< II Na Lii 5 >

1 O NAAMANA ka luna o ka poe kauwa o ke alii o Suria, he kanaka koikoi ia imua o kona haku, a he hanohano o kona maka; no ka mea, ma o na la, ua hoolanakila mai o Iehova i ko Suria; he kanaka koa nui no hoi ia, a ua lepera.
Naamani jẹ́ olórí ogun ọba Aramu. Ó jẹ́ ènìyàn ńlá níwájú ọ̀gá rẹ̀, wọ́n sì bu ọlá fún un, nítorí nípasẹ̀ rẹ̀ ni Olúwa ti fi ìṣẹ́gun fún Aramu. Òun jẹ́ alágbára, akọni ọkùnrin ṣùgbọ́n, ó dẹ́tẹ̀.
2 A ua hele aku ka poe koa hao wale, no ko Suria, a ua lawe pio mai lakou i kekahi kaikamahine opiopio mai ka aina o ka Iseraela mai; a ua lawelawe ia na ka wahine a Naamana.
Nísinsin yìí ẹgbẹgbẹ́ láti Aramu ti jáde lọ láti mú ọmọ obìnrin kékeré kan ní ìgbèkùn láti Israẹli, ó sì sin ìyàwó Naamani.
3 I aku la ia i kona haku wahine, Ina o kuu haku ma ke alo o ke kaula ma Samaria, ina ua hoola mai kela ia ia i kona lepera.
Ó sọ fún ọ̀gá rẹ̀ obìnrin pé, “Tí ó bá jẹ́ wí pé ọ̀gá mi lè rí wòlíì tí ó wà ní Samaria! Yóò wò ó sàn kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ rẹ̀.”
4 A hele aku kekahi, a hai aku la i kona haku, i aku la, Penei a penei ka olelo ana a ke kaikamahine no ka aina o ka Iseraela.
Naamani lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ̀ ó sì wí fún un ohun tí ọmọbìnrin Israẹli ti sọ.
5 I mai la ke alii o Suria, O hele, o hele, a e hoouna aku au i palapala na ke alii o ka Iseraela. A hele aku la ia, a lawe aku la ia ma kona lima i umi talena kala, a me na apana gula eono tausani, a me na lole aahu he umi.
“Ní gbogbo ọ̀nà, lọ,” ọba Aramu dá a lóhùn pé, “Èmi yóò fi ìwé ránṣẹ́ sí ọba Israẹli.” Bẹ́ẹ̀ ni Naamani lọ, ó sì mú pẹ̀lú rẹ̀ tálẹ́ǹtì fàdákà mẹ́wàá, ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ìwọ̀n wúrà àti ìpààrọ̀ aṣọ mẹ́wàá.
6 A lawe aku la ia i ka palapala i ko alii o ka Iseraela, i aku la, Ano, i ka hiki ana'ku o keia palapala ia oe, aia hoi, ua hoouna aku au i ou la ia Naamana i kuu kauwa, i hoola mai ai oe ia ia i kona lepera.
Ìwé tí ó mú lọ sọ́dọ̀ ọba Israẹli kà pé, “Pẹ̀lú ìwé yìí èmi ń rán ìránṣẹ́ mi Naamani sí ọ pé o lè wò ó sàn kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ rẹ̀.”
7 A pau ka heluhelu ana a ke alii o ka Iseraela i ka palapala, haehae iho la ia i kona aahu, i aku la, He Akua anei wau e pepehi aku a e hoola, i hoouna mai ai keia kanaka io'u nei e hoola i ke kanaka i kona lepera? no ia mea, ke noi aku nei au, e noonoo, a ike, ke imi mai nei paha i mea no'u e hewa'i.
Bí ọba Israẹli ti ka ìwé náà ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì wí pé, “Èmi ha jẹ́ Ọlọ́run? Ǹjẹ́ èmi le pa kí n sì mú wá sí ààyè padà? Kí ni ó dé tí eléyìí rán ènìyàn sí mi láti wo ààrùn ẹ̀tẹ̀ rẹ sàn, kí ẹ wo bí ó ti ń wá ọ̀nà láti wá ìjà pẹ̀lú mi!”
