< Kanawailua 1 >

1 EIA na olelo a Mose i olelo aku ai i ka Iseraela a pau ma keia aoao o Ioredane, ma ka waonahele, ma ka papu e ku pono ana i Zupa, mawaena o Parana a me Topela, a me Labana, a me Hazerota, a me Dizahaba.
Wọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ tí Mose sọ fún gbogbo Israẹli ní aginjù, aginjù ìlà-oòrùn Jordani, ni Arabah, ní òdìkejì Ṣufi, ní àárín Parani àti Tofeli, Labani, Haserotu àti Disahabu.
2 (He umikumamakahi la hele mai Horeba, ma ke ala o Mauna Seira, a hiki i Kadesabanea.)
(Ọjọ́ mọ́kànlá ni ó gbà láti rin ìrìnàjò láti Horebu dé Kadeṣi-Barnea, bí a bá gba ọ̀nà òkè Seiri.)
3 A i ka makahiki kanaha, i ka malama umikumamakahi, i ka la mua o ka malama, olelo aku la o Mose i na mamo a Iseraela, e like me na mea a pau a Iehova i kauoha mai ai ia ia no lakou;
Ní ìgbà tí ó pé ogójì ọdún, ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kọ́kànlá, Mose sọ ohun gbogbo tí Olúwa pàṣẹ nípa àwọn ọmọ Israẹli fún wọn.
4 Mahope iho o kana pepehi ana ia Sihona ke alii o ka Amora, ka mea i noho ma Hesebona, a ia Oga ke alii o Basana, ka mea i noho ma Asetarota i Ederei:
Èyí ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣẹ́gun Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani ni ó ṣẹ́gun ní Edrei, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu.
5 Ma keia aoao o Ioredane, ma ka aina o Moaba, i hoomaka'i o Mose e hai aku i keia kanawai, i aku la,
Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani tí ó wà nínú ilẹ̀ Moabu ni Mose bẹ̀rẹ̀ sísọ àsọyé òfin wọ̀nyí wí pé:
6 Olelo mai la o Iehova ko kakou Akua ia kakou ma Horeba, i mai la, Ua loihi ko oukou noho ana ma keia mauna:
Olúwa Ọlọ́run wa bá wa sọ̀rọ̀ ní Horebu pé, “Ẹ ti dúró ní orí òkè yìí pẹ́ tó.
7 E huli ae oukou, a i ka hele ana, e hele oukou i ka mauna o ka Amora, a i kona poe e noho ana a pau, ma na papu, ma na puu, a ma ke awawa, a ma ke kukuluhema, a ma kahakai, i ka aina o ko Kanaana, a i Lebanona, a i ka muliwai nui, ka muliwai o Euperate.
Ẹ yípadà kí ẹ sì tẹ̀síwájú ní ìrìnàjò yín lọ sí ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, ẹ tọ gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń gbé Arabah lọ ní aginjù, ní àwọn orí òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀, ní gúúsù àti ní etí Òkun, lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kenaani àti lọ sí Lebanoni, títí fi dé odò ńlá Eufurate.
8 Aia hoi, ua haawi aku au i ka aina no oukou, e komo oukou, a e la we i ka aina a Iehova i hoohiki ai i ko oukou mau kupuna, ia Aberahama, ia Isaaka, a ia Iakoba, e haawi ia lakou, a me ka lakou poe mamo mahope o lakou.
Wò ó, èmi tí fi ilẹ̀ yí fún un yín, ẹ wọ inú rẹ̀ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí Olúwa ti búra wí pé òun yóò fún àwọn baba yín: fún Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu, àti fún àwọn àrọ́mọdọ́mọ wọn.”
9 Olelo aku la au ia oukou i kela manawa, i aku la, Aole e hiki ia'u, owau wale, ke halihali ia oukou:
Mo wí fún un yín nígbà náà pé, “Èmi nìkan kò lè dá ẹrù u yín gbé.
