< Hagai 2 >

1 I KA la iwakaluakumamakahi o ka malama ahiku, hiki mai la ka olelo a Iehova ma o Hagai la ke kaula, i ka i ana mai,
Ní ọjọ́ kọkànlélógún oṣù keje, ni ọ̀rọ̀ Olúwa wá nípasẹ̀ wòlíì Hagai wí pé,
2 E olelo aku oe ia Zerubabela ke keiki a Saletiela, ke kiaaina o Iuda, a ia Iosua ke keiki a Iosedeka, ke kahuna nui, a i ke koena o kanaka, i ka i ana aku,
“Sọ fún Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, baálẹ̀ Juda, àti Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà àti àwọn ènìyàn yòókù. Béèrè lọ́wọ́ wọn pé,
3 Owai o oukou e koe, nana i ike i kela luakini me kona nani mua? pehea oukou i ike ai i keia, ano, aole anei ia ma ko oukou maka me he mea ole la?
‘Ta ni nínú yín tí ó kù tí ó sì ti rí ilé yìí ní ògo rẹ̀ àkọ́kọ́? Báwo ni ó ṣe ri sí yín nísinsin yìí? Ǹjẹ́ kò dàbí asán lójú yín?
4 Aka, i nui hoi ka ikaika ou, e Zerubabela, wahi a Iehova; i nui hoi ka ikaika ou, e Iosua, e ke keiki a Iosedeka, ke kahuna nui; i nui hoi ka ikaika o oukou, e na kanaka a pau o ka aina nei, a e hana hoi, wahi a Iehova; no ka mea, me oukou pu hoi au, wahi a Iehova o na kaua.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, múra gírí, ìwọ Serubbabeli,’ ni Olúwa wí. ‘Múra gírí, ìwọ Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà. Ẹ sì múra gírí gbogbo ẹ̀yin ènìyàn ilẹ̀ náà,’ ni Olúwa wí, ‘kí ẹ sì ṣiṣẹ́. Nítorí èmi wà pẹ̀lú yín,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
5 E like me ka berita a'u i hoopaa aku ai me oukou, ia oukou i puka ai mai Aigupita mai, pela hoi e noho ai kuu Uhane iwaena o oukou; mai makau oukou.
‘Èyí ni ohun tí Èmi fi bá a yín dá májẹ̀mú nígbà tí ẹ jáde kúrò ní Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni Ẹ̀mí ì mi sì wà pẹ̀lú yín. Ẹ má ṣe bẹ̀rù.’
6 No ka mea, penei ka i ana mai a Iehova, ke Akua o na kaua; I kekahi manawa aku, he liuliu iki ia, a e hoonaue au i ka lani a me ka honua, i ke kai a me ka aina maloo;
“Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Láìpẹ́ jọjọ, Èmi yóò mi àwọn ọrun àti ayé, Òkun àti ìyàngbẹ ilẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i.
7 A e hoonaue hoi au i na lahuikanaka a pau, a e hele mai auanei ka mea i makemakeia e na lahuikanaka a pau, a e hoopiha auanei au i keia hale i ka nani, wahi a Iehova o na kaua.
Èmi yóò mi gbogbo orílẹ̀-èdè, ìfẹ́ gbogbo orílẹ̀-èdè yóò fà sí tẹmpili yìí, Èmi yóò sì kún ilé yìí pẹ̀lú ògo,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
8 No'u no ke kala, no'u hoi ke gula, wahi a Iehova o na kaua.
‘Tèmi ni fàdákà àti wúrà,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
9 E oi auanei ka nani o keia hale hope imua o ko ka mua, wahi a Iehova o na kaua; a ma keia wahi hoi e haawi aku no wau i ka maluhia, wahi a Iehova o na kaua.
‘Ògo ìkẹyìn ilé yìí yóò pọ̀ ju ti ìṣáájú lọ,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Àti ní ìhín yìí ni Èmi ó sì fi àlàáfíà fún ni,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
10 I ka la iwakaluakumamaha o ka iwa o ka malama, i ka lua o ka makahiki o Dariu, hiki mai la ka olelo a Iehova ma o Hagai la ke kaula, i ka i ana mai,
Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹsànán ní ọdún kejì Dariusi, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Hagai wá pé,
11 Penei ka Iehova o na kaua e olelo mai nei, E ninau aku oe i na kahuna no ke kanawai, penei,
“Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Béèrè lọ́wọ́ àwọn àlùfáà ohun tí òfin wí pé:
12 Ina e lawelawe kekahi i ka io laa ma ke kihi o kona aahu, a hoopa aku kona kihi i ka berena, i ka io hoolapalapa paha, a i ka waina, a i ka aila paha, a i kekahi mea ai e ae, e laa no anei ia? Hoole mai la na kahuna, i mai la, Aole.
Bí ẹnìkan bá gbé ẹran mímọ́ ní ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀, tí ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀ kan àkàrà tàbí ọbẹ̀, wáìnì, òróró tàbí oúnjẹ mìíràn, ǹjẹ́ yóò ha jẹ́ mímọ́ bí?’” Àwọn àlùfáà sì dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́.”
13 Alaila i aku la o Hagai, Ina i haumia kekahi i ke kupapau, a hoopa aku ia i kekahi o keia mau mea, e haumia anei ia mea? Pane mai la na kahuna, i mai la, E haumia no.
