< II Oihanaalii 25 >

1 O AMAZIA, he iwakaluakumamalima makahiki ona i kona wa i alii ai, a noho alii iho la ia i na makahiki he iwakaluakumamaiwa ma Ierusalema; a o ka inoa o kona makuwahine o Iehoadama no Ierusalema.
Amasiah jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jehoadani, ó wá láti Jerusalẹmu.
2 Hana iho la ia i ka mea maikai i na maka o Iehova, aole nae me ka naau maikai.
Ó ṣe ohun tí ó dára lójú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe tọkàntọkàn.
3 A paa ia ma kona aupuni, pepehi iho la ia i kana poe kauwa nana i pepehi i kona makuakane, i ke alii.
Lẹ́yìn tí ìjọba ti wà ní ìdarí rẹ̀, ó pa àwọn oníṣẹ́ tí ó pa baba rẹ̀ ọba.
4 Aole oia i pepehi i ka lakou poe keiki, aka, hana oia e like me ka mea i kakauia iloko o ke kanawai, ma ka buke a Mose, kahi a Iehova i kauoha mai ai, i mai la, Aole e make na makua no na keiki, aole hoi e make na keiki no na makua, aka, e make no kela kanaka keia kanaka no kona hewa iho.
Síbẹ̀ kò pa àwọn ọmọ wọn, ṣùgbọ́n ó ṣe ní ìbámu pẹ̀lú ohun tí a kọ nínú òfin nínú ìwé Mose, níbi tí Olúwa ti paláṣẹ pé, “A kò gbọdọ̀ pa àwọn baba fún àwọn ọmọ wọn tàbí àwọn ọmọ fún baba wọn, olúkúlùkù ni kí ó kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.”
5 A hoakoakoa Amazia i ka Iuda, a hoonoho ia lakou ma ko ka hale o na makua, i poe luna no na tausani, a i poe luna no ua haneri, no ka Iuda a pau a me ka Beniamina: a helu oia ia lakou mai ka makahiki iwakalua aku, a loaa ia ia ekolu haneri tausani kanaka i waeia, ka poe hiki ke hele i ke kaua, ka poe i makaukau i ka ihe a me ka palekaua.
Amasiah, pe gbogbo àwọn ènìyàn Juda pọ̀, ó sì fi iṣẹ́ lé wọn lọ́wọ́ gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn sí àwọn alákòóso ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn alákòóso ọ̀rọ̀ọ̀rún fún gbogbo Juda àti Benjamini, ó sì gbá iye wọn láti ẹni ogún ọdún àti jù bẹ́ẹ̀ lọ jọ, ó sì rí i pé ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àwọn ọkùnrin ni ó ti múra fún ìsìn ogun, tí ó lè gbá ọ̀kọ̀ àti àpáta mú.
6 A hoolimalima no hoi oia noloko mai o ka Iseraela i hookahi haneri tausani koa ikaika no na talena kala hookahi haneri.
Ó sì yá ọ̀kẹ́ márùn-ún àwọn ọkùnrin oníjà láti Israẹli fún ọgọ́rùn-ún àwọn tálẹ́ǹtì fàdákà.
7 A hele mai io na la ke kanaka o ke Akua, i mai la, E ke alii, aole pono e hele pu me oe ka poe koa o ka Iseraela; no ka mea, aole o Iehova pu me ka Iseraela, me na mamo a pau a Eperaima.
Ṣùgbọ́n ènìyàn Ọlọ́run kan tọ̀ ọ́ wá ó sì wí pé, “Ọba, àwọn ọ̀wọ́ ogun láti Israẹli kò gbọdọ̀ yan pẹ̀lú rẹ, nítorí tí Olúwa kò wà pẹ̀lú Israẹli kì í ṣe pẹ̀lú ẹnìkankan láti Efraimu.
8 Aka, ina e hele no oe, e hana no pela, e ikaika hoi i ke kaua; aka, e oupe mai ke Akua ia oe imua o ka enemi; no ka mea, aia i ke Akua ka mana e kokua mai ai, a e hoohina mai ai no hoi.
