< Ieremia 23 >

1 A UWE ka poe kahu i luku, a hoopuehu i ka poe hipa o ko'u kihapai! wahi a Iehova.
“Ègbé ni fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn tí ń tú agbo ẹran mi ká tí ó sì ń pa wọ́n run!” ni Olúwa wí.
2 Nolaila, penei ka olelo ana mai a Iehova, ke Akua o ka Iseraela, no na kahu, ka poe hanai i ko'u poe kanaka; Ua hoopuehu oukou i ka'u poe hipa, a ua kipaku ia lakou, aole i hele mai e ike ia lakou; aia hoi, e hoopai no wau maluna o oukou, i ka hewa o ka oukou hana ana, wahi a Iehova.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ ní ti àwọn olùṣọ́-àgùntàn tí ń darí àwọn ènìyàn mi: “Nítorí tí ẹ̀yin tú agbo ẹran mi ká, tí ẹ lé wọn dànù tí ẹ̀yin kò sì bẹ̀ wọ́n wò. Èmi yóò jẹ yín ní yà nítorí nǹkan búburú tí ẹ ti ṣe,” ni Olúwa wí.
3 A e hoiliili no wau i ke koena o ka'u poe hipa, mai na aina a pau mai, kahi a'u i hookuke aku ai ia lakou, a e hoihoi hou mai au ia lakou iloko o ko lakou mau pa: a e kawowo lakou, a mahuahua aku.
“Èmi Olúwa tìkára mi yóò kó ìyókù agbo ẹran mi jọ láti inú gbogbo orílẹ̀-èdè tí mo ti lé wọn, Èmi yóò mú wọn padà sínú pápá oko wọn, níbẹ̀ ni wọn ó ti bí sí i, tí wọn ó sì pọ̀ sí i.
4 A e hoonoho wau i kahu maluna o'lakou, he poe hanai aku ia lakou; aole lakou e makau hou, aole e weliweli, aole hoi lakou e hoopai hou ia, wahi a Iehova.
Èmi ó wá olùṣọ́-àgùntàn fún wọn, tí yóò darí wọn, wọn kì yóò bẹ̀rù tàbí dààmú, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kan kì yóò sọnù,” ni Olúwa wí.
5 Aia hoi, e hiki mai ana na la, wahi a Iehova, o hoala no wau no Davida, i Oha pono, i Alii e noho aupuni, a e pomaikai auanei, a e hana no oia i ka hooponopono, a i ka pololei ma ka honua.
“Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò gbé ẹ̀ka òdodo dìde fún Dafidi, ọba tí yóò lo ìjọba pẹ̀lú ọgbọ́n tí yóò sì ṣe òdodo àti ohun tí ó yẹ lórí ilẹ̀ náà.
6 I kona mau la e hoolaia o ka Iuda, a e noho maluhia o ka Iseraela, a eia hoi kona inoa e kapaia mai ai, O IEHOVA KO KAKOU PONO.
Ní ọjọ́ rẹ̀ ni a ó gba Juda là, Israẹli yóò sì máa gbé ní aláìléwu. Èyí ni orúkọ tí a ó fi máa pè é: Olúwa Òdodo wa.
7 Nolaila, aia hoi, e hiki mai ana na la, wahi a Iehova, aole lakou e olelo hou mai, Ke ola la no o Iehova, ka mea nana i lawe mai ka poe mamo a Iseraela, mai ka aina o Aigupita mai;
Nítorí náà, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí ènìyàn kì yóò tún wí pé, ‘Dájúdájú Olúwa wà láààyè tí ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.’
8 Aka, Ke ola la no o Iehova, ka mea nana i lawe mai, alakai hoi i na hua o ka hale o ka Iseraela, mai ka aina o ko kukulu akau mai, a mai na aina a pau mai, kahi a'u i kipaku aku ai ia lakou; a e noho no lakou ma ko lakou aina iho.
Ṣùgbọ́n wọn yóò máa wí pé, ‘Dájúdájú Olúwa ń bẹ tí ó mú irú-ọmọ ilé Israẹli wá láti ilẹ̀ àríwá àti láti àwọn ilẹ̀ ibi tí mo tí lé wọn lọ,’ wọn ó sì gbé inú ilẹ̀ wọn.”
