< Oihana 26 >
1 A LAILA olelo mai la o Ageripa ia Paulo, Ke aeia'ku nei ia oe e olelo mai nou iho. Hohola ae la o Paulo i kona lima, olelo mai la nona iho;
Agrippa sì wí fún Paulu pé, “A fún ọ láààyè láti sọ tí ẹnu rẹ.” Nígbà náà ní Paulu ná ọwọ́, ó sì sọ ti ẹnu rẹ pé,
2 Pomaikai au i ko'u manao, e ke alii, o Ageripa e, no ka mea, e hoakaka ana au imua ou i keia la, no na mea a pau a'u i hoopiiia mai nei e na Iudaio:
“Agrippa ọba, inú èmi tìkára mi dùn nítorí tí èmi yóò wí ti ẹnu mi lónìí níwájú rẹ, ní ti gbogbo ẹ̀sùn tí àwọn Júù fi kan mi,
3 No ka mea, ua ike no oe i na aoao, a me na mea hoopaapaa a pau o na Iudaio; nolaila, ke nonoi aku nei au ia oe, e hoolohe ahonui mai ia'u.
pàápàá bí ìwọ tí mọ gbogbo àṣà àti ọ̀ràn tí ń bẹ́ láàrín àwọn Júù dájúdájú. Nítorí náà, èmi bẹ̀ ọ́ kí ìwọ fi sùúrù tẹ́tí gbọ́ tèmi.
4 O ko'u noho ana, mai ko'u wa uuku mai, aia ia mai kinohi mai ma Ierusalema iwaena o kou lahuiaina iho, ua ike na Iudaio a pau;
“Àwọn Júù mọ irú ìgbé ayé tí mo ń gbé láti ìgbà èwe mi, láti ìbẹ̀rẹ̀ ayé mi ní orílẹ̀-èdè mi àti ní Jerusalẹmu.
5 Ka poe i ike mai ia'u i kinohou, ina i ake lakou e hoike mai, noho Parisaio no wau ma ka aoao ikaika loa o ko makou hoomana.
Nítorí wọ́n mọ̀ mi láti ìpilẹ̀ṣẹ̀, bí wọ́n bá fẹ́ jẹ́rìí sí i, wí pé, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà ìsìn wa tí ó lè jùlọ, Farisi ni èmi.
6 Ke ku nei no au, ua hookolokoloia mai nei no hoi, no ka manaolana o ka olelo hoopomaikai a ke Akua i olelo mai ai i ko makou mau kupuna.
Nísinsin yìí nítorí ìrètí ìlérí tí Ọlọ́run tí ṣe fún àwọn baba wa ni mo ṣe dúró níhìn-ín fún ìdájọ́.
7 Ke manaolana nei no hoi ko makou poe ohana, he umi a me kumamalua, e loaa ia mea, me ka malama mau aku i ka po a me ke ao; no ia manaolana o'u, e ke alii, e Ageripa e, ua hoopiiia mai noi au e na Iudaio.
Ìlérí èyí tí àwọn ẹ̀yà wa méjèèjìlá tí ń fi ìtara sin Ọlọ́run lọ́sàn án àti lóru tí wọ́n ń retí àti rí i gbà. Ọba Agrippa, nítorí ìrètí yìí ni àwọn Júù ṣe ń fi mi sùn.
8 No ke aha la oukou i manao ai ho mea hiki ole i ke Akua ke hoala mai i ka poe make?
Èéṣe tí ẹ̀yin fi rò o sí ohun tí a kò lè gbàgbọ́ bí Ọlọ́run bá jí òkú dìde?
9 Nolaila, manao no au iloko o'u iho, he mea pono ia'u ke hana i na mea he nui i ku e i ka inoa o Iesn no Nazareta.
“Èmi tilẹ̀ rò nínú ará mi nítòótọ́ pé, ó yẹ ki èmi ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun lòdì sí orúkọ Jesu tí Nasareti.
10 Hana no au ia mau mea ma Ierusalema; hana paa iho la au i na haipule he nui maloko o na halepaahao, ua loaa no ia'u ka mana no ka poe kahuna nui; a ia lakou i pepehiia, owau no kekahi i hoahewa pu aku la lakou.
Èyí ni mo sì ṣe ni Jerusalẹmu. Pẹ̀lú àṣẹ tí mo tí gba lọ́dọ̀ àwọn olórí àlùfáà, mo sọ àwọn púpọ̀ nínú àwọn ènìyàn mímọ́ sí inú túbú, nígbà tí wọ́n sí ń pa wọ́n, mo ní ohùn sí i.
11 Hoopai pinepine aku la au ia lakou maloko o na halehalawai a pau, a koi aku la au ia lakou e olelo hoino; a no ko'u ukiuki loa ia lakou, hoomaau aku la au ia lakou a hiki i na kulanakauhale o na aina e.
Nígbà púpọ̀ ni mo ń fi ìyà jẹ wọ́n láti inú Sinagọgu dé inú Sinagọgu, mo ń fi tipá mú wọn láti sọ ọ̀rọ̀-òdì. Mo sọ̀rọ̀ lòdì sí wọn gidigidi, kódà mo wá wọn lọ sí ìlú àjèjì láti ṣe inúnibíni sí wọn.
