikuaana kipi ia'u me kona naau a pau, aka, me ka wahahee, wahi a Iehova.
Látàrí gbogbo nǹkan wọ̀nyí Juda arábìnrin rẹ̀ aláìgbàgbọ́ kò padà tọ̀ mí wá pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀, bí kò ṣe nípa fífarahàn bí olóòtítọ́,” ni Olúwa wí.
11 A olelo mai la o Iehova ia'u. Ua hoapono ka Iseraela hoihope ia ia iho, mamua o ka Iuda kipi.
Olúwa wí fún mi pé, “Israẹli aláìnígbàgbọ́ ṣe òdodo ju Juda tí ó ní ìgbàgbọ́ lọ.
12 O hele, e kala aku i keia mau olelo ma ke kukulu akau, a e i aku, E hoi mai, e ka Iseraela hoihope, wahi a Iehova; aole hoi au e hookau aku i ko'u ukiuki maluna o oukou; no ka mea, ua lokomaikai au, wahi a Iehova, aole hoi au e hoomauhala mau loa.
Lọ polongo ọ̀rọ̀ náà, lọ sí ìhà àríwá: “‘Yípadà, Israẹli aláìnígbàgbọ́,’ ni Olúwa wí. ‘Ojú mi kì yóò korò sí ọ mọ́, nítorí mo jẹ́ aláàánú, ni Olúwa wí. Èmi kì yóò sì bínú mọ́ títí láé.
13 E hai wale mai hoi oe i kou hewa, i kau hana hewa ana ia Iehova i kou Akua, a ua lulu aku oe i kou mau aoao i na malihini, malalo o na laau uliuli a pau, aole hoi oukou i hooloho i ko'u leo, wahi a Iehova.
Sá à ti mọ ẹ̀bi rẹ, ìwọ ti ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ìwọ ti wá ojúrere rẹ lọ́dọ̀ ọlọ́run àjèjì lábẹ́ gbogbo igikígi tí ó gbilẹ̀, ẹ̀yin kò gba ohun mi gbọ́,’” ni Olúwa wí.
14 E huli mai, e na keiki hoihope, wahi a Iehova, no ka mea, ua mareia au nau: a e lawe no au ia oukou, i hookahi o ke kulanakauhale hookahi, a i elua o ka hale hookahi, a e lawe no au ia oukou i Ziona.
“Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́,” ni Olúwa wí, “nítorí èmi ni ọkọ rẹ. Èmi ó yàn ọ́, ọ̀kan láti ìlú àti méjì láti ẹ̀yà. Èmi ó sì mú ọ wá sí Sioni.
15 A e haawi no au ia oukou i poe kahu mamuli o'ko'u naau, nana e hanai ia oukou i ka ike, a me ka naauao.
Lẹ́yìn èyí, èmi ó fún ọ ní àwọn olùṣọ́-àgùntàn láti inú ọkàn mi, tí wọn yóò ṣáájú yín pẹ̀lú òye àti ìmọ̀.
16 A hiki aku i ka manawa e nui ai oukou, a mahuahua ma ka aina, ia mau la, wahi a Iehova, aole lakou e olelo hou, O ka pahu o ka berita o Iehova; aole hoi e komo ia iloko o ka naau, aole lakou e hoomanao ia mea, aole lakou e hele e ike, aole hoi e hana hou ia ia mea.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, tí ẹ̀yin bá pọ̀ sí i lórí ilẹ̀ náà,” ni Olúwa wí, “àwọn ènìyàn kò tún lè sọ pé, ‘Àpótí ẹ̀rí Olúwa.’ Kò ní wá sí ìrántí wọn mọ́, a kì yóò pàdánù rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò sì tún kan òmíràn mọ́.
17 Ia manawa, e kapa no lakou ia Ierusalema, o ka nohoalii o Iehova; a e hoakoakoaia mai ko na aina a pau imua ona, i ka inoa o Iehova i Ierusalema; aole hoi lakou e hele hou mamuli o ka paakiki o ka naau hewa.
Ní ìgbà náà, wọn yóò pe Jerusalẹmu ní ìtẹ́ Olúwa gbogbo orílẹ̀-èdè yóò péjọ sí Jerusalẹmu láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ Olúwa, wọn kì yóò sì tún tẹ̀lé àyà líle búburú wọn mọ́.
