< II Samuela 11 >

1 A I ka makahiki hou, i ka manawa e hele aku ai na alii [i ke kaua, ] hoouna aku la o Davida ia Ioaba, a me na kauwa ana me ia, a me ka Iseraela a pau; a luku aku la lakou i ka poe mamo a Amona; a pue aku la ia Raba: aka, noho iho la o Davida ma Ierusalema ia manawa.
Lẹ́yìn ìgbà tí ọdún yípo, ní àkókò ìgbà tí àwọn ọba máa ń jáde ogun, Dafidi sì rán Joabu, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, àti gbogbo Israẹli; wọ́n sì pa àwọn ọmọ Ammoni, wọ́n sì dó ti Rabba. Dafidi sì jókòó ní Jerusalẹmu.
2 A i ka manawa ahiahi, ala'e la o Davida mai kona wahi moe, a holoholo ae la maluna o ka hale o ke alii: nana aku la ia mai luna ae o ka hale i kekahi wahine e auau ana: a he maikai loa ua wahine la ke nanaia'ku.
Ó sì ṣe, ní ìgbà àṣálẹ́ kan, Dafidi sì dìde ní ibùsùn rẹ̀, ó sì ń rìn lórí òrùlé ilé ọba, láti orí òrùlé náà ni ó sì rí obìnrin kan tí ó ń wẹ̀ ara rẹ̀; obìnrin náà sì ṣe arẹwà lójú láti wò.
3 Hoouna aku la o Davida e ninau aku no ka wahine. I mai la kekahi, Aole anei keia o Bateseba ke kaikamahine a Eliama, ka wahine hoi a Uria ka Heta?
Dafidi sì ránṣẹ́ ó sì béèrè obìnrin náà. Ẹnìkan sì wí pé, “Èyí ha kọ́ ni Batṣeba, ọmọbìnrin Eliamu, aya Uriah ará Hiti.”
4 Hoouna aku la o Davida i na mea kii aku, a lalau aku la ia ia: a hele mai la ia iloko io na la, a moe iho la kela me ia; no ka mea, ua huikalaia oia i kona haumia ana: a hoi hou aku la ia i kona hale.
Dafidi sì rán àwọn ìránṣẹ́, ó sì mú un; ó sì wọ inú ilé tọ̀ ọ́ lọ, ó sì bá a dàpọ̀, nígbà tí ó sì wẹ ara rẹ̀ mọ́ tán, ó sì padà lọ sí ilé rẹ̀.
5 A hapai ae la ua wahine la, hoouna aku la a hai ia Davida, i ka i ana, Ua hapai au.
Obìnrin náà sì lóyún, ó sì ránṣẹ́ ó sì sọ fún Dafidi, ó sì wí pé, “Èmi ti lóyún.”
6 Hoouna aku la o Davida io Ioaba la, i aku la, E hoouna mai oe ia Uria ka Heta i o'u nei. A hoouna mai la o Ioaba ia Uria io Davida la.
Dafidi sì ránṣẹ́ sí Joabu, pé, “Rán Uriah ará Hiti sí mi.” Joabu sì rán Uriah sí Dafidi.
7 A hiki mai la o Uria io na la, ninau aku la o Davida ia ia i ka pomaikai o Ioaba, me ka pomaikai o na kanaka, a me ka pomaikai ana o ke kaua.
Nígbà tí Uriah sì dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, Dafidi sì bi í léèrè báwo ni Joabu ti ṣe àti àlàáfíà àwọn ènìyàn náà, àti bí ogun náà ti ń ṣe.
8 I aku la o Davida ia Uria, e iho iho oe i kou hale, a e holoi i kou wawae. A hele aku la o Uria iwaho o ka hale o ke alii, a ukali aku la kekahi ai mahope ona na ke alii aku.
Dafidi sì wí fún Uriah pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ, kí o sì wẹ ẹsẹ̀ rẹ.” Uriah sì jáde kúrò ní ilé ọba, oúnjẹ láti ọ̀dọ̀ ọba wá sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
9 Aka, hiamoe iho la o Uria ma ka puka o ka hale o ke alii me na kauwa a pau a kona haku, aole ia i hele aku i kona hale.
Ṣùgbọ́n Uriah sun ní ẹnu-ọ̀nà ilé ọba lọ́dọ̀ gbogbo ìránṣẹ́ olúwa rẹ̀, kò sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀.
10 Hai aku la lakou ia Davida, i aku la, Aole i hele aku o Uria i kona hale. Ninau aku la o Davida ia Uria, Aole anei oe i hele mai mai kou hele ana? Heaha hoi kau i hele ole aku ai i kou hale?
