< Isaia 30 >

1 A UWE na keiki kipi, wahi a Iehova, Ka poe i hooholo manao, aole nae ma o'u nei; Ka poe i ninini i na mohai ninini, aole nae ma ko'u uhane, I kui aku ai lakou i kekahi hewa mo kekahi hewa;
“Ègbé ni àwọn ọmọ fún orílẹ̀-èdè alágídí,” ni Olúwa wí, “Fún àwọn tí ó gbé ètò jáde tí kì í ṣe tèmi, tí wọ́n ń gbìmọ̀ pọ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe nípa Ẹ̀mí mi, tí wọ́n ń dá ẹ̀ṣẹ̀ lórí ẹ̀ṣẹ̀;
2 Ka poe i hele ilalo i Aigupita, Aole nae i ninau ma kuu waha; A hooikaika lakou ia lakou iho ma ka ikaika o Parao, A hilinai aku ma ke aka o Aigupita.
tí wọ́n lọ sí Ejibiti láìṣe fún mi, tí ó ń wá ìrànlọ́wọ́ lọ́dọ̀ Farao fún ààbò, sí òjìji Ejibiti fún ibi ìsádi.
3 E lilo no ka ikaika o Parao i mea e hilahila ai oukou, A me ka hilinai ana i ke aka o Aigupita, oia kekahi mea hilahila.
Ṣùgbọ́n ààbò Farao yóò jásí ìtìjú fún un yín, òjìji Ejibiti yóò mú àbùkù bá a yín.
4 No ka mea, aia ma Zoana kona poe alii, A hiki ae la kona poe luna i Hanesa.
Bí àwọn olórí rẹ tilẹ̀ wà ní Ṣoani, tí àwọn ikọ̀ wọn sì ti dé sí Hanisi,
5 Hilahila no lakou a pau i ka lahuikanaka hiki ole ke kokua ia lakou, Aole alu pu, aole kokua, Aka, he mea hilahila, he mea hoi e hoowahawahaia'i.
gbogbo wọn ni a ó dójútì, nítorí àwọn ènìyàn kan tí kò wúlò fún wọn, tí kò mú ìrànlọ́wọ́ tàbí àǹfààní wá, bí kò ṣe àbùkù àti ìdójúti ni.”
6 Ua kaumaha na holoholona o ke kukulu hema, O na mea hali, no ka aina e kaniuhu ai, a e eha ai hoi, Ma kahi o ka liona wahine, a me ka liona kane, Ka moonihoawa, a me ka moolele; Lawe no lakou i ko lakou waiwai ma ke kua o na hoki opiopio, A me ko lakou ukana hoi, ma na puu o na kamelo, E lilo i na kanaka kokua ole ia lakou.
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ sí àwọn ẹranko tí ó wà ní gúúsù. Láàrín ilẹ̀ ìnira àti ìpọ́njú, ti kìnnìún àti abo kìnnìún ti paramọ́lẹ̀ àti ejò olóró, àwọn ikọ̀ náà kó ẹrù àti ọrọ̀ wọn lẹ́yìn àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ohun ìní wọn ní orí àwọn ìbákasẹ, sí orílẹ̀-èdè aláìlérè,
7 Ua lapuwale ko Aigupita, make hewa ko lakou hooikaika ana, Nolaila au i kapa aku ai ia ia, o Huhuahoopalaleha.
sí Ejibiti tí ìrànlọ́wọ́ rẹ̀ kò wúlò rárá. Nítorí náà mo pè é ní Rahabu aláìlẹ́ṣẹ̀ nǹkan kan.
8 O hele hoi, e palapala ia mea ma ka papa imua o lakou, A e kahakaha hoi ma ka buke, I mea no na la mahope, no na manawa, mau loa aku:
Lọ nísinsin yìí, kí o sì kọ ọ́ sí ara wàláà fún wọn, tẹ̀ ẹ́ sí ara ìwé kíká, pé fún àwọn ọjọ́ tí ó ń bọ̀ kí ó sì lè jẹ́ ẹ̀rí ayérayé.
9 No ka mea, he poe kanaka kipi keia, He poe keiki wahahee, He poe kamalii hoolohe ole i ke kanawai o Iehova:
Àwọn wọ̀nyí jẹ́ ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn àti ẹlẹ́tanu ọmọ, àwọn ọmọ tí wọn kò ṣetán láti tẹ́tí sí ìtọ́ni Olúwa.
