< Pukaana 6 >

1 ALAILA olelo mai la o Iehova ia Mose, Ano, e ike auanei oe i ka mea a'u e hana aku ai ia Parao: no ka mea, e hookuu aku no oia ia lakou me ka lima ikaika, a me ka lima ikaika hoi oia e kipaku aku ai ia lakou, mai kona aina aku.
Nígbà náà ní Olúwa sọ fún Mose pé, “Ní ìsin yìí, ìwọ yóò rí ohun tí èmi yóò ṣe sí Farao pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá mi ni yóò fi jẹ́ kí wọn lọ; pẹ̀lú ọwọ́ agbára ńlá mi, òun yóò lé wọn jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ̀.”
2 Olelo mai la ke Akua ia Mose, i mai la ia ia, Owau no o Iehova.
Ọlọ́run sì tún sọ fún Mose pé, “Èmi ni Olúwa.
3 Hoike aku wau ia'u iho ia Aberahama, ia Isaaka, a ia Iakoba, o ke Akua Mana; aka, ma ko'u inoa, o IEHOVA, aole au i ikeia mai e lakou.
Mo fi ara hàn Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu bí Ọlọ́run alágbára, ṣùgbọ́n nípa orúkọ mi Olúwa, Èmi kò fi ara mi hàn wọ́n.
4 Ua hoopaa no hoi au i kuu berita me lakou, e haawi aku ai no lakou i ka aina o Kanaana, i ka aina i noho ai lakou, he mau malihini ilaila.
Èmí sì tún fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú wọn láti fún wọn ní ilẹ̀ Kenaani, ilẹ̀ tí wọn gbé gẹ́gẹ́ bí àjèjì.
5 Ua lohe hoi au i ka uu ana o na mamo a Iseraela, o ka poe i hooluhiia'i e ko Aigupita; a ua hoomanao wau i kuu berita.
Èmi sì ti tún gbọ́ kíkùn àwọn ọmọ Israẹli àwọn tí àwọn ará Ejibiti mú gẹ́gẹ́ bí ẹrú, àti pé èmi sì ti rántí májẹ̀mú mi.
6 No ia mea, e olelo aku oe i na mamo a Iseraela, Owau no Iehova, a e lawe mai ana no wau ia oukou mailalo mai o na mea kaumaha a ko Aigupita, a e hoopakele no wau ia oukou i ko lakou hooluhi ana; a e hoola wau ia oukou me ka lima kakauha, a me na hoopai ana he nui loa.
“Sọ fún àwọn ará ilé Israẹli, ‘Èmi ni Olúwa, Èmi yóò sọ yín di òmìnira kúrò nínú àjàgà àwọn ará Ejibiti. Èmi yóò sì gbà yín sílẹ̀ kúrò ní oko ẹrú wọn. Èmi yóò dá a yín sílẹ̀ pẹ̀lú apá nínà (àwọn iṣẹ́ ìyanu) àti pẹ̀lú ìdájọ́ ńlá.
7 A e hoonoho no wau ia oukou i poe kanaka no'u, a owau auanei hoi ko oukou Akua: a e ike auanei hoi oukou, owau no Iehova, o ko oukou Akua, nana oukou e lawe ae, mailalo ae o na mea kaumaha a ko Aigupita.
Èmi yóò mú un yín bí ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, ẹni tí ó mú un yín jáde kúrò nínú àjàgà àwọn ará Ejibiti.
8 A e lawe aku no au ia oukou i ka aina a'u i pai ai i ko'u lima, e haawi aku ia wahi no Aberahama, no Isaaka a no Iakoba, oia ka'u e haawi aku ai no oukou i wahi e noho ai: owau no Iehova.
Èmi yóò mú un yín wá ilẹ̀ náà ti èmi ti búra pẹ̀lú ìgbọ́wọ́sókè láti fi fún Abrahamu. Isaaki àti Jakọbu. Èmi yóò fi fún un yín bí ohun ìní, Èmi ni Olúwa.’”