9 Ua nahae ko'u naau iloko o'u no na kaula, haalulu no hoi ko'u mau iwi a pau. Ua like no au me ke kanaka i ona, a like hoi me ke kanaka i lanakilaia e ka waina, no Iehova, a no na huaolelo o kona Hemolele.
Nípa ti àwọn wòlíì èké. Ọkàn mi ti bàjẹ́ nínú mi, gbogbo egungun mi ni ó wárìrì. Èmi dàbí ọ̀mùtí ènìyàn, bí ọkùnrin tí ọtí wáìnì ń pa; nítorí Olúwa àti àwọn ọ̀rọ̀ mímọ́ rẹ̀.
10 No ka mea, ua piha ka aina i ka poe moekolohe; no ka mea, ke kumakena nei ka aina, no ka hoohiki ino aua: ua maloo hoi na wahi maikai o ka waonahele; ua hewa ko lakou holo ana, aole hoi i pono ko lakou ikaika.
Ilẹ̀ náà kún fún panṣágà ènìyàn; nítorí ègún, ilẹ̀ náà gbẹ, àwọn koríko orí aṣálẹ̀ ilẹ̀ náà rọ. Àwọn wòlíì tẹ̀lé ọ̀nà búburú, wọ́n sì ń lo agbára wọn lọ́nà àìtọ́.
11 No ka mea, ua aia no ke kaula, a me ke kahuna, oia, ua loaa no ia'u ko lakou hewa maloko o ko'u hale, wahi a Iehova.
“Wòlíì àti àlùfáà kò gbé ìgbé ayé ìwà-bí-Ọlọ́run; kódà nínú tẹmpili mi ni mo rí ìwà búburú wọn,” ni Olúwa wí.
12 Nolaila, e like auanei ko lakou aoao ia lakou, me kahi pahee maloko o ka pouli; e kipakuia'ku la no lakou, a e haule iloko olaila; no ka mea, e lawe no wau i ka hewa maluna o lakou, i ka makahiki hoi o ko lakou hoopaiia, wahi a Iehova.
“Nítorí náà, ọ̀nà wọn yóò di yíyọ́, a ó lé wọn jáde sínú òkùnkùn; níbẹ̀ ni wọn yóò ṣubú. Èmi yóò mú ìdààmú wá sórí wọn, ní ọdún tí a jẹ wọ́n ní ìyà,” ni Olúwa wí.
13 Ua ike no au i ka lapuwale maloko o na kaula o Samaria, a wanana ae lakou ma o Baala la, a alakai hewa iho la i ko'u poe kanaka, i ka Iseraela.
“Láàrín àwọn wòlíì Samaria, Èmi rí ohun tí ń lé ni sá. Wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórúkọ Baali wọ́n sì mú Israẹli ènìyàn mi ṣìnà.
14 Ua ike no hoi au i ka mea inoino loa iloko o na kaula o Ierusalema; moe kolohe no lakou, a hele ma ka wahahee. Hooikaika no hoi lakou i na lima o ka poe hana hewa, i hoi ole mai kekahi, mai kona hewa mai. Ua like no lakou a pau ia'u me ko Sodoma, a o ka poe hoi e noho ana malaila, ua like no me ko Gomora.
Àti láàrín àwọn wòlíì Jerusalẹmu, èmi ti rí ohun búburú. Wọ́n ṣe panṣágà, wọ́n sì ń ṣèké. Wọ́n fún àwọn olùṣe búburú ní agbára, tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí ẹnìkan tí ó yípadà kúrò nínú ìwà búburú rẹ̀. Gbogbo wọn dàbí Sodomu níwájú mi, àti àwọn ènìyàn olùgbé rẹ̀ bí Gomorra.”
15 Nolaila, penei ka olelo ana mai a Iehova o na kaua, no na kaula; Aia hoi, e hanai aku au ia lakou i ka laau awaawa, a e hoohainu aku au ia lakou i ka wai o ke au; no ka mea, mai na kaula o Ierusalema aku i hele aku ai ka aia, a i ka aina a pau.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí ní ti àwọn wòlíì: “Èmi yóò mú wọn jẹ oúnjẹ kíkorò, wọn yóò mu omi májèlé nítorí láti ọ̀dọ̀ àwọn wòlíì Jerusalẹmu ni àìwà-bí-Ọlọ́run ti tàn ká gbogbo ilẹ̀.”
