< II Samuela 7 >

1 A I ka wa i noho ai ke alii iloko o kona hale, a hoomaha mai la o Iehova ia ia mai o a o, mai kona poe enemi a pau;
Ó sì ṣe, nígbà tí ọba ń gbé ní ilé rẹ̀, tí Olúwa sì fún un ní ìsinmi yíkákiri kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀.
2 I aku la ke alii ia Natana ke kaula, Eia hoi au ke noho nei iloko o ka hale kedera; aka, e noho ana ka pahu o Iehova maloko o na paku.
Ọba sì wí fún Natani wòlíì pé, “Sá wò ó, èmi ń gbé inú ilẹ̀ tí a fi kedari kọ́, ṣùgbọ́n àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ń gbé inú ibi tí a fi aṣọ gé.”
3 I aku la o Natana i ke alii, E hele oe e hana i ka mea a pau iloko o kou naau; no ka mea, me oe pu no o Iehova.
Natani sì wí fún ọba pé, “Lọ, kí o sì ṣe gbogbo èyí tí ó wà ní ọkàn rẹ, nítorí pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ.”
4 A ia po iho no, hiki mai la ka olelo a Iehova io Natana la, i mai la.
Ó sì ṣe ní òru náà, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Natani wá pé,
5 E hele oe e hai aku i kuu kauwa ia Davida, Eia ka Iehova e olelo aku nei, E hana anei oe i hale no'u e noho ai?
“Lọ, sọ fún ìránṣẹ́ mi, fún Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí, ìwọ ó ha kọ́ ilé fún mi tí èmi yóò gbé.
6 No ka mea, aole no au i noho iloko o ka hale maoli mai ka manawa mai a'u i alakai mai nei i na mamo a Iseraela mai Aigupita mai, a hiki i keia la; aka, ua hele no wau maloko o ka halelole, a me ka halelewa.
Nítorí pé, èmi kò ì ti gbé inú ilé kan láti ọjọ́ tí èmi ti mú àwọn ọmọ Israẹli gòkè ti ilẹ̀ Ejibiti wá, títí di òní yìí, ṣùgbọ́n èmi ti ń rìn nínú àgọ́, fún ibùgbé mi.
7 I ko'u hele ana a pau me na mamo a pau a Iseraela, i olelo aku anei au i kekahi ohana a Iseraela, i ka mea a'u i kauoha aku ai e hanai i ko'u poe kanaka i ka Iseraela, i ka i ana aku, Heaha ka mea e hana ole ai oukou i hale kedera no'u?
Ní ibi gbogbo tí èmi ti ń rìn pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ǹjẹ́ èmi ti bá ọ̀kan nínú ẹ̀yà Israẹli, tí èmi pa àṣẹ fún láti máa bọ́ àwọn ènìyàn mi àní Israẹli, sọ̀rọ̀ pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin kò fi kedari kọ́ ilé fún mi.”’
8 Nolaila hoi, e olelo aku oe i kuu kauwa ia Davida, Eia ka Iehova sabaota e olelo mai nei, I lawe mai no wau ia oe mai ka pahipa mai, mamuli mai hoi o ka poe hipa, i alii oe maluua o kuu poe kanaka o ka Iseraela.
“Ǹjẹ́, nítorí náà, báyìí ni ìwọ yóò sì wí fún ìránṣẹ́ mi àní Dafidi pé, ‘Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, Èmi ti mú ìwọ kúrò láti inú agbo àgùntàn wá láti má tẹ̀lé àwọn àgùntàn, mo sì fi ọ́ jẹ olórí àwọn ènìyàn mi, àní Israẹli.
9 Owau hoi kekahi pu me oe i kou mau wahi i hele aku ai, a ua hooki iho no wau i ou poe enemi a pau mai kou maka aku, a ua hookaulana aku au i kou inoa, e like me ka inoa o ka poe nui ma ka honua.
Èmi sì wà pẹ̀lú rẹ níbikíbi tí ìwọ ń lọ, èmi sá à gé gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ kúrò níwájú rẹ, èmi sì ti sọ orúkọ rẹ di ńlá, gẹ́gẹ́ bí orúkọ àwọn ènìyàn ńlá tí ó wà ní ayé.
10 Na'u hoi e hoike aku i wahi no ko'u poe kanaka no ka Iseraela, a e kanu iho no au ia lakou i noho ai lakou ma ko lakou wahi iho, aole e nee hou aku lakou; aole hoi e hoino hou mai ka poe keiki na ka ino ia lakou, e like me ka manawa mamua.
Èmi ó sì yan ibìkan fún àwọn ènìyàn mi, àní Israẹli, èmi ó sì gbìn wọ́n, wọn ó sì má gbé bí ibùjókòó tiwọn, wọn kì yóò sì sípò padà mọ́; àwọn ọmọ ènìyàn búburú kì yóò sì pọ́n wọn lójúmọ́, bí ìgbà àtijọ́.
