< II Samuela 6 >

1 HOULUULU hou ae la o Davida i na kanaka i waeia a pau o ka Iseraela, he kanakolu tausani.
Dafidi sì tún kó gbogbo àwọn akọni ọkùnrin ní Israẹli jọ, wọ́n sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún.
2 Ku ae la o Davida, a hele pu aku la me na kanaka a pau me ia mai Baale o ka Iuda, e halihali mai laila mai i ka pahu o ke Akua, i ka mea i heaia aku ai ka inoa, ka inoa o Iehova sabaota, o ka Mea e noho ana mawaena o na kerubima.
Dafidi sì dìde, ó sì lọ àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ń bẹ́ lọ́dọ̀ rẹ́, láti Baalahi ní Juda wá, láti mú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run tí ibẹ̀ wá, èyí tí a ń pe orúkọ rẹ̀ ní orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun tí ó jókòó láàrín àwọn kérúbù.
3 Kau aku la lakou i ka pahu o ke Akua maluna o ke kaa hou, a lawe mai la ia mailoko ae o ka hale o Abinadaba ma Gibea. Kai aku la o Uza a me Ahio na keikikane a Abinadaba i ke kaa hou.
Wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run náà gun kẹ̀kẹ́ tuntun kan, wọ́n sì mú un láti ilé Abinadabu wá, èyí tí ó wà ní Gibeah: Ussa àti Ahio, àwọn ọmọ Abinadabu sì ń dá kẹ̀kẹ́ tuntun náà.
4 Lawe mai la lakou ia mea mailoko mai o ka hale o Abinadaba ma Gibea, e hele pu ana me ka pahu o ke Akua, a hele aku la o Ahio imua o ka pahu.
Wọ́n sì mú un láti ilé Abinadabu jáde wá, tí ó wà ní Gibeah, pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, Ahio sì ń rìn níwájú àpótí ẹ̀rí náà.
5 Hookani aku la o Davida a me ka ohana a Iseraela a pau imua o Iehova, me na mea kani o na laau o kela ano o keia ano; me na lira, na pesaleteria, na timeberela, na korineta, a me na kimebala.
Dafidi àti gbogbo ilé Israẹli sì ṣiré níwájú Olúwa lára gbogbo onírúurú ohun èlò orin tí a fi igi arère ṣe àti lára ìlù haapu, ní ara tambori, sisitirumu àti lára kimbali.
6 A hiki aku la lakou i kahi hehipalaoa no Nakona, o aku la o Uza i kona lima i ka pahu o ke Akua, a paa aku la ia; no ka mea ua okupe na bipikauo.
Nígbà tí wọ́n dé sí ilẹ̀ ìpakà Nakoni, Ussa sì na ọwọ́ rẹ̀ sí àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, ó sì dìímú, nítorí tí màlúù kọsẹ̀.
7 Huhu mai la o Iehova ia Uza, a hahau mai la ke Akua ia ia malaila, no kona hala; a make iho la ia malaila ma ka pahu o ke Akua.
Ìbínú Olúwa sì ru sí Ussa; Ọlọ́run sì pa á níbẹ̀ nítorí ìṣísẹ̀ rẹ̀; níbẹ̀ ni ó sì kù ní ẹ̀bá àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run.
8 Ukiuki iho la o Davida i ko Iehova hahau ana aku ia Uza; a kapa aku la o Davida i ka inoa o ia wahi, o Perezuza.
Inú Dafidi sì bàjẹ́ nítorí tí Olúwa gé Ussa kúrò, ó sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Peresi-Usa títí ó fi di òní yìí.
9 Makau iho la o Davida ia Iehova ia la, i iho la, Pehea la e hiki aku ai ka pahu o ke Akua io'u la?
Dafidi sì bẹ̀rù Olúwa ní ọjọ́ náà, ó sì wí pé, “Àpótí ẹ̀rí Olúwa yóò ti ṣe tọ̀ mí wá?”
