< Kanawailua 9 >

1 E HOOLOHE, e ka Iseraela; e hele ana oe i keia la ma kela kapa o Ioredane, e komo a hoolilo nou i na lahuikanaka, he oi aku ka nui a me ka ikaika o lakou i kou, a i na kulanakauhale nui, ua paa i ka pa pohaku, a hala i ka lani.
Gbọ́, ìwọ Israẹli. Báyìí, ẹ̀yin ti gbáradì láti la Jordani kọjá, láti lọ gba ilẹ̀ àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n tóbi, tí wọ́n sì lágbára jù yín lọ, tí wọ́n ní àwọn ìlú ńlá ńlá, tí odi wọn kan ọ̀run.
2 He poe kanaka nunui a loihi, na keiki a ka poe Anakima, a oukou i ike ai, a ua lohe hoi oe, Owai la auanei e hiki ke ku imua o na keiki a Anaka?
Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga àní àwọn ọmọ Anaki ni wọ́n. Ẹ gbọ́ nípa wọn, ẹ sì gbọ́ tí àwọn ènìyàn ń sọ nípa wọn pé, “Ta ni ó le è dojú ìjà kọ àwọn ọmọ Anaki (òmíràn)?”
3 E ike pono oe i keia la, o Iehova kou Akua, ka mea e hele ana imua ou, he ahi ia e hoopau ana, nana lakou e luku aku, a nana lakou e hoohaahaa iho imua o kou maka: a e hookuke aku oe ia lakou, a e luku koke aku ia lakou, e like me ka Iehova i olelo mai ai ia oe.
Ṣùgbọ́n kí ó dá a yín lójú lónìí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni ó ń ṣáájú u yín lọ gẹ́gẹ́ bí iná ajónirun. Yóò jó wọn run, yóò sì tẹ orí wọn ba níwájú yín. Ẹ̀yin yóò sì lé wọ́n jáde, ẹ̀yin yóò sì run wọ́n kíákíá, bí Olúwa ti ṣèlérí fún un yín.
4 Mai i iho oe iloko o kou naau mahope o ka Iehova kou Akua kipaku ana aku ia lakou mai kou alo aku, i ka i ana ae, No ko'u pono i lawe mai nei o Iehova ia'u e hoonoho ma keia aina; aka, no ka hewa o keia mau lahuikanaka i kipaku aku ai o Iehova ia lakou mai kou alo aku.
Lẹ́yìn tí Olúwa Ọlọ́run yín bá ti lé wọn jáde níwájú u yín, ẹ má ṣe wí fún ara yín pé, “Torí òdodo mi ní Olúwa ṣe mú mi wá síbí láti gba ilẹ̀ náà.” Rárá, ṣùgbọ́n nítorí ìwà búburú àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí ni Olúwa yóò ṣe lé wọn jáde níwájú u yín.
5 Aole no kou pono, a me ka pololei o kou naau, kou hele ana e noho ma ko lakou aina; aka, no ka hewa o kela mau luhuikanaka, e kipaku aku ai o Iehova kou Akua ia lakou mai kou alo aku, a e hooko hoi ia i ka olelo a Iehova i hoohiki ai i kou mau kupuna, ia Aberahama, ia Isaaka, a me Iakoba.
Kì í ṣe nítorí òdodo yín, tàbí ìdúró ṣinṣin ni ẹ ó fi wọ ìlú wọn lọ láti gba ilẹ̀ wọn, ṣùgbọ́n nítorí ìwà búburú àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí ni Olúwa Ọlọ́run yín yóò fi lé wọn jáde kúrò níwájú u yín láti lè mú ohun tí ó búra fún àwọn baba ṣẹ: fún Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
6 E ike hoi oe, aole o Iehova kou Akua e haawi mai i keia aina maikai i lilo ia nou, no kou pono; no ka mea, he poe kanaka a-i oolea oukou,
Ṣùgbọ́n kí ó yé yín pé kì í ṣe nítorí òdodo yín ni Olúwa Ọlọ́run yín fi ń fún un yín ní ilẹ̀ rere náà, láti ní, nítorí pé ènìyàn ọlọ́rùn líle ni ẹ jẹ́.
7 E hoomanao oe, mai hoopoina i kou hoonaukiuki ana ia Iehova kou Akua ma ka waonahele: ma ka la i puka mai ai oukou mai ka aina o Aigupita mai, a hiki oukou ma keia wahi, ua kipi oukou ia Iehova.
Ẹ rántí, ẹ má sì ṣe gbàgbé bí ẹ̀yin ti mú Olúwa Ọlọ́run yín bínú ní aginjù. Láti ọjọ́ ti ẹ tí kúrò ní Ejibiti ni ẹ̀yin ti ń ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa títí tí ẹ̀yin fi dé ìhín yìí.
8 Ma Horeba hoi i hoonaukiuki aku ai oukou ia Iehova, a huhu mai la o Iehova ia oukou e luku aku ia oukou.
Ní Horebu ẹ̀yin ti mú kí Olúwa bínú, títí dé bi pé ó fẹ́ run yín.