10 He poe olelo i na mea ike, Mai ike oukou; A i na kaula hoi, Mai wanana mai oukou ia makou i na mea pono, E hai mai ia makou i na mea oluolu, E wanana mai i na mea hoopunipuni:
Wọ́n sọ fún àwọn aríran pé, “Ẹ má ṣe rí ìran mọ́!” Àti fún àwọn wòlíì, “Ẹ má ṣe fi ìran ohun tí ó tọ́ hàn wá mọ́! Ẹ sọ ohun tí ó tura fún wa, ẹ sàsọtẹ́lẹ̀ ẹ̀tàn.
11 E kapae ae iwaho o ke alanui, E huli ae mawaho o ke kuamoo, E hoihoi aku i ka Mea Hemolele o ka Iseraela, mai ko makou alo aku.
Ẹ fi ọ̀nà yìí sílẹ̀, ẹ kúrò ní ọ̀nà yìí ẹ dẹ́kun à ń dojú ìjà kọ wá pẹ̀lú Ẹni Mímọ́ Israẹli!”
12 Nolaila, ke olelo mai nei ka Mea Hemolele o ka Iseraela peneia, No ko oukou hoowahawaha ana i keia olelo, A ua hilinai aku i ka alunu, a me ke kekee, A ua hio ma ia mau mea;
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Ẹni Mímọ́ Israẹli wí: “Nítorí pé ẹ ti kọ ọ̀rọ̀ yìí sílẹ̀, ẹ gbára lé ìnilára kí ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé ẹ̀tàn,
13 No ia mea, e lilo ai keia hewa ia oukou, E like me kahi i naha o ka pa e hiolo ana, He wahi hio o ka pa kiekie, E hiolo hiki wawe, ma ke sekona no.
ẹ̀ṣẹ̀ yìí yóò rí fún ọ gẹ́gẹ́ bí ògiri gíga, tí ó sán tí ó sì fì tí ó sì wó lójijì, àti ní ìṣẹ́jú kan.
14 E naha no ia e like me ka naha ana o ka ipulepo o na potera, E nahaha io no, aole ia e aloha mai; Maloko o na mea naha, aole e loaa kekahi apana, E lawe ai i ko ahi enaena, A e huki hoi i ka wai o ka luawai.
Yóò sì fọ́ ọ sí wẹ́wẹ́ bí àpáàdì tí a fọ́ pátápátá àti pé a kò ní rí ẹ̀rún kan nínú àfọ́kù rẹ̀, fún mímú èédú kúrò nínú ààrò tàbí gbígbọ́n omi jáde kúrò nínú àmù.” (questioned)
15 No ka mea, penei i olelo mai ai ka Haku, O Iehova, ka Mea Hemolele o ka Iseraela, Ma ka huli ana mai a me ka hoomaha oukou e ola'i; Ma ka noho malie, a ma ka hilinai mai, malaila ko oukou ikaika; Aole nae oukou i ae mai.
Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli wí: “Nínú ìrònúpìwàdà àti ìsinmi ni ìgbàlà rẹ wà, ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ àti ìgbẹ́kẹ̀lé ni agbára rẹ wà, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò ní ọ̀kankan nínú wọn.
16 A olelo mai no oukou, Aole; Aka, e holo no makou maluna o na lio; Nolaila, e holo io no oukou; E holo makou maluna o na mea mama; Nolaila, e mama'i ka poe hahai ia oukou.
Ẹ̀yin wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò sálọ lórí ẹṣin.’ Nítorí náà ẹ̀yin yóò sá! Ẹ̀yin wí pé, ‘Àwa yóò gun àwọn ẹṣin tí ó yára lọ.’ Nítorí náà àwọn tí ń lé e yín yóò yára!
17 E hee no kekahi tausani o oukou, No ka papa ana o ka mea hookahi; No ka papa ana o na mea elima e hee ai oukou; A waihoia oukou, e like me ke kia ma ka piko o ke kuahiwi, Me he hae la hoi maluna o ka puu.
Ẹgbẹ̀rún yóò sá nípa ìdẹ́rùbà ẹnìkan; nípa ìdẹ́rùbà ẹni márùn-ún gbogbo yín lẹ ó sálọ, títí a ó fi yín sílẹ̀ àti gẹ́gẹ́ bí igi àsíá ní orí òkè, gẹ́gẹ́ bí àsíá lórí òkè.”
18 Nolaila, e kakali no o Iehova, i lokomaikai oia ia oukou, Nolaila, e hiilaniia oia, ma ka hana maikai aku ia oukou: No ka mea, he Akua hooponopono o Iehova; Pomaikai ka poe a pau i hilinai aku ia ia.
