< II Na Lii 6 >
1 OLELO aku la na haumana a ka poe kaula ia Elisai, Aia hoi, ano o kahi a kakou e noho pu nei me oe, ua pilikia ia kakou.
Àwọn ọmọ wòlíì sọ fún Eliṣa pé, “Wò ó, ní ibi tí a ti pàdé pẹ̀lú rẹ, ó kéré fún wa.
2 Ke noi aku nei, e ae mai oe, e hele makou i Ioredane, a e lawe kela kanaka keia kanaka, mailaila mai, i kahi laau, a e hana kakou malaila i wahi no kakou e noho ai. I mai la kela, E hele oukou.
Jẹ́ kí àwa kí ó lọ sí Jordani, ní ibi tí ẹnìkọ̀ọ̀kan ti le rí ọ̀pá kan, jẹ́ kí àwa kí ó kọ́lé síbẹ̀ fún wa láti gbé.” Ó sì wí pé, “Lọ.”
3 A i aku la kekahi, Ke noi aku nei au ia oe, e ae mai oe i ka hele pu me makou. I mai la ia, E hele no wau.
Nígbà náà ni ọ̀kan lára wọn wí pé, “Kí ó wù ọ́, èmí bẹ̀ ọ́, láti bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ lọ?” Eliṣa dá a lóhùn pé, “Èmi yóò lọ,”
4 A hele pu aku la ia me lakou. A hiki lakou ma Ioredane, a kua laau lakou.
Ó sì lọ pẹ̀lú wọn. Wọ́n sì lọ sí Jordani wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní gé igi.
5 A i ke kua laau ana a kekahi, poholo aku la ke koi iloko o ka wai: auwe iho la ia, i aku la, Auwe, e ka haku! no ka mea, no hai ia mea.
Bí ọ̀kan ṣe gé igi náà, àáké irin náà bọ́ sínú omi, ó kígbe sókè pé, “O! Olúwa mi, mo yá a ni!”
6 Ninau aku la ke kanaka o ke Akua, Mahea i poholo ai? Hoike mai la ia i kahi. A oki iho la ia i kahi laau, a hoolei iho la malaila, a laua mai ke koi.
Ènìyàn Ọlọ́run sì béèrè pé, “Níbo ni ó bọ́ sí?” Nígbà tí ó fi ibẹ̀ hàn án, Eliṣa gé igi kan ó sì jù ú síbẹ̀, ó sì mú irin náà fò lójú omi.
7 I aku la ia ia, E lawe mai ia nou. Kikoo aku la kona lima, a lawe mai ia mea.
Ó wí pé, “Gbé e jáde.” Lẹ́yìn náà ọkùnrin náà na ọwọ́ rẹ̀ jáde ó sì mú un.
8 A kaua mai ke alii o Suria i ka Iseraela, a olelo pu ia me kana poe kauwa, i aku la, Ma kela wahi ka'u e hoomoana'i.
Nísinsin yìí ọba Aramu wà ní ogun pẹ̀lú Israẹli ó sì bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ gbèrò, ó wí pé, “Èmi yóò ṣe ibùdó mi sí ibí yìí nínú èyí náà àti bí ibí yìí.”
9 A hoouna aku la ke kanaka o ke Akua i ke alii o ka Iseraela, i aku la, E malama oe, mai hele oe ma kela wahi; no ka mea, ua iho mai ko Suria malaila.
Ènìyàn Ọlọ́run rán iṣẹ́ sí ọba Israẹli pé, “Kíyèsi ara láti kọjá ní ibẹ̀ yẹn, nítorí pé ará Aramu wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ síbẹ̀.”
10 Hoouna aku la ke alii o ka Iseraela i kela wahi a ke kanaka o ke Akua i hai mai ai ia ia, a i hoakaka mai ai ia ia, a malama kela ia ia iho malaila, aole i kekahi manawa, aole hoi i elua wale no.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli wo ibi tí ènìyàn Ọlọ́run náà fihàn, ní ẹ̀ẹ̀kan sí i Eliṣa kìlọ̀ fún ọba, bẹ́ẹ̀ ni ó wà lórí sísọ ní ibẹ̀.
11 A pihoihoi ka naau o ke alii o Suria uo keia mea; a kahea aku la ia i kana poe kauwa, i aku la ia lakou, Aole anei oukou e hai mai ia'u, owai ka mea o kakou i launa pu me ke alii o ka Iseraela?