Àní, tí ẹ bá lọ jà pẹ̀lú ìmúláyàle ní ojú ogun, Ọlọ́run yóò bì ọ́ ṣubú níwájú àwọn ọ̀tá, nítorí Ọlọ́run ní agbára láti ràn ọ́ lọ́wọ́ àti láti bì ọ́ ṣubú.”
9 Olelo aku la o Amazia i ke kanaka o ke Akua, Heaha ka makou e hana'i no kela mau talena hookahi haneri a'u i haawi aku ai na ka poe koa o ka Iseraela? I mai la ke kanaka o ke Akua, E hiki no ia Iehova ke haawi mai ia oe a nui e aku i keia.
Amasiah sì bi ènìyàn Ọlọ́run pé, “Ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì tí mo ti san fún àwọn ọ̀wọ́ ogun àwọn ọmọ Israẹli ń kọ́?” Ènìyàn Ọlọ́run dáhùn pé “Olúwa lè fún ọ ní èyí tí ó ju ìyẹn lọ.”
10 Alaila, hookaawale ae la o Amazia i ka poe koa i hele mai io na la, mailoko mai o Eperaima e hele i ko lakou wahi; a ua nui loa mai la ko lakou huhu i ka Iuda, a hoi lakou i ko lakou wahi me ka huhu wela.
Bẹ́ẹ̀ ni Amasiah, tú àwọn ọwọ́ ogun tí ó ti wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti Efraimu ká. Ó sì rán wọn lọ ilé. Wọ́n kún fún ìbínú pẹ̀lú Juda, wọ́n sì padà lọ ilé pẹ̀lú ìbínú ńlá.
11 A hooikaika iho la o Amazia, a alakai i kona poe kanaka, a hele aku la i ke awawa paakai, a luku iho la i ko Seira he ami tausani.
Nígbà náà, Amasiah ko ogun rẹ jọ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ lọ sí àfonífojì iyọ̀, níbi tí ó ti pa ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn ọkùnrin Seiri.
12 A lawe pio na mamo a Iuda i na kanaka he umi tausani e ola ana, a laweia lakou ma kahi pali, a hoolei aku ia lakou ilalo mai luna aku o ka pali, a pau lakou i ka weluwelu.
Àwọn ọkùnrin Juda pẹ̀lú fi agbára mú àwọn ọkùnrin ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá láààyè. Wọ́n mú wọn lọ sí orí òkè bèbè òkúta, wọ́n jù wọ́n sílẹ̀, kí gbogbo wọn sì fọ́ sí wẹ́wẹ́.
13 A o ka poe koa a Amazia i hoihoi aku ai, i hele ole lakou me ia i ke kaua, hana ino lakou ma na kulanakauhale o Iuda mai Samaria a hiki i Betehorona, a luku iho la lakou i ekolu tausani kanaka, a lawe aku i ka waiwai pio he nui loa.
Ní báyìí àwọn ọ̀wọ́ ogun tí Amasiah ti rán lọ padà, tí wọn kò nípa nínú ogun gbógun sí àwọn ìlú Juda láti Samaria sí Beti-Horoni. Wọ́n pa ẹgbẹ̀rún mẹ́ta nínú wọn, wọ́n sì kó ọ̀pọ̀ ìkógun ńlá.
14 A hoi mai o Amazia mai ka luku ana i ka Edoma, hali mai oia i na akua o ko Seira, a kukulu ae la ia mau mea iluna i akua nona, a kulou ia imua o lakou, a kuni i ka mea ala ia lakou.
Nígbà tí Amasiah padà láti ibi pípa àwọn ará Edomu, ó mú àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn Seiri padà wá. Ó gbé wọn kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bi àwọn ọlọ́run tirẹ̀. Ó tẹríba fún wọn, ó sì rú ẹbọ fún wọn.
15 A ua hoaa mai la ka huhu o Iehova ia Amazia, a hoouna mai oia io na la i ke kaula, e olelo mai ia ia, No ke aha la oe i imi ai i na akua o na kanaka, na mea i hiki ole ke hoopakele i ko lakou poe kanaka, mai kou lima aku.
