< Ezekiela 5 >
1 A OOE, ke keiki a ke kanaka, e lawe oe nou i pahi oi, e lawe oe i ka pahi kahi a ka mea kahi umiumi, a e hookahi ia ma kou poo a ma kou umiumi; alaila e lawe oe nau i mea kaupaona, a e puunaue i ka lauoho.
“Báyìí, ọmọ ènìyàn, mú ìdá tí ó mú kí o sì fi ṣe abẹ ìfárí onígbàjámọ̀, kí o fi fá irun orí àti irùngbọ̀n rẹ. Fi irun yìí sórí ìwọ̀n kí o sì pín in.
2 A e puhi oe i ka hapakolu me ke ahi iwaenakonu o ke kulanakauhale, i ka pau ana o na la o ka hoopuni ana; a e lawe oe i kekahi hapakolu, a e hahau me ka pahi a puni; a e lulu aku i kekahi hapakolu i ka makani, a e unuhi ae au i ka pahikaua mahope iho o lakou.
Nígbà tí ọjọ́ ìgbóguntì bá parí, sun ìdákan nínú ìdámẹ́ta irun yìí níná láàrín ìlú. Mú ìdákan nínú mẹ́ta kí o fi idà bù ú káàkiri ìlú. Kí o sì tú ìdákan yòókù ká sínú afẹ́fẹ́. Nítorí pé pẹ̀lú idà ni èmi yóò máa lé wọn ká.
3 A e lawe ae i kakaikahi o lakou; a e nakinaki maloko o na kihi o kou mau kapa.
Ṣùgbọ́n mú díẹ̀ nínú irun yìí kí o sì ta á mọ́ etí aṣọ rẹ.
4 Alaila e lawe hou i kauwahi o lakou, a e kiola aku iwaenakonu o ke ahi, a hoopau i ke ahi, a e puka mai no mai laila mai ke ahi iloko o ka ohana a pau a Iseraela.
Tún ju díẹ̀ nínú irun yìí sínú iná, kí o sun ún níná. Torí pé láti ibẹ̀ ni iná yóò ti jáde lọ sí gbogbo ilé Israẹli.
5 Ke i mai nei Iehova ka Haku, O Ierusalema keia; na hoonoho au ia ia iwaenakonu o na lahuikanaka, a me na aina e moe ana a puni ia.
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èyí ní Jerusalẹmu, tí mo gbé kalẹ̀ sí àárín àwọn Orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ìlú gbogbo tí o yí i ká.
6 A ua oi aku kona hoololi ana i ka'u pono i hewa mamua o ko na lahuikanaka, a me ko'u mau kanawai mamua o ko na aina e moe ana a puni ia; no ka mea, ua pale lakou i ka'u mau kauoha, a me ko'u mau kanawai, aole hoi i hele lakou ma ia mau mea.
Síbẹ̀ nínú ìwà búburú rẹ ó ti ṣọ̀tẹ̀ si òfin àti ìlànà mi ju àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn ilẹ̀ tó yí i ká lọ. Ó ti kọ òfin mi sílẹ̀, o kò sì pa ìlànà mi mọ́.
7 Nolaila, ke i mai nei Iehova ka Haku, penei; No ka mea, ua oi aku ka oukou lehulehu ana mamua o ko na lahuikanaka e kokoke mai ana a puni oe, aole nae oukou i hele ma ko'u mau kauawai, aole hoi i malama i a'u mau kauoha, aole hoi i hana mamuli o na kanawai o na lahuikanaka e kokoke mai ana a puni oukou:
“Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn ju àwọn orílẹ̀-èdè tó yí yín ká lọ, tí ẹ kò sì tẹ̀lé ìlànà mi tàbí kí o pa òfin mi mọ́. O kò tilẹ̀ túnṣe dáradára tó àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
8 Nolaila, ke i mai nei Iehova ka Haku penei; Owau, owau no kekahi eku e ia oe, a e hooko au i ke kanawai iwaenakonu ou, ma ke alo o na lahuikanaka.
“Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi gan an lòdì sí ọ, Jerusalẹmu, èmi yóò sì jẹ ọ́ ní yà lójú àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
9 A e hana aku au iloko ou i ka mea a'u i hana ole ai, i ka mea a'u e hana like ole hou aku ai, no kau mau mea i inainaia a pau.
Nítorí gbogbo ohun ìríra rẹ, èmi yóò ṣe ohun tí n kò tí ì ṣe rí láàrín rẹ àti èyí tí n kò ní í ṣe irú rẹ̀ mọ́.
10 No ia mea, e ai no na makuakane i na keiki iwaenakonu ou, a e ai no na keiki i ko lakou mau makuakane; a e hooko au i ke kanawai iloko ou, a e lulu aku i ke koena a pau ou i na makani a pau.
