< Ezekiela 23 >

1 HIKI mai la ka olelo a Iehova ia'u, i mai la,
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 E ke keiki a ke kanaka, Elua aku la wahine, na kaikamahine a ka makuwahine hookahi:
“Ọmọ ènìyàn, obìnrin méjì wà, ọmọ ìyá kan náà.
3 Moe kolohe laua ma Aiguipita; moe kolohe laua i ko laua wa opiopio: malaila i kaomiia ko laua mau umauma, a malaila i paopao ai lakou i na omaka o ko laua puupaa ana.
Wọn ń ṣe panṣágà ní Ejibiti, wọn ń ṣe panṣágà láti ìgbà èwe wọn. Ní ilẹ̀ yẹn ni wọn ti fi ọwọ́ pa ọyàn wọn, níbẹ̀ ni wọn sì fọwọ́ pa igbá àyà èwe wọn.
4 A o ko laua mau inoa, o Ahola ke kaikuaana, a o Aholiba kona kaikaina; a na'u no laua, a ua hanau laua i na keikikaue a me na kaikamahine. Pela hoi ko laua mau inoa, o Ahola, o Samaria ia, a o Aholiba, o Ierusalema ia.
Èyí ẹ̀gbọ́n ń jẹ́ Ohola, àbúrò rẹ̀ sì ń jẹ́ Oholiba. Tèmi ni wọ́n, wọ́n sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin. Ohola ni Samaria, Oholiba sì ni Jerusalẹmu.
5 Moe kolohe aku la o Ahola i kona wa na'u, a hauoli no ia i kana mau ipo, ko Asuria kona hoalauna,
“Ohola ń ṣe panṣágà nígbà tí ó sì jẹ́ tèmi; Ó sì ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, àwọn jagunjagun ará Asiria.
6 I aahuia i ke kapa poni uliuli, na luna koa me na'lii, na kanaka ui e makemakeia lakou a pau, a hoohololio e holo ana maluna o na lio.
Aṣọ aláró ni a fi wọ̀ wọ́n, àwọn gómìnà àti àwọn balógun, gbogbo wọn jẹ́ ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà àwọn tí ń gun ẹṣin.
7 Pela ia i hana'i i kona moe kolohe ana me lakou, me ko Asuria poe a pau i waeia, a me ka poe a pau ana i hauoli ai; a me ko lakou mau akuakii a pau i hoohaumia ai oia ia ia iho.
O fi ara rẹ̀ fún gbajúmọ̀ ọkùnrin Asiria gẹ́gẹ́ bí panṣágà obìnrin, o fi òrìṣà gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́,
8 Aole hoi ia i haalele i kona moe kolohe ana mai Aigupita mai; no ka mea, i kona wa opiopio moe pu lakou me ia, a pepe iho la i na u o kona puupaa ana, a ua ninini aku i ko lakou moe kolohe ana maluna ona.
kò fi ìwà panṣágà tí ó ti bẹ̀rẹ̀, ni Ejibiti sílẹ̀, ní ìgbà èwe rẹ̀ àwọn ọkùnrin n bá a sùn, wọn fi ọwọ́ pa àyà èwe rẹ̀ lára wọn sì ń ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
9 Nolaila i haawi aku ai au ia ia iloko o ka lima o kana poe ipo, i ka lima o ko Asuria, na mea ana i hauoli ai.
“Nítorí náà mo fi i sílẹ̀ fún àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, ará Asiria, tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
10 Ua wehe lakou i kona wahi huna, a lalau hoi i kana mau kaikamahine, a pepehi iho la lakou ia ia me ka pahikaua; a kaulana aku la oia iwaena o na wahine, no ka mea, ua hoopai lakou ia ia.
Wọ́n bọ́ ọ sí ìhòhò, wọ́n sì gba àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọn sì pa wọn pẹ̀lú idà. Ó di ẹni ìfisọ̀rọ̀ sọ láàrín àwọn obìnrin wọ́n sì fi ìyà jẹ ẹ́.
11 A ike aku la kona kaikaina o Aholiba ia mea, ua oi aku kona hewa i kona kuko ana mamua ona, a i kona moe kolohe ana mamua o kona kaikuaana i kona moe kolohe ana.
“Àbúrò rẹ̀ Oholiba rí èyí, síbẹ̀ nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ̀, Ó ba ara rẹ jẹ́ ju ẹ̀gbọ́n rẹ̀ lọ.
12 Hauoli iho la oia i ko Asuria kona mau hoalauna, na luna koa a me na'lii kahiko nani ia, na hoohololio, e holo ana maluna o na lio, he poe kanaka ui lakou a pau e makemakeia.
