< Ezera 10 >

1 A PAU ka Ezera pule ana, a me ka uwe ana, a me ka moe ana imua o ka hale o ke Akua, hoakoakoaia ae la io na la he anaina kanaka nui loa o ka Iseraela, na kane, me na wahine a me na kamalii; no ka mea, he nui loa ka uwe o na kanaka.
Nígbà tí Esra ń gbàdúrà tí ó sì ń jẹ́wọ́, ti ó ń sọkún ti ó sì ń gbárayílẹ̀ níwájú ilé Ọlọ́run, ogunlọ́gọ̀ àwọn ọmọ Israẹli ọkùnrin, obìnrin àti àwọn ọmọdé pagbo yí i ká. Àwọn náà ń sọkún kíkorò.
2 A olelo mai o Sekania ke keiki a Iehiela, no na mamo a Elama, i mai la ia Ezera, Ua hana hewa makou i ke Akua, a ua lawe makou i na wahine e no na kanaka o ka aina: aka ano, he manaolana no iloko o ka Iseraela no keia mea.
Nígbà náà ni Ṣekaniah ọmọ Jehieli, ọ̀kan lára ìran Elamu, sọ fún Esra pé, “Àwa ti jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run wa nípa fífẹ́ àwọn obìnrin àjèjì láàrín àwọn ènìyàn tí ó wà yí wa ká. Ṣùgbọ́n síbẹ̀ náà, ìrètí sì wà fún Israẹli
3 Ano hoi, e hoohiki kakou i ko kakou Akua e hookuke aku i na wahine a pau, a me na mea a lakou i hanau ai, e like me ke ao ana a kuu haku, a me ka poe e makau ana i ke kauoha a ko kakou Akua; a e hanaia ia mea ma ke kanawai.
Nísìnsinyìí, ẹ jẹ́ kí a dá májẹ̀mú níwájú Ọlọ́run wa láti lé àwọn obìnrin yìí àti àwọn ọmọ wọn lọ. Gẹ́gẹ́ bí ìmọ̀ràn Esra olúwa mi àti ti àwọn tí ó bẹ̀rù àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wa. Ẹ jẹ́ kí a ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin.
4 E ku ae oe, no ka mea, ia oe no keia mea: o makou pu kekahi me oe; e ikaika oe, a e hana.
Dìde, nítorí, ọ̀rọ̀ tìrẹ ni èyí. Gbogbo wà yóò wá pẹ̀lú rẹ, mú ọkàn le kí o sì ṣe é.”
5 Alaila ku ae la o Ezera, a hoohiki aku la i na kahuna nui, i na Levi, a me ka Iseraela a pau, e hana lakou e like me keia olelo. A hoohiki iho la lakou.
Nígbà náà ni Esra dìde, ó sì fi àwọn aṣíwájú àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi àti gbogbo Israẹli sí abẹ́ ìbúra, láti ṣe ohun tí wọ́n dá lábàá. Wọ́n sì búra.
6 Alaila ku ae la o Ezera mai ke alo mai o ka hale o ke Akua, a komo iloko o ke keena o Iehohanana ke keiki a Eliasiba; a hiki aku ia ilaila, aole ia i ai i ka ai, aole hoi i inu i ka wai; no ka mea, uwe iho la ia no ka hewa o ka poe pio i hoi mai.
Nígbà náà ni Esra padà sẹ́yìn kúrò níwájú ilé Ọlọ́run, ó sì lọ sí iyàrá Jehohanani ọmọ Eliaṣibu. Nígbà tí ó wà níbẹ̀, kò jẹ oúnjẹ bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu omi, nítorí ó sì ń káàánú fún àìṣòótọ́ àwọn ìgbèkùn.
7 A hai aku la lakou ma Iuda, a ma Ierusalema i ka poe pio a pau e honluulu lakou ma Ierusalema;
Ìkéde kan jáde lọ jákèjádò Juda àti Jerusalẹmu fún gbogbo àwọn ìgbèkùn láti péjọ sí Jerusalẹmu.
