< Daniela 9 >

1 I KA makahiki mua o Dariu ke keiki a Ahasuero, no ka ohana a Media, ka mea i hooliloia i alii maluna o ke aupuni o ka poe Kaledea;
Ní ọdún kìn-ín-ní Dariusi ọmọ Ahaswerusi, ẹni tí a bí ní Media, òun ló jẹ ọba lórí ìjọba Babeli.
2 I ka makahiki mua o kona alii ana, ike iho la au, o Daniela nei, iloko o na buke, i ka helu ana o na makahiki ma ka olelo ana mai a Ieho va ia Ieremia i ke kaula, i hoopauia mai ai na makahiki he kanahiku o ko Ierusalema lukuia ana.
Ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba rẹ̀, èmi Daniẹli fi iyè sí i láti inú ìwé, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí wòlíì Jeremiah, wá pé, àádọ́rin ọdún ni Jerusalẹmu yóò fi wà ní ahoro.
3 A haliu aku la au i ko'u maka i ka Haku i ke Akua e imi aku ma ka pule, a me ka nonoi ana, me ka hookeai, a me ke kapa ino, a me ka lehuahi:
Nígbà náà, ni mo yípadà sí Olúwa Ọlọ́run, mo bẹ̀ ẹ́ pẹ̀lú àdúrà àti ẹ̀bẹ̀, pẹ̀lú àwẹ̀, aṣọ ọ̀fọ̀ àti eérú.
4 A pule aku la au ia Iehova i ko'u Akua, me ka hai aku i ko'u hewa, a me ka i aku, E ka Haku, ke Akua nui, a me ka weliweli, ka mea nana i malama i ka berita, a me ke aloha i ka poe i aloha aku ia ia, a me ka poe i malama i kona mau kanawai;
Mo gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run mi, mo sì jẹ́wọ́ wí pé: “Ìwọ Olúwa, Ọlọ́run tí ó tóbi, tí ó sì ní ẹ̀rù, ẹni tí ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ mọ́, pẹ̀lú àwọn tí ó ní ìfẹ́ rẹ̀ àti àwọn tí ó ń pa àwọn òfin rẹ̀ mọ́.
5 Ua lawehala makou, a ua hana hewa hoi, me ka hana ino wale aku, a me ke kipi aku no hoi, ma ka haalele ana i kau mau kauoha, a me kou mau kanawai:
Àwa ti ṣẹ̀, a sì ti ṣe búburú. Àwa ti hu ìwà búburú, a sì ti ṣe ọ̀tẹ̀, a ti yí padà kúrò nínú àwọn àṣẹ àti àwọn ìlànà rẹ̀.
6 Aole makou i hoolohe i kau poe kauwa, i na kaula, ka poe nana i olelo mai ma kou inoa i ko makou poe alii, a me ko makou poe kaukaualii, a me ko makou mau makua, a me na kanaka a pau o ka aina.
Àwa kò fetí sí àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ, ẹni tí ó sọ̀rọ̀ ní orúkọ rẹ sí àwọn ọba wa, àwọn ọmọ-aládé àti àwọn baba wa, àti sí gbogbo ènìyàn ilẹ̀ náà.
7 E ka Haku e, ia oe no ka pono; aka, ia makou no ka hilahila o ka maka, e like me ia i keia la; i na kanaka o Iuda, a me ko Ierusalema poe, a me ka Iseraela a pau, ka poe ma kahi kokoke, a ma kahi mamao aku, a ma na aina a pau kahi au i kipaku ai ia lakou no ka hala a lakou i lawehala aku ai ia oe.
“Olúwa ìwọ ni olódodo, ṣùgbọ́n báyìí ìtìjú dé bá àwọn ènìyàn Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu àti gbogbo Israẹli ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti fọ́n wa ká sí nítorí àìṣòótọ́ ọ wa sí ọ.
8 E ka Haku ia makou no ka hilahila o ka maka, i ko makou poe alii, a i ko makou poe kaukaualii, a i ko makou poe makua hoi, no ka mea, ua hana hewa makou ia oe.