9 Pela no hoi o Mose i olelo aku ai i na mamo a Iseraela: aole nae lakou i hoolohe i ka Mose, no ka ehaeha o ka naau, a no ka luhi koikoi.
Mose sì sọ èyí fún àwọn ará Israẹli, ṣùgbọ́n wọn kò fi etí sílẹ̀ sí Mose nítorí ọkàn wọn tó rẹ̀wẹ̀sì àti nítorí ìgbèkùn búburú bí ohun tí ó ti kọ́ sọ kó wọn sí ní oko ẹrú wọn.
10 Olelo mai la o Iehova ia Mose, i mai la,
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose.
11 E hele oe, e olelo aku ia Parao i ke alii o Aigupita, e hookuu aku oia i na mamo a Iseraela mai kona aina aku.
“Lọ, sọ fún Farao ọba Ejibiti pé kí ó jẹ́ kí àwọn ará Israẹli lọ kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ̀.”
12 Olelo aku o Mose imua o Iehova, i aku la, Aia hoi, aole i hoolohe mai na mamo a Iseraela ia'u, pehea la hoi e hoolohe mai ai o Parao ia'u, i ka mea lehelehe hemahema?
Ṣùgbọ́n Mose sọ fún Olúwa pé, “Nígbà ti àwọn ará Israẹli tó jẹ́ ènìyàn mi kó fetí sí ọ̀rọ̀ mi, báwo ni Farao yóò ṣe fetí sí ọ̀rọ̀ mi, nígbà ti mo jẹ́ akólòlò?”
13 Olelo mai la o Iehova ia Mose a ia Aarona, a hoouna ia laua i na mamo a Iseraela, a ia Parao, no ka lawe ana mai i na mamo a Iseraela mai ka aina mai o Aigupita.
Olúwa bá ìran Mose àti Aaroni sọ̀rọ̀ nípa àwọn ará Israẹli àti Farao ọba Ejibiti, ó pàṣẹ fún wọn pé kí wọn kó àwọn Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.
14 Eia hoi na mea mua o ko lakou mau ohana kupuna: O na keiki a Reubena, a ka hiapo a Iseraela; o Hanoka, o Palu, o Hezerona, a o Karemi: o lakou na ohana a Reubena.
Wọ̀nyí ni olórí ìran wọn: àwọn ọmọ Reubeni àkọ́bí Israẹli ni: Hanoku, Pallu, Hesroni àti Karmi. Àwọn wọ̀nyí ni ìdílé Reubeni.
15 A o na keiki a Simeona; o Iemuela, a o Iamina, o Ohada, o Iakina, o Zohara, a o Saula ke keiki a kekahi wahine Kanaana: o lakou na ohana a Simeona.
Àwọn ọmọ Simeoni ni: Jemueli, Jamini, Ohadi, Jakini, Sohari àti Saulu ọmọ obìnrin Kenaani. Àwọn wọ̀nyí ni ìran Simeoni.
16 Eia hoi na inoa o na keiki a Levi, ma ko lakou mau hanauna: o Geresona, o Kohata, a o Merari: a o na makahiki o ko Levi ola ana, hookahi haneri me kanakolukumamahiku na makahiki.
Ìwọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ wọn: Gerṣoni, Kohati àti Merari. Lefi lo ẹ̀tàdínlógóje ọdún láyé.
17 O na keiki a Geresona, o Libeni, a o Simi, ma ka laua mau ohana.
Àwọn ọmọ Gerṣoni ni ìran wọn ni: Libni àti Ṣimei.
18 A o na keiki a Kohata; o Amerama, o Izehara, o Heberona, a me Uziela: a o na makahiki o ko Kohata ola ana, hookahi haneri me kanakolukumamakolu na makahiki.
Àwọn ọmọ Kohati ni: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli. Kohati lo ẹ̀tàléláádóje ọdún láyé.