16 Ke olelo mai nei o Iehova o na kaua penei, Mai hoolohe oukou i na olelo a na kaula, ka poe wanana mai ia oukou. Hoolilo no lakou ia oukou i mea lapuwale; hai mai no lakou i ka hihio o ko lakou naau iho, aole mai ka waha o Iehova mai.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ má ṣe fi etí sí àsọtẹ́lẹ̀ tí àwọn wòlíì èké ń sọ fún un yín. Wọ́n ń kún inú ọkàn yín pẹ̀lú ìrètí asán. Wọ́n ń sọ ìran láti ọkàn ara wọn, kì í ṣe láti ẹnu Olúwa.
17 Ke olelo ikaika mai nei lakou i ka poe hoowahawaha mai ia'u, Ua olelo mai o Iehova, E loaa ia oukou ka maluhia: a olelo no hoi lakou i kela mea i keia mea i hele mamuli o ka paakiki o kona naau iho, Aohe hewa e hiki mai ana maluna o oukou.
Wọ́n ń sọ fún àwọn tí ó ń gàn mí pé, ‘Olúwa ti wí pé, ẹ̀yin ó ní àlàáfíà.’ Wọ́n sì wí fún gbogbo àwọn tí ó rìn nípa agídí ọkàn rẹ̀ pé, ‘Kò sí ìpalára kan tí yóò ṣẹlẹ̀ sí yín.’
18 No ka mea, owai ka mea i ku ma ka ahaolelo o Iehova, a ike aku la, a lohe i kana olelo? Owai ka mea i haliu aku i kana olelo a lohe?
Ṣùgbọ́n èwo nínú wọn ni ó dúró nínú ìgbìmọ̀ Olúwa láti rí i tàbí gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀? Ta ni ó gbọ́ tí ó sì fetí sí ọ̀rọ̀ náà?
19 Aia hoi, he puahiohio no Iehova ka i puka mai me ka huhu, he puahiohio nui loa; e haule ino no ia maluna o ke poo o ka poe hewa.
Wò ó, afẹ́fẹ́ Olúwa yóò tú jáde pẹ̀lú ìbínú à fẹ́ yíká ìjì yóò fẹ́ sí orí àwọn olùṣe búburú.
20 Aole e hoi hou aku ka huhu o Iehova, a hooko oia, a hana io i ka manao o kona naau. I na la mahope, e hoomaopopo loa oukou ia mea.
Ìbínú Olúwa kì yóò yẹ̀ títí tí yóò sì fi mú èrò rẹ̀ ṣẹ, ní àìpẹ́ ọjọ́, yóò yé e yín yékéyéké.
21 Aole au i hoouna aku i keia poe kaula, ua holo nae lakou; aole au i olelo ia lakou, aka, ua wanana ae lakou.
Èmi kò rán àwọn wòlíì wọ̀nyí síbẹ̀ wọ́n lọ pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọn. Èmi kò tilẹ̀ bá wọn sọ̀rọ̀, síbẹ̀ wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀.
22 Aka, ina i ku lakou maloko o ka'u ahaolelo; ina ua hana aku i ko'u poe kanaka e lohe i ka'u mau olelo, ina ua hoohuli hoi lakou i kela poo, mai ko lakou aoao hewa mai, a mai ka hewa mai hoi o ka lakou hana ana.
Ṣùgbọ́n ì bà ṣe pé wọn dúró nínú ìgbìmọ̀ mi, wọn ìbá ti kéde ọ̀rọ̀ mi fún àwọn ènìyàn mi. Wọn ìbá ti wàásù ọ̀rọ̀ mi fun àwọn ènìyàn wọn ìbá ti yípadà kúrò nínú ọ̀nà àti ìṣe búburú wọn.
23 He Akua kokoke nei au, wahi a Iehova, aole hoi he Akua ma kahi loihi aku?
“Ǹjẹ́ Ọlọ́run tòsí nìkan ni Èmi bí?” ni Olúwa wí, “kì í sì í ṣe Ọlọ́run ọ̀nà jíjìn.
