< Pukaana 14 >

1 OLELO mai la o Iehova ia Mose, i mai la,
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 E i aku oe i na mamo a Iseraela, e kipa ae lakou, a e hoomoana ma ke alo o Pihahirota, mawaena o Migedola a me ke kai, ma kahi e ku pono ana i Baalazepona: ma ke alo o ia wahi oukou e hoomoana ai, ma kahakai.
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí wọn padà sẹ́yìn, kí wọ́n sì pàgọ́ sí tòsí Pi-Hahirotu láàrín Migdoli òun Òkun, kí wọn kí ó pàgọ́ sí ẹ̀bá Òkun, ní òdìkejì Baali-Ṣefoni.
3 E olelo auanei o Parao no na mamo a Iseraela, Ua pilikia lakou iloko o ua aina la, ua paa lakou i ka waonahele.
Farao yóò ronú pé àwọn ọmọ Israẹli ń ráre káàkiri ní ìdààmú ni àti wí pé aginjù náà ti sé wọn mọ́.
4 A na'u no e hoopaakiki i ka naau o Parao, i hahai mai ai oia mahope o lakou: a e hoouaniia auanei au maluna o Parao, a maluna o kona puali a pau; i ike ai hoi ko Aigupita, owau no Iehova. A pela no lakou i hana'i.
Èmi yóò sé ọkàn Farao le ti yóò fi lépa wọn. Ṣùgbọ́n èmi yóò gba ògo fún ará mi láti ìpàṣẹ Farao àti ogun rẹ̀, àti pé àwọn ará Ejibiti yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.” Àwọn Israẹli sì ṣe bẹ́ẹ̀.
5 A haiia aku la i ke alii o Aigupita, Ua holo na kanaka; huli ka naau o Parao a me na kauwa ana e ku e i na kanaka: olelo iho la lakou, no ke aha la kakou i hana'i i keia, a hookuu aku i ka Iseraela i hookauwa ole ai lakou na kakou?
Nígbà tí wọ́n sọ fún ọba Ejibiti pé àwọn ènìyàn náà ti sálọ, ọkàn Farao àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ yí padà sí àwọn ènìyàn, wọ́n sì wí pé, “Kí ni ohun tí àwa ṣe yìí? Àwa ti jẹ́ kí àwọn ọmọ Israẹli kí ó lọ, a sì ti pàdánù ìsìnrú wọn.”
6 Hoomakaukau ae la ia i kona kaakaua, a lawe pu aku la i kona poe kanaka me ia.
Ó sì di kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀, ó sì kó àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀,
7 Lawe aku la ia i na halekaa i waeia eono haneri, a me na kaakaua a pau o Aigupita, a me na luna o ia mau mea a pau.
ó mú ẹgbẹ̀ta ọmọ-ogun oníkẹ̀kẹ́ tí ó jáfáfá jùlọ àti gbogbo ọmọ-ogun oníkẹ̀kẹ́ mìíràn ní Ejibiti, olórí sì wà fún olúkúlùkù wọn.
8 Hoopaakiki iho la o Iehova i ka naau o Parao, o ke alii o Aigupita, a hahai mai la ia mahope o na mamo a Iseraela: a puka mai la na mamo a Iseraela mawaho me ka lima hookiekie.
Olúwa sé ọkàn Farao ọba Ejibiti le, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí lépa àwọn ọmọ Israẹli ti ń jáde lọ ní àìbẹ̀rù.
9 Hahai mai la ko Aigupita mahope o lakou, o na lio a pau, a me na kaakaua o Parao, a me kona hoohololio, a me kona poe koa, a loaa mai lakou nei e hoomoana ana ma kahakai, ma Pihahirota, e ku pono ana i Baalazepona.
Àwọn ará Ejibiti ń lépa wọn pẹ̀lú gbogbo ẹṣin kẹ̀kẹ́ ogun Farao àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀, wọ́n sì lé wọn bá ni ibi tí wọ́n pa àgọ́ sí lẹ́bàá òkun ní ìhà Pi-Hahirotu, ni òdìkejì Baali-Ṣefoni.
10 A hookokoke mai la o Parao, alawa ae la na maka o na mamo a Iseraela, aia hoi, e hele mai ana ko Aigupita mahope o lakou; makau loa iho la lakou: a uwe aku la na mamo a Iseraela ia Iehova.
Bí Farao ti súnmọ́ tòsí ọ̀dọ̀ wọn, àwọn ọmọ Israẹli gbé ojú wọn sókè, wọn sì rí àwọn ará Ejibiti tó súnmọ́ wọn. Ẹ̀rù ńlá sì bá àwọn ará Israẹli, wọ́n kígbe sókè sí Olúwa.
11 I mai la hoi lakou ia Mose, No ka mea, aohe lua kupapau ma Aigupita, ua lawe mai anei oe ia makou e make ma keia waonahele? No ke aha la kau i hana mai ai ia makou pela, i ka lawe ana mai nei ia makou mai Aigupita mai?