Síbẹ̀síbẹ̀ Olúwa sì fẹ́ síjú àánú wò ọ́; ó dìde láti ṣàánú fún ọ. Nítorí Olúwa jẹ́ Ọlọ́run ìdájọ́. Ìbùkún ni fún gbogbo àwọn tí ó dúró dè é!
19 No ka mea, e noho no na kanaka o Ziona ma Ierusalema; Aole loa hoi oukou e uwe hou aku; E lokomaikai loa aku oia i ka leo o kou kahea ana, A lohe oia, e ae mai no ia oe.
Ẹ̀yin ènìyàn Sioni, tí ń gbé ní Jerusalẹmu, ìwọ kì yóò sọkún mọ́. Báwo ni àánú rẹ̀ yóò ti pọ̀ tó nígbà tí ìwọ bá kígbe fún ìrànlọ́wọ́! Bí ó bá ti gbọ́, òun yóò dá ọ lóhùn.
20 Ua haawi mai no ka Haku ia oukou i ka berena o ka popilikia, A me ka wai o ke kaumaha, Aka, aole e lawe hou ia'ku kau poe kumuao, E ike aku no kou mau maka i na kumuao:
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa fún ọ ní àkàrà ìyà àti omi ìpọ́njú, àwọn olùkọ́ rẹ kì yóò fi ara sin mọ́; pẹ̀lú ojú rẹ ni ìwọ ó rí wọn.
21 E lohe no kou mau pepeiao i ka olelo mahope ou, i ka i ana mai, Eia ke ala, e hele maloko olaila, Ina paha oukou e huli ma ka akau, A ina paha oukou e huli ma ka hema,
Bí o bá yí sápá ọ̀tún tàbí apá òsì, etí rẹ yóò máa gbọ́ ohùn kan lẹ́yìn rẹ, wí pé, “Ọ̀nà nìyìí, máa rìn nínú rẹ̀.”
22 E hoohaumia no hoi oukou i ke poi kala o ko oukou mau kii i kalaiia, A me ka wahi gula o kou mau kii hooheheeia; E kiola ana oukou ia, e like me ka welu pea, A e olelo ana no oe ia ia, Hele pela,
Lẹ́yìn náà ni ẹ ó ba àwọn ère yín jẹ́ àwọn tí ẹ fi fàdákà bò àti àwọn ère tí ẹ fi wúrà bò pẹ̀lú, ẹ ó sọ wọ́n nù bí aṣọ tí obìnrin fi ṣe nǹkan oṣù ẹ ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ kúrò níbí!”
23 Alaila e haawi mai no oia i ka ua no kau hua, Ka mea au e kanu ai ma ka lepo; A me ka berena hoi no ka hua ana mai o ka lepo, A e momona no ia, a mahuahua ka maikai; E ai no kou mau holoholona ia la ma na kula palahalaha.
Òun yóò sì rọ òjò fún un yín sí àwọn irúgbìn tí ẹ gbìn sórí ilẹ̀, oúnjẹ tí yóò ti ilẹ̀ náà wá yóò ní ọ̀rá yóò sì pọ̀. Ní ọjọ́ náà ni àwọn ẹran ọ̀sìn yín yóò máa jẹ koríko ní pápá oko tútù tí ó tẹ́jú.
24 O na bipi kauo hoi, a me na hoki opiopio, Na mea i hana ma ka aina, E ai no lakou i ka ai i miko i ka paakai, Ka mea i peahiia i ka peahi a me ke kanana.
Àwọn màlúù àti àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó ń tú ilẹ̀ yóò jẹ oúnjẹ àdídùn tí a fi àmúga àti ṣọ́bìrì fọ́nkálẹ̀.
25 A maluna o na kuahiwi kiekie a pau, A maluna hoi o na puu kiekie a pau, E loaa no na kahawai, a me ka wai e kahe ana, I ka la o ka make nui, I ka haule ana o na halekiai.
Ní ọjọ́ tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò sọ ẹ̀mí wọn nù nígbà tí ilé ìṣọ́ yóò wó lulẹ̀, odò omi yóò sàn lórí òkè gíga àti lórí àwọn òkè kékeré.
26 A e like auanei ka malamalama o ka mahina, Me ka malamalama o ka la, A e pahiku no ka malamalama o ka la, E like me ka malamalama o na la ekiku, I ka la e wahi ai o Iehova i ka eha o kona poe kanaka, A hoola hoi i ka eha o ko lakou hahauia.