10 Ua hoonui mai o Iehova ko oukou Akua ia oukou, aia hoi, ua like oukou i keia la me na hoku o ka lani, he nui loa.
Olúwa Ọlọ́run yín ti sọ yín di púpọ̀ lónìí, ẹ̀yin sì ti pọ̀ bí ìràwọ̀ ní ojú ọ̀run.
11 (A na Iehova ke Akua o ko oukou poe kupuna, e hoonui patausani aku ia oukou, a e hoomaikai mai ia oukou e like me kana i olelo mai ai ia oukou!)
Kí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín sọ yín di púpọ̀ ní ọ̀nà ẹgbẹ̀rún sí i, kí ó sì bùkún un yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
12 Pehea la e hiki ai ia'u, owau wale no ke halihali i ko oukou kaumaha, a me ko oukou luhi, a me ko oukou hoopaapaa ana?
Báwo ni èmi nìkan ṣe lè máa ru àjàgà àti ìṣòro yín àti èdè-àìyedè yín?
13 E wae oukou no oukou i na kanaka akamai, naauao, a ikeia e na hanauna kanaka o oukou, a e hoolilo au ia lakou i poe luna no oukou.
Ẹ yan àwọn ọlọ́gbọ́n, olóye àti àwọn ẹni àpọ́nlé, láti inú ẹ̀yà yín kọ̀ọ̀kan, èmi yóò sì fi wọ́n ṣe olórí yín.”
14 Olelo mai la oukou ia'u, i mai la, He mea pono ke hana i ka mea au i olelo mai nei.
Ẹ̀yin sì dá mi lóhùn wí pé, “Ohun tí ìwọ ti gbèrò láti ṣe nì dára.”
15 A lawe aku la au i na luna o ko oukou mau ohana, i na kanaka naauao, a ikeia, a hoolilo iho la ia lakou i poo maluna o oukou, i luna no na tausani, i luna no na haneri, i luna no na kanalima, a i luna no na umi. i alii no ko oukou mau ohana.
Bẹ́ẹ̀ ni mo yan olórí àwọn ẹ̀yà yín, àwọn ọlọ́gbọ́n ọkùnrin, ẹni àpọ́nlé, mo sì fi jẹ olórí yín, olórí ẹgbẹẹ̀rún, olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún, olórí àràádọ́ta, àti olórí mẹ́wàá mẹ́wàá gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹ̀yà yín.
16 A kauoha aku la au i na lunakanawai o oukou i kela manawa, i ka i ana'e, E hoolohe oukou i na mea iwaena o na hoahanau o oukou, a e hoopono ma ka pololei iwaena o ke kanaka a me kona hoahanau, iwaena o ka malihini me ia.
Mo sì kìlọ̀ fún àwọn onídàájọ́ yín nígbà náà pé, ẹ gbọ́ èdè-àìyedè tí ó wà láàrín àwọn ènìyàn an yín kí ẹ sì ṣe ìdájọ́ òdodo, bóyá ẹjọ́ tí ó ṣẹlẹ̀ láàrín Israẹli sí Israẹli ni tàbí láàrín Israẹli kan sí àlejò.
17 Mai nana oukou i na maka i ka hooponopono ana; e lohe oukou i ka ka mea uuku e like me ka ka mea nui; mai makau oukou i ka maka o ke kanaka; no ka mea, na ke Akua ka hooponopono ana; a o ka mea pohihihi ia oukou, e lawe mai ia mea ia'u, a na'u ia e lohe aku.
Ẹ má sì ṣe ojúsàájú ní ìdájọ́. Ẹ ṣe ìdájọ́ ẹni ńlá àti kékeré bákan náà. Ẹ má ṣe bẹ̀rù ẹnikẹ́ni torí pé ti Ọlọ́run ni ìdájọ́. Ẹjọ́ tí ó bá le jù fún un yín ni kí ẹ mú wá fún mi. Èmi yóò sì gbọ́ ọ.
18 A kauoha aku la au ia oukou i kela manawa i na mea a pau a oukou e hana aku ai.
Nígbà náà ni èmi yóò sọ ohun tí ẹ ó ṣe fún un yín.
