< Isaia 43 >
1 A NO, penei ka olelo ana mai a Iehova, ka mea nana oe i hana, e Iakoba, Ka mea nana oe i hookumu, e Iseraela; Mai makau, no ka mea, ua hoola au ia oe; Ua hea aku au ia oe ma ka inoa; no'u no oe.
Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí, ohun tí Olúwa wí nìyìí, ẹni tí ó dá ọ, ìwọ Jakọbu, ẹni tí ó mọ ọ́, ìwọ Israẹli: “Má bẹ̀rù, nítorí Èmi ti dá ọ nídè; Èmi ti pè ọ́ ní orúkọ; tèmi ni ìwọ ṣe.
2 Ia oe e hele mawaena o na wai, owau pu no me oe; A maloko hoi o na muliwai, aole oe e halanaia ia lakou; Ia oe e hele ae maloko o ke ahi, aole oe e wela; Aole hoi e ai aku ka lapalapa ahi ia oe.
Nígbà tí ìwọ bá ń la omi kọjá, Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ; àti nígbà tí ìwọ bá ń la odò kọjá wọn kì yóò bò ọ́ mọ́lẹ̀. Nígbà tí ìwọ bá la iná kọjá, kò ní jó ọ; ahọ́n iná kò ní jó ọ lára.
3 No ka mea, owau no Iehova kou Akua, Ka Mea Hemolele o ka Iseraela, kou mea e ola'i; Ua haawi au ia Aigupita, i panai nou, Ia Aitiopa, a me Seba hoi, i uku panai nou;
Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, Ẹni Mímọ́ Israẹli Olùgbàlà rẹ; Èmi fi Ejibiti ṣe ìràpadà rẹ, Kuṣi àti Seba dípò rẹ.
4 No ka mea, ua makamae oe ma ko'u mau maka, Ua hoomaikaiia hoi oe, a ua aloha aku au ia oe; Nolaila au e panai aku ai i na kanaka nou, A e lilo no na lahuikanaka i panai no kou ola.
Nítorí pé o ṣe iyebíye àti ọ̀wọ́n níwájú mi, àti nítorí pé mo fẹ́ràn rẹ, Èmi yóò fi ènìyàn rọ́pò fún ọ, àti ènìyàn dípò ẹ̀mí rẹ.
5 Mai makau oe, no ka mea, owau pu no me oe; Na'u no e lawe mai i kau poe mamo, mai ka hikina mai, A e hoakoakoa no au i kau, mai ke komohana mai.
Má bẹ̀rù nítorí èmi wà pẹ̀lú rẹ; Èmi yóò mú àwọn ọmọ rẹ láti ìlà-oòrùn wá èmi ó sì kó ọ jọ láti ìwọ̀-oòrùn.
6 E olelo aku no au i ke kukulu akau, E haawi mai; A i ke kukulu hema hoi. Mai aua oe; E kai mai i ka'u mau keiki kane, mai kahi loihi mai, A me ka'u mau kaikamahine, mai na kihi o ka honua;
Èmi yóò sọ fún àríwá pé, ‘Fi wọ́n sílẹ̀!’ Àti fún gúúsù, ‘Má ṣe dá wọn dúró.’ Mú àwọn ọmọkùnrin mi láti ọ̀nà jíjìn wá àti àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin mi láti ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé—
7 O na mea hoi a pau i heaia ma ko'u inoa, A no ko'u nani i hana aku ai au ia lakou; Na'u no i hookumu, na'u hoi i hana.
ẹnikẹ́ni tí a ń pe orúkọ mi mọ́, tí mo dá fún ògo mi, tí mo mọ̀ àti tí mo ṣe.”
8 E kai mai i ka poe kanaka makapo, he mau maka no nae ko lakou, A me na mea kuli hoi, he mau pepeiao no nae ko lakou.
Sin àwọn tí ó ní ojú ṣùgbọ́n tí wọ́n fọ́jú jáde, tí wọ́n ní etí ṣùgbọ́n tí wọn dití.
9 E hoakoakoaia mai ko na aina a pau, E hoiliiliia mai hoi na lahuikanaka a pau; Owai ka mea o lakou e hiki ia ia ke hai i keia, A hoiko mai hoi i na mea kahiko? E kai mai lakou i ko lakou poe ike maka, i hoaponoia'i lakou: A o lakou kekahi e hoolohe mai, a olelo, Ua oiaio.