11 A mai ka manawa mai a'u i hoonoho ai i na lunakanawai maluna o ko'u poe kanaka o ka Iseraela, a hiki i ka hoomaha ana ia oe mai kou poe enemi ae a pau. Eia hoi ka Iehova e i mai nei ia oe, Na Iehova no e hana i hale nou.
Àti gẹ́gẹ́ bí àkókò ìgbà tí èmi ti fi àṣẹ fún àwọn onídàájọ́ lórí àwọn ènìyàn mi, àní Israẹli, èmi fi ìsinmi fún ọ lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ. “‘Olúwa sì wí fún ọ pé Olúwa yóò kọ ilé kan fún ọ.
12 Aia pau kou mau la, a moe iho oe me ou poe kupuna, e hooku ae au i kau keiki mahope ou, i ka mea e puka ana mailoko ae o kou opu, a e hookupaa hoi au i kona aupuni.
Nígbà tí ọjọ́ rẹ bá pé, tí ìwọ ó sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ, èmi yóò sì gbé irú-ọmọ rẹ lékè lẹ́yìn rẹ, èyí tí ó ti inú rẹ jáde wá, èmi yóò sì fi ìdí ìjọba rẹ kalẹ̀.
13 Nana no e hana i hale no ko'u inoa, a e hookupaa hoi au i ka nohoalii o kona aupuni a mau loa aku.
Òun ó sì kọ́ ilé fún orúkọ mi, èmi yóò sì fi ìdí ìjọba rẹ kalẹ̀ láéláé.
14 Owau no auanei kona makuakane, a e lilo hoi ia i keiki na'u: a i hana ino kela, na'u no e paipai aku ia ia me ka laau ma ko ke kanaka, a me ka hahau ana ma ko na keiki a na kanaka.
Èmi ó máa ṣe baba fún un, òun yóò sì máa jẹ́ ọmọ mi. Bí òun bá dẹ́ṣẹ̀, èmi yóò sì fi ọ̀pá ènìyàn nà án, àti ìnà àwọn ọmọ ènìyàn.
15 Aka, aole au e lawe i ko'u aloha mai ona aku la, me a'u i lawe aku ai ia mea mai o Saula aku, ka mea a'u i hoolei aku ai mai ko'u alo aku.
Ṣùgbọ́n àánú mi kì yóò yípadà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí èmi ti mú un kúrò lọ́dọ̀ Saulu, tí èmi ti mú kúrò níwájú rẹ.
16 A e hookupaa mau loa ia aku kau ohana a me kou aupuni imua ou: e hookupaaia hoi kou nohoalii a mau loa aku.
A ó sì fi ìdílé rẹ àti ìjọba rẹ múlẹ̀ níwájú rẹ títí láé, a ó sì fi ìdí ìtẹ́ rẹ múlẹ̀ títí láé.’”
17 Ma keia mau olelo a pau, a ma keia hihio a pau ka Natana i olelo aku ai ia Davida.
Gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, àti gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìran yìí, bẹ́ẹ̀ ni Natani sì sọ fún Dafidi.
18 Alaila komo aku la o Davida ke alii iloko, a noho iho la imua o Iehova, a olelo aku la, Owai la hoi wau, e ka Haku e Iehova? Heaha hoi ko'u ohana i malama mai ai oe ia'u a hiki i neia wa?
Dafidi ọba sì wọlé lọ, ó sì dúró níwájú Olúwa, ó sì wí pé, “Olúwa Olódùmarè, ta ni èmi, àti kí sì ni ìdílé mi, tí ìwọ fi mú mi di ìsinsin yìí?
19 He mea uuku hoi keia imua o kou maka, e Iehova ka Haku; aka, ua olelo mai hoi oe no ka ohana a kau kauwa a liuliu aku mahope. Ua like anei keia me ko ke kanaka, e Iehova ka Haku?
Nǹkan kékeré ni èyí sá à jásí lójú rẹ, Olúwa Olódùmarè; ìwọ sì ti sọ nípa ìdílé ìránṣẹ́ rẹ pẹ̀lú ní ti àkókò tí o jìnnà. Èyí ha ṣe ìwà ènìyàn bí, Olúwa Olódùmarè?
20 Heaha ka mea hou aku e hiki ia Davida ke olelo aku ia oe? no ka mea, ua ike pono mai oe i kau kauwa nei, e Iehova ka Haku.
“Àti kín ní ó tún kù tí Dafidi ìbá tún máa wí fún ọ? Ìwọ, Olúwa Olódùmarè mọ̀ ìránṣẹ́ rẹ.
21 No ka pono o kau olelo, a e like me ko loko o kou naau kau i hana mai ai i keia mau mea nui a pau, i mea e ike ai kau kauwa.
Nítorí ọ̀rọ̀ rẹ, àti gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ ọkàn rẹ, ni ìwọ ṣe ṣe gbogbo nǹkan ńlá wọ̀nyí, kí ìránṣẹ́ rẹ lè mọ̀.