8 A o na mea a pau i hele ole mai i na la ekolu, e like me ke kauoha a na luna, a me ka poe kahiko, e hoolaaia kona waiwai a pau, a e hookaawaleia oia mai ko anaina kanaka aku o ka poe pio i lawe pio ia aku.
Ẹnikẹ́ni tí ó ba kọ̀ láti jáde wá láàrín ọjọ́ mẹ́ta yóò pàdánù ohun ìní rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú ìpinnu àwọn ìjòyè àti àwọn àgbàgbà, àti pé a ó lé òun fúnra rẹ̀ jáde kúrò láàrín ìpéjọpọ̀ àwọn ìgbèkùn.
9 Alaila hoakoakoaia ae la na kanaka a pau o ka Iuda, a o ka Beniamina i Ierusalema i na la ekolu, i ka iwa o ka malama, a i ka la iwakalua o ka malama; a noho iho la na kanaka a pau ma ke ala o ka hale o ke Akua, e haalulu ana no keia mea, a no ka ua nui.
Láàrín ọjọ́ mẹ́ta náà, gbogbo àwọn ọkùnrin Juda àti Benjamini tí péjọ sí Jerusalẹmu. Ní ogúnjọ́ oṣù kẹsànán, gbogbo àwọn ènìyàn jókòó sí ìta gbangba iwájú ilé Ọlọ́run, wọ́n wà nínú ìbànújẹ́ ńlá nítorí ọ̀ràn yìí, àti nítorí òjò púpọ̀ tó tì rọ̀.
10 Ku ae la o Ezera ke kahuna, a olelo aku la ia lakou, Ua hana hewa oukou, a ua lawe i na wahine e, e hoomahuahua i ka hala o ka Iseraela.
Nígbà náà ni àlùfáà Esra dìde, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ṣe àìṣòótọ́, ẹ ti fẹ́ obìnrin àjèjì, ẹ ti dá kún ẹ̀bi Israẹli.
11 Ano hoi, e hai aku oukou ia Iehova ke Akua o ko oukou poe makua, a e hana i kona makemake; a hookaawale oukou ia oukou iho mai na kanaka o ka aina aku, a mai na wahine e aku.
Nísinsin yìí, ẹ jẹ́wọ́ níwájú Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba yín, kí ẹ sì ṣe ìfẹ́ rẹ̀. Ẹ ya ara yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn tí ó yí i yín ká àti láàrín àwọn ìyàwó àjèjì yín.”
12 Alaila olelo mai la ka ahakanaka a pau, i mai la me ka leo nui, E like me kau olelo, pela makou e hana aku ai.
Àpéjọpọ̀ ènìyàn náà sì dáhùn lóhùn rara pé, ohun tí ó sọ dára! A gbọdọ̀ ṣe bí o ti wí.
13 Aka, ua nui na kanaka, a he manawa ua nui, aole e hiki ia makou ke ku mawaho, a o ka hana, aole ia no ka la hookahi, aole no na la elua; no ka mea, ua nui na mea o makou i hana hewa ma keia mea.
Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ ni ó wà ni ibi yìí síbẹ̀ àkókò òjò ni; àwa kò sì lè dúró ní ìta. Yàtọ̀ sí èyí, a kò le è yanjú ọ̀rọ̀ yìí láàrín ọjọ́ kan tàbí ọjọ́ méjì, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa pọ̀ jọjọ lórí àwọn nǹkan wọ̀nyí.
14 Ano hoi, e hoonohoia na luna o ka ahakanaka a pau, a o na mea a pau ma ko kakou mau kulanakauhale i lawe i na wahine e, e hele mai lakou i ka manawa maopopo, a me lakou pu no na lunakahiko o kela kulanakauhale keia kulanakauhale, a me na lunakanawai ona, a e hoohuli ae i ka inaina o ko kakou Akua mai o kakou aku no keia hewa.
