< II Samuela 12 >

1 HOOUNA mai la o Iehova ia Natana io Davida la: hele mai la ia io na la, i mai la ia ia, Elua mau kanaka ma kekahi kulanakauhale; ua waiwai kekahi, a ua ilihune kekahi.
Olúwa sì rán Natani sí Dafidi òun sì tọ̀ ọ́ wá, ó sì wí fún un pé, “Ọkùnrin méjì ń bẹ ní ìlú kan; ọ̀kan jẹ́ ọlọ́rọ̀, èkejì sì jẹ́ tálákà.
2 He nui loa hoi na ohana hipa a me na ohana bipi a ke kanaka waiwai:
Ọkùnrin ọlọ́rọ̀ náà sì ní àgùntàn àti màlúù lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
3 Aka, na ke kanaka ilihune, hookahi wale no keikihipa wahine uuku ana i kuai ai a hanai iho ai: noho pu iho la ia me ia a me na keiki ana; ai iho la ia i kana ai, a inu hoi ma kona kiaha, a moe iho la ia ma kona poli, a me he kaikamahine la ia nana.
Ṣùgbọ́n ọkùnrin tálákà náà kò sì ní nǹkan bí kò ṣe àgùntàn kékeré kan èyí tí ó sì ń tọ́, ó sì dàgbà ní ọwọ́ rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀; a máa jẹ nínú oúnjẹ rẹ̀, a sí máa mu nínú ago rẹ̀, a sì máa dùbúlẹ̀ ní àyà rẹ̀, ó sì dàbí ọmọbìnrin kan fún un.
4 A hele mai la he kanaka hele i ua kanaka waiwai la, a aua iho la ia ke lawe i ko kana ohana hipa a me kana ohana bipi e kalua na ua kanaka la i hele mai io na la; aka, kii aku la ia i ke keikihipa a ke kanaka ilihune, a kalua iho la na ke kanaka i hele mai io na la.
“Àlejò kan sì tọ ọkùnrin ọlọ́rọ̀ náà wá, òun kò sì fẹ́ mú nínú àgùntàn rẹ̀, àti nínú màlúù rẹ̀, láti fi ṣe àlejò fún ẹni tí ó tọ̀ ọ́ wá, o sì mú àgùntàn ọkùnrin tálákà náà fi ṣe àlejò fún ọkùnrin tí ó tọ̀ ọ́ wá.”
5 Huhu loa aku la o Davida i ua kanaka la; i aku la oia ia Natana, Ma ke ola ana o Iehova, he oiaio no e make ke kanaka nana i hana ia mea.
Ìbínú Dafidi sì ru gidigidi sí ọkùnrin náà; ó sì wí fún Natani pé, “Bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ọkùnrin náà tí ó ṣe nǹkan yìí, kíkú ni yóò kú.
6 A e hoihoi pa-ha aku ia i ke keikihipa, no ka hana ana ia mea, a no ka mea, aohe ona aloha.
Òun yóò sì san àgùntàn náà padà ní mẹ́rin mẹ́rin, nítorí tí ó ṣe nǹkan yìí àti nítorí tí kò ní àánú.”
7 I aku la o Natana ia Davida, O oe no ia kanaka: Penei ka Iehova ke Akua no ka Iseraela i olelo mai ai, Ua poni aku no au ia oe i alii raaluna o ka Iseraela, a ua hoopakele hoi au ia oe i ka lima o Saula:
Natani sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ ni ọkùnrin náà. Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Èmi fi ọ́ jẹ ọba lórí Israẹli, èmi sì gbà ọ́ lọ́wọ́ Saulu.
8 A haawi aku la au i ka hale o kou haku nou, a me na wahine a kou haku iloko o kou poli, a haawi aku la hoi au i ka ohana o ka Iseraela a me ka Iuda nou: a ina he uuku keia mau mea, alaila e haawi aku hoi au nau, i kela mau mea, a i keia mau mea.
Èmi sì fi ilé olúwa rẹ fún ọ, àti àwọn obìnrin olúwa rẹ sí àyà rẹ, èmi sì fi ìdílé Israẹli àti ti Juda fún ọ; tí àwọn wọ̀nyí bá sì kéré jù fún ọ èmi ìbá sì fún ọ sí i jù bẹ́ẹ̀ lọ.