12 No ia mau mea i hele ai au i Damaseko, me ka mana a me ke aeia na na kahuna nui mai,
“Nínú irú ìrìnàjò yìí ní mo ń bá lọ sí Damasku pẹ̀lú ọlá àti àṣẹ ikọ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn olórí àlùfáà.
13 I ke awakea, e ke alii e, ike aku la au ma ke alanui, he malamalama mai ka lani mai, he mea oi loa aku mamua o ka malamalama o ka la, ua puni au i ka malamalama, a me ka poe i hele pu me au.
Ni ọ̀sán gangan, ìwọ ọba Agrippa, bí mo ti wà ní ojú ọ̀nà, mo rí ìmọ́lẹ̀ kan láti ọ̀run wá, tí ó mọ́lẹ̀ ju oòrùn lọ, ó mọ́lẹ̀ yí mi ká, àti àwọn tí ń bá mi lọ sì àjò.
14 A hina makou a pau i ka honua, lohe aku la au i ka leo, i ka i ana mai ia'u, i mai la ma ka olelo Hebera, E Saulo, e Saulo, no ke aha la oe e hoomaau mai nei ia'u? He mea eha nou ke keehi mai i na kui.
Gbogbo wa sì ṣubú lulẹ̀, mo gbọ́ ohùn tí ń fọ sì mi ni èdè Heberu pé, ‘Saulu, Saulu! Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣe inúnibíni sí mi? Ohun ìrora ní fún ọ láti tàpá sí ẹ̀gún!’
15 I aku la au, Owai oe, e ka Haku? I mai la kela, o Iesu no wau, o ka mea au e hoomaau mai nei.
“Èmi sì wí pé, ‘Ìwọ ta ni, Olúwa?’ “Olúwa sì wí pé, ‘Èmi ni Jesu tí ìwọ ń ṣe inúnibíni sí.
16 Aka, e ala hoi oe, a e ku iluna ma na wawae ou; no ka mea, ua ikea au ia oe, no keia mea, e hoolilo ana au ia oe i lawehana, a i mea hoike aku i keia mea au i ike iho nei, a me na mea a'u e hoike hou aku ai nau.
Ṣùgbọ́n dìde, kí o sí fi ẹsẹ̀ rẹ tẹlẹ̀: nítorí èyí ni mo ṣe farahàn ọ́ láti yàn ọ́ ní ìránṣẹ́ àti ẹlẹ́rìí, fún ohun wọ̀nyí tí ìwọ tí rí nípa mi, àti àwọn ohun tí èmi yóò fi ara hàn fún ọ.
17 Na'u no oe e hoopakele i kanaka a me ko na aina e; e hoouna aku ana no au ia oe io lakou la,
Èmi yóò gbà ọ lọ́wọ́ àwọn ènìyàn rẹ àti lọ́wọ́ àwọn aláìgbàgbọ́. Èmi rán ọ sí wọn nísinsin yìí
18 E hookaakaa'i i ko lakou mau maka, a e hoohuli ia lakou, mai ka pouli mai i ka malamalama, a mai ka mana o Satana i ke Akua, i loaa ia lakou ke kala ana o ka hala, a me ka hooilina mawaena o ka poe i hoomaemaeia e ka manaoio mai ia'u.
láti là wọ́n lójú, kí wọn lè yípadà kúrò nínú òkùnkùn sí ìmọ́lẹ̀, àti kúrò lọ́wọ́ agbára Satani sí Ọlọ́run, kí wọn lè gba ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀, àti ogún pẹ̀lú àwọn tí a sọ di mímọ́ nípa ìgbàgbọ́ nínú mi.’
19 Nolaila, e ke alii, e Ageripa e, aole au i hoole aku ia hoakaku, mai ka lani mai.
“Nítorí náà, Agrippa ọba, èmi kò ṣe àìgbọ́ràn sì ìran ọ̀run náà.
20 Aka, hoike mua aku la au ia lakou ma Damaseko, a ma Ierusalema, a ma na mokuna a pau ma Iudea, a i ko na aina e, i mihi lakou, a e huli i ke Akua, a e hana i na hana e ku i ka mihi.
Ṣùgbọ́n mo kọ́kọ́ sọ fún àwọn tí ó wà ní Damasku, àti ní Jerusalẹmu, àti já gbogbo ilẹ̀ Judea, àti fún àwọn kèfèrí, kí wọn ronúpìwàdà, kí wọ́n sì yípadà sí Ọlọ́run, kí wọn máa ṣe iṣẹ́ tí ó yẹ sì ìrònúpìwàdà.
21 No keia mau mea, lalau mai na Iudaio ia'u maloko o ka luakini, hoao mai la lakou e pepehi mai ia'u a make.
Nítorí nǹkan wọ̀nyí ni àwọn Júù ṣe gbá mi mú nínú tẹmpili, tí wọ́n sì ń fẹ́ pa mí.