24 E huna anei kekahi ia ia iho ma na wahi malu, i ike ole aku ai au ia ia, wahi a Iehova? Aole anei au i hoopiha i ka lani, a me ka honua? wahi a Iehova.
Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè sá pamọ́ sí ibi kọ́lọ́fín kan, kí èmi má ba a rí?” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ èmi kò ha a kún ọ̀run àti ayé bí?” ni Olúwa wí.
25 Ua lohe no wau i na mea a na kaula i olelo ai, ka poe i wanana wahahee ma ko'u inoa, me ka olelo iho, Ua moeuhane au, ua moeuhane au.
“Mo ti gbọ́ gbogbo ohun tí àwọn wòlíì èké tí ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ mi ń sọ. Wọ́n sọ wí pé, ‘Mo lá àlá! Mo lá àlá!’
26 Pehea la ka loihi o ka noho ana o keia iloko o ka naau o na kaula, ka poe wanana wahahee? Oia, he poe kaula lakou no ka hoopunipuni o ko lakou naau iho;
Títí di ìgbà wo ni èyí yóò fi máa tẹ̀síwájú ni ọkàn àwọn wòlíì èké wọ̀nyí tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ ìtànjẹ ọkàn wọn?
27 He poe manao e haawi i ko'u poe kanaka i ka hoopoina i ko'u inoa, no ko lakou mau moeuhane, na mea a kela mea keia mea o lakou i hai ae i kona hoalauna, e like me ko lakou poe makua i hoopoina i ko'u inoa ma o Baala la.
Wọ́n rò wí pé àlá tí wọ́n ń sọ fún ara wọn yóò mú kí àwọn ènìyàn mi gbàgbé orúkọ mi, gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn ṣe gbàgbé orúkọ mi nípa sí sin òrìṣà Baali.
28 O ke kaula moeuhane, e hai ae oia i ka moeuhane; a o ka mea ia ia ka'u olelo, e hai pololei oia i ka'u olelo. Heaha ke aa i ka palaoa, wahi a Iehova?
Jẹ́ kí wòlíì tí ó bá lá àlá sọ àlá rẹ̀, ṣùgbọ́n jẹ́ kí ẹni tí ó ní ọ̀rọ̀ mí sọ ọ́ ní òtítọ́. Kí ni koríko gbígbẹ ní í ṣe nínú ọkà?” ni Olúwa wí.
29 Aole anei i like ka'u olelo me ke ahi? wahi a Iehova; a like hoi me ka hamare, ka mea e nahaha ai ka pohaku?
“Ọ̀rọ̀ mi kò ha a dàbí iná?” ni Olúwa wí, “àti bí òòlù irin tí ń fọ́ àpáta túútúú?
30 Nolaila au e ku e nei i na kaula, wahi a Iehova, na mea aihue i ka'u mau olelo, o kela kanaka keia kanaka i ka kona hoalauna.
“Nítorí náà, èmi lòdì sí àwọn wòlíì ni,” Olúwa wí, “Tí ń jí ọ̀rọ̀ tí ó yẹ kí ó ti ọ̀dọ̀ mi wá lò lọ́dọ̀ ara wọn.
31 Aia hoi, ke ku e nei au i na kaula, wahi a Iehova, ka poe hana me ko lakou alelo, a olelo mai, Ke i mai nei oia.
Bẹ́ẹ̀,” ni Olúwa wí, “Èmi lòdì sí àwọn wòlíì tí wọ́n lo ahọ́n wọn káàkiri, síbẹ̀ tí wọ́n ń sọ wí pé, ‘Olúwa wí.’
32 Aia hoi, ke ku e nei au i ka poe wanana iho i na moeuhane wahahee, wahi a Iehova, a hai ae ia mau mea, a alakai hewa i ko'u poe kanaka, i ka lakou mau mea wahahee, a i ka lakou kaena ana: aole nae au i hoouna ia lakou, aole i kauoha aku ia lakou: nolaila, aole lakou e hoopomaikai iki i keia poe kanaka, wahi a Iehova.