10 Nolaila, aole i lawe o Davida i ka pahu o Iehova io na la i ke kulanakauhale o Davida: aka, lawe ae la o Davida ia mea iloko o ka hale o Obededoma no Gata.
Dafidi kò sì fẹ́ mú àpótí ẹ̀rí Olúwa sọ́dọ̀ rẹ̀ sí ìlú Dafidi; ṣùgbọ́n Dafidi sì mú un yà sí ilé Obedi-Edomu ará Gitti.
11 A waiho wale ia ka pahu o Iehova ma ka hale o Obededoma no Gata i na malama ekolu, a hoopomaikai mai la o Iehova ia Obededoma a me ko ka hale ona a pau.
Àpótí ẹ̀rí Olúwa sì gbé ní ilé Obedi-Edomu ará Gitti ní oṣù mẹ́ta; Olúwa sì bùkún fún Obedi-Edomu, àti gbogbo ilé rẹ̀.
12 Hai aku la lakou ia Davida i ke alii, i mai la, E, ua hoopomaikai o Iehova i ko ka hale o Obededoma, a me na mea a pau ia ia, no ka pahu o ke Akua. A hele aku la o Davida, a lawe mai la i ka pahu o ke Akua, mai ka hale o Obededoma mai, a iloko o ke kulanakauhale o Davida me ka olioli.
A sì rò fún Dafidi ọba pé, “Olúwa ti bùkún fún ilé Obedi-Edomu, àti gbogbo èyí tí í ṣe tirẹ̀, nítorí àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run.” Dafidi sì lọ, ó sì mú àpótí ẹ̀rí náà gòkè láti ilé Obedi-Edomu wá sí ìlú Dafidi pẹ̀lú ayọ̀.
13 Aia, hele aku la ka poe halihali i ka pahu o Iehova i na ana eono, mohai aku la oia i na bipi a me na mea i kupaluia.
Ó sì ṣe nígbà tí àwọn ènìyàn tí ó ru àpótí ẹ̀rí Olúwa bá sì ṣí ẹsẹ̀ mẹ́fà, òun a sì fi màlúù àti ẹran àbọ́pa rú ẹbọ.
14 Haa ikaika aku la hoi o Davida imua o Iehova; a ua kaeiia o Davida i ka epoda olona.
Dafidi sì fi gbogbo agbára rẹ̀ jó níwájú Olúwa; Dafidi sì wọ efodu ọ̀gbọ̀.
15 A halihali mai la o Davida a me ka ohana a Iseraela a pau i ka pahu o Iehova me ka hooho ana, a me ka hookani ana i ka pu.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti gbogbo ilé Israẹli sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa gòkè wá, pẹ̀lú ìhó ayọ̀, àti pẹ̀lú ìró ìpè.
16 A i ka hiki ana mai o ka pahu o ke Akua iloko o ke kulanakauhale o Davida, nana aku la o Mikala ke kaikamahine a Saula ma ka puka makani, a ike aku la i ke alii ia Davida e lele ana, a e haa ana imua o Iehova; hoowahawaha aku la kona naau ia ia.
Bí àpótí ẹ̀rí Olúwa sì ti wọ ìlú Dafidi wá; Mikali ọmọbìnrin Saulu sì wo láti ojú fèrèsé, ó sì rí Dafidi ọba ń fò sókè ó sì ń jó níwájú Olúwa; òun sì kẹ́gàn rẹ̀ ní ọkàn rẹ̀.
17 Lawe mai la lakou i ka pahu o Iehova iloko, a kau iho la ia ma kona wahi, mawaena konu o ka halelewa a Davida i kukulu ai nona: a mohai aku la o Davida i na mohaikuni, a me na mohai aloha imua o Iehova.