Nítorí náà láàrín rẹ àwọn baba yóò máa jẹ ọmọ wọn, àwọn ọmọ náà yóò máa jẹ baba wọn. Èmi yóò jẹ ọ́ ní yà, èmi yóò sì tú àwọn tó bá ṣẹ́kù ká sínú ẹ̀fúùfù.
11 Nolaila, ma ko'u ola ana, wahi a Iehova ka Haku, Oiaio, no kou hoohaumia ana i ko'u keenakapu, me kou mau mea i inainaia, a me kou mau mea hoopailua, nolaila e hoemi au ia oe, aole e aloha ko'u maka ia oe, aole hoi au e menemene aku ia oe.
Nítorí náà, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ṣe wà láààyè, nítorí pé ìwọ ti sọ ibi mímọ́ mi di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn àwòrán ẹ̀gbin àti àwọn ohun ìríra rẹ, èmi yóò mú ojúrere mi kúrò lára rẹ, èmi kò ní í da ọ sí, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò wò ọ́ pẹ̀lú àánú mọ́.
12 E make no kekahi hapakolu i ka mai ahulau, a me ka wi e hoopauia'e lakou iwaenakonu ou; a e haule kekahi hapakolu i ka pahikaua a puni oe; a e lulu aku au i kekahi hapakolu i na makani a pau, a e unuhi ae au i ka pahikaua mahope iho lakou.
Ìdámẹ́ta nínú àwọn ènìyàn rẹ yóò kú nípa àjàkálẹ̀-ààrùn tàbí kí ìyàn run wọ́n: ìdámẹ́ta yóò ṣubú nípa idà lẹ́yìn odi rẹ, èmi yóò sì tú ìdámẹ́ta yòókù ká sínú ẹ̀fúùfù, èmi yóò sì máa fi idà lé wọn.
13 Pela e hookoia'i ko'u huhu, e kau aku au i ko'u inaina maluna o lakou, a e hooluoluia au; a e ike lakou owau o Iehova ka i olelo aku ia mea i kuu manao lili ana, i ko'u hooko ana i kuu ukiuki maluna o lakou.
“Ìbínú mi yóò sì dúró, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú gbígbóná mi yóò sì rọlẹ̀, èmi yóò sì ti gba ẹ̀san mi. Nígbà tí mo bá sì parí ìbínú mi lórí wọn, wọn ó mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀ nínú ìtara mi.
14 A e hoolilo aku au ia oe i neoneo, a i mea e hoinoia iwaena o na lahuikanaka e kokoke mai ana a puni oe, ma na maka o na mea a pau e maalo ae ana.
“Èmi yóò fi ọ́ ṣòfò, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀gàn fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, àti lójú àwọn tó ń kọjá.
15 Pela e lilo ai ia i mea i hoinoia'i, i mea e aki ai, i mea e ao ai, a i mea e weliweli ai no na lahuikanaka e kokoke mai ana a puni oe, i kuu wa e hooko ai i ke kanawai iloko ou me ka huhu, a me ka ukiuki, a me ka papa ikaika aku Owau o Iehova ka i olelo aku.
O ó wá di ẹ̀gàn, ẹ̀sín àti ẹ̀kọ̀ àti ohun ẹ̀rù àti ìyanu fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, nígbà tí mo bá fìyà jẹ ọ́ nínú ìbínú àti nínú ìbínú gbígbóná mi. Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀.
16 I kuu hoouna ana i na pua ino o ka wi, i mea e luku ai ia lakou, o ka mea hoi a'u e hoouna aku ai e luku ia oukou; a e hoonui aku au i ka wi maluna o oukou, a e uhaki au i ko oukou kookoo o ka berena.
Nígbà tí èmi ó rán ọfà búburú ìyàn sí wọn, èyí tí yóò jẹ́ fún ìparun wọn. Èmí tí èmi yóò rán run yín. Èmí yóò sì sọ ìyàn di púpọ̀ fún yín. Èmí yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá oúnjẹ yín.
17 Pela e hoouna aku ai au maluna o oukou i ka wi, a me na holoholona ino, a e hoonele lakou ia oe; o ka mai ahulau, a me ke koko ke hele mawaena ou; a e lawe au i ka pahikaua maluna ou. Owau o Iehova ka i olelo aku.
Èmi yóò rán ìyàn àti ẹranko búburú sí i yín, wọn yóò fi yín sílẹ̀ ni àìlọ́mọ. Àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò kọjá láàrín yín. Èmi yóò si mú idà wá sórí rẹ. Èmi Olúwa ló sọ bẹ́ẹ̀.”