8 A i ka manawa i lohe ai o Elisai ke kanaka o ke Akua, ua haehae ke alii i kona aahu, hoouna aku la ia i ke alii, i aku la, No ke aha la oe i haehae ai i kou aahu? e hele mai ia ano i o'u nei, a e ike auanei ia, he kaula no iloko o ka Iseraela.
Nígbà tí Eliṣa ènìyàn Ọlọ́run gbọ́ pé ọba Israẹli ti ya aṣọ rẹ̀, ó sì rán iṣẹ́ yìí sí i pé, “Kí ni ó dé tí o fi fa aṣọ rẹ ya? Jẹ́ kí ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi. Òun yóò sì mọ̀ pé wòlíì wà ní Israẹli.”
9 A hele mai o Naamana me kona mau lio, a me kona halekaa, a ku ma ka puka o ka hale o Elisai.
Bẹ́ẹ̀ ni Naamani sì lọ pẹ̀lú ẹṣin rẹ̀ àti kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Eliṣa.
10 Hoouna aku la o Elisai i elele io na la, i aku la, E hele oe e auau iloko o Ioredane, ehiku auau ana, a e hoi hou mai no kou io ia oe, a e maemae oe.
Eliṣa rán ìránṣẹ́ láti lọ sọ fún un pé, “Lọ, wẹ̀ ara rẹ ní ìgbà méje ní odò Jordani, ẹran-ara rẹ yóò sì tún padà bọ̀ sípò, ìwọ yóò sì mọ́.”
11 Huhu iho la o Naamana, a hele aku la, i iho la, Aia hoi, ua i iho au ia'u iho, E hele io mai auanei ia iwaho, a e ku, a e kahea aku i ka inoa o Iehova o kona Akua, a hapai i kona lima maluna o ka wahi, a e hoola i ka lepera.
Ṣùgbọ́n Naamani lọ pẹ̀lú ìbínú ó sì wí pé, “Mo lérò pé yóò sì dìde jáde wá nítòótọ́ sí mi, yóò sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run, fi ọwọ́ rẹ̀ lórí ibẹ̀ kí ó sì wo ẹ̀tẹ̀ mi sàn.
12 Aole anei e oi aku ka pono o Abana, a me Parepara, na muliwai o Damaseko, mamua o ko na wai a pau o ka Iseraela? aole anei e pono ia'u ke holoi iloko o ia mau mea, a maemae? A huli ae la ia a hele aku la me ka huhu.
Abana àti Fapari, odò Damasku kò ha dára ju gbogbo omi Israẹli lọ? Ṣé èmi kò le wẹ̀ nínú wọn kí n sì mọ́?” Bẹ́ẹ̀ ni ó yípadà, ó sì lọ pẹ̀lú ìrunú.
13 Hele mai kana poe kauwa a kokoke, olelo aku la ia ia, i aku la, E kuu makua, ina i olelo mai ke kaula ia oe i kekahi mea nui, aole anei oe i hana? oiaio hoi, i kana i ana mai ia oe, E auau oe, a e maemae?
Ìránṣẹ́ Naamani lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ ó sì wí pé, “Baba mi, tí wòlíì bá ti sọ fún ọ láti ṣe ohun ńlá kan, ṣé ìwọ kì bá ti ṣe, mélòó mélòó nígbà náà, nígbà tí ó sọ fún ọ pé, ‘Wẹ̀ kí o sì mọ́’!”
14 Alaila hele aku la ia ilalo, a lu iho la iloko o Ioredane, ehiku lu ana, e like me ka olelo a ke kanaka o ke Akua; a hoi hou mai kona io e like me ka io o ke keiki uuku, a ua maemae ia.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ ó sì tẹ ara rẹ̀ bọ inú odò Jordani ní ìgbà méje, gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run ti sọ fún un, ẹran-ara rẹ̀ sì tún padà sí mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ọmọkùnrin kékeré.
15 A hoi hou aku la ia i ke kanaka o ke Akua, oia a me kona poe a pau, a hiki aku la, a ku imua ona; i aku la, Aia hoi, ano ua ike au, aole he Akua ma ka honua a pau, maloko o ka Iseraela wale no; ano hoi, ke noi aku nei au ia oe, e lawe oe i ka makana a kau kauwa.
