< Isaia 14 >

1 A LAILA, e aloha mai no o Iehova i ka Iakoba, E olioli hou no ia i ka Iseraela, A e hoomaha ia lakou ma ko lakou aina iho; A e hui pu ia na malihini me lakou, A e hoopili lakou i ko ka hale o Iakoba.
Olúwa yóò fi àánú hàn fún Jakọbu, yóò tún Israẹli yàn lẹ́ẹ̀kan sí i yóò sì fi ìdí wọn kalẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn tìkára wọn. Àwọn àjèjì yóò darapọ̀ mọ́ wọn, wọn yóò sì fọwọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú ilé e Jakọbu.
2 E lawe na lahuikanaka ia lakou, A e hoihoi ia lakou i ko lakou wahi iho; A e noho no lakou mamuli o ko ka hale o ka Iseraela, I kauwakane, a i kauwawahine, ma ka aina o Iehova; A e lawe pio lakou i ka poe i hoopio ai ia lakou, A e noho alii lakou maluna o ka poe nana lakou i hookaumaha.
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò gbà wọ́n wọn yóò sì mú wọn wá sí ààyè e wọn. Ilé Israẹli yóò gba àwọn orílẹ̀-èdè gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin ní ilẹ̀ Olúwa. Wọn yóò kó àwọn akónilẹ́rú wọn ní ìgbèkùn wọn yóò sì jẹ ọba lórí àwọn amúnisìn wọn.
3 A i ka la e hoomaha mai ai o Iehova ia oe, Mai kou pilikia, a me kou poino, A mai ka hana kaumaha i kauia maluna ou,
Ní ọjọ́ tí Olúwa yóò fi ìtura fún un yín kúrò nínú ìpọ́njú àti ìyà àti ìdè ìkà,
4 Alaila oe e haku ai i keia mele no ke alii o Babulona, I ka i ana iho, Nani ka pau ana o ka mea nana i hookaumaha, Ka pau ana hoi o ka mea auhau i ke gula!
ẹ ó sì fi ọ̀rọ̀ àbùkù yìí kan ọba Babeli pé, báwo ni amúnisìn ṣe wá sí òpin! Báwo ni ìbínú rẹ̀ ṣe parí!
5 Ua uhaki o Iehova i ke kookoo o ka poo hewa, I ke kookoo alii hoi o ka poe hookaumaha.
Olúwa ti dá ọ̀pá ìkà náà, ọ̀pá àwọn aláṣẹ,
6 O ka mea i hahau i na kanaka me ka huhu, He hahau ana me ka hoomaha ole; Hahi no oia maluna o ko na aina me ka ukiuki, He hoomaau hooki ole.
èyí tí ó ti lu àwọn ènìyàn bolẹ̀ pẹ̀lú ti kò dáwọ́ dúró, nínú ìrunú ni ó ṣẹ́gun àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú ìgbónára tí kò lópin.
7 A ua malu ka honua a pau, na maha no; Hookani olioli lakou.
Gbogbo ilẹ̀ ni ó wà ní ìsinmi àti àlàáfíà, wọ́n bú sí orin.
8 Hoaikola no hoi na laau kaa maluna ou, A me na kedera o Lebanona, i ae la, Mai kou wa i moe ai ilalo, Aohe mea e pii mai e kua ia makou.
Pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn igi junifa àti àwọn igi kedari ti Lebanoni ń yọ̀ lórí rẹ wí pé, “Níwọ́n bí a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ báyìí, kò sí agégi tí yóò wá láti gé wa lulẹ̀.”
9 Ua pihoihoi ka po malalo ia oe, E halawai me oe i kou hiki ana aku. Nou no ia i hoea mai ai i na mea lapu, I na mea mana hoi a pau o ka honua: Hooku ae la hoi ia iluna, i na'lii a pau o na aina, mai ko lakou nohoalii mai. (Sheol h7585)
Ibojì tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni a ru sókè láti pàdé rẹ ní ìpadàbọ̀ rẹ̀ ó ru ẹ̀mí àwọn tí ó ti lọ sókè láti wá kí ọ gbogbo àwọn tí ó jẹ́ olórí ní ayé ó mú kí wọn dìde lórí ìtẹ́ wọn gbogbo àwọn tí ó jẹ ọba lórí àwọn orílẹ̀-èdè. (Sheol h7585)
10 A olelo mai no lakou a pau ia oe, i ka i ana, Ua lilo anei oe i nawaliwali, e like me makou? Ua hoohalikeia anei oe me makou?
Gbogbo wọn yóò dáhùn, wọn yóò wí fún ọ wí pé, “Ìwọ pẹ̀lú ti di aláìlera, gẹ́gẹ́ bí àwa pẹ̀lú ìwọ náà ti dàbí wa.”