Òun náà ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí ará Asiria àwọn gómìnà àti àwọn balógun, jagunjagun nínú aṣọ ogun, àwọn tí ń gun ẹṣin, gbogbo àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà.
13 Alaila ike aku la au ua haumia ia, hele pu hoi laua i ka aoao hookahi;
Mo rí i pé òun náà ba ara rẹ̀ jẹ́; àwọn méjèèjì rìn ojú ọ̀nà kan náà.
14 A ua hoomahuahua oia i kona moe kolohe ana; no ka mea, i kona ike ana i na kanaka i kakauia ma ka paia, o na kii o ko Kaledea i kakauia me ka pena ulaula,
“Ṣùgbọ́n ó tẹ̀síwájú nínú ṣíṣe panṣágà. O ri àwòrán àwọn ọkùnrin lára ògiri, àwòrán àwọn ara Kaldea àwòrán pupa,
15 Kaeiia hoi me na kaei ma ko lakou puhaka, nani hoi ko lakou lole hooluuia ma ko lakou mau poo, he poe alii lakou a pau i ka nana aku, ma ke ano o ko Babulona no Kaledea, ko lakou aina hanau:
pẹ̀lú ìgbànú ni ìdí wọn àti àwọn ìgbàrí ni orí wọn; gbogbo wọn dàbí olórí kẹ̀kẹ́ ogun Babeli ọmọ ìlú Kaldea.
16 A i kona ike ana ia lakou me kona mau maka, hauoli aku la oia ia lakou, a hoouna aku la i na elele io lakou la ma Kaledea.
Ní kété tí ó rí wọn, ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí wọn, ó sì rán oníṣẹ́ sí wọn ni Kaldea.
17 Hele mai la hoi ko Babela io na la iloko o ka moe aloha, a hoohaumia ia ia me ko lakou moe kolohe ana, a ua haumia oia ia lakou, a ua ku e kona manao ia lakou.
Àwọn ará Babeli wá sọ́dọ̀ rẹ̀, lórí ibùsùn ìfẹ́, nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wọn, wọ́n bà á jẹ́. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n bà á jẹ́ tán, ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn ní ìtìjú.
18 A pela i hoike ai oia i kona moe kolohe ana, a wehe hoi i kona wahi huna; alaila ku e ko'u manao ia ia, e like me ke ku e ana o ko'u naau i kona kaikuaana.
Nígbà tí ó tẹ̀síwájú nínú iṣẹ́ panṣágà rẹ̀ ní gbangba wọ́n sì tú u sí ìhòhò, mo yí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ ní ìtìjú, gẹ́gẹ́ bí mo ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
19 Ua hoomabuahua nae oia i kona moe kolohe ana, e hoomanao ana i na la o kona opiopio ana i moe kolohe ai i ka aina o Aigupita.
Síbẹ̀síbẹ̀ ó ń pọ̀ sí i nínú ìdàpọ̀ rẹ̀ bí ó ti ń rántí ìgbà èwe rẹ̀ tí ó jẹ́ panṣágà ní Ejibiti.
20 No ka mea, ua hauoli oia i kana mau ipo, o ko lakou io he like me ka io o na hoki, a o ko lakou kahe ana ua like me ko na lio kahe ana.
Nítorí ó fẹ́ olùfẹ́ àwọn olùfẹ́ wọn ní àfẹ́jù, tí àwọn tí nǹkan ọkùnrin wọn dàbí ti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ẹni tí ìtújáde ara wọn dàbí ti àwọn ẹṣin.
21 Pela i hoomanao ai oe i ka moe kolohe ana o kou wa opiopio, i ka pepe ana o kou mau omaka i ko Aigupita no na u o kou opiopio ana.
Báyìí ni ìwọ pe ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ìgbà èwe rẹ wá sí ìrántí, ní ti rírin orí ọmú rẹ láti ọwọ́ àwọn ará Ejibiti, fún ọmú ìgbà èwe rẹ.
22 Nolaila, e Aholiba, ke i mai nei Iehova ka Haku penei; E hooku ae au i kau mau ipo e ku e ia oe, na mea a kou naau i ku e ai, a e lawe mai au ia lakou e ku e ia oe a puni;
“Nítorí náà, Oholiba, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò gbé olólùfẹ́ rẹ dìde sí ọ, àwọn tí o kẹ́yìn si ní ìtìjú, èmi yóò sì mú wọn dojúkọ ọ́ ní gbogbo ọ̀nà
23 I ko Babulona, a me ko Kaledea a pau, o Pekoda, a me Soa, a me Koa, a me ko Asuria a pau me lakou; he poe kanaka ui i makemakeia lakou a pau na luna koa, me na'lii, a me na haku nui, a he kaulana hoi, e holo ana lakou a pau maluna o na lio.
