< Hagai 1 >

1 I KA lua o ka makahiki o Dariu ke alii, i ke ono o ka malama, i ka la mua o ua malama la, hiki mai la ka olelo a Iehova ma o Hagai la, o ke kaula, ia Zerubabela ke keiki a Saletiela, ke kiaaina o Iuda, a ia Iosua ke keiki a Iosedeka, ke kahuna nui, i ka i ana ae,
Ní ọdún kejì ọba Dariusi ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹfà, ọ̀rọ̀ Olúwa wá nípasẹ̀ wòlíì Hagai sí Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, baálẹ̀ Juda, àti sọ́dọ̀ Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà.
2 Ke olelo mai nei o Iehova o na kaua, penei, i mai la; Ke i mai nei keia poe kanaka, Aole i hiki mai ka manawa, ka manawa e kapili ai i ka hale o Iehova.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Àwọn ènìyàn wọ̀nyí wí pé, ‘Kò tí ì tó àkókò láti kọ́ ilé Olúwa.’”
3 Nolaila, hiki mai ai ka olelo a Iehova ma o Hagai la, o ke kaula, i ka i ana'e,
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa wá láti ọ̀dọ̀ wòlíì Hagai wí pé,
4 E oukou nei, o ka manawa anei keia no oukou e noho ai iloko o ko oukou mau hale papa kedera, a e neoneo ai hoi keia hale?
“Ǹjẹ́ àkókò ni fún ẹ̀yin fúnra yín láti máa gbé ní ilé tí a ṣe ní ọ̀ṣọ́ nígbà tí ilé yìí wà ni ahoro?”
5 Nolaila hoi, eia ka Iehova ke Akua o na kaua e olelo nei; E noonoo oukou i ko oukou mau aoao.
Nísìnsinyìí, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ kíyèsi ọ̀nà yín.
6 Ua lulu nui aku oukou, a he uuku ka mea a oukou i ohi ai; ua ai oukou, aole nae i maona; ua inu oukou, aole nae i kena ka makewai; ua aahu kapa oukou, aole no nae oukou i mehana; a o ka mea i hana e ukuia mai, ua hahaoia kana uku maloko o ke eke pukapuka.
Ẹ̀yin ti gbìn ohun ti ó pọ̀. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kórè díẹ̀ níbẹ̀. Ẹ̀yin jẹun, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò yó. Ẹ̀yin mu ṣùgbọ́n kò tẹ́ ẹ yín lọ́run; ẹ̀yin wọ aṣọ, ṣùgbọ́n kò mú òtútù yin lọ; ẹyin gba owó iṣẹ́ ṣùgbọ́n ẹ ń gbà á sínú ajádìí àpò.”
7 Eia ka Iehova ke Akua o na kaua i olelo mai nei; e noonoo oukou i ko oukou mau aoao.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ kíyèsi ọ̀nà yín.
8 E pii aku i ke kuahiwi a e lawe mai i laau, a e hana i ka hale a e oluolu au ia, a e hoomaikaiia auanei hoi au, wahi a Iehova.
Ẹ gun orí àwọn òkè ńlá lọ, kí ẹ sì mú igi wá pẹ̀lú yín. Kí ẹ sì kọ́ ilé náà, kí inú mi bà le è dùn sí i, kí a sì yín mí lógo,” ni Olúwa wí.
9 Kuko aku la oukou i nui, aia hoi he uuku; lawe aku la oukou iloko o ka hale, a pupuhi aku la au ia. No ke aha? wahi a Iehova, ke Akua o na kaua. No kuu hale no i neoneo, a holo oukou kela mea keia mea i kona hale iho.
“Ẹyin ti ń retí ọ̀pọ̀, ṣùgbọ́n kíyèsi i, o yípadà sí díẹ̀. Ohun tí ẹ̀yin mú wa ilé, èmi sì fẹ́ ẹ dànù. Nítorí kí ni?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Nítorí ilé mi tí ó dahoro; tí olúkúlùkù yín sì ń sáré fún ilé ara rẹ̀.
10 Nolaila, ua paniia ka lani maluna o oukou, i haawi ole mai ai ia i ka hau, a ua pau ka hoohua mau ana o ka honua i kona hua.
Nítorí yín ni àwọn ọ̀run ṣe dá ìrì dúró tí ilẹ̀ sì kọ̀ láti mu èso jáde.
11 Ua kahea aku la au i manawa wi maluna o ka aina, a maluna o na mauna, a maluna o ka ai, a maluna o ka waina hou, a maluna o ka aila oliva, a maluna o na mea a pau a ka lepo e hua mai ai, a maluna o kanaka, maluna o na holoholona, a maluna o ka hana a pau a na lima.
Mo sì ti pe ọ̀dá sórí ilẹ̀ àti sórí àwọn òkè ńlá, sórí ọkà àti sórí wáìnì tuntun, sórí òróró àti sórí ohun ti ilẹ̀ ń mú jáde, sórí ènìyàn, sórí ẹran àti sórí gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín.”
12 Alaila, hoolohe ae la o Zerubabela ke keiki a Saletiela, a o Iosua ke keiki a Iosedeka, ke kahuna nui, a me ke koena kanaka a pau, i ka leo o Iehova ko lakou Akua, a me ka olelo a Hagai ke haula, me ka Iehova o ko lakou Akua i hoouna mai ai ia ia, a makau ae la na kanaka ia Iehova.
Nígbà náà ni Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà pẹ̀lú gbogbo ènìyàn ìyókù, gba ohùn Olúwa Ọlọ́run wọn gbọ́ àti ọ̀rọ̀ wòlíì Hagai, nítorí Olúwa Ọlọ́run ni ó rán an. Àwọn ènìyàn sì bẹ̀rù Olúwa.
13 Olelo aku la o Hagai o ka elele o Iehova, ma ka ke kauoha a Iehova i na kanaka, i ka i ana ae, Me oukou pu no wau, wahi a Iehova.
Nígbà náà ni Hagai ìránṣẹ́ Olúwa ń jíṣẹ́ Olúwa fún àwọn ènìyàn pé, “Èmí wà pẹ̀lú yín,” ni Olúwa wí.
14 A paipai mai la o Iehova i ka naau o Zerubabela ke keiki a Saletiela, ke kiaaina o Iuda, a me ka naau o Iosua ke keiki a Iosedeka, ke kahuna nui, a me ka naau o ke koena kanaka a pau; a hele aku la lakou a hana iho la i ka hale o Iehova o na kaua, o ko lakou Akua,
Nítorí náà, Olúwa ru ẹ̀mí Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli sókè, baálẹ̀ Juda àti ẹ̀mí Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà àti ẹ̀mí gbogbo ènìyàn ìyókù. Wọ́n sì wá, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣiṣẹ́ lórí ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run wọn,
15 I ka la iwakaluakumamaha o ka malama eono, i ka lua o ka makahiki o ke alii o Dariu.
ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹfà ní ọdún kejì ọba Dariusi.

< Hagai 1 >