11 Ua hoopohoia kou hanohano ilalo i ka po, A me ke kani ana o kou mau lira; O kahi moe malalo ou he ilo ia, A uhi mai no hoi ka ilo ia oe, (Sheol h7585)
Gbogbo rẹ̀ ni ó di ìrẹ̀sílẹ̀ lọ sí ibojì, pẹ̀lú ariwo àwọn dùùrù rẹ, àwọn ìdin ni wọ́n fọ́nkálẹ̀ lábẹ́ rẹ àwọn ekòló sì ti bò ọ́ mọ́lẹ̀. (Sheol h7585)
12 Auwe kou haule ana mai ka lani mai, E ka Hokuloa, ke keiki a ke kakahiaka! Ua kuaia oe ilalo i ka honua, O oe, ka mea i hooauhee i ko na aina.
Báwo ni ìwọ ṣe ṣubú lulẹ̀ láti ọ̀run wá, ìwọ ìràwọ̀ òwúrọ̀, ọmọ òwúrọ̀ náà! A ti sọ ọ́ sílẹ̀ sínú ayé, ìwọ tí o ti tẹ orí àwọn orílẹ̀-èdè ba rí!
13 Aka, ua olelo no oe iloko o kou naau, E pii aku no wau i ka lani, E hookiekie no wau i ko'u nohoalii, Maluna o na hoku o ke Akua; E noho no wau ma ka mauna o ka halawai ana, Ma na aina loihi aku o ke kukulu akau.
Ìwọ sọ nínú ọkàn rẹ pé, “Èmi yóò gòkè lọ sí ọ̀run; èmi yóò gbé ìtẹ́ mi sókè ga ju àwọn ìràwọ̀ Ọlọ́run, Èmi yóò gúnwà ní orí òkè àpéjọ ní ṣóńṣó orí òkè mímọ́.
14 E pii aku no wau maluna o kahi kiekie o na ao, E like ana au me ka Mea kiekie loa.
Èmi yóò gòkè lọ rékọjá àwọn àwọsánmọ̀; èmi yóò ṣe ara mi gẹ́gẹ́ bí Ọ̀gá-ògo.”
15 Ua hoohaahaaia ka oe, ilalo o ka po, A i kahi hohonu hoi o ka lun! (Sheol h7585)
Ṣùgbọ́n a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ wọ inú ibojì lọ lọ sí ìsàlẹ̀ ọ̀gbun. (Sheol h7585)
16 O ka poe ike aku ia oe, e haka pono aku no lakou ia oe, E makaikai aku no ia oe, a e olelo iho, O keia anei ke kanaka nana i hoonaueue ka honua? A hooluliluli hoi na aupuni?
Àwọn tí ó rí ọ yóò tẹjúmọ́ ọ, wọ́n ronú nípa àtubọ̀tán rẹ: “Ǹjẹ́ èyí ni ẹni tí ó mi ayé tìtì tí ó sì jẹ́ kí àwọn ilẹ̀ ọba wárìrì.
17 Nana i hoolilo ka honua nei, i waonahele, A anai hoi i kona poe kulanakauhale? Ka mea i kuu ole i kona mea pio, e hoi hou i ko lakou wahi?
Ẹni tí ó sọ ayé di aginjù, tí ó sì pa ìlú ńlá ńlá rẹ̀ run tí kò dá àwọn òǹdè rẹ̀ sílẹ̀ láti padà sílé?”
18 O na'lii a pau o na aina, maloko o ka nani lakou a pau e moe nei, O kela mea keia mea ma kona wahi iho.
Gbogbo àwọn ọba orílẹ̀-èdè ni a tẹ́ sílẹ̀ ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú ibojì tirẹ̀.
19 Ua hooleiia'ku ka oe mawaho o kou lua, Me he oha la i hoopailuaia, Me he aahu la o ka poe i pepehiia, Ka poe hoi i houia i ka pahikaua, Me he kupapau la i hahiia.
Ṣùgbọ́n a jù ọ́ síta kúrò nínú ibojì gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ka igi tí a kọ̀sílẹ̀, àwọn tí a pa ni ó bò ọ́ mọ́lẹ̀, àwọn tí idà ti gún, àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú òkúta inú ọ̀gbun. Gẹ́gẹ́ bí òkú ó di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ ní abẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀,
20 Aole oe e huipuia me lakou ma ke kanu ana, No ka mea, ua hooki loa oe i kou aina iho, Ua luku no oe i kou poe kanaka; Aole e hea hou ia ka hanauna o ka poe hewa a i ke ao pau ole,
a kò ní sin ọ́ pẹ̀lú wọn, nítorí pé o ti ba ilẹ̀ rẹ jẹ́ o sì ti pa àwọn ènìyàn rẹ. Ìran àwọn ìkà ni a kì yóò dárúkọ wọn mọ́.
21 E hoomakaukau oukou i ka make no kana mau keiki, No ka hewa o na makua o lakou; I ole lakou e ku mai, a komo i ka aina, I hoopiha ole hoi lakou i ka aina i na kulanakauhale.
Tọ́jú ibìkan tí a ó ti pa àwọn ọmọkùnrin rẹ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba ńlá wọn, wọn kò gbọdọ̀ dìde láti jogún ilẹ̀ kí wọ́n sì bo orí ilẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìlú u wọn.