àwọn ará Babeli àti gbogbo ara Kaldea àwọn ọkùnrin Pekodi àti Ṣoa àti Koa àti gbogbo ará Asiria pẹ̀lú wọn, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà, gbogbo àwọn gómìnà àti balógun, olórí oníkẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn onípò gíga, gbogbo àwọn tí ń gun ẹṣin.
24 A e hele ku e mai lakou ia oe me na kaa kaua, a me na kaa waiwai, a me na huila, a me ke anaina kanaka, e hoonoho ku e ia oe i ka pale kaua, i ka pale umauma, a me ka mahiole a puni; a e hoonoho aku au i ka hoopai ana imua o lakou, a e hoopai aku lakou ia oe mamuli o ko lakou hoopai ana.
Wọn yóò wa dojúkọ ọ pẹ̀lú ohun ìjà, kẹ̀kẹ́ ogun pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ẹrù àti pẹ̀lú ìwọ́jọpọ̀ ènìyàn; wọn yóò mú ìdúró wọn lòdì sí ọ ní gbogbo ọ̀nà pẹ̀lú asà ńlá àti kékeré pẹ̀lú àṣíborí. Èmi yóò yí ọ padà sí wọn fun ìjìyà, wọn yóò sì fi ìyà jẹ ọ gẹ́gẹ́ bí wọn tí tó.
25 A e hooku e au i ko'u lili ia oe, a hana lakou me ka ukiuki ia oe, a o kaili lakou i kou ihu a me kou mau pepeiao; a e haule kou koena i ka pahikaua; a e lawe lakou i kau mau keikikane a me kau mau kaikamahine; a e hoopauia kou koena i ke ahi.
Èmi yóò sì dojú ìbínú owú mi kọ ọ́, wọn yóò sì fìyà jẹ ọ́ ní ìrunú. Wọ́n yóò gé àwọn imú àti àwọn etí yín kúrò, àwọn tí ó kù nínú yín yóò ti ipá idà ṣubú. Wọn yóò mú àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọkùnrin yín lọ, àwọn tí o kù nínú yín ni iná yóò jórun.
26 E hemo hoi ia lakou kou mau kapa komo, a e kaili ae hoi lakou i kou mau mea nani e nani ai.
Wọn yóò sì kó àwọn aṣọ àti àwọn ohun ọ̀ṣọ́ iyebíye yín.
27 Pela e hooki ai au i kou moe haumia ana, mai ou aku, a me kou moe kolohe ana no Aigupita mai, i ole oe e leha hou ae i kou mau maka ia lakou, aole hoi e hoomanao hou aku ia Aigupita.
Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti iṣẹ́ panṣágà tí ẹ bẹ̀rẹ̀ ni Ejibiti. Ẹ̀yin kò ní wo àwọn nǹkan wọ̀nyí pẹ̀lú ìpòùngbẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò ní rántí Ejibiti mọ.
28 No ka mea, ke olelo nei Iehova ka Haku, penei; Aia hoi, e haawi aku au ia oe iloko o ka lima o ka poe au i hoowahawaha ai, a i ka lima o ka poe a kou naau i ku e ai.
“Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò fi ọ lé ọwọ́ àwọn tí ó kórìíra, lọ́wọ́ àwọn ẹni tí ọkàn rẹ ti ṣí kúrò.
29 A e hana aku lakou ia oe me ka inaina, a e lawe ae i kau mea i hana'i, a e waiho aku ia oe he olohelohe me ke kapa ole; a e akaka loa kou moe kolohe ana, o kou moe haumia ana a me kou hookamakama ana.
Wọn yóò fìyà jẹ ọ́ pẹ̀lú ìkórìíra, wọn yóò sì kó gbogbo ohun tí o ṣiṣẹ́ fún lọ. Wọn yóò fi ọ́ sílẹ̀ ní ìhòhò goloto, ìtìjú iṣẹ́ panṣágà rẹ ni yóò farahàn. Ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ̀ àti panṣágà rẹ.
30 E hana aku au i keia mau mea ia oe no kou hele moe kolohe ana mamuli o na lahuikanaka, a no kou haumia ana i ko lakou mau akuakii.
Èmi yóò ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí sí ọ, nítorí ìwọ ti bá àwọn kèfèrí ṣe àgbèrè lọ, o sì fi àwọn òrìṣà wọn ba ara rẹ̀ jẹ́.