Háà! Olúwa, àwa àti àwọn ọba wa, àwọn ọmọ-aládé, àti àwọn baba wa, ìtìjú dé bá wa nítorí àwa ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ.
9 I ka Haku ko makou Akua ke aloha, a me ke kala i na hala; ua kipi aku no nae makou ia ia;
Olúwa Ọlọ́run wa ní àánú, ó sì ń dáríjì, bí àwa tilẹ̀ ti ṣe ọ̀tẹ̀ sí i;
10 Aole hoi makou i hoolohe i ka leo o Iehova, ko makou Akua, e hele ma kona mau kanawai, na mea ana i hai mai ai imua o makou ma kana poe kauwa o na kaula.
àwa kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, a kò sì pa àwọn òfin rẹ mọ́, èyí tí ó fún wa nípasẹ̀ àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.
11 Oiaio, ua lawehala ka Iseraela a pau i kou kanawai ma ka haalele ana, a me ka malama ole ana i kou leo; no ia mea, ua nininiia mai ka poino maluna o makou, a me ka hoohiki i kakauia ma ke kanawai ia Mose, ke kauwa a ke Akua, no ka mea, ua hana hewa makou ia ia.
Gbogbo Israẹli ti ṣẹ̀ sí òfin rẹ, wọ́n ti yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, wọ́n kọ̀ láti ṣe ìgbọ́ràn sí ọ. “Nígbà náà ni ègún àti ìdájọ́ tí a kọ sílẹ̀ pẹ̀lú ìbúra nínú òfin Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run dà sórí i wa, nítorí tí àwa ti sẹ̀ sí ọ.
12 A ua hooko mai oia i ka olelo ana i olelo ku e mai ai ia makou, a me ko makou poe lunakanawai, ka poe nana makou i hookolokolo mai, i kona hooili ana maluna o makou i ka poino nui; no ka mea, aohe hana malalo iho o ka lani a puni e like me ka mea i hanaia maluna o Ierusalema.
Ìwọ ti mú ọ̀rọ̀ tí o sọ sí wa sẹ àti lórí àwọn alákòóso wa, nípa mímú kí ibi ńlá bá wa, irú èyí tí kò tí ì ṣẹlẹ̀ rí lábẹ́ ọ̀run, bí ó ti ṣẹlẹ̀ sí Jerusalẹmu yìí.
13 E like me ka mea i palapalaia ma ke kanawai ia Mose, ua hiki mai keia poino a pau maluna o makou; aole nae makou i pule aku imua o Iehova ko makou Akua, i huli makou mai ko makou hewa aku, a i ike i kou oiaio.
Bí a ti kọ ọ́ sínú òfin Mose bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ibi yìí ti dé bá wa, síbẹ̀ a kò bẹ̀bẹ̀ fún ojúrere Olúwa Ọlọ́run wa, nípa yíyí padà kí a kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ wa kí a sì mọ òtítọ́ rẹ.
14 No ia mea, ua nana o Iehova i ka poino, a hooili mai maluna o makou; no ka mea, ua pono o Iehova ko makou Akua ma ka hana a pau ana i hana'i; no ka mea, aole makou i hoolohe aku i kona leo.
Olúwa kò jáfara láti mú ibi náà wá sórí wa, nítorí olódodo ni Olúwa Ọlọ́run wa nínú u gbogbo ohun tí ó ń ṣe; síbẹ̀ àwa kò ṣe ìgbọ́ràn sí i.
15 Ano, e ka Haku, e ko makou Akua e, ka mea nana e hoopuka mai i kou poe kanaka mai ka aina o Aigupita mai me ka lima kakauha, a hookaulana oe i kou inoa e like me ia i keia la; ua hewa makou, a ua hana ino aku no hoi makou
“Ní ìsinsin yìí, Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, pẹ̀lú ọwọ́ agbára, tí ó fún ara rẹ̀ ní orúkọ tí ó wà títí di òní, a ti ṣẹ̀, a sì ti ṣe búburú.
16 E ka Haku e, ke noi aku nei au ia oe, e like me kou pono a pau, e hoohuliia'ku kou huhu, a me kou ukiuki mai kou kulanakauhale o Ierusalema aku, mai kou mauna hoano aku; no ka mea, no ko makou hewa, a no ka hala o ko makou poe makua, ua lilo o Ierusalema a me kou poe kanaka i mea hoowahawahaia o na mea a pau a puni makou.