Nítòótọ́, mo lòdì sí àwọn tí ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa àlá èké,” ni Olúwa wí. “Wọ́n ń sọ bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń mú àwọn ènìyàn mi ṣìnà nípa onírúurú èké wọn, síbẹ̀ èmi kò rán wọn tàbí yàn wọ́n. Wọn kò sì ran àwọn ènìyàn wọ̀nyí lọ́wọ́ bí ó ti wù kí ó kéré mọ,” ni Olúwa wí.
33 A hiki i ka manawa e ninau mai ai ia oe, o keia poe kanaka, a o ke kaula paha, a o ke kahuna paha, a olelo mai, Heaha ka wanana a Iehova? Alaila, e olelo aku oe ia lakou, O ka wanana hea? E haalele no wau ia oukou, wahi a Iehova.
“Nígbà tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, tàbí wòlíì tàbí àlùfáà bá bi ọ́ léèrè wí pé, ‘Kí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa?’ Sọ fún wọn wí pé, ‘Ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ wo? Èmi yóò pa yín tì ni Olúwa wí.’
34 A o ke kaula, a o ke kahuna, a o ka lahuikanaka e olelo, Ka wanana a Iehova, na'u no e hoopai aku i kela kanaka, a me ko kona hale.
Bí wòlíì tàbí àlùfáà tàbí ẹnikẹ́ni bá sì gbà wí pé, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa.’ Èmi yóò fi ìyà jẹ ọkùnrin náà àti gbogbo agbo ilé rẹ̀.
35 Penei oukou e olelo ai, o kela mea keia mea i kona hoalauna, o kela mea keia mea i kona hoahanau; Heaha ka Iehova i pane mai ai? a heaha hoi ka Iehova i olelo mai ai?
Èyí ni ohun tí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín ń sọ fún ọ̀rẹ́ àti ará ilé rẹ̀: ‘Kí ni ìdáhùn Olúwa?’ Tàbí ‘Kí ni ohun tí Olúwa sọ?’
36 A mai hai hou oukou i ka wanana a Iehova; no ka mea, o ka olelo a kela kanaka keia kanaka, oia kana wanana: no ka mea, ua hoololi oukou i na olelo a ke Akua ola, o Iehova o na kaua, o ko kakou Akua.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọdọ̀ dárúkọ ọ̀rọ̀ ‘ìjìnlẹ̀ Olúwa’ mọ́, nítorí pé ọ̀rọ̀ oníkálùkù ènìyàn di ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ rẹ̀. Nítorí náà, ẹ̀yin ń yí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run alààyè, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run wa padà.
37 Penei oe o olelo aku ai i ke kaula, Heaha ka Iehova i pane mai ai ia oe? a heaha hoi ka Iehova i olelo mai ai?
Èyí ni ohun tí ẹ̀yin ń sọ fún wòlíì: ‘Kí ni ìdáhùn Olúwa sí ọ́?’ Tàbí ‘Kí ni ohun tí Olúwa bá ọ sọ?’
38 Aka, no ka oukou olelo ana, Ka wanana a Iehova; nolaila, penei ka olelo ana mai a Iehova; No ka oukou olelo ana mai i keia olelo, Ka wanana a Iehova, a ua hoouna aku au ia oukou, me ka i iho, Mai olelo oukou, Ka wanana a Iehova;
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀yin ń sọ wí pé, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa,’ èyí ni ohun tí Olúwa sọ, Ẹ̀yin ń lo ọ̀rọ̀ yìí, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa,’ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo sọ fún un yín láti má ṣe lò ó mọ́, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa.’
39 Nolaila, wau no, e hoopoina loa no wau ia oukou, a e haalele no wau ia oukou, a me ke kulanakauhale a'u i haawi aku ai ia oukou, a me ko oukou poe kupuna, a e lilo auanei oukou mai ko'u alo aku.
Nítorí náà, Èmi yóò gbàgbé yín, bẹ́ẹ̀ ni n ó lé e yín kúrò níwájú mi pẹ̀lú àwọn ìlú tí mo fi fún un yín àti àwọn baba yín.
40 A e haawi no wau ia oukou, i mea hoowahawaha mau loa, a i hilahila pau ole, aole hoi e poinaia.
Èmi yóò sì mú ìtìjú ayérayé wá sí orí yín, ìtìjú tí kò ní ní ìgbàgbé.”

< Ieremia 23 >