< Ieremia 24 >

1 HOIKE mai o Iehova ia'u, aia hoi, elua hinai fiku e kau ana ma ke alo o ka luakini o Iehova, mahope iho o ka lawe pio ana o Nebukaneza, o ke alii o Babulona ia Iekonia i ke keiki a Iehoiakima, ke alii o ka Iuda, a me na kaukaualii o ka Iuda, a me na kamana, a me na amara, mai Ierusalema aku, a lawe ia lakou i Babulona.
Lẹ́yìn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda àti àwọn ìjòyè wọn, àwọn oníṣọ̀nà àti oníṣẹ́ ọwọ́ ti Juda lọ sí ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí ilẹ̀ àjèjì Babeli tán. Olúwa fi agbọ̀n èso ọ̀pọ̀tọ́ méjì hàn mí tí a gbé sí iwájú pẹpẹ Olúwa.
2 Hookahi hinai fiku maikai loa, e like me na fiku oo mua; a o kela hinai, he fiku inoino, aole pono ke aiia, no ko lakou inoino loa.
Agbọ̀n kan ni èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó dára bí èyí tí ó tètè pọ́n; èkejì sì ní èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó burú rékọjá tí kò sì le è ṣe é jẹ.
3 Alaila, olelo mai la o Iehova ia'u. Heaha kau e ike nei, e Ieremia? I aku la au, He mau fiku; o na fiku maikai, ua maikai loa, a o na fiku ino, ua inoino loa, aole pono ke aiia, no ko lakou inoino loa.
Nígbà náà ni Olúwa bi mí pé, “Kí ni ìwọ rí Jeremiah?” Mo dáhùn pe, “Èso ọ̀pọ̀tọ́.” Mo dáhùn. “Èyí tí ó dáradára púpọ̀, ṣùgbọ́n èyí tí ó burú burú rékọjá tí kò sì ṣe é jẹ.”
4 Hiki hou mai la ka olelo a Iehova ia'u, i mai la,
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
5 Ke olelo mai nei o Iehova, ke Akua o ka Iseraela penei; E like me keia mau fiku maikai, pela no wau e hoomaopopo ai i ka poe i lawepioia o ka Iuda, ka poe a'u i kipaku aku ai, mai keia wahi aku a i ka aina o ko Kaledea, i mea e pono ai.
“Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Gẹ́gẹ́ bí àwọn èso ọ̀pọ̀tọ́ dáradára yìí ni Èmi yóò ka àwọn tí wọ́n lọ sí ilẹ̀ àjèjì láti Juda sí tí èmi rán jáde kúrò ní ibí yìí lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kaldea.
6 No ka mea, e kau no ko'u maka maluna o lakou i mea e pono ai, a e lawe hou mai no wau ia lakou i keia aina; a e kukulu no wau ia lakou, aole au e wawahi ia lakou, e kanu no wau ia lakou, aole e uhuki ia lakou.
Ojú mi yóò máa ṣọ́ wọn lọ fún rere, Èmi yóò gbé wọn ró, n kò ní já wọn lulẹ̀. Èmi yóò gbìn wọ́n, n kò sì ní fà wọ́n tu.
7 A e haawi no wau ia lakou i naau e ike mai ai ia'u, owau no o Iehova; a o lakou auanei ko'u poe kanaka, a owau auanei ko lakou Akua; no ka mea, e hoi mai no lakou ia'u me ko lakou naau a pau.
Èmi yóò fún wọn ní ọkàn láti mọ̀ mí pé, “Èmi ni Olúwa.” Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi; Èmi ni yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn; nítorí pé wọn yóò padà sọ́dọ̀ mi pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
8 A e like me na fiku inoino, pono ole ke aiia no ka inoino loa; He oiaio, wahi a Iehova, pela no wau e haawi aku ai ia Zedekia, i ke alii o ka Iuda, a me kana poe alii, a me ke koena o Ierusalema, ka poe e koe ana ma keia aina, a me ka poe e noho ana ma ka aina o Aigupita;
“‘Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí èso ọ̀pọ̀tọ́ tí kò dára, tí ó burú tí kò ṣe é jẹ,’ ni Olúwa wí, ‘bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò ṣe pẹ̀lú Sedekiah ọba Juda, àwọn ìjòyè rẹ̀ àti àwọn tí ó yẹ ní Jerusalẹmu, yálà wọ́n wà lórí ilẹ̀ yìí tàbí wọ́n ń gbé Ejibiti.
9 A haawi no wau ia lakou e laweia iloko o na aupuni a pau o ka honua nei, i mea hoopai, a i mea hoowahawaha, a i mea henehene, a i mea kuamuamu, a i mea hoopoino, ma na wahi a pau, a'u e kipaku aku ai ia lakou.
Èmi yóò sọ wọ́n di ìwọ̀sí àti ẹni ibi nínú gbogbo ìjọba ayé, láti di ẹni ìfibú àti ẹni òwe, ẹni ẹ̀sín, àti ẹni ẹ̀gàn ní ibi gbogbo tí Èmi ó lé wọn sí.
10 A e hoouna aku au i ka pahikaua, a me ka wi, a me ka mai ahulau iwaena o lakou, a hoopauia lakou, mai ka aina a'u i haawi aku ai ia lakou, a i ko lakou poe makua.
Èmi yóò rán idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn sí wọn, títí tí gbogbo wọn yóò parun lórí ilẹ̀ tí a fún wọn àti fún àwọn baba wọn.’”

< Ieremia 24 >