18 Ia mau la, e hele pu no ko ka hale o ka Iuda, me ko ka hale o ka Iseraela, a e hele pu mai no lakou mai ka aina o ka akau mai, a i ka aina au i haawi aku ai i aina hooili no kou poe makua.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ni ilé Juda yóò darapọ̀ mọ́ ilé Israẹli. Wọn yóò sì wá láti ilẹ̀ àríwá wá sí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá yín gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní.
19 Aka, i iho la au, Pehea la au e waiho ai ia oe iwaena o na keiki, a haawi hoi ia oe i ka aina maikai i aina hooili nani o na pae aina? A olelo aku la au, E kapa mai oukou ia'u, o Ko'u Makua, aole hoi e huli mai o'u aku nei.
“Èmi fúnra mi sọ wí pé, “‘Báwo ni inú mi yóò ti dùn tó, kí èmi kí ó tọ́ ọ bí ọmọkùnrin kí n sì fún ọ ní ilẹ̀ tí ó tó.’ Mo rò pé ìwọ yóò pè mí ní ‘Baba mi’ o kò sì ní ṣàì tọ̀ mí lẹ́yìn.
20 Oiaio, e like me ka wahine haalele ino i kana kane, pela oukou i haalele ino mai ai ia'u, e ko ka hale o ka Iseraela, wahi a Iehova.
Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí aláìgbàgbọ́ obìnrin sí ọkọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ o jẹ́ aláìgbàgbọ́ sí mi. Ìwọ ilé Israẹli,” ni Olúwa wí.
21 Ua loheia ka Ieo maluna o na wahi kiekie, o ka uwe ana, e me ka nonoi ana a na mamo a Iseraela; a ua hookekee lakou i ko lakou aoao, a ua hoopoina lakou ia Iehova i ko lakou Akua.
A gbọ́ ohùn àgàn láti ibi gíga, ẹkún àti ẹ̀bẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli, nítorí wọ́n ti yí ọ̀nà wọn po, wọ́n sì ti gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn.
22 E hoi mai oukou, e na keiki hoihope, a e hoola no wau i ko oukou hoihope ana. Aia hoi, ke hele mai nei makou iou la, no ka mea, o oe no o Iehova, o ko makou Akua.
“Padà, ẹ̀yin ènìyàn aláìnígbàgbọ́, Èmi ó wo ìpadàsẹ́yìn kúrò ní ọ̀nà títọ́ rẹ sàn.” “Bẹ́ẹ̀, ni a ó wá sọ́dọ̀ rẹ nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run wa.
23 He oiaio, he mea wahahee na mea o na mauna mai, a no na kuahiwi lehulehu mai: He oiaio, maloko o Iehova, o ko makou Akua, ke ola o ka Iseraela.
Nítòótọ́, asán ni ìbọ̀rìṣà àti ìrúkèrúdò tí ó wà ní àwọn orí òkè kéékèèké àti àwọn òkè gíga, nítòótọ́, nínú Olúwa Ọlọ́run wa ni ìgbàlà Israẹli wà.
24 Na ka hilahila i hoopau i na hana a ko makou poe makua, mai ko makou wa uuku mai, i ko lakou hipa, a me ko lakou hipi, a me ka lakou keikikane, a me ka lakou kaikamahine.
Láti ìgbà èwe wa ni àwọn òrìṣà ìtìjú ti jẹ èso iṣẹ́ àwọn baba wa run, ọ̀wọ́ ẹran wọn àti agbo ẹran wọn, ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
25 Ke moe nei makou ilalo iloko o ko makou hilahila, a ua uhiia makou i ko makou palaimaka; no ka mea, ua hana hewa aku makou ia Iehova i ko makou Akua, o makou, a me ko makou poe makua, mai ko makou wa opiopio, a hiki loa mai nei i keia la, aole hoi i hoolohe i ka leo o Iehova, ko makou Akua.
Jẹ́ kí a dùbúlẹ̀ nínú ìtìjú wa, kí ìtìjú wa bò wá mọ́lẹ̀. A ti ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, àwa àti àwọn baba wa, láti ìgbà èwe wa títí di òní a kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa.”

< Ieremia 3 >