9 Heaha hoi kau i hoowahawaha ai i ke kanawai o Iehova, e hana i ka hewa imua o kona maka? Ua pepehi ae oe ia Uria ka Heta me ka pahikaua, a ua lawe oe i kana wahine i wahine nau; a ua pepehi i ke kane me ka pahikaua a ka poe mamo a Amona.
Èéṣe tí ìwọ fi kẹ́gàn ọ̀rọ̀ Olúwa, tí ìwọ fi ṣe nǹkan tí ó burú lójú rẹ̀, àní tí ìwọ fi fi idà pa Uriah ará Hiti, àti tí ìwọ fi mú obìnrin rẹ̀ láti fi ṣe obìnrin rẹ, o sì fi idà àwọn ọmọ Ammoni pa á.
10 No ia mea hoi, aole loa e kaawale aku ka pahikaua mai kou ohana aku; no ka mea, ua hoowahawaha mai oe ia'u, a ua lawe oe i ka wahine a Uria ka Heta i wahine nau.
Ǹjẹ́ nítorí náà idà kì yóò kúrò ní ilé rẹ títí láé; nítorí pé ìwọ gàn mí, ìwọ sì mú aya Uriah ará Hiti láti ṣe aya rẹ.’
11 Penei ka Iehova i olelo mai ai, Eia hoi, e hoala auanei au i ka ino ku e ia oe maloko o kou hale, a e lawe au i kau mau wahine imua o kou maka, a e haawi aku ia lakou na kou hoalauna, a e moe ia me kau mau wahine imua o keia la.
“Báyìí ni Olúwa wí, kíyèsi i, ‘Èmi ó jẹ́ kí ibi kí ó dìde sí ọ láti inú ilé rẹ wá, èmi ó sì gba àwọn obìnrin rẹ lójú rẹ, èmi ó sì fi wọ́n fún aládùúgbò rẹ, òun ó sì bá àwọn obìnrin rẹ sùn níwájú òòrùn yìí.
12 No ka mea, ua hana malu oe i kau; aka, e hana au i keia mea imua o ka Iseraela a pau, a imua hoi o ka la.
Àti pé ìwọ ṣe é ní ìkọ̀kọ̀, ṣùgbọ́n èmi ó ṣe nǹkan yìí níwájú gbogbo Israẹli, àti níwájú òòrùn.’”
13 I aku la o Davida ia Natana, Ua hana hewa wau ia Iehova. I mai la o Natana ia Davida, Ua kala aku hoi o Iehova i kou hewa; aole oe e make.
Dafidi sì wí fún Natani pé, “Èmi ṣẹ̀ sí Olúwa!” Natani sì wí fún Dafidi pé, “Olúwa pẹ̀lú sì ti mú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kúrò; ìwọ kì yóò kú.
14 Aka, no ka mea, ma keia hana ana au, ua loaa i ka poe enemi o Iehova ke kumu e olelo hoino ai, he oiaio no e make ke keiki i hanau mai nau.
Ṣùgbọ́n nítorí nípa ìwà yìí, ìwọ fi ààyè sílẹ̀ fún àwọn ọ̀tá Olúwa láti sọ ọ̀rọ̀-òdì, ọmọ náà tí a ó bí fún ọ, kíkú ní yóò kú.”
15 Hoi aku la o Natana i kona hale. Hahau mai la o Iehova i ke keiki a ka wahine a Uria i hanau mai ai na Davida, a mai nui iho la ia.
Natani sì lọ sí ilé rẹ̀ Olúwa sì fi ààrùn kọlu ọmọ náà tí obìnrin Uriah bí fún Dafidi, ó sì ṣe àìsàn púpọ̀.
16 Nolaila, nonoi aku la o Davida i ke Akua no ke keiki: hookeai iho la o Davida, komo aku la, a moe iho la ma ka honua a ao ka po.