Ìbínú Olúwa ru sí Amasiah, ó sì rán wòlíì kan sí i, tí ó wí pé, “Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń béèrè lọ́wọ́ àwọn ọlọ́run àwọn ènìyàn yìí, tí wọn kò le gba àwọn ènìyàn tiwọn kúrò lọ́wọ́ rẹ?”
16 A i kana olelo ana i ke alii, i mai kela ia ia, Ua hooliloia anei oe i kakaolelo no ke alii? Ua oki; no ke aha la oe e pepehiia iho ai? Alaila, hooki iho la ua kaula la me ka olelo ana mai, Ua ike au, ua paa ko ke Akua manao e pepehi mai ia oe, no ka mea, ua hana oe i keia, aole i hoolohe mai oe i ka'u olelo.
Bí ó ti n sọ̀rọ̀, ọba wí fún un pé, “Ṣé a yàn ọ́ ní olùgba ọba lámọ̀ràn ni? Dúró! Èéṣe tí a ó fi lù ọ́ bolẹ̀?” Bẹ́ẹ̀ ni, wòlíì náà dúró ṣùgbọ́n ó wí pé, “Èmi mọ̀ pé Ọlọ́run ti pinnu láti pa ọ́ run nítorí ìwọ ti ṣe èyí, ìwọ kò sì tẹ́tí sí ìmọ̀ràn mi.”
17 A kukakuka iho la o Amazia ke alii o Iuda, a hoouna aku oia io Ioasa la ke keiki a Iehoahaza, ke keiki a Iehu, ke alii o ka Iseraela, i aku la, Ina kaua, e nana kaua he inaka no he maka.
Lẹ́yìn tí Amasiah ọba Juda ti béèrè lọ́wọ́ àwọn olùdámọ̀ràn, ó rán ìpèníjà yìí sí Jehoaṣi ọmọ Jehoahasi ọmọ Jehu, ọba Israẹli pé, “Wá bá mi lójúkojú.”
18 Hoouna mai la o Ioasa ke alii o ka Iseraela io Amazia la, ke alii o ka Iuda, i mai la, Hoouna ke kakalaioa ma Lebanona i ka laau kedera ma Lebanona, i aku la, E haawi mai oe i kau kaikamahine na ka'u keiki i wahine nana; a hele ae la kekahi holoholona o ke kula ma Lebanona, a hehi iho la maluna o ke kakalaioa.
Ṣùgbọ́n Jehoaṣi ọba Israẹli fèsì padà sí Amasiah ọba Juda pé, “Koríko kékeré kan ní Lebanoni rán iṣẹ́ sí igi kedari ní Lebanoni, fi ọmọbìnrin rẹ fún ọmọkùnrin mi ní ìgbéyàwó. Nígbà náà, ẹhànnà ẹranko ènìyàn ni Lebanoni wá, ó sì tẹ òṣùṣú náà lábẹ́ ẹsẹ̀.
19 Olelo mai oe, Aia hoi ua luku au i ka Edoma, a ua kiekie kou naau me ke kaena ana. E noho malie oe ma ka hale; no ke aha la oe e hakaka mai ai, i pono ole ai oe, a haule oe, o oe, a me ka Iuda a pau pu me oe?
Ìwọ wí fún ara à rẹ wí pé, ìwọ ti ṣẹ́gun Edomu àti nísinsin yìí ìwọ ní ìhàlẹ̀ àti ìgbéraga. Ṣùgbọ́n dúró ní ilé! Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń wá wàhálà tí o sì fi ń fa ìṣubú rẹ àti ti Juda pẹ̀lú?”
20 Aole i hoolohe o Amazia; no ka mea, na ke Akua mai ia, i haawi uia ia lakou iloko o ka lima o ka lakou poe enemi, no ka mea, ua imi lakou i na akua o ka Edoma.
Amasiah, bí ó tì wù kí ó rí kò tẹ́tí nítorí Ọlọ́run ṣe é kí ó lè gbé wọn lé Jehoaṣi lọ́wọ́: nítorí wọ́n wá àwọn ọlọ́run Edomu.
