< Kinohi 13 >

1 PII hou mai la o Aberama mai Aigupita mai, oia me kana wahine, a me kana mau mea a pau, a me ia no o Lota, i kau wahi o ke kukuluhema.
Abramu sì gòkè láti Ejibiti lọ sí ìhà gúúsù, pẹ̀lú aya rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní àti Lọti pẹ̀lú.
2 Ua waiwai nui loa o Aberama i na holoholona, i ke kala a me ke gula.
Abramu sì ti di ọlọ́rọ̀ gidigidi; ní ẹran ọ̀sìn, ó ní fàdákà àti wúrà.
3 Hele ae la ia i kona hele ana mai ke kukuluhema mai a Betela, kahi i ku ai o kona halelewa mamua, mawaena o Betela a me Hai;
Láti gúúsù, ó ń lọ láti ibìkan sí ibòmíràn títí ó fi dé ilẹ̀ Beteli, ní ibi tí àgọ́ rẹ̀ ti wà ní ìṣáájú rí, lágbedeméjì Beteli àti Ai.
4 Kahi o ke kuahu ana i haua'i mamua: ilaila o Aberama i kahea aku ai i ka inoa o Iehova.
Ní ibi pẹpẹ tí ó ti tẹ́ síbẹ̀ ní ìṣáájú, níbẹ̀ ni Abramu sì ń ké pe orúkọ Olúwa.
5 A o Lota hoi, ka mea i hele pu me Aberama, he hipa no kana me na bipi a me na halelewa.
Àti Lọti pẹ̀lú, tí ó ń bá Abramu rìn kiri, ní agbo ẹran, ọ̀wọ́ ẹran àti àgọ́.
6 Aole i pono ka aina no laua, i noho pu ai laua, no ka nui o ko laua waiwai, aole i hiki ia laua ke noho pu.
Ṣùgbọ́n ilẹ̀ náà kò le gbà wọ́n tí wọ́n bá ń gbé pọ̀, nítorí, ohun ìní wọn pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́, dé bi wí pé wọn kò le è gbé pọ̀.
7 Hakaka ae la ka poe kahubipi a Aberama me ka poe kahubipi a Lota: e noho ana no ka Kanaana a me ka Perezi ma ia aina ia manawa.
Èdè-àìyedè sì bẹ̀rẹ̀ láàrín àwọn darandaran Abramu àti ti Lọti. Àwọn ará Kenaani àti àwọn ará Peresi sì ń gbé ní ilẹ̀ náà nígbà náà.
8 I aku la o Aberama ia Lota, Ea, aole make hakaka kaua, kekahi i kekahi, aole hoi ka'u poe kahubipi me kau poe kahubipi; no ka mea, he mau hoahanau kaua.
Abramu sì wí fún Lọti pé, “Èmi bẹ̀ ọ́, má ṣe jẹ́ kí èdè-àìyedè kí ó wà láàrín èmi àti ìrẹ, àti láàrín àwọn darandaran wa, nítorí pé ẹbí kan ni àwa ṣe.
9 Aole anei ma kou alo ka aina a pau? ke noi aku nei au ia oe, e hookaawale kaua: ina oe ma ka lima hema, alaila e hele au ma ka lima akau; a ma ka lima akau oe, alaila e hele au ma ka lima hema.
Gbogbo ilẹ̀ ha kọ́ nìyí níwájú rẹ? Jẹ́ kí a pínyà. Bí ìwọ bá lọ sí apá ọ̀tún, èmi yóò lọ sí apá òsì, bí ó sì ṣe òsì ni ìwọ lọ, èmi yóò lọ sí apá ọ̀tún.”
10 Alawa ae la ko Lota mau maka, ike aku la i na wahi papu o Ioredane, he nui ka wai ma ia wahi a pau i kou hele ana mai i Zoara, mamua o ko Iehova luku ana ia Sodoma a me Gomora, e like me ka mahinaai o Iehova, a e like me ka aina i Aigupita.
Lọti sì gbójú sókè, ó sì ri wí pé gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jordani ni omi rin dáradára bí ọgbà Olúwa, bí ilẹ̀ Ejibiti, ní ọ̀nà Soari. (Èyí ní ìṣáájú kí Olúwa tó pa Sodomu àti Gomorra run.)
11 Alaila, wae iho la o Lota i ka papu a pau o Ioredane: a hele aku la o Lota ma ka hikina, a hookaawale ae la laua i ke kekahi me kekahi.
Nítorí náà Lọti yan gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jordani yìí fún ara rẹ̀, ó sì ń lọ sí ọ̀nà ìlà-oòrùn. Òun àti Abramu sì pínyà.
12 Noho iho la o Aberama ma ka aina i Kanaana, a noho aku la o Lota ma na kulanakauhale o ua papu la, a kukulu iho la i kona halelewa ma Sodoma.
Abramu ń gbé ni ilẹ̀ Kenaani, Lọti sì jókòó ní ìlú agbègbè àfonífojì náà, ó sì pàgọ́ rẹ̀ títí dé Sodomu.
13 A o na kanaka o Sodoma, he poe hewa lakou, he lawehala loa imua o Iehova.
Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Sodomu jẹ́ ènìyàn búburú, wọn sì ń dẹ́ṣẹ̀ gidigidi ni iwájú Olúwa.
14 Olelo mai la o Iehova ia Aberama mahope mai o ko Lota hookaawale ana ae mai ona aku la, E alawa ae oe i kou mau maka, a e nana aku mai kou wahi e noho nei, i ke kukuluakau a i ke kukuluhema, a i ka hikina hoi a i ke komohana:
Olúwa sì wí fún Abramu lẹ́yìn ìpinyà òun àti Lọti pé, “Gbé ojú rẹ sókè nísinsin yìí, kí o sì wò láti ibi tí o gbé wà a nì lọ sí ìhà àríwá àti sí ìhà gúúsù, sí ìlà-oòrùn àti sí ìwọ̀ rẹ̀.
15 No ka mea, o ka aina a pau au e ike nei, na'u ia e haawi aku nou, a no kau poe mamo mahope mau loa aku.
Gbogbo ilẹ̀ tí ìwọ ń wò o nì ni èmi ó fi fún ọ àti irú-ọmọ rẹ láéláé.
16 E hoomahuahua aku no wau i kau poe mamo e like me ka lepo o ka honua: ina e hiki i ke kanaka ke helu i na huna lepo o ka honua, alaila e heluia kau poe mamo.
Èmi yóò mú kí irú-ọmọ rẹ kí ó pọ̀ bí erùpẹ̀ ilẹ̀, tó bẹ́ẹ̀ tí ó bá ṣe pé ẹnikẹ́ni bá le è ka erùpẹ̀ ilẹ̀, nígbà náà ni yóò tó lè ka irú-ọmọ rẹ.
17 E ku ae; e kaahele i ka aina ma kona loa a ma kona laula; no ka mea, na'u no ia e haawi aku nou.
Dìde, rìn òró àti ìbú ilẹ̀ náà já, nítorí ìwọ ni Èmi yóò fi fún.”
18 Alaila lawe ae la o Aberama i kona halelewa, hele aku la ia a noho iho la ma na laau oka no Mamere, aia no ma Heberona, a hana iho la ia ilaila i kuahu no Iehova.
Nígbà náà ni Abramu kó àgọ́ rẹ̀, ó sì wá, ó sì jókòó ní ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó Mamre, tí ó wà ní Hebroni. Níbẹ̀ ni ó gbé tẹ́ pẹpẹ kan sí fún Olúwa.

< Kinohi 13 >