Wọ́n sọ fún Mose pé, “Ṣe nítorí pé kò sí ibojì ni Ejibiti ní ìwọ ṣe mú wa wá láti kú sínú aginjù? Kí ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa ti ìwọ fi mú wa jáde láti Ejibiti wá?
12 Aole anei keia o ka olelo a makou i hai aku ai ia oe ma Aigupita, i ka i ana aku, E waiho pela ia makou, i hookauwa aku ai makou na ko Aigupita? No ka mea, he mea maikai no makou ke hookauwa aku na ko Aigupita, aole hoi e make ma ka waonahele.
Ǹjẹ́ èyí kọ́ ni àwa sọ fún ọ ni Ejibiti, ‘Fi wá sílẹ̀, jẹ́ kí àwa máa sin ará Ejibiti’? Nítorí kò bá sàn fún wa kí a sin àwọn ará Ejibiti ju kí a kú sínú aginjù yìí lọ!”
13 Olelo aku la o Mose i na kanaka, mai makau oukou, e ku malie oukou, a e nana aku i ka hoola ana o Iehova, i ka mea ana e hoike mai ai ia oukou i keia la; no ka mea, o ko Aigupita a oukou i ike ai i keia la, aole oukou e ike hou ia lakou, mahope mau loa aku.
Nígbà náà ni Mose sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ má bẹ̀rù, ẹ dúró ṣinṣin kí ẹ sì rí ìdáǹdè tí Olúwa yóò fi fún un yín lónìí, àwọn ará Ejibiti ti ẹ̀yin rí lónìí ni ẹ kò ni tún padà rí wọn mọ́.
14 Na Iehova no e kaua aku no oukou, a e noho malie oukou.
Olúwa yóò jà fún un yín; kí ẹ̀yin kí ó sá à mu sùúrù.”
15 I mai la o Iehova ia Mose, No ke ah a la oe e kahea mai nei ia'u? e i aku oe i na mamo a Iseraela, e hele aku lakou imua.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń ké pè mí? Sọ fún àwọn ará Israẹli kí wọn máa tẹ̀síwájú.
16 Aka, E hapai oe i kou kookoo, a e o aku kou lima maluna o ke kai, a e hookaawale ia: a e hele aku no na mamo o Iseraela mawaena o ke kai, ma kahi maloo.
Ṣùgbọ́n, gbé ọ̀pá rẹ̀ sókè, kí o sì na ọwọ́ rẹ sí orí omi Òkun, kí ó lè pín ní yà kí àwọn ọmọ Israẹli lè la òkun kọjá ni orí ìyàngbẹ ilẹ̀.
17 A na'u iho no e hoopaakiki i na naau o ko Aigupita, a e hahai mai lakou mahope o lakou nei: a e hoonani au ia'u iho ma o Parao la a ma kona poe koa a pau, a ma kona mau kaakaua, a me na hoohololio ona.
Nígbà náà ni èmi yóò sé ọkàn àwọn ará Ejibiti le, wọn yóò sì máa lépa wọn; Èmi yóò gba ògo fún ara mi lórí Farao; lórí gbogbo ogun rẹ̀, lórí kẹ̀kẹ́ ogun àti lórí àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.
18 A e ike auanei ko Aigupita, owau no Iehova, ke hoonani wau ia'u iho ma o Parao la, a me kona mau kaakaua, a me na hoohololio ona.
Àwọn ará Ejibiti yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa nígbà ti èmi bá gba ògo fún ara mi lórí Farao: lórí kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ àti lórí àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.”
19 A o ka anela o ke Akua i hele mamua o ke kahua hoomoana o ka Iseraela, hoi aku la ia mahope o lakou; a hele ae la hoi ke kia ao mai mua ao o lakou, a ku iho la mahope o lakou.
Nígbà náà ni angẹli Ọlọ́run tó ti ń ṣáájú ogun Israẹli lọ, padà o sì rìn ni ẹ̀yìn wọn; Òpó ìkùùkuu tí ń rìn ni iwájú wọn sì padà sí í rìn ni ẹ̀yìn wọn.
20 Hele mai la ia mawaena o ko Aigupita poe a me ka Iseraela: a lilo ia i ao pouli; a hoomalamalama mai no nae i ka po; nolaila, aole i hookokoke mai kela poe i keia mai ia po a ao.
Ó sì wà láàrín àwọn ọmọ-ogun Ejibiti àti Israẹli. Ìkùùkuu sì ṣú òkùnkùn sí àwọn ará Ejibiti ni òru náà. Ṣùgbọ́n ó tan ìmọ́lẹ̀ sí àwọn Israẹli ni òru náà, ọ̀kan kò sì súnmọ́ èkejì ni gbogbo òru náà.
21 O aku la o Mose i kona lima maluna o ke kai; na Iehova i hookahe ke kai me ka makani ikaika, mai ka hikina mai, i kela po a ao, a lilo iho la ke kai i aina maloo, a ua maheleia ae la na wai.