31 Ua hele oe ma ka aoao o kou kaikuaana; nolaila e haawi aku ai au i kona kiaha iloko o kou lima.
Ìwọ ti rin ọ̀nà ti ẹ̀gbọ́n rẹ rìn, Èmi yóò sì fi ago rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́.
32 Olelo mai o Iehova ka Haku, penei; E inu no oe i ko ke kiaha o kou kaikuaana he hohonu a he nui; a e heneheneia oe a e akaakaia, no ka mea, he nui ko loko.
“Èyí yìí ní ohun ti Olúwa Olódùmarè wí: “Ìwọ yóò mu nínú ago ẹ̀gbọ́n rẹ, ago tí ó tóbi tí ó sì jinnú: yóò mú ìfiṣẹ̀sín àti ìfiṣe ẹlẹ́yà wá, nítorí tí ago náà gba nǹkan púpọ̀.
33 E piha auanei oe i ka ona a me ka ehaeha, me ke kiaha o ka makau a me ka neoneo, o ke kiaha o kou kaikuaana o ko Samaria.
Ìwọ yóò mu àmupara àti ìbànújẹ́, ago ìparun àti ìsọdahoro ago ẹ̀gbọ́n rẹ Samaria.
34 E inu no hoi oe ia mea, a e omo ae hoi, a e wahi no hoi oe i na apana ona, a e kaili ae i kou mau u ponoi; no ka mea, ua olelo au ia mea, wahi a Iehova ka Haku.
Ìwọ yóò mú un ni àmugbẹ; ìwọ yóò sì fọ sí wẹ́wẹ́ ìwọ yóò sì fa ọmú rẹ̀ ya. Èmi ti sọ̀rọ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
35 Nolaila, ke olelo mai nei Iehova, penei; No ka mea, ua hoopoina mai oe ia'u, a ua kiola oe ia'u mahope o kou kua; nolaila e halihali oe i kou moe haumia ana a me kou moe kolohe ana.
“Nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Níwọ́n bí ìwọ ti gbàgbé mi, tí ìwọ sì ti fi mi sí ẹ̀yìn rẹ, ìwọ gbọdọ̀ gba àbájáde ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ.”
36 Olelo hou mai la o Iehova ia'u, E ke keiki a ke kanaka, e hoahewa anei oe ia Ahola, a me Aholiba? oia, e hai aku oe ia laua i ko laua mea e inainaia;
Olúwa sọ fún mi pé: “Ọmọ ènìyàn, ń jẹ́ ìwọ yóò ṣe ìdájọ́ Ohola àti Oholiba? Nítorí náà dojúkọ wọn nípa ìkórìíra tí wọn ń ṣe,
37 No ka mea, ua moe kolohe laua, a he koko no iloko o ko laua mau lima, a me ko laua mau akuakii i moe kolohe ai laua, a ua hoohele laua i ka laua mau keiki i hanau na'u iwaena o ke ahi i mea ai na lakou.
nítorí wọn ti dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn. Wọn dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà pẹ̀lú àwọn òrìṣà wọn; kódà wọ́n fi àwọn ọmọ wọn tí wọn bí fún ni ṣe ìrúbọ, gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ fún wọn.
38 Eia hoi kekahi mea a lakou i hana mai ia'u, ua hoohaumia lakou i ko'u wahi hoano ia la hookahi, a ua hehi hoi i ko'u mau Sabati.
Bákan náà ni wọ́n ti ṣe èyí náà sí mi. Ní àkókò kan náà wọn ba ibi mímọ́ mi jẹ́, wọ́n sì lo ọjọ́ ìsinmi mi ní àìmọ́.
39 No ka mea, i ko laua pepehi aua i ka laua mau keiki, no ko laua mau akuakii, alaila hele mai laua ia la no, iloko o ko'u wahi hoano, e hoohaumia ia wahi; pela hoi i hana'i laua, ea, iwaenakonu o kuu hale!
Ní ọjọ́ náà gan an wọ́n fi àwọn ọmọ wọn rú ẹbọ sí àwọn òrìṣà, wọn wọ ibi mímọ́ mi lọ wọn sì lò ó ní ìlòkulò. Ìyẹn ní wọn ṣe ní ilé mi.
40 Eia hou hoi, ua kii aku olua i na kanaka e hele mai lakou mai kahi loihi mai, ia lakou i hoounaia'ku ai ka elele, oia hoi, ua hiki mai lakou; no lakou hoi i holoi ai oe ia oe iho, a pena hoi i kou mau maka, a kahiko hoi ia oe iho me na mea e nani ai.