19 A o na keiki a Merari; o Mahali a o Musi: o lakou nei na ohana a Levi, ma na hanauna o lakou.
Àwọn ọmọ Merari ni: Mahili àti Muṣi. Ìwọ̀nyí ni ìran Lefi gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ wọn.
20 Lawe iho la o Amerama ia Iokebeda, i ke kaikuwahine o kona makuakane, i wahine nana; a hanau mai la nana o Aarona laua o Mose: a o na makahiki o ko Amerama ola ana, hookahi haneri me kanakolukumamahiku na makahiki.
Amramu sì fẹ́ Jokebedi arábìnrin baba rẹ̀ ní ìyàwó. Jokebedi sì bí Aaroni àti Mose fún un. Amramu lo ẹ̀tàdínlógóje ọdún láyé.
21 A o na keiki a Izehara, o Kora, o Nepega, a me Zikeri.
Àwọn ọmọ Isari ni: Kora, Nefegi àti Sikri.
22 A o na keiki a Uziela; o Misaela, o Elezapana, a me Ziteri.
Àwọn ọmọ Usieli ni: Miṣaeli, Elsafani àti Sitiri.
23 Lawe ae la o Aarona ia Eliseba, i ke kaikamahine a Aminadaba, o ke kaikuwahine o Nahesona i wahine nana, a hanau mai la nana, o Nadaba, o Abihu, o Eleazara a me Itamara.
Aaroni fẹ́ Eliṣeba ọmọbìnrin Amminadabu tí í ṣe arábìnrin Nahiṣoni, ó sì bí Nadabu, Abihu, Eleasari àti Itamari.
24 A o na keiki a Kora; o Asira, o Elekana, a o Abiasapa; o lakou na ohana a Kora.
Àwọn ọmọ Kora ni: Asiri, Elkana àti Abiasafu. Ìwọ̀nyí ni ìran Kora.
25 Lawe ae la o Eleazara ke keiki a Aarona i kekahi kaikamahine a Putiela i wahine nana: a ua hanau mai nana o Pinehasa; o lakou na mea mua o na makua o ka Levi, ma ka lakou mau ohana.
Eleasari ọmọ Aaroni fẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọbìnrin Putieli ní ìyàwó, ó sì bí Finehasi fún un. Ìwọ̀nyí ni olórí àwọn Lefi ni ìdílé ìdílé.
26 Oia o ua Aarona la laua o ua Mose la, na mea a Iehova i olelo mai ai, E lawe mai olua i na mamo a Iseraela mai Aigupita mai, ma ko lakou poe kaua.
Aaroni àti Mose yìí kan náà ni Olúwa sọ fún pé, “Ẹ kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti ní ìsọ̀rí ìsọ̀rí.”
27 O laua no na mea i olelo ia Parao i ke alii o Aigupita, no ka lawe ana mai i na mamo a Iseraela, mai Aigupita mai: o ua Mose la no keia laua o Aarona.
Àwọn ni ó bá Farao ọba Ejibiti sọ̀rọ̀ nípa kíkó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni Ejibiti, àní Mose àti Aaroni yìí kan náà ni.
28 A i ka la a Iehova i olelo mai ai ia Mose ma ka aina o Aigupita,
Nígbà tí Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ni Ejibiti,
29 Olelo mai la o Iehova ia Mose, i mai la, Owau no Iehova: e hai aku oe ia Parao i ke alii o Aigupita, i na mea a pau a'u e olelo aku ai ia oe.
Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Èmi ni Olúwa. Sọ ohun gbogbo ti mo ti sọ fún ọ fún Farao ọba Ejibiti.”
30 Olelo aku o Mose imua o Iehova, Aia hoi, he lehelehe hemahema ko'u, pehea la e hoolohe mai ai o Parao ia'u?
Ṣùgbọ́n Mose sì wí ní iwájú Olúwa pé, “Níwọ́n ìgbà ti mo jẹ́ akólòlò, ọ̀nà dà ti Farao yóò ṣe fi etí sí mi?”

< Pukaana 6 >