Èyí mú ọba Aramu bínú. Ó pe àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣé ìwọ kò ní sọ fún mi èwo nínú wa ni ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ọba Israẹli?”
12 I mai la kekahi o na kauwa, Aole, e kuu haku e ke alii; aka, o Elisai ke kaula iloko o ka Iseraela, ka mea nana e hai aku i ke alii o ka Iseraela i na mea au i olelo ai maloko o kou keena moe.
Ọ̀kan lára ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí pé, “Kò sí ọ̀kan nínú wa, olúwa ọba mi, ṣùgbọ́n Eliṣa, wòlíì tí ó wà ní Israẹli, sọ fún ọba Israẹli ọ̀rọ̀ gangan tí ó sọ nínú yàrá rẹ̀.”
13 I aku la ia, E hele oukou a ike i kona wahi, i hoouna aku ai au e kii ia ia. A haiia mai ia ia, Aia no ia ma Dotana.
Ọba pa á láṣẹ, “Lọ, kí ẹ lọ wo ibi tí ó wà, kí èmi kí ó lè rán ènìyàn láti lọ mú un wá.” Ìròyìn padà wá wí pé, “Ó wà ní Dotani.”
14 Hoouna aku la ia malaila i na lio, a me na halekaa, a me ka poe koa, he nui: a hele aku lakou i ka po, a hoopuni ae la i ke kulanakauhale.
Nígbà náà ni ó rán àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ àti ogun ńlá tí ó le síbẹ̀. Wọ́n sì lọ ní alẹ́ wọ́n sì yí ìlú náà ká.
15 A i ke ala ana o ke kauwa a ke kanaka o ke Akua i kakahiaka nui, a hele iwaho, aia hoi, ua puni ke kulanakauhale i ka poe kaua, i na lio, a me na halekaa: i aku la kana kauwa ia ia, Auwe, e kuu haku! pehea la e hanaia'i?
Nígbà tí ìránṣẹ́ ènìyàn Ọlọ́run dìde ó sì jáde lọ ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, ogun pẹ̀lú ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ wọn ti yí ìlú náà ká. “Yé è, olúwa mi! Kí ni kí àwa kí ó ṣe?” ìránṣẹ́ náà béèrè.
16 I mai la ia, Mai makau oe; no ka mea, ua oi aku ka poe me kakou, mamua o ka poe me lakou.
“Má ṣe bẹ̀rù,” wòlíì náà dáhùn, “Àwọn tí ó wà pẹ̀lú wa, wọ́n pọ̀ ju àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn lọ.”
17 A pule aku la o Elisai, i aku la, E Iehova, ke noi aku nei au ia oe, e wehe ae oe i kona maka, i ike ia. A wehe ae la o Iehova i na maka o ke kanaka opiopio, a ike aku la ia, aia hoi, na paapu ka mauna i na lio, a me na halekaa ahi, a puni o Elisai.
Eliṣa sì gbàdúrà, “Olúwa, la ojú rẹ̀ kí ó ba à lè ríran.” Nígbà náà Olúwa la ojú ìránṣẹ́ náà, ó sì wò, ó sì rí òkè ńlá tí ó kún fún ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ iná gbogbo yí Eliṣa ká.
18 A iho mai lakou io na la, pule aku la o Elisai ia Iehova, i aku la, Ke noi aku nei au ia oe, e hahau mai oe i keia poe kanaka i ka makapo. A hahau mai la ia ia lakou i ka makapo, e like me ka olelo a Elisai.
Bí àwọn ọ̀tá ṣe ń sọ̀kalẹ̀ wá níwájú rẹ, Eliṣa gbàdúrà sí Olúwa pé. “Bu ìfọ́jú lu àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” Olúwa sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Eliṣa ti béèrè.
19 I aku la o Elisai ia lakou, Aole keia ke ala, aole hoi keia ke kulanakauhale; e hahai oukou ia'u, a e alakai aku au ia oukou i ke kanaka a oukou e imi nei; aka, alakai no ia ia lakou i Samaria.
Eliṣa sọ fún wọn pé, “Èyí kì í ṣe ọ̀nà bẹ́ẹ̀ ni èyí kì í ṣe ìlú náà. Tẹ̀lé mi, èmi yóò mú u yín lọ sí ọ̀dọ̀ ọkùnrin tí ẹ̀yin ń wá.” Ó sì sìn wọ́n lọ sí Samaria.