Nígbà náà ni Hagai wí pé, “Bí ẹnìkan tí ó jẹ́ aláìmọ́ nípa fífi ara kan òkú bá fi ara kan ọ̀kan lára nǹkan wọ̀nyí, ǹjẹ́ yóò ha jẹ́ aláìmọ́?” Àwọn àlùfáà sì dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, yóò jẹ́ aláìmọ́.”
14 Olelo aku la o Hagai, i aku la, Pela no keia poe kanaka, a pela keia lahuikanaka imua o'u, wahi a Iehova: a pela hoi ka hana a pau a ko lakou lima; a o ka mea a lakou e mohai mai ai ilaila, he haumia ia.
Nígbà náà ni Hagai dáhùn ó sì wí pé, “‘Bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn wọ̀nyí rí, bẹ́ẹ̀ sì ni orílẹ̀-èdè yìí rí níwájú mi,’ ni Olúwa wí. ‘Bẹ́ẹ̀ sì ni olúkúlùkù iṣẹ́ ọwọ́ wọn; èyí tí wọ́n sì fi rú ẹbọ níbẹ̀ jẹ́ aláìmọ́.
15 Nolaila hoi, e noonoo pono oukou mai keia la e noho nei a hiki i ka wa mamua, i ka wa i kau ole ia'i ka pohaku maluna o kekahi pohaku ma ka luakini o Iehova.
“‘Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ ro èyí dáradára láti òní yìí lọ, ẹ kíyèsi bí nǹkan ṣe rí tẹ́lẹ̀, a to òkúta kan lé orí èkejì ní tẹmpili Olúwa.
16 Mai ia manawa, ina hele aku kekahi i ka puu hua ai he iwakalua na ana ona, a loaa he umi; a i hele aku hoi kekahi i kahi kaomi waina e hookahe ai i na ana he kanalima mailoko mai o ke kaomi waina, a loaa iho he iwakalua wale no.
Nígbà tí ẹnikẹ́ni bá dé ibi òkìtì òsùwọ̀n ogun, mẹ́wàá péré ni yóò ba níbẹ̀. Nígbà tí ẹnikẹ́ni bá dé ibi ìfúntí wáìnì láti wọn àádọ́ta ìwọ̀n, ogún péré ni yóò ba níbẹ̀.
17 Hahau aku la au ia oukou i ka maloo a me ka popo, a me ka huahekili ma na hana a pau a ko oukou mau lima; aka, aole o oukou i huli mai i o'u nei, wahi a Iehova.
Mo fi ìrẹ̀dànù, ìmúwòdù àti yìnyín bá gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín jẹ; síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí ọ̀dọ̀ mi,’ ni Olúwa wí.
18 E noonoo oukou mai keia la e noho nei a mamua aku, mai ka la iwakaluakumamaha o ka malama aiwa, a hiki i kela la i hookumuia'i ka luakini o Iehova; e noonoo oukou.
‘Láti òní lọ, láti ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹsànán yìí kí ẹ kíyèsi, kí ẹ sì rò ó dáradára, ọjọ́ ti a fi ìpìlẹ̀ tẹmpili Olúwa lélẹ̀, rò ó dáradára.
19 Ua koe anei ka hua ai iloko ka halepapaa? Eia hoi, aole ka waina, a me ka fiku, a me ka pomegerane, a me ka laau oliva i hua mai i ka hua: mai keia la aku nae, e hoomaikai aku no wau ia oukou.
Ǹjẹ́ èso ha wà nínú abà bí? Títí di àkókò yìí, àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ àti pomegiranate, àti igi olifi kò ì tí ì so èso kankan. “‘Láti òní lọ ni èmi yóò bùkún fún un yin.’”
20 Hiki hou mai la ka olelo a Iehova ia Hagai i ka la iwakaluakumamaha o ua malama la, i ka i ana mai,
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ Hagai wá nígbà kejì, ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù náà pé,
21 E i aku oe ia Zerubabela ke kiaaina o Iuda, penei, E hoonaue ana au i ka lani a me ka honua;
“Sọ fún Serubbabeli baálẹ̀ Juda pé èmi yóò mi àwọn ọ̀run àti ayé.
22 A e hookahuli au i ka nohoalii o na aupuni, a e hoolilo au i ka ikaika o na aupuni kanaka e i mea ole; e hookahuli hoi au i na halekaa a me ka poe holo maloko; a e haule iho auanei na lio a me na hoohololio, o kela mea keia mea o lakou, i ka pahikaua a kona hoahanau.
Èmi yóò bi ìtẹ́ àwọn ìjọba ṣubú, Èmi yóò sì pa agbára àwọn aláìkọlà run, Èmi yóò sì dojú àwọn kẹ̀kẹ́ ogun dé, àti àwọn tí ń gùn wọ́n; ẹṣin àti àwọn ẹlẹ́ṣin yóò ṣubú; olúkúlùkù nípa idà arákùnrin rẹ̀.”
23 Ia la hoi, wahi a Iehova o na kaua, e lawe au ia oe, e Zerubabela ke keiki a Saletiela, o ka'u kauwa, wahi a Iehova, a e hoolike au ia oe me ke komolima hoopili wepa; no ka mea, ua koho au ia oe, wahi a Iehova o na kaua.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Ní ọjọ́ náà, ìwọ ìránṣẹ́ mi Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, Èmi yóò mú ọ, Èmi yóò sì sọ ọ di bí òrùka èdìdì mi, nítorí mo ti yan ọ, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”

< Hagai 2 >