Òṣùpá yóò sì tàn bí oòrùn, àti ìtànṣán oòrùn yóò mọ́lẹ̀ ní ìlọ́po méje, gẹ́gẹ́ bí ìmọ́lẹ̀ odidi ọjọ́ méje, nígbà tí Olúwa yóò di ojú ọgbẹ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ tí yóò sì wo ọgbẹ́ tí ó ti dá sí wọn lára sàn.
27 Aia hoi, ke hele mai nei ka inoa o Iehova mai kahi loihi mai, Ua wela kona ukiuki, a nui loa ke a ana; Ua piha kona mau lehelehe i ka inaina, A ua like no kona elelo me ke ahi e hoopau ana.
Kíyèsi i, orúkọ Olúwa ti òkèèrè wá pẹ̀lú ìbínú gbígbóná àti kurukuru èéfín tí ó nípọn; ètè rẹ̀ kún fún ìbínú ahọ́n rẹ̀ sì jẹ́ iná ajónirun.
28 Ua like kona hanu me ka waikahe e holo moku ana, E pii no ia a waenakonu o ka a-i, E kanana i na lahuikanaka i ko kanana o ka make; Aia ma na iwia o na kanaka he kaulawaha e alakai hewa ana.
Èémí rẹ̀ sì dàbí òjò alágbára, tí ó rú sókè dé ọ̀run. Ó jọ àwọn orílẹ̀-èdè nínú kọ̀ǹkọ̀sọ̀; ó sì fi sí ìjánu ní àgbọ̀n àwọn ènìyàn láti ṣì wọ́n lọ́nà.
29 He mele no ko oukou, E like me ko ka po i ka wa e malama ai i ka ahaaina; He olioli o ka naau, e like me ka mea hele mamuli o ka hokiokio, A hiki aku i ka mauna o Iehova, i ka pohaku hoi o ka Iseraela.
Ẹ̀yin ó sì kọrin gẹ́gẹ́ bí i ti alẹ́ tí ẹ̀ ń ṣe àjọyọ̀ àpéjọ mímọ́, ọkàn yín yóò yọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí àwọn ènìyàn gòkè lọ pẹ̀lú fèrè sí orí òkè Olúwa, àní sí àpáta Israẹli.
30 O Iehova ka mea e loheia'i kona leo nani, E hoike aku no oia i ka iho ana o kona lima, Me ka ukiuki o ka inaina, A me ka lapalapa o ke ahi e hoopau ana, O ka ua nui, a me ka ino, a me ka huahekili.
Olúwa yóò jẹ́ kí wọn ó gbọ́ ohùn ògo rẹ̀ yóò sì jẹ́ kí wọ́n rí apá rẹ̀ tí ó ń bọ̀ wálẹ̀ pẹ̀lú ìbínú gbígbóná àti iná ajónirun, pẹ̀lú mọ̀nàmọ́ná, àrá àti yìnyín.
31 No ka mea, ma ka leo o Iehova, E moku loa auanei ko Asuria, Me ka laau e hahau no ia.
Ohùn Olúwa yóò fọ́ Asiria túútúú, pẹ̀lú ọ̀pá aládé rẹ̀ ni yóò lù wọ́n bolẹ̀.
32 Ma na wahi a pau e hiki aku ai ka laau hoopai, Ka mea a Iehova e kau ai maluna ona, O na pahu kani no kekahi, a me na mea kani; A e kaua no oia ia ia me ke kaua weliweli.
Ẹgba kọ̀ọ̀kan tí Olúwa bá gbé lé wọn pẹ̀lú ọ̀pá ìjẹníyà rẹ̀ yóò jẹ́ ti ṣaworo àti ti dùùrù, gẹ́gẹ́ bí ó ti ń bá wọn jà lójú ogun pẹ̀lú ìkùùkuu láti apá rẹ̀.
33 No ka mea, ua hoomakaukau kahiko ia o Topeta, No ko alii hoi ia i hoomakaukauia'i; Ua hana oia ia wahi a hohonu, a ua nui hoi; He wahi ahi, a ua nui hoi ka wahie, Na ka hanu no o Iehova e hoa iho, E like me ka luaipele e kahe ana.
A ti tọ́jú Tofeti sílẹ̀ tipẹ́tipẹ́, a ti tọ́jú rẹ̀ sílẹ̀ fún ọba. Ojú ààrò rẹ̀ ni a ti gbẹ́ jì tí ó sì fẹ̀, pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ iná àti igi ìdáná; èémí Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìṣàn sulfuru ń jó ṣe mú un gbiná.

< Isaia 30 >