20 A hiki lakou i Samaria, i aku la o Elisai, E Iehova, e hookaakaa ae oe i ko lakou nei maka, i ike ai lakou. A hookaakaa ae la o Iehova i ko lakou maka, a ike lakou, aia hoi lakou iwaena konu o Samaria.
Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n wọ ìlú náà, Eliṣa wí pé, “Olúwa, la ojú àwọn ọkùnrin wọ̀nyí kí wọn kí ó lè ríran.” Nígbà náà Olúwa la ojú wọn, wọ́n sì ríran, wọ́n sì wà níbẹ̀, nínú Samaria.
21 I mai la ke alii o ka Iseraela ia Elisai, i kona ike ana ia lakou, E kuu makua, e pepehi anei au? e pepehi anei au ia lakou?
Nígbà tí ọba Israẹli rí wọn, ó béèrè lọ́wọ́ Eliṣa pé, “Ṣé kí èmi kí ó pa wọ́n, baba mi? Ṣé kí èmi kí ó pa wọ́n?”
22 I aku la ia, Mai pepehi oe: e pono anei e pepehi i na mea au i lawe pio ai mo kau pahikaua a me kou kakaka? E kau i ka ai, a me ka wai imua o lakou, i ai ai lakou, a i inu hoi, a hoi aku i ko lakou haku.
“Má ṣe pa wọ́n,” ó dáhùn. “Ṣé ìwọ yóò pa àwọn ọkùnrin tí ìwọ mú pẹ̀lú idà rẹ tàbí ọrun rẹ? Gbé oúnjẹ àti omi síwájú wọn kí wọn kí ó lè jẹ kí wọn sì mu, nígbà náà kí wọn padà lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá wọn.”
23 A hoomakaukau iho la ia i ahaaina nui na lakou, a pau ka lakou ai ana, a me ka inu ana, hookuu aku la ia ia lakou, a hele aku la lakou i ko lakou haku. Aole i hele hou mai ka poe hao wale o Suria i ka aina o ka Iseraela.
Bẹ́ẹ̀ ni ó pèsè àsè ńlá fún wọn, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jẹ tí wọ́n mu, ó sì rán wọn lọ, wọ́n sì padà sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá wọn. Bẹ́ẹ̀ ni ẹgbẹ́ láti Aramu dáwọ́ ìgbógunti ilẹ̀ Israẹli dúró.
24 A mahope iho hoakoakoa ae la o Benehadada, ke alii o Suria, i kona poe kaua a pau, a pii mai la e hoopilikia i Samaria.
Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, ni Beni-Hadadi ọba Aramu kó gbogbo àwọn ogun rẹ̀ jọ wọ́n sì yan sókè wọ́n sì dúró ti Samaria.
25 A ua wi nui iloko o Samaria: aia hoi hoopilikia lakou ia, a kuaiia ke poo o ka hoki i kanawalu sekela kala, a hookahi hapaha o ke kaba lepo manu nunu i na sekela kala elima.
Ìyàn ńlá sì mú ní ìlú Samaria; wọ́n dúró tí ì tó bẹ́ẹ̀ tí a fi ń ta orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan ní ọgọ́rùn-ún ìwọ̀n fàdákà àti ìdámẹ́rin òsùwọ̀n kábù imí ẹyẹlé, fún ìwọ̀n fàdákà márùn-ún.
26 A i ka hele ana ae o ke alii o ka Iseraela maluna o ka papohaku, kahea mai la kekahi wahine ia ia, i mai la, E kokua mai, e kuu haku, e ke alii.
Gẹ́gẹ́ bí ọba Israẹli ti ń kọjá lọ lórí odi, obìnrin kan sọkún sí i pé, “Ràn mí lọ́wọ́, olúwa ọba mi!”
27 I aku la ia, a i ole o Iehova e kokua mai ia oe, ma ka mea hea anei e kokua aku ai au ia oe? ma kahi e hehi ai i ka palaoa anei, a ma kahi e kaomi ai i ka waina anei?
Ọba sì dá a lóhùn pé, “Bí Olúwa kò bá gbà ọ́, níbo ni èmi yóò gbé ti gbà ọ́? Láti inú ilẹ̀ ìpakà, tàbí láti inú ibi ìfúntí?”