Gbogbo orílẹ̀-èdè kó ra wọn jọ àwọn ènìyàn sì kó ra wọn papọ̀. Ta ni nínú wọn tó sọ àsọtẹ́lẹ̀ yìí tí ó sì kéde fún wa àwọn nǹkan ti tẹ́lẹ̀? Jẹ́ kí wọ́n mú àwọn ẹlẹ́rìí wọn wọlé wá láti fihàn pé wọ́n tọ̀nà tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn mìíràn yóò gbọ́, tí wọn yóò sọ pé, “Òtítọ́ ni.”
10 O oukou no ko'u poe ike maka, wahi a Iehova, O ka'u kauwa hoi ka mea a'u i wae ai, I ike mai oukou, a manaoio mai ia'u; A hoomaopopo hoi, owau no Ia, Mamua o'u, aohe akua i hanaia, Aole hoi auanei mahope o'u.
“Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi,” ni Olúwa wí, “Àti ìránṣẹ́ mi tí èmi ti yàn, tó bẹ́ẹ̀ tí ẹ̀yin yóò fi mọ̀ àti tí ẹ̀yin ó fi gbà mí gbọ́ tí yóò sì yé e yín pé èmi ni ẹni náà. Ṣáájú mi kò sí ọlọ́run tí a dá, tàbí a ó wa rí òmíràn lẹ́yìn mi.
11 Owau, owau no o Iehova, Aole hoi mea hoola e ae, owau wale no.
Èmi, àní Èmi, Èmi ni Olúwa, yàtọ̀ sí èmi, kò sí olùgbàlà mìíràn.
12 Ua olelo aku no au, ua hoola aku hoi, A ua hoikeike aku hoi, i ka wa aole akua malihini iwaena o oukou: O oukou no ko'u poe ike maka, wahi a Iehova, Owau no ke Akua,
Èmi ti fihàn, mo gbàlà mo sì ti kéde Èmi, kì í sì í ṣe àwọn àjèjì òrìṣà láàrín yín. Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi,” ni Olúwa wí, “Pé Èmi ni Ọlọ́run.
13 Mamua aku o ka manawa, owau no Ia; Aohe mea hiki ke hoopakele, mai ko'u lima aku; Hana no au, a owai la ka mea hiki ke hooki mai?
Bẹ́ẹ̀ ni, àti láti ayérayé Èmi ni ẹni náà. Kò sí ẹnikẹ́ni tí ó lè gbà kúrò lọ́wọ́ mi. Nígbà tí mo bá ṣe nǹkan, ta ni ó lè yí i padà?”
14 Ke olelo mai nei o Iehova, ke oukou Hoolapanai, Ka Mea Hemolele hoi o ka Iseraela, penei; Ua hoouna aku au i Babulona no oukou, A ua kiola au ilalo i ko lakou poe auhee a pau, A me ko Kaledea, ka poe e olioli ana i na moku.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí, olùràpadà rẹ, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli: “Nítorí rẹ Èmi yóò ránṣẹ́ sí Babeli láti mú wọn sọ̀kalẹ̀ wá gẹ́gẹ́ bí ìsáǹsá, gbogbo ará Babeli, nínú ọkọ̀ ojú omi nínú èyí tí wọ́n fi ń ṣe ìgbéraga.
15 Owau no Iehova, ko oukou Mea Hemolele, Ka mea nana i hana ka Iseraela, o ko oukou Alii.
Èmi ni Olúwa, Ẹni Mímọ́ rẹ, Ẹlẹ́dàá Israẹli, ọba rẹ.”
16 Penei i olelo mai ai o Iehova, Ka mea nana i hana i alanui ma ke kai, I kuamoo hoi maloko o na wai nui;
Èyí ni ohun tí Olúwa wí, Ẹni náà tí ó la ọ̀nà nínú Òkun, ipa ọ̀nà láàrín alagbalúgbú omi,
17 Ka mea i hoopuka mai i ke kaakaua, a me ka lio, I ka poe koa, a me ka mea ikaika; Moe pu no lakou ilalo, aole ala hou, Ua kinaiia lakou, ua pio hoi, e like me ka uiki.
ẹni tí ó wọ́ àwọn kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin jáde, àwọn jagunjagun àti ohun ìjà papọ̀, wọ́n sì sùn síbẹ̀, láìní lè dìde mọ́, wọ́n kú pirá bí òwú-fìtílà:
18 Mai hoomanao oukou i na mea mamua, Mai manao hoi i na mea kahiko.
“Gbàgbé àwọn ohun àtẹ̀yìnwá; má ṣe gbé nínú ohun àtijọ́.
