< Isaia 23 >

1 KA wanana no Turo. E aoa oukou, e na moku o Taresisa, No ka mea, ua anaiia oia, aohe hale, aole wahi e komo ai; Ua haiia mai ia lakou, mai ka aina o Kitima mai.
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Tire. Hu, ìwọ ọkọ̀ ojú omi Tarṣiṣi! Nítorí a ti pa Tire run láìsí ilé tàbí èbúté. Láti ilẹ̀ Saipurọsi ni ọ̀rọ̀ ti wá sọ́dọ̀ wọn.
2 E noho malie, e ka poe noho ma kahakai; Holo ae la ka mea kalepa o Zidona, mai kela aoao ae o ke kai, a hoopiha no ia ia oe.
Dákẹ́ jẹ́ẹ́, ẹ̀yin ènìyàn erékùṣù àti ẹ̀yin oníṣòwò ti Sidoni, ẹ̀yin tí àwọn a wẹ Òkun ti sọ dọlọ́rọ̀.
3 O ka hua o ka Nile, i ulu ma na wai nui, A me ka ai o ka muliwai, oia kona waiwai; A lilo ia i wahi kuai no na aina.
Láti orí àwọn omi ńlá ni irúgbìn ìyẹ̀fun ti ilẹ̀ Ṣihori ti wá; ìkórè ti odò Naili ni owóòná Tire, òun sì ti di ibùjókòó ọjà fún àwọn orílẹ̀-èdè.
4 E hilahila oe, e Zidona, No ka mea, ua olelo mai ko kai, o kahi paa hoi o ke kai, I mai, Aole au i kuakoko, aole au i hanau keiki, Aole au i hanai i kanaka ui, Aole hoi au i malama i na wahine puupaa.
Kí ojú kí ó tì ọ́, ìwọ Sidoni àti ìwọ àní ìwọ ilé ààbò ti Òkun, nítorí Òkun ti sọ̀rọ̀. “Èmi kò tí ì wà ní ipò ìrọbí tàbí ìbímọ rí Èmi kò tí ì wo àwọn ọmọkùnrin tàbí kí n tọ́ àwọn ọmọbìnrin dàgbà rí.”
5 A hiki aku ka lohe i Aigupita, E nahu hookina lakou, no ka lohe ana ia Turo.
Nígbà tí ọ̀rọ̀ bá dé Ejibiti, wọn yóò wà ní ìpayínkeke nípa ìròyìn láti Tire.
6 E hele ae oukou i Taresisa, E aoa oukou, e ka poe noho ma kahakai.
Kọjá wá sí Tarṣiṣi; pohùnréré, ẹ̀yin ènìyàn erékùṣù.
7 O keia anei ko oukou wahi i hauoli ai, Ka mea i hookumuia i ka wa kahiko loa? Na kona wawae e lawe aku ia ia i kahi loihi e noho ai.
Ǹjẹ́ èyí náà ni ìlú àríyá yín, ògbólógbòó ìlú náà, èyí tí ẹsẹ̀ rẹ̀ ti sìn ín lọ láti lọ tẹ̀dó sí ilẹ̀ tí ó jìnnà réré.
8 Owai ka mea i manao mua i keia ia Turo, I ka mea i hoalii aku ia hai? He poe alii no kona poe kalepa, A o kona poe kuai, he poe koikoi no o ka aina.
Ta ló gbèrò èyí sí Tire, ìlú aládé, àwọn oníṣòwò ẹni tí ó jẹ́ ọmọ-aládé tí àwọn oníṣòwò wọ́n jẹ́ ìlúmọ̀míká ní orílẹ̀ ayé?
9 Ua manao mai o Iehova o na kaua ia mea, I hoohaumia oia i ka hanohano o na mea nani a pau, A e hoohaahaa hoi i na mea koikoi a pau o ka honua.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti ṣètò rẹ̀, láti tẹrí ìgbéraga àti ògo rẹ ba àti láti rẹ gbogbo àwọn ọlọ́lá ilé ayé sílẹ̀.
10 E hele oe maluna o kou aina e like me ka wai kahe, E ke kaikamahine o Taresisa, aole kaei i koe.
Tu ilẹ̀ rẹ gẹ́gẹ́ bí i ti ipadò odò Ejibiti, ìwọ ọmọbìnrin Tarṣiṣi, nítorí ìwọ kò ní èbúté mọ́.