“Wọn tilẹ̀ rán oníṣẹ́ sí àwọn ènìyàn tí wọ́n wá láti ọ̀nà jíjìn, nígbà tí wọ́n dé, ìwọ wẹ ara rẹ fún wọn, ìwọ kún ojú rẹ, ìwọ sì fi ọ̀ṣọ́ iyebíye sára.
41 A noho no oe maluna o kahi moe nui, a he papa i hoomakaukauia imua ona, maluna iho hoi i hoonoho ai oe i kuu mea ala, a me kuu aila.
Ìwọ jókòó lórí ibùsùn ti o lẹ́wà, pẹ̀lú tábìlì tí a tẹ́ ní iwájú rẹ lórí, èyí tí o gbé tùràrí àti òróró tí ó jẹ́ tèmi kà.
42 A o ka leo o ke anaina e nanea ana kekahi me ia, a ua lawe pu ia na makaainana me ka poe ona, mai ka waonahele mai, ua kau lakou i na kupee ma ko lakou mau lima, a me na lei nani maluna o ko lakou mau poo.
“Ariwo ìjọ ènìyàn tí kò bìkítà wà ní àyíká rẹ̀; a mú àwọn ara Sabeani láti aginjù pẹ̀lú àwọn ọkùnrin láti ara àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn aláìníláárí, wọ́n sì mú àwọn ẹ̀gbà ọrùn ọwọ́ sí àwọn ọwọ́ obìnrin náà àti ẹ̀gbọ́n rẹ̀, adé dáradára sì wà ní orí wọn.
43 Alaila olelo iho au no ka mea kahiko ma ka moe kolohe ana, E moe kolohe anei lakou mo ia, a oia pu hoi me lakou?
Lẹ́yìn náà mo sọ̀rọ̀ nípa èyí tí ó lo ara rẹ̀ sá nípa panṣágà ṣíṣe, ‘Nísinsin yìí jẹ kí wọn lo o bí panṣágà, nítorí gbogbo ohun tí ó jẹ́ nìyẹn.’
44 Aka, komo iloko lakou io na la e like me ko lakou hele ana ae iloko i ka wahine hookamakama; pela e komo ai lakou iloko io Ahola la, a io Aholiba la i na wahine moe haumia.
Wọn ba sùn bí ọkùnrin ti bá panṣágà sùn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe sùn pẹ̀lú obìnrin onífẹ̀kúfẹ̀ẹ́, Ohola àti Oholiba.
45 A o na kanaka pono, e hoahewa lakou ia laua e like me ka lakou hoahewa ana i na wahine moe kolohe, a mamuli hoi o ke ano o na wahine hookahe i ke koko; no ka mea, he mau wahine moe kolohe laua a he koko ko loko o ko laua mau lima.
Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin olódodo yóò pàṣẹ pé kí wọ́n fi ìyà jẹ àwọn obìnrin tí ó dá ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè tí ó sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ nítorí pé panṣágà ni wọ́n ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn.
46 No ka mea, ke olelo mai nei Iehova ka Haku penei; E lawe mai au i ka lehulehu maluna o laua, a e haawi aku au ia laua e laweia'ku a eha oia.
“Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Mú àgbájọ àwọn ènìyànkénìyàn wá sọ́dọ̀ wọn ki ó sì fi wọn lé ọwọ́ ìpayà àti ìkógun.
47 A e hailuku aku ke anaina ia laua me na pohaku, a e kua iho ia laua ilalo me ka lakou mau pahikaua, e luku lakou i ka laua mau keiki kane a me ka laua mau kaikamahine, a e hoopau i ko laua mau hale me ke ahi.
Àwọn ènìyànkénìyàn náà yóò sọ wọ́n ni òkúta, yóò sì gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà wọn; wọn ó sì pa àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn, wọ́n ó sì jó àwọn ilé wọn kanlẹ̀.”
48 Pela e hoopau aku ai au i ka moe kolohe, mai ka aina aku, i aoia'ku ai na wahine a pau aole e hana mamuli o ko olua moe kolohe ana.
“Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ni ilẹ̀ náà, kí gbogbo àwọn obìnrin le gba ìkìlọ̀ kí wọn kí ó ma sì ṣe fi ara wé ọ.
49 A e uku lakou i ko olua moe kolohe ana maluna o olua, a e halihali olua i na hewa o ko olua mau akuakii; a e ike no oukou owau no Iehova ka Haku.
Ìwọ yóò sì jìyà fún ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, ìwọ yóò sì gba àbájáde àwọn ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà tí o dá. Nígbà náà ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.”

< Ezekiela 23 >