< Isaia 49 >

1 E HALIU mai oukou ia'u, e na aina e, E hoolohe hoi oukou, e na lahuikanaka, ma kahi mamao aku; Hea mai o Iehova ia'u mai ka opu mai, Mai ka opu mai hoi o ko'u makuwahine, ua hoike oia i ko'u inoa.
Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin erékùṣù: gbọ́ èyí, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè jíjìnnà réré: kí a tó bí mi Olúwa ti pè mí; láti ìgbà bíbí mi ni ó ti dá orúkọ mi.
2 Ua hana oia i ko'u waha a like me ka pahikaua oi, Ua huna mai oia ia'u ma ke aka o kona lima, Ua hana mai oia ia'u, a like me ka pua i anaiia, Ua huna mai oia ia'u iloko o kona aapua,
Ó ṣe ẹnu mi bí idà tí a pọ́n, ní abẹ́ òjìji ọwọ́ rẹ̀ ni ó ti pa mí mọ́: ó ṣe mí ní ọfà tí a ti dán, ó sì fi mí pamọ́ sínú àpò rẹ̀.
3 Ua olelo mai oia ia'u, O oe no ka'u kauwa, O Iseraela hoi oe, ka mea a'u e hoonaniia'i.
Ó sọ fún mi pé, “Ìránṣẹ́ mi ni ìwọ í ṣe, Israẹli nínú ẹni tí n ó ti fi ògo mi hàn.”
4 Alaila, i iho la au, Ua hooikaika makehewa au, No ka ole, a no ka lapuwale au i hoopau ai i ko'u ikaika; Me Iehova nae ko'u aponoia. Me ko'u Akua hoi ka'u hana ana.
Ṣùgbọ́n èmi sọ pé, “Mo ti ṣe wàhálà lórí asán; mo ti lo gbogbo ipá mi lórí asán àti ìmúlẹ̀mófo. Síbẹ̀síbẹ̀ ohun tí ó tọ́ sí mi ṣì wà lọ́wọ́ Olúwa, èrè mi sì ń bẹ pẹ̀lú Ọlọ́run mi.”
5 Ano ke olelo mai nei o Iehova, Ka mea i hana mai ia'u i kauwa nana, mai ka opu mai, I mea hoi e hoihoi mai i ka Iakoba ia ia, Ina e hoakoakoa ole ia ka Iseraela, E nani io no nae au ma na maka o Iehova, O ko'u Akua hoi oia ko'u ikaika.
Nísinsin yìí Olúwa wí pé ẹni tí ó mọ̀ mí láti inú wá láti jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ láti mú Jakọbu padà tọ̀ mí wá àti láti kó Israẹli jọ sọ́dọ̀ ara rẹ̀, nítorí pé a bọ̀wọ̀ fún mi ní ojú Olúwa Ọlọ́run mi sì ti jẹ́ agbára mi,
6 I mai la ia, He mea uuku ia e lilo oe i kauwa na'u, E hooku mai i na ohana o ka Iakoba, A e hoihoi i ka poe i malamaia o ka Iseraela; E haawi no hoi au ia oe i malamalama no ko na aina e, I lilo oe i mea hoola aku no'u, ma na kukulu o ka honua,
Òun wí pé: “Ó jẹ́ ohun kékeré fún ọ láti jẹ́ ìránṣẹ́ mi láti mú ẹ̀yà Jakọbu padà bọ̀ sípò àti láti mú àwọn ti Israẹli tí mo ti pamọ́. Èmi yóò sì fi ọ́ ṣe ìmọ́lẹ̀ fún àwọn kèfèrí, kí ìwọ kí ó lè mú ìgbàlà mi wá sí òpin ilẹ̀ ayé.”
7 Penei ka olelo ana mai a Iehova, Ka Hoolapanai o ka Iseraela, kona mea Hemolele hoi, I ka mea i hoowahawahaia e na kanaka, I ka mea a ka lahuikanaka i hoopailua ai, I ke kauwa hoi na ka poe e noho alii ana, E ike aku na'lii a e ku iluna, E kulou aku no hoi na luna, No Iehova, ka mea oiaio, ka Mea Hemolele o ka Iseraela, Nana no e makemake aku ia oe.
Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Olùdáǹdè àti Ẹni Mímọ́ Israẹli— sí ẹni náà tí a gàn tí a sì kórìíra lọ́wọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, sí ìránṣẹ́ àwọn aláṣẹ: “Àwọn ọba yóò rí ọ wọn yóò sì dìde sókè, àwọn ọmọ ọba yóò rí i wọn yóò sì wólẹ̀, nítorí Olúwa ẹni tí í ṣe olóòtítọ́, Ẹni Mímọ́ Israẹli tí ó ti yàn ọ́.”