Nígbà náà ni Mose na ọwọ́ rẹ̀ sí orí Òkun, ni gbogbo òru náà ni Olúwa fi lé òkun sẹ́yìn pẹ̀lú ìjì líle láti ìlà-oòrùn wá, ó sì sọ ọ́ di ìyàngbẹ ilẹ̀. Omi òkun sì pínyà,
22 Hele mai la na mamo a Iseraela mawaena o ke kai ma kahi maloo: a lilo ka wai i pali no lakou ma ko lakou lima akau a me ko lakou lima hema.
àwọn ọmọ Israẹli sì la ìyàngbẹ ilẹ̀ kọjá nínú òkun pẹ̀lú ògiri omi ní ọ̀tún àti òsì.
23 Hahai mai la ko Aigupita, a hele mai mahope o lakou, o na lio a pau o Parao, a me kona mau kaakaua, a me na hoohololio iwaena o ke kai.
Àwọn ará Ejibiti sì ń lépa wọn, gbogbo ẹṣin Farao, kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀ wọ́ tọ̀ wọ́n lọ sínú òkun.
24 A hiki i ka wati wanaao, nana mai la o Iehova i ka poe kaua o Aigupita, mai ke kia ahi a me ke ao mai, a hoopilikia ae la i ka poe kaua o Aigupita.
Ní ìṣọ́ òwúrọ̀ Olúwa bojú wo ogun àwọn ará Ejibiti láàrín ọ̀wọ̀n iná àti ìkùùkuu, ó sì kó ìpayà bá àwọn ọmọ-ogun Ejibiti.
25 Hoohemohemo iho la ia i na huila o ko lakou mau kaakaua, i hele pupu ai lakou; no ia mea, olelo mai la ko Aigupita, E auhee kakou mai ke alo aku o ka Iseraela; no ka mea, ua kaua mai no o Iehova me lakou pu i ko Aigupita.
Ó sì yọ àgbá ẹsẹ̀ kẹ̀kẹ́ ogun wọn kí ó bá à le ṣòro fún wọn láti fi kẹ̀kẹ́ ogun náà rìn. Àwọn ará Ejibiti wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sá àsálà kúrò ní iwájú àwọn ará Israẹli nítorí Olúwa ń bá wa jà nítorí wọn.”
26 Olelo mai la o Iehova ia Mose, E o aku kou lima maluna o ke kai, i hoi hou mai ai ka wai maluna o ko Aigupita, maluna o ko lakou mau halekaa, a maluna o ko lakou poe hoohololio.
Olúwa sì wí fún Mose pé, “Na ọwọ́ rẹ sí orí òkun kí omi òkun lè ya padà sórí àwọn ará Ejibiti, kẹ̀kẹ́ ogun wọn àti sórí ẹlẹ́ṣin wọn.”
27 Hoo aku la no o Mose i kona lima maluna o ke kai, a hoi mai no ke kai i kona piha ana i ka wa e pualena ana o ke ao; auhee aku la ko Aigupita i ka loaa ana o ka wai; a lulu iho la o Iehova i ko Aigupita iloko o ke kai.
Mose sì na ọwọ́ rẹ̀ sí orí òkun, òkun sì padà bọ́ sí ipò rẹ̀ nígbà ti ilẹ̀ mọ́. Àwọn ará Ejibiti ń sá fún omi òkun, Olúwa sì gbá wọn sínú òkun.
28 Hoi hou aku la ke kai, a popoi iho la maluna o na kaakaua, a me na hoohololio, a me ka poe koa a pau o Parao i hele mai iloko o ke kai mahope o lakou: aole loa kekahi o lakou i koe.
Omi òkun sì ya padà, ó sì bo kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin: àní, gbogbo ọmọ-ogun Farao tiwọn wọ inú òkun tọ àwọn ọmọ Israẹli lọ kò sí ọ̀kan nínú wọn tí ó yè.
29 Aka, o na mamo a Iseraela, hele mai la lakou ma kahi maloo iwaenakonu o ke kai: a o na wai, he pali ia no lakou ma ko lakou lima akau, a me ko lakou lima hema.
Ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli la òkun kọjá lórí ìyàngbẹ ilẹ̀ pẹ̀lú ògiri omi ni ọ̀tún àti òsì wọn.
30 Pela i hoola mai ai o Iehova i ka Iseraela ia la, mai ka lima o ko Aigupita mai; a ike aku la ka Iseraela i ko Aigupita maluna o kahakai, ua make.
Ni ọjọ́ yìí ni Olúwa gba Israẹli là kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti; Israẹli sì rí òkú àwọn ará Ejibiti ni etí òkun.
31 Ike aku la ka Iseraela i kela hana nui a Iehova i hana aku ai i ko Aigupita: a makau iho la na kanaka ia Iehova; a manaoio aku la lakou ia Iehova, a me kana kauwa o Mose.
Nígbà ti àwọn ọmọ Israẹli rí iṣẹ́ ìyanu ńlá ti Olúwa ṣe fún wọn lára àwọn ará Ejibiti, àwọn ènìyàn bẹ̀rù Olúwa, wọ́n sì gba Olúwa àti Mose ìránṣẹ́ rẹ gbọ́.

< Pukaana 14 >