Dafidi sì bẹ Ọlọ́run nítorí ọmọ náà, Dafidi sì gbààwẹ̀, ó sì wọ inú ilé lọ, ó sì dùbúlẹ̀ lórí ilé ni òru náà.
17 Ku ae la na lunakahiko o kona hale, hele aku la io na la e hoala ia ia mai ka honua ae: aole ia i ae aku, aole hoi i ai i ka ai me lakou.
Àwọn àgbàgbà ilé rẹ̀ sì dìde tọ̀ ọ́ lọ, láti gbé e dìde lórí ilé, ó sì kọ̀, kò sì bá wọn jẹun.
18 A i ka hiku o ka la, make iho la ke keiki. Makau iho la na kauwa a Davida e hai aku ia ia, ua make ke keiki; i ae la lakou, Aia i ke ola ana o ke keiki, olelo aku la kakou ia ia, aole ia i hoolohe mai i ko kakou leo: he oiaio no, e hana eha oia ia ia iho, ke hai aku kakou ia ia, ua make ke keiki.
Ní ọjọ́ keje, ọmọ náà sì kú. Àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì bẹ̀rù láti wí fún un pé, ọmọ náà kú: nítorí tí wọ́n wí pé, “Kíyèsi i, nígbà tí ọmọ náà ń bẹ láààyè, àwa sọ̀rọ̀ fún un, òun kọ̀ si gbọ́ ohùn wa! Ǹjẹ́ yóò ti ṣe ara rẹ̀ ní èṣe tó, bí àwa bá wí fún un pé, ọmọ náà kú.”
19 A ike ae la o Davida i ka hamumumu a na kauwa ana, ike iho la o Davida, ua make ke keiki: nolaila i aku la o Davida i kana mau kauwa, Ua make anei ke keiki? I mai la lakou, Ua make.
Nígbà tí Dafidi sì rí pé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ń sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, Dafidi sì kíyèsi i, pé ọmọ náà kú, Dafidi sì béèrè lọ́wọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ọmọ náà kú bí?” Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Ó kú.”
20 Alaila, ku ae la o Davida mai ka honua aku, auau iho la, a hamo iho la i ka aila, aahu iho la ia ia i ka lole hou, hele aku la i ka hale o Iehova, a hoomana aku la. Alaila hoi mai la ia i kona hale: a kena aku la ia, a kau mai la lakou i ka ai imua ona, a ai iho la ia.
Dafidi sì dìde ní ilẹ̀, ó sì wẹ̀, ó fi òróró pa ara, ó sì pààrọ̀ aṣọ rẹ̀, ó sì wọ inú ilé Olúwa lọ, ó sì wólẹ̀ sin, ó sì wá sí ilé rẹ̀ ó sì béèrè, wọ́n sì gbé oúnjẹ kalẹ̀ níwájú rẹ̀, ó sì jẹun.
21 Alaila, i aku la kana mau kauwa ia ia. Heaha keia au i hana iho nei? hookeai iho la oe me ka uwe i ke keiki i kona wa e ola ana; a make iho ke keiki, ua ala ae oe a ai iho i ka ai.
Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì bí léèrè pé, “Kí ni èyí tí ìwọ ṣe yìí? Nítorí ọmọ náà nígbà tí ó ń bẹ láààyè ìwọ gbààwẹ̀, o sì sọkún; ṣùgbọ́n nígbà tí ọmọ náà kú, ó dìde ó sì jẹun.”
22 I mai la kela, A e ola ana ke keiki, hookeai iho la au me ka uwe: i iho la au, Malama paha e aloha mai ke Akua ia'u i ola ke keiki.
Ó sì wí pé, “Nígbà tí ọmọ náà ń bẹ láààyè, èmi gbààwẹ̀, èmi sì sọkún: nítorí tí èmi wí pé, ‘Ta ni ó mọ̀? Bí Olúwa ó ṣàánú mi, kí ọmọ náà le yè.’
23 Ano hoi, ua make ia: no ke aha hoi au e hookeai ai? E hiki anei ia'u ke hoihoi mai ia ia? Owau ke hele aku io na la, aka, aole ia e hoi hou mai io'u nei.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ó ti kú, nítorí kín ni èmi ó ṣe máa gbààwẹ̀? Èmi ha tún lè mú un padà bí? Èmi ni yóò tọ̀ ọ́ lọ, òun kì yóò sì tún tọ̀ mí wá.”