Nígbà tí wọ́n sì sọ fún Dafidi pé, “Uriah kò sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀,” Dafidi sì wí fún Uriah pé, “Ṣe bí ọ̀nà àjò ni ìwọ ti wá? Èéha ti ṣe tí ìwọ kò fi sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ.”
11 I aku la o Uria ia Davida, Ke noho nei ka pahuberita, a o ka Iseraela a o ka Iuda iloko o na halelewa; ke hoomoana la hoi kuu haku o Ioaba me na kauwa a kuu haku mawaho ma ke kula; e komo anei hoi au iloko o ko'u hale e ai, a e inu, a e moe me ka'u wahine? Ma kou ola ana, me ke ola ana hoi o kou uhane, aole au e hana ia mea.
Uriah sì wí fún Dafidi pé, “Àpótí ẹ̀rí, àti Israẹli, àti Juda jókòó nínú àgọ́; àti Joabu olúwa mi, àti àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi wà ní ibùdó ní pápá, èmi ó ha lọ sí ilé mi, láti jẹ àti láti mu, àti láti bá obìnrin mi sùn? Bí ìwọ bá wà láààyè, àti bí ẹ̀mí rẹ́ si ti ń bẹ láààyè, èmi kì yóò ṣe nǹkan yìí.”
12 I aku la o Davida ia Uria, E noho iho hoi oe i keia la, a apopo e kuu aku ai au ia oe e hoi. A noho iho la o Uria ma Ierusalema ia la, a hiki i kekahi la ae.
Dafidi sì wí fún Uriah pé, “Sì dúró níhìn-ín lónìí, lọ́la èmi ó sì jẹ́ kí ìwọ ó lọ.” Uriah sì dúró ní Jerusalẹmu ní ọjọ́ náà, àti ọjọ́ kejì.
13 Kahea aku la o Davida ia ia, a ai iho la ia a inu hoi imua ona; hoinu iho la o Davida ia ia a ona: a ahiahi ae la, hele aku la ia iwaho e moe ma kona wahi moe me na kauwa o kona haku, aole nae ia i hele i kona hale.
Dafidi sì pè é, ó sì jẹ, ó sì mú nítorí rẹ̀; ó sì mu kí ọtí pa á; òun sì jáde ní alẹ́ lọ sí ibùsùn rẹ̀ lọ́dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ olúwa rẹ̀, kò sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé rẹ̀.
14 A kakahiaka ae, kakau iho la o Davida i ka palapala ia Ioaba, a hoouka aku la ia ma ka lima o Uria.
Ó sì ṣe ní òwúrọ̀, Dafidi sì kọ̀wé sí Joabu, ó fi rán Uriah.
15 Kakau iho la ia iloko o ka palapala, i ka i ana'ku, E hoonoho aku oe ia Uria ma ke alo o ke kaua ikaika, a e hoi i hope oukou mai ona aku la, i pepehiia'i oia a make.
Ó sì kọ sínú ìwé pé, “Fi Uriah síwájú ibi tí ogun gbé le, kí ẹ sì fàsẹ́yìn, kí wọn lè kọlù ú, kí ó sì kú.”
16 A i ko Ioaba nana ana aku i ke kulanakauhale, hoonoho aku la oia ia Uria ma kahi ana i ike ai ilaila na kanaka ikaika.
Ó sì ṣe nígbà tí Joabu ṣe àkíyèsí ìlú náà, ó sì yan Uriah sí ibi kàn ní ibi tí òun mọ̀ pé àwọn alágbára ọkùnrin ń bẹ níbẹ̀.
17 Hele mai la na kanaka o ua kulanakauhale la iwaho, a kaua mai la ia Ioaba ma: a hina iho la kekahi poe kanaka o na kauwa a Davida, a make iho la hoi o Uria ka Heta.
Àwọn ọkùnrin ìlú náà sì jáde wá, wọ́n sì bá Joabu jà, díẹ̀ sì ṣubú nínú àwọn ènìyàn náà nínú àwọn ìránṣẹ́ Dafidi, Uriah ará Hiti sì kú pẹ̀lú.
18 Hoouna aku la o Ioaba, a hai aku la ia Davida i na mea a pau o ke kaua;
Joabu sì ránṣẹ́ ó sì ro gbogbo nǹkan ogun náà fún Dafidi.
19 Kauoha aku la ia i ka elele, i aku la, A pau kau hai ana aku i na mea o ke kaua i ke alii;
Ó sì pàṣẹ fún ìránṣẹ́ náà pé, “Nígbà tí ìwọ bá sì parí àti máa ro gbogbo nǹkan ogun náà fún ọba.