28 Ninau aku ke alii ia ia, Heaha kau? I mai la kela, Ua i mai keia wahine ia'u, E haawi mai i kau keiki, i ai iho ai kaua i keia la, a e ai iho kaua i ka'u keiki i ka la apopo.
Nígbà náà ọba béèrè lọ́wọ́ obìnrin náà pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀?” Obìnrin náà dáhùn pé, “Obìnrin yìí wí fún mi pé, ‘Mú ọmọkùnrin rẹ wá kí àwa kí ó lè jẹ ẹ́ lónìí, ní ọ̀la àwa yóò jẹ ọmọkùnrin tèmi.’
29 Hoolapalapa iho la maua i ka'u keiki, a ua ai iho, a i aku la au ia ia i kekahi la, e haawi mai oe i kau keiki; a ua huna ia i kana keiki.
Bẹ́ẹ̀ ni a ṣe ọmọkùnrin mi a sì jẹ ẹ́. Ní ọjọ́ kejì mo wí fún un pé, ‘Mú ọmọkùnrin rẹ wá kí àwa kí ó lè jẹ,’ ṣùgbọ́n ó ti gbé e pamọ́.”
30 A lohe ae la ke alii i ka olelo a ka wahine, haehae iho la ia i kona aahu; a hele ae la ia maluna o ka papohaku, a nana mai la na kanaka, aia hoi, he kapa inoino maluna o kona kino maloko.
Nígbà tí ọba gbọ́ ọ̀rọ̀ obìnrin náà, ó fa aṣọ rẹ̀ ya. Gẹ́gẹ́ bí ó sì ti ń kọjá lọ sí orí odi, àwọn ènìyàn wò ó níbẹ̀ ní abẹ́, ó ní aṣọ ọ̀fọ̀ ní ara rẹ̀.
31 I aku la ia, E hana mai ke Akua ia'u pela, a e oi aku hoi, ke waihoia ko poo o Elisai, ke keiki a Sapata, maluna ona i keia la.
Ó sì wí pé, “Kí Ọlọ́run kí ó fi ìyà jẹ mí, àti jù bẹ́ẹ̀ lọ dájúdájú, pé orí ọmọkùnrin Eliṣa ọmọ Ṣafati kì ó wà ní ọrùn rẹ̀ ní òní!”
32 A e noho ana o Elisai iloko o kona hale, a e noho pu ana me ia na lunakahiko; a hoouna aku ke alii i ke kanaka mai kona alo aku: aka, mamua o ka hiki ana'ku o ke elele io na la, i mai la ia i na lunakahiko, E nana oukou ua hoouna mai nei keia keiki a ka mea pepehi kanaka e lawe i kuu poo: e nana, i ka manawa e hele mai ai ke elele, e pani aku i ka puka, a e hoopaa aku oukou ia ia ma ka puka: aole anei e kani ana na wawae o kona haku mahope ona?
Nísinsin yìí Eliṣa jókòó ní ilé rẹ̀ àwọn àgbàgbà náà jókòó pẹ̀lú rẹ̀. Ọba sì rán oníṣẹ́ síwájú rẹ̀, ṣùgbọ́n kí ó tó dé ibẹ̀, Eliṣa sọ fún àwọn àgbàgbà pé, “Ṣé ẹ̀yin kò rí bí apànìyàn ti ń rán ẹnìkan láti gé orí mi kúrò? Ẹ wò ó, nígbà tí ìránṣẹ́ náà bá dé, ẹ ti ìlẹ̀kùn kí ẹ sì dìímú ṣinṣin ní ẹnu-ọ̀nà, ìró ẹsẹ̀ olúwa rẹ̀ kò ha wà lẹ́yìn rẹ?”
33 A i kana kamailio ana me lakou, aia hoi, hiki mai ke elele io na la, i mai la, Aia hoi, no Iehova mai keia ino; no ke aha la au e kali hou aku ai ia Iehova?
Nígbà tí ó sì ń sọ̀rọ̀ sí wọn, ìránṣẹ́ náà sọ̀kalẹ̀ wá bá a. Ọba náà sì wí pé, “Ibi yìí láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni. Kí ni ó dé tí èmi yóò fi dúró de Olúwa sí i?”