Nígbà náà Naamani àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ padà lọ sí ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run. Ó sì dúró níwájú rẹ̀ ó sì wí pé, “Nísinsin yìí èmi mọ̀ pé kò sí Ọlọ́run ní gbogbo àgbáyé àyàfi ní Israẹli nìkan. Jọ̀wọ́ gba ẹ̀bùn láti ọwọ́ ìránṣẹ́ rẹ.”
16 I mai la ia, Ma ke ola o Iehova, imua ona a'u e ku nei, aole au e lawe. Koi aku la keia ia ia; aka, hoole mai la ia.
Wòlíì náà dáhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ẹni tí mo ń sìn, èmi kò nígbà ohun kan,” bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Naamani rọ̀ ọ́ láti gbà á, ó kọ̀.
17 I aku la o Naamana, Ke noi aku nei au ia oe, aole anei e haawiia mai i kau kauwa ka lepo e kaumaha ai na hoki elua ke hali? no ka mea, ma keia hope aku aole kau kauwa e kaumaha aku i ka mohaikuni, a me ka alana i na akua e, aka, ia Iehova wale no.
Naamani wí pé, “Tí o kò bá nígbà, jọ̀wọ́ jẹ́ kí a fi fún èmi ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ ẹrù erùpẹ̀ tí ìbáaka méjì le rù, nítorí láti òní lọ ìránṣẹ́ rẹ kì yóò rú ẹbọ sísun àti rú ẹbọ sí ọ̀kan lára àwọn ọlọ́run mìíràn mọ́ bí kò ṣe sí Olúwa.
18 E kala mai o Iehova i keia mea i kau kauwa, i ka hele ana o kuu haku iloko o ka hale o Rimona e hoomana malaila, a e hilinai ia maluna o kuu lima, a e hoomana au ma ka hale o Rimona; i kuu hoomana ana ma ka hale o Rimona, e kala mai o Iehova i keia mea i kau kauwa.
Ṣùgbọ́n kí Olúwa kí ó dáríjì ìránṣẹ́ rẹ fún nǹkan yìí. Nígbà tí ọ̀gá mi wọ inú ilé Rimoni láti fi orí balẹ̀ tí ó sì fi ara ti ọwọ́ mi tí mo sì tẹ ara mi ba pẹ̀lú níbẹ̀. Nígbà tí èmi tẹ ara mi ba ní ilé Rimoni, kí Olúwa dáríjì ìránṣẹ́ rẹ fún èyí.”
19 I mai la keia ia ia E hele oe me ke aloha. A hele ia mai ona aku la, aole loihi.
Eliṣa wí pé, “Máa lọ ní àlàáfíà.” Lẹ́yìn ìgbà tí Naamani tí rin ìrìnàjò tí ó jìnnà,
20 I iho la o Gehazi ke kauwa a Elisai ke kanaka no ke Akua, Aia hoi, ua hoole kuu haku ia Naamana i keia kanaka no Suria, aole i lawe mai kona lima mai i ka mea ana i lawe mai ai: aka, ma ke ola o Iehova e holo no au mahope ona, a e lawe i kekahi mea mai ona mai la.
Gehasi, ìránṣẹ́ Eliṣa ènìyàn Ọlọ́run, ó wí fún ara rẹ̀ pé, “Ọ̀gá mi jẹ́ ẹni tí ó rọ́nú lórí Naamani, ará Aramu, nípa pé kò gba ohunkóhun ní ọwọ́ rẹ̀ ohun tí ó mú wá, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, èmi yóò sá tẹ̀lé e èmi yóò sì gba ohun kan ní ọwọ́ rẹ̀.”
21 A hahai aku la o Gehazi mahope o Naamana; a ike ae la o Naamana ia ia e holo mai ana mahope ona, iho ilalo ia mai ka halekaa mai e halawai me ia, i mai la, Ua pono anei?