19 A ia kakou i haalele ai ia Horeba, hele kakou maloko o kela waonahele nui weliweli a pau, a oukou i ike ai ma ke ala o ka mauna o ka Amora, e like me ka Iehova i kauoha mai ai ia kakou; a hiki kakou ma Kadesabanea.
Nígbà náà ní a gbéra láti Horebu, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wá, a sì la àwọn ilẹ̀ lókè Amori kọjá lọ dé gbogbo aginjù ńlá tí ó ba ni lẹ́rù nì tí ẹ̀yin ti rí, bẹ́ẹ̀ ni a sì dé Kadeṣi-Barnea.
20 A aku la au ia oukou, Ua hiki mai oukou ma ka mauna o ka Amora, ka mea a Iehova ko kakou Akua i haawi mai ai no kakou.
Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ ti dé ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, èyí tí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.
21 Aia hoi, ke waiho mai nei o Iehova kou Akua i ka aina imua ou: e pii ae, e komo, e like me ka Iehova ke Akua o kou mau kupuna i olelo mai ai ia oe; mai makau, mai hoopauaho.
Ẹ kíyèsi i, Olúwa Ọlọ́run yín ló ni ilẹ̀ náà. Ẹ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín tí sọ fún un yín. Ẹ má bẹ̀rù, ẹ má sì ṣe fòyà.”
22 A hele mai la oukou a pau io'u nei, i mai la, E hoouna aku kakou i na kanaka imua o kakou, a e makaikai lakou i ka aina no kakou, a e hai mai ia kakou i ke ala a kakou e pii aku ai, a me na kulanakauhale a kakou e hele aku ai.
Nígbà náà ni gbogbo yín tọ̀ mí wá wí pé, “Jẹ́ kí a yan àwọn ayọ́lẹ̀wò láti yọ́ ilẹ̀ náà wò fún wa, kí wọn sì fún wa ní ìròyìn àwọn ọ̀nà tí a ó gbà àti àwọn ìlú tí a ó bá pàdé.”
23 Oluolu iho la au ia olelo: a lawe ae la au i na kanaka o oukou, he umikumamalua, pakahi ke kanaka no kela ohana, keia ohana.
Èrò náà sì dára lójú mi, torí èyí ni mo ṣe yan àwọn ènìyàn méjìlá nínú yín, ẹnìkan láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.
24 Huli ae la lakou, a pii aku la ma ka mauna, a hiki ma ke kahawai o Esekola, a makaikai aku la i ka aina
Wọ́n sì gòkè lọ sí ilẹ̀ òkè náà, wọ́n sì wá sí àfonífojì Eṣkolu, wọ́n sì yẹ̀ ẹ́ wò.
25 Lawe lakou i ka hua o ka aina ma ko lakou mau lima, a iho mai io kakou nei, a hai mai ia kakou, i mai la, He maikai ka aina a Iehova ko kakou Akua e haawi mai nei ia kakou.
Wọ́n sì mú lára èso ilẹ̀ náà wá fún wa pé, “Ilẹ̀ tí ó dára ni Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.”
26 Aole nae oukou i pii aku, aka, kipi aku oukou i ke kauoha a Iehova ko oukou Akua.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fẹ́ gòkè lọ; ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run yín.
27 A ohumu ae la oukou iloko o ko oukou mau halelewa, i iho la, No ka inaina o Iehova ia kakou, i lawe mai ai oia ia kakou mailoko mai o ka aina o Aigupita, e haawi ia kakou iloko o ka lima o ka Amora, e luku mai ia kakou.
Ẹ kùn nínú àgọ́ ọ yín, ẹ sì wí pé, “Olúwa kórìíra wa, torí èyí ló fi mú wa jáde láti Ejibiti láti fi wá lé àwọn ará Amori lọ́wọ́ láti pa wá run.