Jẹ́ kí àwọn ìjòyè wa ṣojú fún gbogbo ìjọ ènìyàn, lẹ́yìn náà, jẹ́ kí ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú àwọn ìlú wa tí ó ti fẹ́ obìnrin àjèjì wá ní àsìkò tí a yàn, pẹ̀lú àwọn àgbàgbà àti àwọn onídàájọ́ ìlú kọ̀ọ̀kan, títí ìbínú gíga Ọlọ́run wa lórí ọ̀rọ̀ yìí yóò fi kúrò ní orí wa.
15 O Ionatana wale no, ke keiki a Asahela, a o Iahazia ke keiki a Tikeva i noho no keia mea, a o Mesulama, a me Sabetai ka Levi, i kokua mai ia laua.
Jonatani ọmọ Asaheli àti Jahseiah ọmọ Tikfa nìkan pẹ̀lú àtìlẹ́yìn Meṣullamu àti Ṣabbetai ará Lefi, ni wọ́n tako àbá yìí.
16 A hana aku la pela ka poe pio i hoi mai. A o Ezera ke kahuna, me na kauaka koikoi o na makua, no ka hale o ko lakou mau makua, o lakou a pau ma ko lakou inoa i hookaawaleia, a noho iho la lakou i ka la mua o ka umi o ka malama e hookolokolo ai i keia mea.
Nígbà náà ni àwọn ìgbèkùn ṣe gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe fi ẹnu kò sí. Àlùfáà Esra yan àwọn ọkùnrin tí wọ́n jẹ́ olórí àwọn ìdílé, ẹnìkọ̀ọ̀kan láti ìdílé kọ̀ọ̀kan, gbogbo wọn ni a sì mọ̀ pẹ̀lú orúkọ wọn. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹwàá, wọ́n jókòó láti ṣe àyẹ̀wò àwọn ẹjọ́ náà,
17 A hoopau lakou me na kanaka a pau i lawe i na wahine e, i ka la akahi o ka malama mua.
ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kìn-ín-ní ni wọn parí pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí wọ́n fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì.
18 A ua loaa iwaena o na keiki a na kahuna, na mea i lawe i na wahine e; no na mamo a Iesua ke keiki a Iozadaka, a me kona mau hoahanau, o Maaseia, a o Eliezera, o Iariba, a me Gedalia.
Lára ìran àwọn àlùfáà àwọn wọ̀nyí fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì. Nínú ìran Jeṣua ọmọ Josadaki, àti àwọn arákùnrin rẹ: Maaseiah, Elieseri, Jaribi àti Gedaliah.
19 A haawi mai lakou i ko lakou mau lima e hookuke aku i ka lakou mau wahine; a kaumaha aku lakou i ka hipakane o ka poe hipa i mohaihala no ko lakou lawehala ana.
Gbogbo wọn ni wọ́n ṣe ìpinnu láti lé àwọn ìyàwó wọn lọ, wọ́n sì fi àgbò kan láàrín agbo ẹran lélẹ̀ fún ẹ̀bi wọn gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀.
20 A no na mamo a Imera; o Hanani, a me Zebadia.
Nínú ìran Immeri: Hanani àti Sebadiah.
21 A no na mamo a Harima; o Maaseia, o Elia, o Semaia, o Iehiela, a me Uzia.
Nínú ìran Harimu: Maaseiah, Elijah, Ṣemaiah, Jehieli àti Ussiah.
22 A no na mamo a Pasura; o Elioenai, o Maaseia, o Isemaela, o Nataneela, o Iozabada, a me Elasa.
Nínú ìran Paṣuri: Elioenai, Maaseiah, Iṣmaeli, Netaneli, Josabadi àti Eleasa.
23 A no na Levi; o Iozabada, o Simei, o Kelaia, (oia o Kelita, ) o Petahia, o Iuda, a me Eliezera.
Lára àwọn ọmọ Lefi: Josabadi, Ṣimei, Kelaiah (èyí tí í ṣe Kelita), Petahiah, Juda àti Elieseri.
24 A no ka poe mele; o Aliasiba: a no na kiaipuka; o Saluma, o Telema, a me Uri.
Nínú àwọn akọrin: Eliaṣibu. Nínú àwọn aṣọ́nà: Ṣallumu, Telemu àti Uri.
