< II Samuela 9 >

1 I AKU la Davida, Aole anei e koe kekahi o ka ohana a Saula, i hoike aku ai au ia ia i aloha no Ionatana?
Dafidi sì béèrè pé, ọ̀kan nínú àwọn ẹni tí ń ṣe ìdílé Saulu kù síbẹ̀ bí? Kí èmi lè ṣe oore fún un nítorí Jonatani.
2 Aia kekahi kauwa no ka ohana o Saula, o Ziba kona inoa: a kii aku la lakou ia ia e hele io Davida la, i aku la ke alii ia ia, O oe no o Ziba? I mai la kela, Owau no o kau kauwa.
Ìránṣẹ́ kan sì ti wà ní ìdílé Saulu, orúkọ rẹ̀ sí ń jẹ́ Ṣiba, wọ́n sì pè é wá sọ́dọ̀ Dafidi, ọba sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Ìwọ ni Ṣiba bí?” Ó sì dáhùn wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ni.”
3 I aku la ke alii, Aole anei e koe kekahi o ka ohana a Saula, i hoike aku ai au i ke aloha o ke Akua ia ia? I mai la o Ziba i ke alii, Ke koe nei no kekahi keikikane a Ionatana, ua oopa na wawae ona.
Ọba sì wí pé, “Kò ha sí ọ̀kan nínú ìdílé Saulu síbẹ̀, kí èmi ṣe oore Ọlọ́run fún un?” Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Jonatani ní ọmọ kan síbẹ̀ tó ya arọ.”
4 I aku la ke alii ia ia, Auhea la ia? I mai la o Ziba i ke alii, aia maloko o ka hale o Makira ke keiki a Amiela i Lodebara.
Ọba sì wí fún un pé, “Níbo ni ó gbé wà?” Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Wò ó, òun wà ní ilé Makiri, ọmọ Ammieli, ní Lo-Debari.”
5 Alaila, hoouna aku la o Davida ke alii, a lawe mai la ia ia mai loko mai o ka hale o Makira ke keiki a Amiela mai Lodebara mai.
Dafidi ọba sì ránṣẹ́, ó sì mú un láti ilé Makiri ọmọ Ammieli láti Lo-Debari wá.
6 A hiki mai la Mepiboseta, ke keiki a Ionatana, ke keiki a Saula, io Davida la, kulou iho la ia ilalo kona alo, a hoomaikai aku la, I aku la o Davida, E Mepiboseta. I mai la kela, Eia kau kauwa.
Mefiboṣeti ọmọ Jonatani ọmọ Saulu sì tọ Dafidi wá, ó sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀, ó sì bú ọlá fún un. Dafidi sì wí pé, “Mefiboṣeti!” Òun sì dáhùn wí pé, “Wò ó, ìránṣẹ́ rẹ!”
7 I aku la o Davida ia ia, Mai makau oe: no ka mea, e oiaio no, e lokomaikai aku au ia oe no Ionatana kou makuakane, a e hoihoi aku au nou i ka aina a pau o kou kupunakane o Saula; a e ai mau oe i ka berena ma kuu papaaina.
Dafidi sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù, nítorí pé nítòótọ́ èmi ó ṣe oore fún ọ nítorí Jonatani baba rẹ, èmi ó sì tún fi gbogbo ilé Saulu baba rẹ fún ọ, ìwọ ó sì máa bá mi jẹun nígbà gbogbo ní ibi oúnjẹ mi.”
8 Kulou iho la ia, i mai la, Heaha kau kauwa, i ike mai ai oe ia'u he ilio make?
Mefiboṣeti sì tẹríba, ó sì wí pé, “Kí ni ìránṣẹ́ rẹ jásí, tí ìwọ ó fi máa wo òkú ajá bí èmi.”
9 Alaila kahea aku la ke alii ia Ziba ke kauwa a Saula, i aku la ia ia, Ua haawi aku au na ke keiki a kou haku i na mea a pau o Saula a o kana ohana a pau.
Ọba sì pe Ṣiba ìránṣẹ́ Saulu, ó sì wí fún un pé, “Gbogbo nǹkan tí í ṣe ti Saulu, àti gbogbo èyí tí í ṣe ti ìdílé rẹ̀ ni èmi fi fún ọmọ olúwa rẹ.
10 E malama oe i ka aina nona, o oe me au mau keiki a me au mau kauwa; a e lawe mai hoi oe i ai na ke keiki a kou haku e ai ai: aka, o Mepiboseta ke keiki a kou haku, e ai mau ia ma ko'u papaaina. Aia ia Ziba na keikikane he umi kumamalima, a me na kauwa he iwakalua.
Ìwọ, àti àwọn ọmọ rẹ, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ ni yóò sì máa ro ilẹ̀ náà fún un, ìwọ ni yóò sì máa mú ìkórè wá, ọmọ olúwa rẹ yóò sì máa rí oúnjẹ jẹ, ṣùgbọ́n Mefiboṣeti ọmọ olúwa rẹ yóò sì máa bá mi jẹun nígbà gbogbo ní ibi oúnjẹ mi.” (Ṣiba sì ní ọmọ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àti ogún ìránṣẹ́kùnrin.)
11 Alaila olelo aku la o Ziba i ke alii, E like me ka mea a pau a ko'u haku a ke alii i kauoha mai ai i kana kauwa, pela no e hana aku ai kau kauwa. A o Mepiboseta, e ai ia ma ko'u papaaina e like me kekahi keiki kane a ke alii.
Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí olúwa mi ọba ti pàṣẹ fún ìránṣẹ́ rẹ, bẹ́ẹ̀ náà ni ìránṣẹ́ rẹ ó ṣe.” Ọba sì wí pé, “Ní ti Mefiboṣeti, yóò máa jẹun ní ibi oúnjẹ mi, gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ ọba.”
12 He keikikane opiopio ka Mepiboseta, o Mika kona inoa: a o na mea a pau i noho ma ka hale o Ziba, he mau kauwa lakou na Mepiboseta.
Mefiboṣeti sì ní ọmọ kékeré kan, orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Mika. Gbogbo àwọn tí ń gbé ní ilé Ṣiba ni ó sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún Mefiboṣeti.
13 A noho iho la o Mepiboseta ma Ierusalema, a ai mau iho la ia ma ka papaaina o ke alii: a ua oopa kela ma kona mau wawae a elua.
Mefiboṣeti sì ń gbé ní Jerusalẹmu, òun a sì máa jẹun nígbà gbogbo ní ibi oúnjẹ ọba; òun sì yarọ ní ẹsẹ̀ rẹ̀ méjèèjì.

< II Samuela 9 >