< Isaia 36 >

1 I KA makahiki umikumamaha o ke alii, o Hezekia, pii ku e mai la Sanekariba ke alii o Asuria, i na kulanakauhale a pau i paa i ka pa o ka Iuda, a hoopio iho la ia lakou.
Ní ọdún kẹrìnlá ìjọba Hesekiah, Sennakeribu ọba Asiria kọlu gbogbo àwọn ìlú olódi ní ilẹ̀ Juda ó sì kó gbogbo wọn.
2 A hoouna ae la ke alii o Asuria ia Rabesake, mai Lakisa ae, a i Ierusalema, i ke alii io Hezekia la, me na koa he nui loa. A ku iho la oia ma ka auwai o ka waipuna luna, ma ke ala e hiki aku ai i ke kula o ka mea holoi lole.
Lẹ́yìn náà, ọba Asiria rán olórí ogun rẹ̀ pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ-ogun láti Lakiṣi sí ọba Hesekiah ní Jerusalẹmu. Nígbà tí ọ̀gágun náà dúró níbi ojúṣàn adágún ti apá òkè, ní ojú ọ̀nà sí pápá alágbàfọ̀,
3 Alaila, hele aku la io na la, o Eliakima, ke keiki a Hilekia, o ka mea maluna o ko ka hale, a me Sebena, ke kakauolelo, a me Ioa, ke keiki a Asana, ke kakaumooolelo.
Ṣebna Eliakimu ọmọ Hilkiah alábojútó ààfin, Ṣebna akọ̀wé, àti Joah ọmọ Asafu akọ̀wé jáde lọ pàdé rẹ̀.
4 I mai la o Rabesake ia lakou, E i aku oukou ia Hezekia, ke olelo mai nei ke alii nui, ke alii o Asuria penei, Heaha keia hilinai ana au e hilinai nei?
Ọ̀gágun náà sọ fún wọn wí pé, “Ẹ sọ fún Hesekiah, “‘Èyí yìí ni ohun tí ọba ńlá, ọba Asiria sọ pé: Lórí i kí ni ìwọ gbé ìgbẹ́kẹ̀lé tìrẹ yìí lé?
5 Ke olelo nei au, he olelo lapuwale kou akamai a me kou ikaika i ke kaua. Ke hilinai aku nei oe ia wai, i kipi mai ai oe ia'u?
Ìwọ sọ wí pé ìwọ ní ète àti agbára ogun—ṣùgbọ́n ìwọ ń sọ ọ̀rọ̀ asán. Ta ni ìwọ gbẹ́kẹ̀lé tí ìwọ fi ṣọ̀tẹ̀ sí mi?
6 Aia ka! ke hilinai nei oe i ke kookoo o keia ohe naha, o Aigupita, ka mea e komo ai i ka lima a puka, ke hilinai ke kanaka maluna ona. Pela o Parao, ke alii o Aigupita i ka poe a pau i hilinai maluna ona.
Wò ó nísinsin yìí, ìwọ gbẹ́kẹ̀lé Ejibiti ẹ̀rún igi ọ̀pá lásán tí í gún ni lọ́wọ́ tí í sì í dọ́gbẹ́ sí ni lára tí a bá gbára lé e! Bẹ́ẹ̀ ni Farao ọba Ejibiti sí àwọn tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé e.
7 Aka, ina olelo mai oe ia'u. Ke hilinai aku nei makou ia Iehova, i ko makou Akua; aole anei oia ka mea nona na wahi kiekie, a nona hoi na kuahu a Hezekia i wawahi ai, a ua olelo no hoi i ka Iuda, a i ko Ierusalema, Mamua o keia kuahu oukou e hoomana'i?
Bí o bá sì sọ fún mi pé, “Àwa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run wa,” kì í ṣe òun ni Hesekiah ti mú àwọn ibi gíga àti pẹpẹ rẹ̀ kúrò, tí ó sì wí fún Juda àti Jerusalẹmu pé, “Ẹ̀yin gbọdọ̀ sìn níwájú pẹpẹ yìí”?