22 Nolaila, e Iehova e ke Akua, he nui oe; no ka mea, aohe mea like me oe, aohe hoi Akua e ae, o oe wale no; e like me ka mea a pau a makou i lohe ai ma ko makou pepeiao.
“Ìwọ sì tóbi, Olúwa Olódùmarè! Kò sì sí ẹni tí ó dàbí rẹ, kò sì sí Ọlọ́run kan lẹ́yìn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí àwa fi etí wá gbọ́.
23 Owai la ka lahuikanaka ma ka honua nei e like me kou poe kanaka me ka Iseraela, ka poe a ke Akua i kii aku ai e hoola i poe kanaka nona, i mea e kaulana ai kona inoa, a e hana aku no lakou i na mea nui a weliweli no kou aina, imua o kou poe kanaka, o ka poe au i hoola ae nou mai na lahuikanaka o Aigupita, a me ko lakou mau akua mai.
Orílẹ̀-èdè kan wo ni ó sì ń bẹ ní ayé tí ó dàbí àwọn ènìyàn rẹ, àní Israẹli, àwọn tí Ọlọ́run lọ rà padà láti sọ wọ́n di ènìyàn rẹ̀, àti láti sọ wọ́n ní orúkọ, àti láti ṣe nǹkan ńlá fún un yín, àti nǹkan ìyanu fún ilé rẹ̀, níwájú àwọn ènìyàn rẹ, tí ìwọ ti rà padà fún ara rẹ láti Ejibiti wá, àní àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn òrìṣà wọn.
24 No ka mea, ua hoolilo oe nou i kou kanaka i ka Iseraela, i poe kanaka nou mahope mau loa aku; a o oe, e Iehova, ua lilo mai oe i Akua no lakou.
Ìwọ sì fi ìdí àwọn ènìyàn rẹ, àní Israẹli kalẹ̀ fún ara rẹ láti sọ wọ́n di ènìyàn rẹ títí láé; ìwọ Olúwa sì wá di Ọlọ́run fún wọn.
25 Ano hoi, e Iehova ke Akua, e hookupaa mau loa oe i ka olelo au i olelo mai ai no kau kauwa a me kana ohana, a e hana mai e like me kau olelo.
“Ǹjẹ́, Olúwa Ọlọ́run, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ náà tí ìwọ sọ ní ti ìránṣẹ́ rẹ, àti ní ti ìdílé rẹ̀, kí ó dúró títí láé, kí ó sí ṣe bí ìwọ ti wí.
26 A e hoonani mau loa ia kou inoa, i ka i ana, O Iehova sabaota, oia ke Akua maluna o ka Iseraela: a e hookupaaia hoi ka ohana a kau kauwa a Davida imua ou.
Jẹ́ kí orúkọ rẹ ó ga títí láé, pé, ‘Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni Ọlọ́run lórí Israẹli!’ Sì jẹ́ kí a fi ìdílé Dafidi ìránṣẹ́ rẹ múlẹ̀ níwájú rẹ.
27 No ka mea, ua hoike mai oe, e Iehova sabaota, ke Akua no ka Iseraela, iloko o ka pepeiao o kau kauwa, i ka i ana mai, E hana au i hale nou: nolaila, ua manao iho kau kauwa iloko o kona naau e pule aku i keia pule ia oe.
“Nítorí pé ìwọ, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli ti sọ létí ìránṣẹ́ rẹ, pé, ‘Èmí ó kọ́ ilé kan fún ọ.’ Nítorí náà ni ìránṣẹ́ rẹ sì ṣe ní i lọ́kàn rẹ̀ láti gbàdúrà yìí sí ọ.
28 Ano hoi, e Iehova ka Haku, o oe no ua Akua la, a he oiaio hoi kau mau olelo; a ua olelo mua mai oe i keia lokomaikai i kau kauwa nei:
Ǹjẹ́, Olúwa Olódùmarè, ìwọ ni Ọlọ́run náà, àwọn ọ̀rọ̀ rẹ sì jásí òtítọ́, ìwọ sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ nǹkan rere yìí fún ìránṣẹ́ rẹ.
29 Nolaila hoi, e lealea mai oe, a e hoopomaikai mai i ka ohana a kau kauwa, i mau loa ia imua ou: no ka mea, ua olelo no oe, e Iehova ka Haku; a ma kau hoopomaikai ana e pomaikai ai ka ohana a kau kauwa mahope mau loa aku.
Ǹjẹ́, jẹ́ kí ó wù ọ́ láti bùkún ìdílé ìránṣẹ́ rẹ, kí ó wà títí láé níwájú rẹ, nítorí ìwọ, Olúwa Olódùmarè, ni ó ti sọ ọ́: sì jẹ́ kí ìbùkún wà ní ìdílé ìránṣẹ́ rẹ títí láé, nípasẹ̀ ìbùkún rẹ.”

< II Samuela 7 >