Bẹ́ẹ̀ ni Gehasi sáré tẹ̀lé Naamani. Nígbà tí Naamani rí i tí ó ń sáré tẹ̀lé e, ó sì sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́ láti pàdé rẹ̀. “Ṣé gbogbo nǹkan wà dáradára?” ó béèrè.
22 I aku la ia, Ua pono. Ua hoouna mai kuu haku ia'u, i mai la, Aia hoi, i keia manawa, ua hiki mai ia'u nei elua kanaka ui mai ka mauna o Eperaima mai, he mau haumana a ka poe kaula; ke noi aku nei au ia oe, e haawi mai oe no laua i hookahi talena kala, a i elua lole aahu.
“Gbogbo nǹkan wà dáradára,” Gehasi dá a lóhùn. “Ọ̀gá mi rán mi láti sọ wí pé, ‘Àwọn ọ̀dọ́ ọmọkùnrin méjì láti ọ̀dọ̀ ọmọ wòlíì wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ mi láti orí òkè ìlú ti Efraimu. Jọ̀wọ́ fún wọn ní ẹ̀bùn fàdákà àti ìpààrọ̀ aṣọ méjì.’”
23 I mai la o Naamana, E oluolu mai oe i ka lawe i na talena elua. Koi mai la oia ia ia, a hoopaa iho la ia i na talena elua iloko o na aa elua, a me na lole aahu elua, a haawi aku la i na kauwa ana elua; a lawe aku la laua imua ona.
Naamani wí pé, “Ní gbogbo ọ̀nà, mú ẹ̀bùn méjì.” Ó sì rọ Gehasi láti gbà wọ́n, ó sì di ẹ̀bùn méjì náà ti fàdákà ní inú àpò méjì, pẹ̀lú ìpààrọ̀ aṣọ méjì, ó sì fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ méjì, wọ́n sì kó wọn lọ sọ́dọ̀ Gehasi.
24 A hiki aku la ma Opela, lawe ae la oia ia mau mea, mai ko laua lima mai, a waiho iho la iloko o ka hale; a kuu aku la i na kanaka, a hoi aku la laua.
Nígbà tí Gehasi sì dé ibi ilé ìṣọ́, ó gbà wọ́n lọ́wọ́ wọn, ó sì tó wọ́n sínú ilé, ó sì jọ̀wọ́ àwọn ọkùnrin náà lọ́wọ́ lọ, wọ́n sì jáde lọ.
25 Komo aku la ia maloko, a ku imua o kona haku; ninau mai la o Elisai ia ia, Mai hea mai oe, e Gehazi? I aku la ia, Aole i hele kau kauwa io, a ia nei.
Nígbà náà ó sì wọlé wá ó sì dúró níwájú ọ̀gá rẹ̀ Eliṣa. “Níbo ni o ti wà Gehasi?” Eliṣa béèrè. “Ìránṣẹ́ rẹ kò lọ sí ibìkan kan.” Gehasi dá a lóhùn.
26 I mai la kela ia ia, Aole anei i hele kuu naau, i ka manawa i huli ae ke kanaka mai kona halekaa mai e halawai me oe? He manawa anei keia e lawe i ke kala, a e lawe i na aahu, me na oliva, a me na pawaina, a me na hipa, a me na bipi, a me na kauwakane a me na kauwawahine?
Ṣùgbọ́n Eliṣa wí fún un pé, “Ẹ̀mí mi kò ha wà pẹ̀lú rẹ nígbà tí ọkùnrin náà sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́ láti pàdé rẹ? Ṣé àsìkò tí ó yẹ láti gba owó nìyìí, tàbí láti gba aṣọ, ọgbà olifi, ọgbà àjàrà, àgùntàn, màlúù tàbí ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin?
27 Nolaila e pili mau loa mai ko Naamana lepera ia oe, a me kou hua. A hele ia mai kona alo aku me ka mai lepera e like me ka hau.
Ẹ̀tẹ̀ Naamani yóò lẹ̀ mọ́ ọ àti sí irú-ọmọ rẹ títí láé.” Nígbà náà Gehasi kúrò níwájú Eliṣa, ó sì di adẹ́tẹ̀, ó sì funfun gẹ́gẹ́ bí ẹ̀gbọ̀n òwú.

< II Na Lii 5 >