11 O aku no oia i kona lima maluna o ke kai, Hoonaueue no oia i na aupuni: Ua kauoha mai o Iehova no Poinike, E hooki loa aku i kona mau pakaua.
Olúwa ti na ọwọ́ rẹ̀ jáde sí orí Òkun ó sì mú kí àwọn ilẹ̀ ọba wárìrì. Ó ti pa àṣẹ kan tí ó kan Kenaani pé kí a pa ilé ààbò rẹ̀ run.
12 A ua olelo mai ia, Aole oe e hooho lanakila hou, E ka wahine puupaa i pue wale ia, ke kaikamahine a Zidona; E ku iluna, e hele i kela aoao, i Kitima; Aole nae e loaa ia oe ka maha malaila.
Ó wí pé, “Kò sí àríyá fún ọ mọ́, ìwọ wúńdíá ti Sidoni, tí a ti tẹ̀ mọ́lẹ̀ báyìí! “Gbéra, rékọjá lọ sí Saipurọsi, níbẹ̀ pẹ̀lú o kì yóò ní ìsinmi.”
13 Aia hoi ko ka aina o Kaledea; He mea ole keia poe kanaka, A hookumu ko Asuria ia wahi no ka poe i noho ma ka waonahele; Na lakou i kukulu i kolaila mau halekiai, A hana no hoi i kolaila mau halealii; A nana i hoohiolo i na kauhale.
Bojú wo ilẹ̀ àwọn ará Babeli, àwọn ènìyàn tí kò jámọ́ nǹkan kan báyìí. Àwọn Asiria ti sọ ọ́ di ibùgbé àwọn ohun ẹranko aginjù; wọn ti gbé ilé ìṣọ́ ìtẹ̀gùn wọn sókè, wọ́n ti tú odi rẹ̀ sí ìhòhò wọ́n sì ti sọ ọ́ di ààtàn.
14 E aoa oukou, e na moku o Taresisa, No ka mea, ua hoohioloia kou pakaua,
Hu, ìwọ ọkọ̀ ojú omi Tarṣiṣi; wọ́n ti pa odi rẹ̀ run!
15 A hiki aku i kela la, E hoopoinaia no o Turo i na makahiki he kanahiku, E like me na makahiki o ke alii hookahi: A pau na makahiki he kanahiku, Alaila, e olioli no o Turo me ka ka wahine hookamakama.
Ní àkókò náà a ó gbàgbé Tire fún àádọ́rin ọdún, ọjọ́ ayé ọba kan. Ṣùgbọ́n ní òpin àádọ́rin ọdún wọ̀nyí, yóò ṣẹlẹ̀ sí Tire gẹ́gẹ́ bí orin àgbèrè:
16 E lawe oe i ka lira, e poai i ke kulanakauhale, E ka wahine hookamakama i hoopoinaia: E hookanikani maikai, e hoonui i ka olioli, I hoomanao hou ia'i oe.
“Mú dùùrù kan, rìn kọjá láàrín ìlú, ìwọ àgbèrè tí a ti gbàgbé; lu dùùrù dáradára, kọ ọ̀pọ̀ orin, kí a lè ba à rántí rẹ.”
17 A hiki i ka pau ana o na makahiki he kanahiku, Alaila e nana mai no o Iehova ia Turo, A e hoi hou no ia i kana hana e waiwai ai, A e moe kolohe no oia me ko na aupuni a pau o keia ao, Maluna o ka honua nei.
Ní òpin àádọ́rin ọdún náà, Olúwa yóò bá Tire jà. Òun yóò sì padà sí àyálò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí panṣágà, yóò sì máa ṣe òwò rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ilẹ̀ ọba tí ó wà ní ilẹ̀ ayé.
18 Aka, o kona waiwai loaa, a me kona uku, E laa no ia no Iehova, Aole ia e hoahuia, aole e malamaia ma kahi e; No ka mea, o kona waiwai kuai, no ka poe ia e noho ana imua o Iehova, I mea e ai ai a maona, a i mea aahu nani.
Síbẹ̀síbẹ̀ èrè rẹ̀ àti owó iṣẹ́ rẹ̀ ni a ó yà sọ́tọ̀ fún Olúwa; a kò ní kó wọn pamọ́ tàbí kí a há wọn mọ́wọ́. Ère rẹ̀ ni a ó fi fún àwọn tí ó ń gbé níwájú Olúwa, fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ oúnjẹ àti aṣọ.

< Isaia 23 >