Olúwa, ní ìbámu pẹ̀lú ìwà òdodo rẹ, yí ìbínú àti ìrunú rẹ padà kúrò ní Jerusalẹmu ìlú u rẹ, òkè mímọ́ rẹ. Ẹ̀ṣẹ̀ wa àti àìṣedéédéé àwọn baba wa ti mú Jerusalẹmu àti ènìyàn rẹ di ẹ̀gàn fún gbogbo àwọn tí ó yí wọn ká.
17 Ano, e ko makou Akua, e hoolohe mai i ka pule a kau kauwa, a me kona noi ana no ka Haku, a e haliu oluolu mai i kou maka maluna o kou hale hoano i hooneoneoia'i.
“Nísinsin yìí, Ọlọ́run wa, gbọ́ àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ, nítorí i tìrẹ Olúwa, fi ojú àánú wo ibi mímọ́ rẹ tí ó ti dahoro.
18 E ko'u Akua, e haliu mai i kou pepeiao, a e hoolohe mai; e wehe i kou mau maka, a e nana mai i ko makou poino, a me ke kulanakauhale i kapaia ma kou inoa; no ka mea, aole pule aku makou imua ou no ko makou pono, aka, no kou aloha nui mai no.
Tẹ́ etí rẹ sílẹ̀, Ọlọ́run, kí o gbọ́; ya ojú rẹ sílẹ̀, kí o sì wo ìdahoro ìlú tí a ń fi orúkọ rẹ pè. Àwa kò gbé ẹ̀bẹ̀ wa kalẹ̀ níwájú u rẹ nítorí pé a jẹ́ olódodo, bí kò ṣe nítorí àánú ńlá rẹ.
19 E ka Haku e, e hoolono mai; e ka Haku e, e kala mai; e ka Haku e, e hoolohe mai, a e hana hoi; mai kakali, no kou pono iho no, e ko'u Akua: no kou kulanakauhale a me kou poe i kapaia ma kou inoa.
Olúwa, fetísílẹ̀! Olúwa, dáríjì! Olúwa, gbọ́ kí o sì ṣe é! Nítorí i tìrẹ, Ọlọ́run mi, má ṣe pẹ́ títí, nítorí ìlú rẹ àti àwọn ènìyàn rẹ ń jẹ́ orúkọ mọ́ ọ lára.”
20 A i ka'u olelo ana, a me ka'u pule ana, a me ko'u hai ana i ko'u hewa, a me ka hewa o ko'u poe o ka Iseraela, a i ko'u noi ana imua o Iehova ko'u Akua no ka mauna hoano o ko'u Akua;
Bí mo ṣe ń sọ̀rọ̀, tí mo sì ń gba àdúrà, tí mo ń jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi àti ẹ̀ṣẹ̀ àwọn Israẹli ènìyàn mi, tí mo sì ń mú ẹ̀bẹ̀ mi tọ Olúwa Ọlọ́run mi nítorí òkè mímọ́ rẹ.
21 Oiaio, i ka'u olelo ana ma ka pule, o ke kanaka o Gaberiela, ka mea a'u i ike ai mamua ma ka hihio, ua hooholo mama ia mai oia, a hoopa mai ia'u i ka manawa o ka mohai ahiahi:
Bí mo ṣe ń gba àdúrà náà lọ́wọ́, Gabrieli ọkùnrin tí mo rí nínú ìran ìṣáájú, yára kánkán wá sí ọ̀dọ̀ mi ní àkókò ẹbọ àṣálẹ́.
22 A hoakaka mai la oia ia'u, a kamailio pu me au, i mai, E Daniela, ua hele mai nei au e haawi ia oe i ke akamai, a me ka naauao.
Ó jẹ́ kí ó yé mi, ó sì wí fún mi pé, “Daniẹli, mo wá láti jẹ́ kí o mọ̀ kí o sì ní òye.
