< Isaia 55 >

1 E A! na mea a pau e makewai, E hele mai oukou i na wai, A o ka mea kala ole, e hele mai hoi oukou, e kuai no, a e ai iho; Oia, e hele mai, e kuai i ka waina, a me ka waiu, me ke kala ole, a me ke kumu ole.
“Ẹ wá, gbogbo ẹ̀yin tí òǹgbẹ ń gbẹ, ẹ wá sí ibi omi; àti ẹ̀yin tí kò ní owó; ẹ wá, ẹ rà kí ẹ sì jẹ! Ẹ wá ra wáìnì àti wàrà láìsí owó àti láìdíyelé.
2 No ke aha la oukou i kaupaona aku ai i ka oukou kala i ka mea, aole ia he berena? A i ko oukou waiwai hoi, i ka mea hoomaona ole mai? E hoolohe pono mai oukou ia'u, a e ai hoi i ka mea i maikai io, A e olioli hoi ko oukou uhane ma ka momona.
Èéṣe tí ẹ fi ń ná owó fún èyí tí kì í ṣe àkàrà àti làálàá yín lórí ohun tí kì í tẹ́nilọ́rùn? Tẹ́tí sílẹ̀, tẹ́tí sí mi, kí ẹ sì jẹ èyí tí ó dára, bẹ́ẹ̀ ni ọkàn yín yóò láyọ̀ nínú ọrọ̀ tí ó bójúmu.
3 E haliu mai i ko oukou pepeiao, a e hele mai ia'u; A hoolohe mai, a e ola no ko oukou uhane; A e hana no au me oukou i berita mau loa, I ka lokomaikai oiaio hoi o Davida.
Tẹ́tí sílẹ̀ kí o sì wá sọ́dọ̀ mi; gbọ́ tèmi, kí ọkàn rẹ lè wà láààyè. Èmi yóò dá májẹ̀mú ayérayé pẹ̀lú rẹ, ìfẹ́ òtítọ́ tí mo ṣèlérí fún Dafidi.
4 Aia hoi, ua haawi aku au ia ia i mea hoike no na kanaka, I alakai hoi, a i luna no na lahuikanaka.
Kíyèsi i, mo ti fi òun ṣe ẹlẹ́rìí fún àwọn ènìyàn, olórí àti apàṣẹ fún àwọn ènìyàn.
5 Aia hoi, e kahea aku no oe i ka lahuikanaka au i ike ole ai; A o ka lahuikanaka i ike ole ia oe, e holo aku no lakou iou la, No Iehova, kou Akua, a no ka Mea Hemolele o ka Iseraela; No ka mea, ua hoonani mai oia ia oe.
Lóòtítọ́ ìwọ yóò ké sí àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò mọ̀ àti orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò mọ̀ ni yóò sáré tọ̀ ọ́ wá, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ Ẹni Mímọ́ Israẹli nítorí pé ó ti fi ohun dídára dá ọ lọ́lá.”
6 E imi oukou ia Iehova, oiai oia ma kahi e loaa'i, E hea aku ia ia, oiai oia ma kahi kokoke.
Ẹ wá Olúwa nígbà tí ẹ lè rí i; ẹ pè é nígbà tí ó wà nítòsí.
7 E haalele ke kanaka hewa i kona aoao, A me ke kanaka lawehala, i kona mau manao; A e hoi mai hoi oia io Iehova la, a e lokomaikai no oia ia ia, A i ko kakou Akua hoi, no ka mea, e kala nui loa auanei oia.
Jẹ́ kí ìkà kí ó kọ ọ̀nà rẹ̀ sílẹ̀ àti ènìyàn búburú èrò rẹ̀. Jẹ́ kí ó yípadà sí Olúwa, Òun yóò sì ṣàánú fún un, àti sí Ọlọ́run wa, nítorí Òun yóò sì dáríjì.
8 No ka mea, o ko'u mau manao, aole ia o ko oukou mau manao, A o ko oukou mau aoao, aole ia o ko'u mau aoao, wahi a Iehova.
“Nítorí èrò mi kì í ṣe èrò yín, tàbí ọ̀nà yín a ha máa ṣe ọ̀nà mi,” ni Olúwa wí.
9 No ka mea, e like me ke kiekie o na lani maluna o ka honua, Pela no ke kiekie o ko'u mau aoao maluna o ko oukou mau aoao, A me ko'u mau manao, maluna o ko oukou mau manao.
“Gẹ́gẹ́ bí ọ̀run ti ga ju ayé lọ, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀nà mi ga ju ọ̀nà yín lọ àti èrò mi ju èrò yín lọ.
10 No ka mea, e like me ka ua, a me ka hau i iho mai, mai na lani mai, Aole hoi e hoi hou ilaila, aka, e hoomau mai no i ka honua, A hoohua iho la ia ia, e hoomuo no hoi, I haawi mai ia i ka hua na ka mea lulu hua, A i berena hoi na ka mea ai;
Gẹ́gẹ́ bí òjò àti yìnyín ti wálẹ̀ láti ọ̀run tí kì í sì padà sí ibẹ̀ láì bomirin ilẹ̀ kí ó sì mú kí ó tanná kí ó sì rudi, tó bẹ́ẹ̀ tí yóò fi mú irúgbìn fún afúnrúgbìn àti àkàrà fún ọ̀jẹun,
11 Pela auanei ka'u olelo, ka mea i puka aku, mai ko'u waha aku, Aole ia e hoi nele mai ia'u; Aka, e hana no ia i ka mea a'u e makemake ai, A e hooko io ia i ka mea a'u e hoouna aku ai ia ia.
bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rọ̀ mi tí ó jáde láti ẹnu mi wá; kì yóò padà sọ́dọ̀ mi lọ́wọ́ òfo, ṣùgbọ́n yóò ṣe ohun tí mo fẹ́, yóò sì mú ète mi tí mo fi rán an wá sí ìmúṣẹ.
12 No ka mea, e puka aku auanei oukou me ka olioli, A e alakaiia'ku oukou me ka malu: E hookani i ke oli na kuahiwi, a me na mauna imua o oukou, A e paipailima hoi na laau a pau o ke kula.
Ẹ̀yin yóò jáde lọ ní ayọ̀ a ó sì darí i yín lọ ní àlàáfíà; òkè ńlá ńlá àti kéékèèké yóò bú sí orin níwájú yín àti gbogbo igi inú pápá yóò máa pàtẹ́wọ́.
13 Ma kahi o ke kakalaioa e ulu mai auanei ka laau kaa, A ma kahi o ka laau ooi, ka hadasa hoi; A e lilo ia i mea kaulana no Iehova, I ouli mau loa no hoi e hooki ole ia'i.
Dípò igi ẹ̀gún ni igi junifa yóò máa dàgbà, àti dípò ẹ̀wọ̀n, maritili ni yóò yọ. Èyí yóò wà fún òkìkí Olúwa, fún àmì ayérayé, tí a kì yóò lè parun.”

< Isaia 55 >