20 Ina paha e huhu mai ke alii, a e i mai hoi ia oe, No ke aha la oukou i hele aku ai pela a kokoke i ke kulanakauhale i ke kaua ana o oukou? Aole anei oukou i ike, e pana mai lakou mai luna mai o ka pa?
Bí ó bá ṣe pé, ìbínú ọba bá ru, ti òun sì wí fún ọ pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin fi súnmọ́ ìlú náà láti bá wọn jà, ẹ̀yin kò mọ̀ pé wọn ó tafà láti orí odi wá.
21 Nawai i pepehi ia Abimeleka ke keiki a Ierubeseta? Aole anei he wahine i hoolei iho i ka apana pohaku wili palaoa maluna ona, i make ai oia ma Tebeza? No ke aha la oukou i hele aku ai a kokoke i ka pa? Alaila e i aku oe, Ua make no hoi kau kauwa o Uria o ka Heta.
Ta ni ó pa Abimeleki ọmọ Jerubu-Beṣeti? Kì í ṣe obìnrin ni ó yí òkúta-ọlọ lù ú láti orí odi wá, tí ó sì kú ní Tebesi? Èéha ti rí tí ẹ̀yin fi súnmọ́ odi náà? Ìwọ yóò sì wí fún un pé, Uriah ìránṣẹ́ rẹ ará Hiti kú pẹ̀lú.’”
22 Hele aku la ka elele, hiki aku la a hai aku la ia Davida i na mea a pau a Ioaba i hoouna aku ai ia ia.
Ìránṣẹ́ náà sì lọ, ó sì wá, ó sì jẹ́ gbogbo iṣẹ́ tí Joabu rán an fún Dafidi.
23 I aku la ka elele ia Davida, He oiaio ua lanakila mai kela poe kanaka maluna o makou, a hele mai la lakou iwaho io makou la ma ke kula, a hahai aku la makou ia lakou a hiki i ke komo ana ma ka puka.
Ìránṣẹ́ náà sì wí fún Dafidi pé, “Nítòótọ́ àwọn ọkùnrin náà lágbára jù wá lọ, wọ́n sì jáde tọ̀ wá wá ní pápá, àwa sì tẹ̀lé wọn títí wọ́n fi dé ẹ̀yìn odi.
24 A pana mai la ka poe pana mai luna mai o ka pa maluna iho o kau poe kauwa, a ua make kekahi poe kauwa a ke alii, a ua make hoi kau kauwa o Uria.
Àwọn tafàtafà sì ta sí ìránṣẹ́ rẹ láti orí odi wá, díẹ̀ nínú àwọn ìránṣẹ́ ọba sì kú, ìránṣẹ́ rẹ̀ Uriah ará Hiti sì kú pẹ̀lú.”
25 Alaila i aku la o Davida i ka elele, Penei kau e olelo aku ai ia Ioaba, Mai hoino oe ia mea ma kou manao; no ka mea, i ka ai ana mai a ka pahikaua e like me keia, pela no i na mea a pau: e hooikaika ae oe i kou kaua ana i ke kulanakauhale, a e hookahuli ia wahi; a nau no e hooikaika aku ia ia.
Dafidi sì wí fún ìránṣẹ́ náà pé, “Báyìí ni ìwọ yóò wí fún Joabu pé, ‘Má ṣe jẹ́ kí nǹkan yìí burú ní ojú rẹ, nítorí pé idà a máa pa lọ́tùn ún lósì, mú ìjà rẹ le sí ìlú náà, kí o sì bì í ṣubú.’ Kí ìwọ sì mú un lọ́kàn le.”
26 A lohe ae la ka wahine a Uria, ua make o Uria kana kane, kanikau iho la ia i kana kane.
Nígbà tí aya Uriah sì gbọ́ pé Uriah ọkọ rẹ̀ kú, ó sì ṣọ̀fọ̀ nítorí ọkọ rẹ̀.
27 A pau ae la ke kanikau ana, kii aku la o Davida, a lawe mai la ia ia i kona hale, a lilo ae la ia i wahine nana: a hanau mai la ia i keikikane nana: aka, he ino ka mea a Davida i hana'i imua o Iehova.
Nígbà tí ìṣọ̀fọ̀ náà sì kọjá tan, Dafidi sì ránṣẹ́, o sì mú un wá sí ilé rẹ̀, ó sì di aya rẹ̀, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún un, ṣùgbọ́n nǹkan náà tí Dafidi ṣe burú níwájú Olúwa.

< II Samuela 11 >