23 Ma ka hoomaka ana o kou noi, i puka mai ai ke kauoha, a ua hele mai hoi au e hoakaka ia oe; no ka mea, o oe ke kanaka i aloha nui ia; no ia mea, e ike oe i ka mea, a e noonoo oe i ka hihio.
Bí o ṣe bẹ̀rẹ̀ sí nígbà àdúrà, a fún ọ ní ìdáhùn kan, èyí tí mo wá láti sọ fún ọ, nítorí ìwọ jẹ́ àyànfẹ́ gidigidi. Nítorí náà, gba ọ̀rọ̀ náà yẹ̀ wò kí ìran náà sì yé ọ:
24 Ua hoopaaia maluna o kou poe kanaka he kanahiku hebedoma, a maluma o kou kulanakauhale hoano, e hoopauia ka hewa, a e hoopauia hoi na hala, a e hookalaia mai ka ino, a e hookomo mai i ka pono mau, a e hooko i ka hihio, a me ka mea i wananaia, a e poni i ka Mea hemolele loa.
“Àádọ́rin ọ̀sẹ̀ ni a pàṣẹ fún àwọn ènìyàn rẹ àti fún àwọn ìlú mímọ́ rẹ láti parí ìrékọjá, láti fi òpin sí ẹ̀ṣẹ̀, láti ṣe ètùtù sí ìwà búburú, láti mú òdodo títí ayé wá, láti ṣe èdìdì ìran àti wòlíì àti láti fi òróró yan Ibi Mímọ́ Jùlọ.
25 E ike oe, a e noonoo hoi, mai ka puka ana mai o ke kauoha e hoihoi, a e kukulu ia Ierusalema, a hiki aku i ka Mesia, ke Alii, ehiku ia hebedoma, a he kanaono a me kumamalua hebedoma; alaila e kukulu hou ia na alanui, a me ka pa, i na manawa popilikia no.
“Nítorí náà, mọ èyí pé, láti ìgbà tí a ti gbé ọ̀rọ̀ náà jáde wí pé kí a tún Jerusalẹmu ṣe, kí a sì tún kọ́, títí dé ìgbà ọmọ-aládé, ẹni òróró náà, alákòóso wa yóò fi dé, ó jẹ́ ọ̀sẹ̀ méje àti ọ̀sẹ̀ méjìlélọ́gọ́ta, a ó sì tún ìgboro àti yàrá rẹ̀ mọ, ṣùgbọ́n ní àkókò wàhálà ni.
26 A mahope iho o ua mau hebedoma la he kanaono me kumamalua, e okiia ana ka Mesia, aole nae nona iho; a o na kanaka o ke alii ka poe e hele mai ana, e luku auanei lakou i ke kulanakauhale a me ka hale hoano; a o kona hopena me he kai hoee la, a i ka hope o ua kaua la e hoopaaia mai ka hooneoneo ana.
Lẹ́yìn ọ̀sẹ̀ méjìlélọ́gọ́ta, a ó ké Ẹni òróró náà kúrò, kò sì ní ní ohun kan. Àwọn ènìyàn ọmọ-aládé náà tí yóò wá ni yóò pa ìlú náà àti ibi mímọ́ run. Òpin yóò dé bí ìkún omi, ogun yóò máa jà títí dé òpin, a sì ti pàṣẹ ìdahoro.
27 A e hoopaa iho no ia i ka berita me ka lehulehu no ka hebedoma hookahi; a iwaenakonu o ua hebedoma la e hookiia na mohai, a me na mohaikuni, a maluna o ka pahalo e kau na mea haumia e hooneoneo ai a hiki i ka manawa e nininiia mai ai ka hoopai ana maluna o ka poe i luku aku.
Yóò sì fi ìdí i májẹ̀mú kan múlẹ̀ pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún ọ̀sẹ̀ kan. Ní àárín ọ̀sẹ̀ ni yóò mú òpin bá ẹbọ àti ọrẹ ẹbọ. Àti lórí apá kan ni yóò dà ìríra tí ó mú ìdahoro wá, títí tí òpin tí a ti pàṣẹ lórí asọnidahoro yóò fi padà fi dé bá a.”

< Daniela 9 >