9 Ia'u i pii ae i ka mauna e loaa na papapohaku, na papa o ke kanawai a Iehova i hana'i no oukou, hookahi kanaha ao, a hookahi kanaha po, a'u i noho ai ma ka mauna; aole au i ai i ka ai, aole hoi i inu i ka wai:
Nígbà tí mo gòkè lọ láti lọ gba wàláà òkúta, wàláà májẹ̀mú ti Olúwa ti bá a yín dá. Ogójì ọ̀sán àti òru ni mo fi wà lórí òkè náà, èmi kò fẹnu kan oúnjẹ bẹ́ẹ̀ ni ń kò mu omi.
10 A haawi mai o Iehova ia'u i na papapohaku elua, i kakauia e ka lima o ke Akua; a maluna o ia mau mea na huaolelo a pau a Iehova i olelo mai ai ia oukou ma ka mauna, mailoko mai o ke ahi i ka la o ka houluulu ana.
Olúwa fún mi ní wàláà òkúta méjì tí a fi ìka Ọlọ́run kọ. Lórí wọn ni a kọ àwọn òfin tí Ọlọ́run sọ fún un yín lórí òkè láàrín iná, ní ọjọ́ ìpéjọpọ̀ sí.
11 A pau na la he kanaha, a me na po he kanaha, haawi mai la o Iehova ia'u i na papapohaku elua, oia na papa o ke kanawai.
Lópin ogójì ọ̀sán àti òru wọ̀nyí, Olúwa fún mi ní sílétì òkúta méjì, wàláà òkúta májẹ̀mú náà.
12 A olelo mai o Iehova ia'u, E ku ae oe, e iho koke oe mai keia wahi aku; no ka mea, ua hana hewa kou poe kanaka au i lawe mai nei mai ka aina o Aigupita mai: ua kapae koke ae lakou mai ke ala aku a'u i kauoha aku ai ia lakou; ua hana lakou i kii i hooheeheeia no lakou.
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ̀kalẹ̀ kúrò níhìn-ín kíákíá, torí pé àwọn ènìyàn rẹ tí o mú jáde láti Ejibiti ti hùwà ìbàjẹ́. Wọ́n ti yípadà kúrò, nínú ọ̀nà mi, wọ́n sì ti ṣe ère dídá fún ara wọn.”
13 Olelo mai hoi o Iehova ia'u, i mai la, Ua ike au i keia poe kanaka, aia hoi, he poe kanaka a-i oolea keia.
Olúwa sì sọ fún mi pé, “Mo ti rí àwọn ènìyàn wọ̀nyí pé ènìyàn ọlọ́rùn líle gbá à ni wọ́n.
14 E waiho mai oe ia'u, i luku aku ai au ia lakou, a i hokai aku ai i ko lakou inoa malalo ae o ka lani: a e hoolilo aku au ia oe i lahuikanaka ikaika loa, a nui loa hoi i ko lakou.
Fi mí sílẹ̀, jẹ́ kí n run wọ́n, kí n sì pa orúkọ wọn rẹ́ kúrò lábẹ́ ọ̀run. Èmi yóò sì sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè tí ó lágbára tí ó sì pọ̀jù wọ́n lọ.”
15 A huli ae au, a iho ilalo mai ka mauna mai, ua wela ka mauna i ke ahi; a ma kuu mau lima elua na papa elua o ke kanawai.
Báyìí ni mo yípadà, tí mó sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè náà wá, orí òkè tí o ń yọ iná. Àwọn wàláà májẹ̀mú méjèèjì sì wà lọ́wọ́ mi.
16 A nana iho la au, aia hoi, ua hana hewa oukou ia Iehova i ko oukou Akua, ua hana oukou i bipikeiki i hooheeheeia no oukou; ua kapae koke oukou mai ke ala aku a Iehova i kauoha mai ai ia oukou.
Ìgbà tí mo ṣàkíyèsí, mo rí i pé ẹ ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ ti ṣe ère òrìṣà ní ìrí ọ̀dọ́ màlúù, fún ara yín. Ẹ ti yípadà kánkán kúrò nínú ọ̀nà tí Olúwa ti pàṣẹ fún un yín.
17 A lawe ae la au i na papa elua a hoolei aku la mai ko'u mau lima aku, a nahaha iho la imua o ko oukou maka.
Bẹ́ẹ̀ ni mó ju wàláà méjèèjì náà mọ́lẹ̀, mo sì fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́ lójú u yín.
18 A haule iho la au imua o Iehova, e like mamua, hookahi kanaha ao, hookahi kanaha po; aole au i ai i ka berena, aole hoi i inu i ka wai, no ko oukou hewa a pau a oukou i hana hewa ai imua o Iehova, e hoonaukiuki aku ai ia ia.
Lẹ́yìn náà mo tún wólẹ̀ níwájú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, èmi kò jẹ oúnjẹ kankan bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mu omi, nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí ẹ tí dá, tí ẹ sì ń ṣe búburú lójú Olúwa, tí ẹ sì ń mú u bínú.