22 No ke kokua ana mai o ke Akua ia'u, ua ku paa no wan, a hiki mai nei i keia la, e hoike ana aku i ka poe liilii, a me ka poe nui, i ka i ana aku i keia mau mea wale no, i na mea a ka poe kaula, a me Mose no hoi i olelo mai ai, e hiki mai ana:
Ṣùgbọ́n bí mo sì tí ri ìrànlọ́wọ́ gbà láti ọ́dọ̀ Ọlọ́run, mo dúró títí ó fi di òní, mo ń jẹ́rìí fún èwe àti àgbà, èmi kò sọ ohun mìíràn bí kò ṣe ohun tí àwọn wòlíì àti Mose tí wí pé, yóò ṣẹ.
23 E make no ka Mesia e pono ai, oia hoi ka mua o ka poe make i ala hou mai, nana no e hoike aku i ka malamalama i ko onei kanaka, a me ko na aina e.
Pé, Kristi yóò jìyà, àti pé òun ni yóò jẹ́ ẹni àkọ́kọ́ láti jíǹde kúrò nínú òkú, òun ni yóò sí kéde ìmọ́lẹ̀ fún àwọn ènìyàn àti fún àwọn aláìgbàgbọ́.”
24 A i kana hoakaka ana pela i kona iho, i ae la o Peseto me ka leo nui, E Paulo, ua hehena oe; na na palapala he nui oe i hoolilo ai i hehena.
Bí ó sì ti ń sọ tẹnu rẹ̀, Festu wí ní ohùn rara pé, “Paulu! Orí rẹ dàrú; ẹ̀kọ́ àkọ́jù rẹ ti dà ọ́ ní orí rú!”
25 I aku la ia, Aole au hehena, e Peseto maikai e, aka, ke olelo aku nei au i na olelo oiaio a me ka naauao.
Paulu dalóhùn wí pé, “Orí mi kò dàrú, Festu ọlọ́lá jùlọ; ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ òtítọ́ àti ọ̀rọ̀ òye ni èmi ń sọ jáde.
26 Ua ike no hoi ke alii i keia mea, ke olelo wiwo ole aku nei au imua o kona alo; no ka mea, ke manao nei au aole i nalo ia ia kekahi o keia mau mea, no ka mea, aole i hanaia keia ma kahi nalo.
Nítorí ọba mọ̀ gbogbo nǹkan wọ̀nyí, níwájú ẹni tí èmi ń sọ̀rọ̀ ni àìbẹ̀rù: nítorí mo gbàgbọ́ pé ọ̀kan nínú nǹkan wọ̀nyí kò pamọ́ fún un, nítorí tí a kò ṣe nǹkan yìí ní ìkọ̀kọ̀.
27 E ke alii, e Ageripa e, ke manaoio mai nei anei oe i ka na kaula! Ua ike no au, ua manaoio no oe.
Agrippa ọba, ìwọ gba àwọn wòlíì gbọ́ bí? Èmi mọ̀ pé ìwọ gbàgbọ́.”
28 Olelo aku la o Ageripa ia Paulo, Ua aneane oe e hoohuli mai ia'u i Kristiano.
Agrippa sì wí fún Paulu pé, “Ǹjẹ́ ìwọ lérò pé ìwọ le fi àkókò díẹ̀ yìí sọ mí di Kristiani?”
29 I mai la o Paulo, Ke pule nei au i ke Akua, i ole oe ma ka aneane wale no, aka, ma ka oiaio e lilo ai oe, a me ka poe a pau e hoolohe mai ia'u i keia la, i mea e like io ai me au nei, ma na mea a pau, o keia paa wale no ke koe.
Paulu sì dáhùn wí pé, “Ní àkókò kúkúrú tàbí gígùn, mo gbàdúrà sí Ọlọ́run pé kí ó má ṣe ìwọ nìkan, ṣùgbọ́n kí gbogbo àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ mi lónìí pẹ̀lú lè di irú ènìyàn tí èmi jẹ́ láìsí ẹ̀wọ̀n wọ̀nyí.”
30 A ku ae la ke alii iluna, a me ke alii kiaaina, a me Berenike, a me ka poe e noho pu ana me lakou.
Nígbà tí ó sì sọ nǹkan wọ̀nyí tan, ọba dìde, àti baálẹ̀, àti Bernike, àti àwọn tí o bá wọn jókòó,
31 I ko lakou hoi ana'ku, kamailio ae la lakou ia lakou iho no, i ae la, Aole i hana keia kanaka i ka mea ku i ka make a me ka paa.
Nígbà tí wọn wọ ìyẹ̀wù lọ, wọn bá ara wọn jíròrò, wọ́n sọ pé, “Ọkùnrin yìí kò ṣe nǹkan kan tí ó yẹ sí ikú tàbí sì ẹ̀wọ̀n.”
32 I ae la o Ageripa ia Peseto, Ina aole keia kanaka i hoopii ia Kaisara, ina ua pono ke wehe ia ia.
Agrippa sì wí fún Festu pé, “A bà dá ọkùnrin yìí sílẹ̀ bí ó bá ṣe pe kò ì tí ì fi ọ̀ràn rẹ̀ lọ Kesari.”