28 Mahea la uanei kakou e pii aku ai? Ua hooweliweli mai ko kakou mau hoahanau i ko kakou naau, ua i mai, Ua nui e aku na kanaka, na loihi hoi lakou ia kakou; a o na kulanakauhale nui, ua paa i ka pa pohaku a hala i ka lani; a ua ike hoi makou i na keiki a Anaka malaila.
Níbo la ó lọ? Àwọn arákùnrin wa ti kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá wa nípa sísọ pé, ‘Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga jù wá lọ; àwọn ìlú náà tóbi jọjọ bẹ́ẹ̀ ni odi wọn ga kan ọ̀run. A tilẹ̀ rí àwọn òmíràn (ìran Anaki) níbẹ̀.’”
29 I aku la au ia oukou, Mai hopohopo oukou, mai makau hoi ia lakou.
Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ má ṣojo, ẹ kò sì gbọdọ̀ bẹ̀rù wọn.
30 O Iehova ko oukou Akua, ka mea hele imua o oukou, nana no e kaua aku no oukou, e like me na mea a pau ana i hana'i no oukou ma Aigupita imua o ko oukou maka:
Olúwa Ọlọ́run yín, tí ń ṣáájú yín yóò jà fún un yín; bí ó ti ṣe fún un yín ní Ejibiti lójú ẹ̀yin tìkára yín
31 A ma ka waonahele, kahi au i ike ai ia Iehova kou Akua, e like me ka ke kanaka hali ana i kana keiki, pela ia i hali ai ia oe ma ke ala a pau a oukou i hele ai, a hiki mai oukou ma keia wahi.
àti ní aginjù. Níbẹ̀ ni ẹ ti rí i bí Olúwa Ọlọ́run yín ti gbé yín, bí baba ti í gbé ọmọ rẹ̀, ní gbogbo ọ̀nà tí ẹ lọ títí ẹ fi padà dé ibí yìí.”
32 Aka, ma keia mea, aole no oukou i hooiaio aku i ka Iehova ko oukou Akua;
Pẹ̀lú gbogbo èyí tí mo wí, ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín,
33 Oia ka i hele ae ma ke ala imua o oukou, ma ke ahi i ka po, a ma ke ao i ke ao, e imi ana i wahi no oukou e kukulu ai i ko oukou mau halelewa, e kuhikuhi ana ia oukou i ke ala e hele ai.
tí ń ṣáájú u yín lọ ní gbogbo ọ̀nà yín, nípa fífi iná ṣe amọ̀nà yín ní òru àti ìkùùkuu ní ọ̀sán, láti fi àwọn ibi tí ẹ lè tẹ̀dó sí hàn yín àti àwọn ọ̀nà tí ẹ ó rìn.
34 A lohe mai la o Iehova i ka leo o ka oukou olelo, a huhu mai la ia oukou, a hoohiki iho la, i ka i ana mai,
Nígbà tí Olúwa gbọ́ ohun tí ẹ sọ, inú bí i, ó sì búra wí pé,
35 He oiaio, aole loa kekahi o keia poe kanaka o keia hanauna ino e ike aku i ka aina maikai a'u i hoohiki ai e haawi aku no ko oukou poe kupuna;
“Kò sí ọ̀kan nínú ìran búburú yìí tí yóò dé ilẹ̀ rere tí mo ti búra láti fún àwọn baba ńlá a yín.
36 O Kaleba wale no ke keiki a Iepune; oia ke ike aku ia, a e haawi aku au i ka aina ana i hehi iho ai nona, a no kana mau keiki; no ka mea, ua hahai kupaa aku la ia ia Iehova.
Bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne. Òun ni yóò wọ̀ ọ́. Èmi yóò sì fún òun àti àwọn ìran rẹ̀ ní ilẹ̀ náà tí ó ti fi ẹsẹ̀ rẹ̀ tẹ̀; torí pé ó fi gbogbo ọkàn rẹ̀ tẹ̀lé Olúwa.”