25 A no ka Iseraela hoi; no na mamo a Parosa; o Ramia, o Iezia, o Malekia, Miamina, o Eleazara, o Malekiia, a me Benaia.
Àti lára àwọn ọmọ Israẹli tókù. Nínú ìran Paroṣi: Ramiah, Issiah, Malkiah, Mijamini, Eleasari, Malkiah àti Benaiah.
26 A no na mamo a Elama; o Matania, o Zekaria, o Iehiela, o Abedi, o Ieremota, a me Elia.
Nínú ìran Elamu: Mattaniah, Sekariah, Jehieli, Abdi, Jerimoti àti Elijah.
27 A no na mamo a Zatu; o Elioenai, o Eliasiba, o Matania, o Ieremota, o Zabada, a me Aziza.
Nínú àwọn ìran Sattu: Elioenai, Eliaṣibu, Mattaniah, Jerimoti, Sabadi àti Asisa.
28 A no na mamo a Bebai; o Iehohanana, o Hanania, o Zabai, a me Atelai.
Nínú àwọn ìran Bebai: Jehohanani, Hananiah, Sabbai àti Atlai.
29 A no na mamo a Bani; o Mesulama, o Maluka, o Adaia, o Iasuba, o Seala, a me Ramota.
Nínú àwọn ìran Bani: Meṣullamu, Malluki, Adaiah, Jaṣubu, Ṣeali àti Jerimoti.
30 A no na mamo a Pahata-moaba; o Adena, o Kelala, o Benaia, o Maaseia, o Matania, o Bezaleela, o Binui, a me Manase.
Nínú àwọn Pahati-Moabu: Adma, Kelali, Benaiah, Maaseiah, Mattaniah, Besaleli, Binnui àti Manase.
31 A no na mamo a Harima; o Eliezera, o Isiia, o Malekia, o Semaia, o Simeona,
Nínú àwọn ìran Harimu: Elieseri, Iṣiah, Malkiah àti Ṣemaiah, Simeoni,
32 O Beniamina, o Maluka, a me Semaria.
Benjamini, Malluki àti Ṣemariah.
33 A no na mamo a Hasuma; o Matenai, o Matata, o Zabada, o Elipeleta, o Ieremai, o Manase, a me Simei.
Nínú àwọn ìran Haṣumu: Mattenai, Mattatta, Sabadi, Elifaleti, Jeremai, Manase àti Ṣimei.
34 No na mamo a Bani; o Maadai, o Amerama, a me Uela,
Nínú àwọn ìran Bani: Maadai, Amramu, Ueli,
35 O Benaia, o Bedeia, o Kelu,
Benaiah, Bediah, Keluhi
36 O Vania, o Meremota, o Eliasiba,
Faniah, Meremoti, Eliaṣibu,
37 O Matania, o Matenai, a me Iaasau,
Mattaniah, Mattenai àti Jaasu.
38 A o Bani, o Binui, o Simei,
Àti Bani, àti Binnui: Ṣimei,
39 A o Selemia, o Natana, a me Adaia,
Ṣelemiah, Natani, Adaiah,
40 O Makenadebai, a Sasai, o Seharai,
Maknadebai, Sasai, Ṣarai,
41 O Azareela, o Selemia, o Semaria,
Asareeli, Ṣelemiah, Ṣemariah,
42 O Saluma, o Amaria, o Iosepa.
Ṣallumu, Amariah àti Josẹfu.
43 No na mamo a Nebo; o Ieiela, o Matitia, o Zabada, o Zebina, o Iadau, o Ioela, o Benaia.
Nínú àwọn ìran Nebo: Jeieli, Mattitiah, Sabadi, Sebina, Jaddai, Joẹli àti Benaiah.
44 O keia mau mea a pau, ua lawe lakou i na wahine e; a o na wahine a kekahi poe o lakou ua hanau keiki na lakou.
Gbogbo àwọn wọ̀nyí ló fẹ́ obìnrin àjèjì, àwọn mìíràn nínú wọn sì bi ọmọ ní ipasẹ̀ àwọn ìyàwó wọ̀nyí.

< Ezera 10 >