8 Ke olelo mai nei o Iehova penei, I ka manawa aloha, ua hoolohe aku au ia oe, A i ka la hoola, ua kokua aku no au ia oe; A na'u hoi e malama aku ia oe, A e haawi no hoi ia oe i berita no na kanaka, I mea e paa ai ka aina, e hooili aku no hoi i na hooilina neoneo;
Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Ní àkókò ojúrere mi, èmi yóò dá ọ lóhùn, àti ní ọjọ́ ìgbàlà, èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́; Èmi yóò pa ọ́ mọ́, n ó sì ṣe ọ́ láti jẹ́ májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn, láti mú ilẹ̀ padà bọ̀ sípò àti láti ṣe àtúnpín ogún rẹ̀ tí ó ti dahoro,
9 I olelo no hoi oe i ka poe i paa, E hele iwaho, A i ka poe ma ka pouli, E hoike ia oukou iho. E ai no lakou ma na alanui, A ma na puu a pau ka lakou ai.
láti sọ fún àwọn ìgbèkùn pé, ‘Ẹ jáde wá,’ àti fún àwọn tí ó wà nínú òkùnkùn pé, ‘Ẹ gba òmìnira!’ “Wọn yóò máa jẹ ní ẹ̀bá ọ̀nà àti koríko tútù lórí òkè aláìléwéko.
10 Aole lakou e pololi, aole e makewai; Aole e hahau mai ka wela, a me ka la ia lakou; No ka mea, o ka mea aloha ia lakou, nana lakou e alakai, E alakai aku no oia ia lakou i na waipuna.
Ebi kì yóò pa wọ́n bẹ́ẹ̀ ni òǹgbẹ kì yóò gbẹ wọ́n, tàbí kí ooru inú aṣálẹ̀ tàbí oòrùn kí ó pa wọ́n. Ẹni tí ó ṣàánú fún wọn ni yóò máa tọ́ wọn, tí yóò sì mú wọn lọ sí ibi orísun omi.
11 E hoolilo ana no au i ko'u mau kuahiwi a pau, i alanui, A e hookiekieia hoi ko'u mau kuamoo.
Èmi yóò sọ gbogbo àwọn òkè ńlá mi di ojú ọ̀nà àti gbogbo òpópónà mi ni a ó gbé sókè.
12 Aia hoi, e hele mai no keia poe, ma kahi loihi mai; Aia hoi, o keia poe, mai ke kukulu akau, a mai ke komohana mai; A o keia poe hoi, mai ka aina o Sinima mai.
Kíyèsi i, wọn yóò wá láti ọ̀nà jíjìn àwọn díẹ̀ láti àríwá àti àwọn díẹ̀ láti ìwọ̀-oòrùn, àwọn díẹ̀ láti ẹkùn Siene.”
13 E oli oukou, e na lani, e hauoli hoi, e ka honua; E hookani i ke oli, e na mauna; No ka mea, ua hoomaha mai o Iehova i kona poe kanaka, A e aloha mai no hoi ia i kona poe i hoopilikiaia.
Ẹ hó fún ayọ̀, ẹyin ọ̀run; yọ̀, ìwọ ilẹ̀ ayé; bú sórin, ẹ̀yin òkè ńlá! Nítorí Olúwa tu àwọn ènìyàn rẹ̀ nínú yóò sì ṣàánú fún àwọn ẹni tí a ń pọ́n lójú.
14 Aka, ua olelo mai o Ziona, Ua haalele o Iehova ia'u, Ua hoopoina hoi ko'u Haku ia'u.
Ṣùgbọ́n Sioni sọ pé, “Olúwa ti kọ̀ mí sílẹ̀, Olúwa ti gbàgbé è mi.”
15 E hiki anei i ka wahine ke hoopoina i kana keiki aiwaiu, I ole ia e aloha aku i ke keiki a kona opu? Oia, e hiki no ia lakou ke hoopoina. Aka, aole au e hoopoina ia oe.
“Ǹjẹ́ abiyamọ ha le gbàgbé ọmọ ọmú rẹ̀ kí ó má sì ṣàánú fún ọmọ rẹ̀ tí ó ti bí? Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun le gbàgbé, Èmi kì yóò gbàgbé rẹ!
16 Aia hoi, ua kahakaha au ia oe ma na poho lima o'u; Ua mau loa no kou mau papohaku ma ko'u alo.
Kíyèsi i, mo ti kọ ọ́ sí àtẹ́lẹwọ́ mi ògiri rẹ wà níwájú mi nígbà gbogbo.
17 E hiki wawe no kau mau keiki; O ka poe nana oe i pepehi, A me ka poe i hooneoneo ia oe, e puka aku no lakou mawaho ou.
Àwọn ọmọ rẹ ti kánjú padà, àti àwọn tí ó sọ ọ́ dahoro ti padà lẹ́yìn rẹ.
18 E alawa ae oe i kou mau maka mao, a mao, e nana hoi; Akoakoa mai lakou a pau, a hele mai iou la. Me au e ola nei, wahi a Iehova, E aahu io no oe ia lakou a pau me he kahiko la, A e kakoo hoi ia lakou, e like me ka wahine mare.
Gbójú rẹ sókè kí o sì wò yíká; gbogbo àwọn ọmọkùnrin rẹ kórajọ wọ́n sì wá sọ́dọ̀ rẹ. Níwọ́n ìgbà tí mo bá wà láààyè,” ni Olúwa wí, “Ìwọ yóò wọ gbogbo wọ́n gẹ́gẹ́ bí ohun ọ̀ṣọ́; ìwọ yóò wọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí ìyàwó.