21 Pela i pii aku ai o Ioasa ke alii o ka Iseraela, a nana laua he maka no he maka, oia a me Amazia ke alii o ka Iuda ma Betesemesa, aia uo ma Iuda.
Bẹ́ẹ̀ ni Jehoaṣi, ọba Israẹli: òun àti Amasiah ọba Juda dojúkọ ara wọn ní Beti-Ṣemeṣi ní Juda.
22 A ua lukuia ka Iuda imua o ka Iseraela, a auhee aku la kela kanaka, keia kanaka i kona halelewa.
Àwọn ọmọ Israẹli da Juda rú, gbogbo olúkúlùkù ènìyàn sì sálọ sí ìlú rẹ̀.
23 A lawe pio o Ioasa ke alii o ka Iseraela ia Amazia ke alii o ka Iuda, ke keiki a Ioasa, ke keiki a Iehoahaza ma Betesemesa, a lawe ia ia i Ierusalema; a wawahi ia i ka pa o Ierusalema mai ka puka o Eperaima a i ka puka o ke kihi, eha haneri kubita.
Jehoaṣi ọba Israẹli fi agbára mú Amasiah ọba Juda, ọmọ Joaṣi ọmọ Ahasiah ní Beti-Ṣemeṣi. Nígbà náà Joaṣi mú u wá sí Jerusalẹmu. Ó sì wó ògiri Jerusalẹmu lulẹ̀ láti ẹnu-ọ̀nà Efraimu sí igun ẹnu-ọ̀nà apá kan títí ń lọ sí irinwó ìgbọ̀nwọ́ ní gígùn.
24 A lawe aku ia i ke gula a pau, a me ke kala, a me na kiaha a pau i loaa ia ia iloko o ka hale o ke Akua me Obededoma, a me ka waiwai o ka hale o ke alii, a me na mea e paa ana me he poe panai la, a hoi aku la i Samaria.
Ọba kó gbogbo wúrà àti fàdákà àti gbogbo ohun èlò tí wọ́n rí ni ilé Ọlọ́run tí ọ́ wà ní àbojútó Obedi-Edomu, lápapọ̀ pẹ̀lú àwọn ìṣúra ààfin àti àwọn ògo pẹ̀lú, ó sì padà lọ sí Samaria.
25 A ola o Amazia ke keiki a Ioasa, ke alii o ka Iuda, mahope o ka make ana o Ioasa, ke keiki a Iehoahaza ke alii o ka Iseraela, he umi a me kumamalima makahiki.
Amasiah ọmọ Joaṣi ọba Juda gbé fún ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún lẹ́yìn ikú Jehoaṣi ọmọ Jehoahasi ọba Israẹli.
26 A o ke koena o na hana a Amazia, ka mua a me ka hope, aole anei i kakauia'i ia mau mea ma ka buke no na'lii o ka Iuda, a me ka Iseraela?
Fún ti iṣẹ́ mìíràn ti ìjọba Amasiah láti ìbẹ̀rẹ̀ dé ìparí, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé àwọn ọba Juda àti Israẹli?
27 A mai ka wa mai o ko Amazia huli ana ae mai Iehova aku, ohumu ku e ka poe ma Ierusalema ia ia, a mahuka aku la ia i Lakisa; a hoouna lakou i Lakisa, a pepehi lakou ia ia malaila.
Láti ìgbà tí Amasiah ti yípadà kúrò láti máa tẹ̀lé Olúwa, wọ́n dìtẹ̀ sí i ní Jerusalẹmu, ó sì sálọ sí Lakiṣi ṣùgbọ́n, wọ́n rán àwọn ọkùnrin tẹ̀lé e lọ sí Lakiṣi, wọ́n sì pa á síbẹ̀.
28 A hali mai lakou ia ia maluna o na lio, a kanu lakou ia ia me kona poe kupuna ma ke kulanakauhale o Iuda.
A gbé e padà pẹ̀lú ẹṣin. A sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú ńlá ti Juda.

< II Oihanaalii 25 >