37 Huhu mai no hoi o Iehova ia'u no oukou, i mai la, Aole hoi oe e hele ilaila.
Torí i tiyín ni Olúwa fi bínú sí mi wí pé, “Ìwọ náà kì yóò wọ ibẹ̀ bákan náà,
38 O Iosua, ke keiki a Nuna, e ku ana imua on, oia ke hele ilaila: e hooikaika oe ia ia, no ka mea, nana no ia e hooili aku no ka Iseraela.
ṣùgbọ́n Joṣua ọmọ Nuni tí ń ṣe olùrànlọ́wọ́ rẹ ni yóò wọ ibẹ̀. Mú un, ní ọkàn le torí pé, òun yóò ṣáájú àwọn ọmọ Israẹli láti gba ilẹ̀ náà.
39 O ka oukou poe keiki uuku a oukou i i mai ai e lilo auanei i poe pio, a me na keiki a oukou, ka poe ike ole ai i ka pono a i hewa ia la, o lakou ke hele ilaila, a na'u ia e haawi aku no lakou, a e komo no lakou ia wahi.
Àwọn èwe yín tí ẹ sọ pé wọn yóò kó lẹ́rú. Àwọn ọmọ yín tí ko tí ì mọ rere yàtọ̀ sí búburú ni yóò wọ ilẹ̀ náà.
40 Aka, o oukou, e haliu ae oukou, a e hele ma ka waonahele ma ke ala o ke Kaiula.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, ẹ yí padà sí aginjù tí ó wà ní ọ̀nà tí ó lọ sí Òkun Pupa.”
41 Alaila, olelo mai la oukou, i mai la ia'u, Ua hana hewa makou ia Iehova, e pii no makou, a e kaua aku, e like me na mea a pau a Iehova ko kakou Akua i kauoha mai ai ia kakou. A i ka wa a oukou, a kela kanaka, keia kanaka i hawele ai i kana mea kaua, ua makaukau oukou e pii maluna o ka puu.
Nígbà náà ni ẹ fèsì wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí Olúwa. A ó sì gòkè lọ láti jà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wa.” Torí náà gbogbo yín ẹ mú ohun ìjà a yín, ẹ rò pé ó rọrùn láti gòkè lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè náà.
42 I mai la o Iehova ia'u, E i aku oe ia lakou, Mai pii oukou, aole hoi e kaua aku: no ka mea, aole owau me oukou; o lukuia mai oukou e ko oukou poe enemi.
Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ fún wọn, ‘Ẹ má ṣe gòkè lọ láti jà torí pé èmi kì yóò wà pẹ̀lú u yín. Àwọn ọ̀tá a yín yóò sì ṣẹ́gun yín.’”
43 A olelo aku la au ia oukou, aole oukou i hoolohe mai; hoohala oukou i ke kauoha a Iehova, aa aku la oukou, a pii ae la maluna o ka puu.
Bẹ́ẹ̀ ni mo sọ fún yín, ẹ̀yin kò sì gbọ́, ẹ̀yin ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa, pẹ̀lú ìgbéraga yín, ẹ gòkè lọ sí ìlú olókè náà.
44 A o ka Amora e noho ana ma ua puu la, hele mai lakou e ku e ia oukou, a hahai mai lakou ia oukou, e like me ka ka nalomeli hana ana, a pepehi mai ia oukou ma Seira a hiki mai i Horema.
Àwọn ará Amori tí ń gbé ní àwọn òkè náà, dojúkọ yín bí àgbájọpọ̀ oyin. Wọ́n sì lù yín bolẹ̀ láti Seiri títí dé Horma.
45 A hoi hou mai oukou, a uwe iho la imua o Iehova: aka, aole o Iehova i hoolohe mai i ko oukou leo, aole hoi ia i haliu mai i ka pepeiao ia oukou.
Ẹ padà, ẹ sì sọkún níwájú Olúwa, òun kò sì fetí sí igbe ẹkún yín, Ó sì kọ etí dídi sí i yín.
46 A noho iho la oukou ma Kadesa i na la he nui, e like me na la a oukou i noho ai.
Báyìí ni ẹ sì dúró ní Kadeṣi fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti ṣe.

< Kanawailua 1 >