19 No ka mea, o kou mau wahi mehameha, a neoneo, A me ka aina o kou luku ana, E pilikia ana no ia, no ka nui o ka poe e noho ana; A e loihi lilo aku no hoi ka poe i ale ia oe.
“Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a tí run ọ́, a sì sọ ọ́ di ahoro tí gbogbo ilẹ̀ rẹ sì di ìparun, ní ìsinsin yìí, ìwọ yóò kéré jù fún àwọn ènìyàn rẹ, bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ó jẹ ọ́ run ni yóò wà láti ọ̀nà jíjìn réré.
20 O na keiki o kou pa ana, e olelo no lakou ma kou mau pepeiao, Ua pilikia au i keia wahi, E haawi mai ia'u i wahi e noho ai au.
Àwọn ọmọ tí a bí ní àkókò ọ̀fọ̀ rẹ yóò sọ ní etígbọ̀ọ́ rẹ, ‘Ibi yìí ti kéré jù fún wa; ẹ fún wa láyè sí i tí a ó máa gbé.’
21 Alaila, e olelo iho no oe ma kou naau, Nawai i hoohanau mai i keia poe na'u? Nele au i ka'u mau keiki, a mehameha, He pio no. e kuewa aku ana; Nawai i hoonui mai i keia poe? Aia hoi, ua waiho wale ia au, mahea hoi lakou nei?
Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ ní ọkàn rẹ pé, ‘Ta ló bí àwọn yìí fún mi? Mo ti ṣọ̀fọ̀ mo sì yàgàn; a sọ mi di àtìpó a sì kọ̀ mí sílẹ̀. Ta ló wo àwọn yìí dàgbà? A fi èmi nìkan sílẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí níbo ni wọ́n ti wá?’”
22 Ke olelo mai nei o Iehova, ka Haku penei, Aia hoi, e hapai no wau i ko'u lima no ko na aina e, A e kau no wau i ko'u hae no na lahuikanaka; A e lawe mai no lakou i kau poe keikikane ma ka poli, A e kaikaiia kau mau kaikamahine, ma na poohiwi.
Ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nìyìí, “Kíyèsi i, Èmi yóò ké sí àwọn aláìkọlà, Èmi yóò gbé àsíá mi sókè sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn; wọn yóò kó àwọn ọmọkùnrin yín wá ní apá wọn wọn yóò sì gbé àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin ní èjìká wọn.
23 A e lilo na'lii i poe makuakane hanai nou, A o na wahine alii a lakou, i poe makuwahine hanai nou; A e kulou ilalo i ka honua ko lakou maka imua ou, A e palu iho lakou i ka lepo o kou mau wawae; A e ike auanei oe, owau no Iehova; No ka mea, o ka poe e kali ia'u, aole lakou e hilahila.
Àwọn ọba ni yóò jẹ́ alágbàtọ́ baba fún ọ, àwọn ayaba wọn ni yóò sì jẹ́ ìyá-alágbàtọ́. Wọn yóò foríbalẹ̀ ní iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ojú wọn dídàbolẹ̀; wọn yóò máa lá erùpẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa; gbogbo àwọn tí wọ́n ní ìrètí nínú mi ni a kì yóò jákulẹ̀.”
24 E kailiia'ku anei ka waiwai pio, mai ka poe ikaika aku? E hoopakeleia'nei ke pio i lawe pono ia?
Ǹjẹ́ a le gba ìkógun lọ́wọ́ jagunjagun, tàbí kí á gba ìgbèkùn lọ́wọ́ akíkanjú?
25 Aka, ke olelo mai nei o Iehova penei, E kailiia'ku no na pio o ka poe ikaika, A e hoopakeleia ka waiwai i pio, mai ka poe hooweliweli mai; No ka mea, e paio aku au i ka mea i paio pu me oe, A e hoola no wau i kau poe keiki.
Ṣùgbọ́n ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Bẹ́ẹ̀ ni, a ó gba àwọn ìgbèkùn lọ́wọ́ àwọn jagunjagun, àti ìkógun lọ́wọ́ àwọn akíkanjú; ẹni tí ó bá ọ jà ni èmi ó bá jà, àti àwọn ọmọ rẹ ni èmi ó gbàlà.
26 O ka poe hooluhi aku ia oe, E hanai aku au ia lakou i ko lakou io iho, A e ona auanei lakou i ko lakou koko iho, e like me ka waina hou; A e ike no na mea io a pau, owau no Iehova, O kou Ola, a me kou Hoolapanai, Ka Mea mana hoi o ka Iakoba.
Èmi yóò mú kí àwọn aninilára rẹ̀ jẹ ẹran-ara wọn; wọn yóò mu ẹ̀jẹ̀ ara wọn yó bí ẹni mu wáìnì. Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn yóò mọ̀ pé, Èmi, Olúwa, èmi ni Olùgbàlà rẹ, Olùdáǹdè rẹ, Alágbára kan ṣoṣo ti Jakọbu.”

< Isaia 49 >