22 Na'u no e ala'e iluna e ku e ia lakou, Wahi a Iehova o na kaua; E hooki loa no wau i ka inoa o Babulona, A me ke koena, a me na keiki, a me na mamo, Wahi a Iehova.
“Èmi yóò dìde sókè sí wọn,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Èmi yóò ké orúkọ rẹ̀ kúrò ní Babeli àti àwọn tí ó sálà, àwọn ọmọ àti ìran rẹ̀,” ni Olúwa wí.
23 E hooili aku au ia wahi no ke kipoda, A e lilo hoi ia i kiowai; A e kahili aku au ia me ke kahili o ka make, Wahi a Iehova o na kaua.
Èmi yóò yí i padà sí ibùgbé àwọn òwìwí àti sí irà; Èmi yóò fi ọwọ́ ìparun gbá a, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
24 Ua hoohiki mai o Iehova o na kaua, i mai la, Me ka'u i manao ai, pela io no ia: O ka'u i noonoo ai, oia ke kupaa.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra, “Gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣètò, bẹ́ẹ̀ ni yóò rí, àti bí mo ti pinnu, bẹ́ẹ̀ ni yóò sì dúró.
25 E lukuia auanei ko Asuria ma kuu aina, E hahi no wau ia ia maluna o ko'u kuahiwi; E laweia kana auamo mai o lakou aku, E haule hoi kona mea kaumaha mai luna mai o ko lakou poohiwi.
Èmi yóò run Asiria ní ilẹ̀ mi, ní àwọn orí òkè mi ni èmi yóò ti rún un mọ́lẹ̀. Àjàgà rẹ̀ ni a ó mú kúrò lọ́rùn àwọn ènìyàn mi, ẹrù u rẹ̀ ni ó mú kúrò ní èjìká wọn.”
26 Oia ka manao i manaoia'i no ka honua a pau; Oia ka lima i oia mai maluna ona lahuikanaka a pau.
Èyí ni ètò tí a pinnu rẹ̀ fún gbogbo ayé, èyí ni ọwọ́ tí a nà jáde káàkiri gbogbo orílẹ̀-èdè.
27 No ka mea, ua paa ka manao o Iehova o na kaua, Owai la hoi ka mea hiki ke hoole? Ua oia mai kona lima, Owai la ka mea e hoihoi aku ia?
Nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti pète, ta ni yóò sì ká a lọ́wọ́ kò? Ọwọ́ọ rẹ ti nà jáde, ta ni ó sì le è fà á padà?
28 I ka makahiki i make ai o ke alii, o Ahaza, keia wanana.
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ yí wá ní ọdún tí ọba Ahasi kú.
29 Mai olioli oe, e Pelisetia a pau, No ka hakiia o ka laau i hahau ia oe; No ka mea, mai ke aa o ka nahesa e laha mai ai ka moo pepeiaohao, A o kana hua hoi, he moo lele.
Má ṣe yọ̀, gbogbo ẹ̀yin Filistia, pé ọ̀pá tí ó lù ọ́ ti dá; láti ibi gbòǹgbò ejò náà ni paramọ́lẹ̀ yóò ti hù jáde, èso rẹ̀ yóò sì jẹ́ oró ejò tí í jóni.
30 E ai no ka poe hune loa, A e moe no ilalo ka poe ehaeha me ka maluhia; Aka, e hooki loa au i kou aa i ka wi, A e luku aku oia i kou poe i koe.
Ẹni tí ó kúṣẹ̀ẹ́ jù yóò ní pápá oko, àwọn aláìní yóò sì dùbúlẹ̀ láìléwu. Ṣùgbọ́n gbòǹgbò o rẹ̀ ni èmi ó fi ìyàn parun, yóò sì ké àwọn ẹni rẹ tí ó sálà kúrò.
31 E aoa, e ka pukapa, e uwe aku, e ke kulanakauhale, Ua maule oe, e Pilisetia a pau. No ka mea, ke punohu mai nei ka uwahi mai ka akau mai, Aohe mea helelei o kona poe kaua.
Hu, ìwọ ẹnu-ọ̀nà! Kígbe, ìwọ ìlú! Yọ́ kúrò, gbogbo ẹ̀yin Filistia! Èéfín kurukuru kan ti àríwá wá, kò sì ṣí amóríbọ́ kan nínú ẹgbẹ́ wọn.
32 Pehea la e olelo aku ai i na elele o ka aina? Ua hookumu o Iehova ia Ziona, E loaa auanei ka puuhonua no kona poe kanaka poino.
Kí ni ìdáhùn tí a ó fún agbẹnusọ orílẹ̀-èdè náà? “Olúwa ti fi ìdí Sioni kalẹ̀, àti nínú rẹ̀ ni àwọn ènìyàn rẹ̀ tí a ti pọ́n ọn lójú yóò ti rí ààbò o wọn.”

< Isaia 14 >