19 No ka mea, makau iho la au i ka huhu a me ka inaina nui a Iehova i huhu mai ai ia oukou e luku ia oukou: aka, hoolohe mai no o Iehova ia'u i kela manawa.
Mo bẹ̀rù ìbínú àti ìrunú Olúwa, nítorí pé inú bí i sí i yín dé bi wí pé ó fẹ́ pa yín run. Ṣùgbọ́n Olúwa tún fetí sí mi lẹ́ẹ̀kan sí i.
20 A huhu nui mai no hoi o Iehova ia Aarona e pepehi ia ia: a pule aku au no Aarona hoi i kela manawa.
Inú sì bí Olúwa sí Aaroni láti pa á run, nígbà náà ni mo tún gbàdúrà fún Aaroni náà.
21 Lawe aku la au i ko oukou hala, i ka bipikeiki a oukou i hana'i, a puhi aku la i ke ahi, a kui iho la, a pepe liilii a aiai e like me ka lepo; a hoolei aku i kona lepo iloko o ke kahawai, e kahe ana mai ka mauna mai.
Bẹ́ẹ̀ ni mo sì mú ohun tí ó mú un yín dẹ́ṣẹ̀, àní ère ẹgbọrọ màlúù tí ẹ ti ṣe, mo sì fi iná sun ún, bẹ́ẹ̀ ni mo gún un, mo sì lọ̀ ọ́ lúúlúú bí eruku lẹ́búlẹ́bú, mo sì da ẹ̀lọ̀ rẹ̀ sínú odò tí ń sàn nísàlẹ̀ òkè.
22 A ma Tabera, a ma Masa, a ma Kiberohataava, hoonaukiuki aku la oukou ia Iehova.
Ẹ̀yin tún mú Olúwa bínú ní Tabera, Massa àti ní Kibirotu-Hattaafa.
23 A ia Iehova hoi i hoouna aku ai ia oukou mai Kadesabanea aku, i ka i ana aku, E pii oukou a noho ma ka aina a'u i haawi ai no oukou; alaila kipi mai la oukou i ke kauoha a Iehova ko oukou Akua, aole oukou i hooia aku ia ia, aole hoi oukou i hoolohe i kona leo.
Nígbà tí Olúwa ran an yín jáde ní Kadeṣi-Barnea, Ó wí pé, “Ẹ gòkè lọ, kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí mo fi fún un yín.” Ṣùgbọ́n ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé e, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò gbọ́ tirẹ̀.
24 He poe kipi oukou ia Iehova mai ka manawa mai o kuu ike ana ia oukou.
Láti ìgbà tí mo ti mọ̀ yín ni ẹ ti ń ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa.
25 A haule iho la au imua o Iehova, hookahi kanaha ao, hookahi kanaha po, e like me kuu haule ana mamua; no ka mea, ua i mai o Iehova e luku aku ia oukou.
Mo ti wólẹ̀ níwájú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti òru wọ̀nyí nítorí pé Olúwa sọ pé Òun yóò pa yín run.
26 No ia mea, pule aku la au ia Iehova, i aku la, E Iehova, e ka Haku e, mai luku mai oe i kou poe kanaka, a me kou hooilina au i hoola'i ma kou mana, i ka mea hoi au i lawe mai nei mai Aigupita mai me ka lima ikaika.
Mo gbàdúrà sí Olúwa wí pé, “Olúwa Olódùmarè, má ṣe run àwọn ènìyàn rẹ, àní ogún rẹ tí o ti rà padà, nípa agbára rẹ tí o sì fi agbára ńlá mú wọn jáde láti Ejibiti wá.
27 E hoomanao oe i kau mau kauwa, ia Aberahama, ia Isaaka, a me Iakoba: mai manao oe i ka paakiki o keia poe kanaka, aole hoi i ko lakou hewa a me ko lakou hala;
Rántí àwọn ìránṣẹ́ rẹ Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu. Fojú fo orí kunkun àwọn ènìyàn yìí, pẹ̀lú ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
28 O olelo mai auanei ko ka aina nolaila i lawe mai ai oe ia makou, No ka hiki ole ia Iehova ke lawe aku ia lakou ma ka aina ana i olelo mai ai ia lakou, a no kona inaina ia lakou, i lawe mai oia ia lakou e luku ia lakou ma ka waonahele.
Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti mú wa jáde wá yóò wí pé, ‘Torí pé Olúwa kò lè mú wọn lọ sí ilẹ̀ náà tí ó ti ṣèlérí fún wọn, àti pé ó ti kórìíra wọn, ni ó fi mú wọn jáde láti pa wọ́n ní aginjù.’
29 O kou poe kanaka no nae lakou, a me kou hooilina au i lawe mai nei me kou mana ikaika, a me kou lima kakauha.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn rẹ ni wọ́n, ogún rẹ tí o ti fi ọwọ́ agbára rẹ àti nínà ọwọ́ rẹ mú jáde.”

< Kanawailua 9 >