24 Hooluolu aku la o Davida ia Bateseba i kana wahine; komo aku la ia iloko io na la, a moe me ia: a hanau mai la ia i keikikane, a kapa aku la kela i kona inoa, o Solomona; a aloha mai la o Iehova ia ia.
Dafidi sì ṣìpẹ̀ fún Batṣeba aya rẹ̀, ó sì wọlé tọ̀ ọ́, ó sì bá a dàpọ̀, òun sì bí ọmọkùnrin kan, Dafidi sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Solomoni, Olúwa sì fẹ́ ẹ.
25 Hoouna mai la ia i ke kaula ia Natana, a kapa mai la ia i kona inoa o Iedidia, no Iehova.
Ó sì rán Natani wòlíì, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Jedidiah, nítorí Olúwa.
26 Kaua aku la o Ioaba ia Raba o na mamo a Amona, a hoopio mai la i ke kulanakauhale alii.
Joabu sì bá Rabba ti àwọn ọmọ Ammoni jagun, ó sì gba ìlú ọba wọn.
27 Hoouna mai la o Ioaba i na elele io Davida la, i mai la, E, ua kana aku no wau ia Raba, a ua hoopio iho i ke kulanakauhale wai.
Joabu sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí Dafidi, ó sì wí pé, “Èmi ti bá Rabba jà, èmi sì ti gba àwọn ìlú olómi.
28 Ano hoi, e hoakoakoa pu mai oe i na kanaka e koe, e kaua aku i ke kulanakauhale, a e hoopio ia wahi; o pio auanei ke kulanakauhale ia'u, a e kaheaia ko'u inoa maluna ona.
Ǹjẹ́ nítorí náà kó àwọn ènìyàn ìyókù jọ, kí o sì dó ti ìlú náà, kí o sì gbà á, kí èmi má bá à gba ìlú náà kí a má ba à pè é ní orúkọ mi.”
29 Hoakoakoa pu ae la o Davida i na kanaka a pau, a hele aku la i Raba, kaua aku la ia, a hoopio iho la ia wahi.
Dafidi sì kó gbogbo ènìyàn náà jọ, sí Rabba, ó sì bá a jà, ó sì gbà á.
30 Lawe ae la hoi ia i ka papale o ko lakou alii, mailuna o kona poo, ma ke kaupaona ana, he talena gula ia, me na pohaku makamae, a ua kauia maluna o ke poo o Davida. A lawe mai la ia i ka waiwai pio o ke kulanakauhale he nui loa.
Òun sì gba adé ọba wọn kúrò lórí rẹ̀, ìwúwo rẹ̀ sì jẹ́ tálẹ́ǹtì wúrà kan, ó sì ní òkúta oníyebíye lára rẹ̀; a sì fi dé Dafidi lórí. Òun sì kó ìkógun ìlú náà ni ọ̀pọ̀lọpọ̀.
31 Lawe ae la hoi oia i na kanaka maloko, a kau iho la ia lakou malalo o na pahiolo, a malalo o na mea hao oioi, a malalo hoi o na koilipi hao, a hoohele aku la hoi ia lakou mawaena o ka umu pohakuula: pela ia i hana aku ai i na kulanakauhale a pau i na mamo a Amona. A hoi aku la o Davida a me na kanaka a pau i Ierusalema.
Ó sì kó àwọn ènìyàn náà tí ó wà nínú rẹ̀, ó sì fi wọ́n sí iṣẹ́ ayùn, àti sí iṣẹ́ nǹkan ìtulẹ̀ tí a fi irin ṣe, àti sí iṣẹ́ àáké irin, ó sì fi wọ́n sí iṣẹ́ bíríkì ṣíṣe, bẹ́ẹ̀ náà ni òun sì ṣe sí gbogbo ìlú àwọn ọmọ Ammoni. Dafidi àti gbogbo àwọn ènìyàn náà sì padà sí Jerusalẹmu.

< II Samuela 12 >