Wọ́n sì mú àpótí ẹ̀rí Olúwa náà wá, wọ́n sì gbé e kalẹ̀ sípò rẹ̀ láàrín àgọ́ náà tí Dafidi pa fún un. Dafidi sì rú ẹbọ sísun àti ẹbọ ìrẹ́pọ̀ níwájú Olúwa.
18 A pau ae la ka Davida mohai ana i na mohaikuni a me na mohai hoomalu, hoomaikai aku la ia i na kanaka ma ka inoa o Iehova sabaota.
Dafidi sì parí ìṣe ẹbọ sísun àti ẹbọ ìrẹ́pọ̀ náà, ó sì súre fún àwọn ènìyàn náà ní orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
19 A haawi aku la ia na ka poe kanaka a pau, na ke anaina kanaka a pau o ka Iseraela, na na wahine a me na kane, na kela mea keia mea, i ka popo berena a me kauwahi ia, a me kekahi pai huawaina. A hoi hou aku la na kanaka a pau i ko lakou mau wahi.
Ó sì pín fún gbogbo àwọn ènìyàn náà, àní fún gbogbo ọ̀pọ̀ ènìyàn Israẹli, àti ọkùnrin àti obìnrin; fún olúkúlùkù ìṣù àkàrà kan àti ekìrí ẹran kan, àti àkàrà díndín kan. Gbogbo àwọn ènìyàn náà sì túká lọ, olúkúlùkù sí ilé rẹ̀.
20 Hoi hou aku la o Davida e hooaloha i ko ka hale ona. Hele mai la o Mikala ke kaikamahine a Saula e halawai me Davida, i mai la, Kai ka nani o ke alii o ka Iseraela i keia la, nana i wehe ae i kona kapa i keia la imua o na maka o na kauwawahine a kona poe kanaka, e like me ka wehe hilahila ole ana o kekahi kanaka lapuwale.
Dafidi sì yípadà láti súre fún àwọn ará ilé rẹ̀, Mikali ọmọbìnrin Saulu sì jáde láti wá pàdé Dafidi, ó sì wí pé, “Báwo ni ọba Israẹli ṣe ṣe ara rẹ̀ lógo bẹ́ẹ̀ lónìí, tí ó bọ́ ara rẹ̀ sílẹ̀ lónìí lójú àwọn ìránṣẹ́bìnrin àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn lásán tí ń bọ́ra rẹ̀ sílẹ̀.”
21 I aku la o Davida ia Mikala, Imua ia o Ieliova, nana au i koho mai imua o kou makuakane, imua hoi o kana ohana a pau e hoonoho ia'u i alii maluna o ko Iehova poe kanaka, maluna o ka Iseraela: nolaila hoi e hula au imua o Iehova.
Dafidi sì wí fún Mikali pé, “Níwájú Olúwa ni, ẹni tí ó yàn mí fẹ́ ju baba rẹ lọ, àti ju gbogbo ìdílé rẹ lọ, láti fi èmi ṣe olórí àwọn ènìyàn Olúwa, àní lórí Israẹli, èmi ó sì súre níwájú Olúwa.
22 A ma keia hope, e lilo ana au i mea i hoowahawahaia, a i mea ino hoi imua o ko'u maka iho: a o ka poe kauwawahine au i olelo mai ai, e hoomaikaiia mai hoi au e lakou.
Èmi ó sì tún rẹ ara mi sílẹ̀ jú bẹ́ẹ̀ lọ, èmi ó sì ṣe aláìníyìn lójú ara mi, àti lójú àwọn ìránṣẹ́bìnrin náà ti ìwọ wí, lọ́dọ̀ wọn náà ni èmi ó sì ní ògo.”
23 Nolaila, aohe keiki a Mikala ke kaikamahine a Saula a hiki i kona la i make ai.
Mikali ọmọbìnrin Saulu kò sì bí ọmọ, títí o fi di ọjọ́ ikú rẹ̀ nítorí tí ó sọ̀rọ̀-òdì yìí sí Dafidi.

< II Samuela 6 >