8 Ano la, ea, e hoolimalima oe me kuu haku, me ke alii o Asuria, a e haawi aku no au ia oe i elua tausani lio, ina paha e hiki ia oe ke hoonoho i na hololio maluna o lakou.
“‘Ẹ wá nísinsin yìí, bá ọ̀gá mi pa ìmọ̀ pọ̀, ọba Asiria, èmi yóò fún ọ ní ẹgbẹ̀rún méjì ẹṣin bí ìwọ bá le è fi agẹṣin lé wọn lórí!
9 Pehea hoi oe e hoohuli aku ai i ka maka o kekahi luna uuku o na kauwa a kuu haku, a hilinai hoi maluna o Aigupita, no na kaakaua, a no na hololio?
Báwo ni ẹ ṣe lè lé ẹyọ kan ṣoṣo padà nínú èyí tí ó kéré jù nínú àwọn balógun olúwa mi, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ gbẹ́kẹ̀lé Ejibiti fún kẹ̀kẹ́-ẹṣin àti àwọn ẹlẹ́ṣin?
10 Ano hoi, aole anei o Iehova kekahi pu me au i pii mai nei i keia aina, e luku ia? Ua olelo mai no o Iehova ia'u, E pii ae oe i keia aina, a e luku iho ia.
Síwájú sí i, ǹjẹ́ mo wa lè wá bá ilẹ̀ yìí jà kí n sì pa á run láìsí Olúwa? Olúwa fún rara rẹ̀ ló sọ pé kí n bá orílẹ̀-èdè yìí jà kí n sì pa á run.’”
11 Alaila, olelo aku la o Eliakima, a me Sebena, a me Ioa, ia Rabesake, Ke noi aku nei au ia oe, e olelo mai oe i kau mau kauwa nei ma ka olelo Suria, no ka mea, ua ike makou ia. Mai olelo mai ma ka olelo Iudaio, ma na pepeiao o na kanaka maluna o ka pa.
Lẹ́yìn náà ni Eliakimu, Ṣebna àti Joah sọ fún ọ̀gágun náà pé, “Jọ̀wọ́ máa bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ sọ̀rọ̀ ní èdè Aramaiki, nítorí pé àwa gbọ́ ọ. Má ṣe bá wa sọ̀rọ̀ ní èdè Heberu ní etí àwọn ènìyàn tí ó wà lórí ògiri mọ́.”
12 Aka, olelo mai la o Rabesake, Ua hoouna mai nei anei ko'u haku ia'u i kou haku, a iou la, e olelo i keia mau olelo? Aole anei i ka poe kanaka e noho ana ma ka pa, i ai lakou i ko lakou lepo iho, a inu hoi i ko lakou mimi iho me oukou?
Ṣùgbọ́n aláṣẹ dáhùn pé, “Ṣé fún ọ̀gá rẹ àti ìwọ nìkan ní ọ̀gá mi rán mi sí láti sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí kì í sì í ṣe fún àwọn ọkùnrin tí ó jókòó lórí odi ni gẹ́gẹ́ bí ìwọ, ni yóò ní láti jẹ ìgbẹ́ ará wọn kí wọ́n sì mu ìtọ̀ ará wọn?”
13 Alaila, ku mai la o Rabesake, a hea ae la me ka leo nui, ma ka olelo Iudaio, i ae la, E hoolohe mai oukou i na olelo a ke alii nui, ke alii o Asuria.
Lẹ́yìn náà ni ọ̀gágun náà dìde tí ó sì ké síta ní èdè Heberu pé, “Ẹ gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ ọba ńlá, ọba Asiria!
14 Ke i mai nei ke alii penei, Mai walewale oukou ia Hezekia, no ka mea, aole e hiki ia ia ke hoopakele ia oukou.
Ohun tí ọba wí nìyìí, Ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah tàn yín jẹ. Òun kò le è gbà yín sílẹ̀!
15 Mai ae aku i ko Hezekia hooikaika ana ia oukou e hilinai ia Iehova, i ka i ana iho, E oiaio no e hoopakele o Iehova ia kakou; aole e haawiia keia kulanakauhale iloko o ka lima o ke alii o Asuria.
Ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah rọ̀ yín láti gbẹ́kẹ̀lé Olúwa nígbà tí ó sọ pé, ‘Olúwa yóò kúkú gbà wá; a kì yóò fi ìlú yìí lé ọba Asiria lọ́wọ́.’
16 Mai hoolohe i ka Hezekia; no ka mea, ke olelo mai nei ke alii o Asuria penei, E hana oukou me au i kuikahi, a e puka mai iwaho io'u nei; a e ai kela mea keia mea o oukou i ko kona kumu waina, a i ko kona laau fiku, a e inu hoi keia mea, keia mea o oukou i ka wai o kona luawai iho;
“Ẹ má ṣe tẹ́tí sí Hesekiah. Ohun tí ọba Asiria wí nìyìí. Ẹ fi ẹ̀bùn bá mi rẹ́, kí ẹ sì jáde tọ̀ mí wá. Lẹ́yìn náà, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín yóò sì jẹ nínú àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni yóò sì mu omi nínú kànga rẹ̀,
17 A hiki aku au, a lawe aku ia oukou i ka aina e like me ko oukou aina iho, he aina ai, a waina hoi, he aina berena, a me na pawaina.
títí tí èmi yóò fi mú un yín lọ sí ilẹ̀ kan tí ó dàbí i tiyín, ilẹ̀ tí ó ní irúgbìn oníhóró àti wáìnì tuntun, ilẹ̀ tí ó ní àkàrà àti ọgbà àjàrà.
18 E ao oukou, o hoowalewale mai o Hezekia ia oukou, i ka i ana mai, E hoopakele mai no o Iehova ia kakou. Ua hoopakele anei na akua o kekahi lahuikanaka i ko lakou aina iho, mai ka lima aku o ke alii o Asuria?
“Ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah ṣì yín lọ́nà nígbà tí ó sọ wí pé, ‘Olúwa yóò gbà wá.’ Ǹjẹ́ ọlọ́run orílẹ̀-èdè kan ha ti gbà á kúrò lọ́wọ́ ọba Asiria bí?
19 Aia la ihea na'kua o Hamata a me Arepada? Auhea hoi na'kua o Separevaima? Ua hoopakele anei lakou ia Samaria mai ko'u lima aku?
Níbo ni àwọn òrìṣà Hamati àti Arpadi ha wà? Níbo ni àwọn òrìṣà Sefarfaimi ha wà? Ǹjẹ́ wọn ti já Samaria gbà kúrò lọ́wọ́ mi bí?
20 Owai la ka mea o na'kua o ia mau aina a pau nana i hoopakele i kona aina iho, mai ko'u lima aku, i hoopakele ai o Iehova ia Ierusalema, mai ko'u lima aku?
Èwo nínú àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè wọ̀nyí ló ha ti dáàbò bo ilẹ̀ ẹ rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi? Báwo ni Olúwa ṣe wá le gba Jerusalẹmu kúrò lọ́wọ́ mi?”
21 Ekemu ole lakou, aole i olelo aku ia ia i kekahi huaolelo; no ka mea, oia ke kauoha a ke alii, i mai la, Mai olelo aku ia ia.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà dákẹ́ rọ́rọ́ wọn kò sì mú èsì kankan wá, nítorí ọba ti pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ má ṣe dá a lóhùn.”
22 Alaila, hele mai la o Eliakima, ke keiki a Hilekia, ka mea maluna o ko ka hale, a me Sebena, ke kakauolelo, a me Ioa, ke keiki a Asapa, ke kakaumooolelo, io Hezekia la, me ka haehaeia o ka lole, a hai ae la ia ia i na olelo a Rabesake.
Lẹ́yìn náà ni Eliakimu ọmọ Hilkiah alákòóso ààfin, Ṣebna akọ̀wé àti Joah ọmọ Asafu akọ̀wé àkọsílẹ̀ lọ sí ọ̀dọ̀ Hesekiah pẹ̀lú aṣọ wọn ní fífàya, wọ́n sì sọ ohun tí ọ̀gágun ti wí.

< Isaia 36 >