19 Aia hoi, e hana ana au i mea hou; I keia manawa no ia e puka mai ai; Aole anei oukou e ike mai? He oiaio no, e hana no wau i alanui ma ka waonahele, A i kahawai hoi ma ka waoakua.
Wò ó, Èmi ń ṣe ohun tuntun! Nísinsin yìí, ó ti yọ sókè; àbí o kò rí i bí? Èmi ń ṣe ọ̀nà kan nínú aṣálẹ̀ àti odò nínú ilẹ̀ ṣíṣá.
20 E hoomaikai mai no ia'u ka holoholona o ke kula, O na iliohae a me na keiki iana; No ka mea, ua haawi au i ka wai ma ka waonahele, A me na muliwai ma ka waoakua, I mea e hoohainu ai i ko'u poe kanaka, i ko'u poe hoi i waeia.
Àwọn ẹhànnà ẹranko bọ̀wọ̀ fún mi, àwọn ajáko àti àwọn òwìwí, nítorí pé mo pèsè omi nínú aṣálẹ̀ àti odò nínú ilẹ̀ sísá, láti fi ohun mímu fún àwọn ènìyàn mi, àyànfẹ́ mi,
21 I keia poe kanaka no a'u i hana'i no'u iho; Na lakou no e hai aku i ko'u nani.
àwọn ènìyàn tí mo dá fún ara mi kí wọn kí ó lè kéde ìyìn mi.
22 Aka, aole oe i hea mai ia'u, e ka Iakoba, Ua uluhua oe ia'u, e ka Iseraela.
“Síbẹ̀síbẹ̀ ìwọ kò tí ì ké pè mí, ìwọ Jakọbu, àárẹ̀ kò tí ì mú ọ nítorí mi ìwọ Israẹli.
23 Aole oe i lawe mai ia'u i ka hipa o kou mau mohaikuni; Aole hoi oe i hoomaikai mai ia'u i kau mau mohai. Aole au i hookaumaha aku ia oe i ka alana, Aole hoi au i hooluhiluhi aku ia oe ma na mea ala.
Ìwọ kò tí ì mú àgùntàn wá fún mi fún ẹbọ sísun, tàbí kí o bọ̀wọ̀ fún mi pẹ̀lú ẹbọ rẹ. Èmi kò tí ì wàhálà rẹ pẹ̀lú ọrẹ ìyẹ̀fun tàbí kí n dààmú rẹ pẹ̀lú ìbéèrè fún tùràrí.
24 Aole oe i kuai i oheala na'u, i ke kala, Aole hoi oe i hoomaona mai ia'u i ke kelekele o kau mau mohai; Aka, ua hookaumaha mai oe ia'u, i kou mau hewa, Ua hooluhiluhi mai oe ia'u i kou mau hala,
Ìwọ kò tí ì ra kalamusi olóòórùn dídùn fún mi, tàbí kí o da ọ̀rá ẹbọ rẹ bò mí. Ṣùgbọ́n ẹ ti wàhálà mi pẹ̀lú ẹ̀ṣẹ̀ yín ẹ sì ti dààmú mi pẹ̀lú àìṣedéédéé yín.
25 Owau, owau no ka mea nana e holoi i kou mau hewa, no'u iho; Aole hoi au e hoomanao i kou mau hala.
“Èmi, àní Èmi, Èmi ni ẹni tí ó wẹ àwọn àìṣedéédéé rẹ nù, nítorí èmi fún ara mi, tí n kò sì rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ mọ́.
26 E hooeueu mai oe i ko'u manao; E hooponopono pu kakou; E hai mai hoi oe, i hoaponoia mai ai oe.
Bojú wo ẹ̀yìn rẹ fún mi, jẹ́ kí a jọ ṣe àríyànjiyàn ọ̀rọ̀ náà papọ̀; ro ẹjọ́ láti fihàn pé o kò lẹ́sẹ̀ lọ́rùn.
27 Hewa no kou makuakane makamua, A ua kipi mai no hoi ia'u kau mau luna.
Baba yín àkọ́kọ́ dẹ́ṣẹ̀; àwọn agbẹnusọ yín ṣọ̀tẹ̀ sí mi.
28 A e hoohaumia aku au i na luna hoano, A e haawi aku au i ka Iakoba no ka poino, A me ka Iseraela no ka hoinoia.
Nítorí náà, èmi ti sọ àwọn olórí ibi mímọ́ náà di àìmọ́, bẹ́ẹ̀ ni èmi ti fi Jakọbu fún ègún àti Israẹli fún ẹ̀gàn.