< II Oihanaalii 12 >

1 A PAA ke aupuni o Rehoboama, a ikaika hoi ia, alaila haalele oia i ke kanawai o Iehova, a me ia pu ka Iseraela a pau.
Lẹ́yìn ìgbà tí a fi ìjọba Rehoboamu múlẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba, tí ó sì ti di alágbára, òun àti gbogbo Israẹli, pẹ̀lú rẹ̀ ni wọ́n pa òfin Olúwa tì.
2 A i ka lima o ka makahiki o ke alii o Rehoboama, pii mai la o Sisaka, ke alii o Aigupita i Ierusalema, no ka mea, ua lawehala lakou ia Iehova,
Nítorí tí wọn kò ṣọ òtítọ́ sí Olúwa. Ṣiṣaki ọba Ejibiti dojúkọ Jerusalẹmu ní ọdún karùn-ún ti ọba Rehoboamu.
3 Me na kaa kaua he umikumamalua tausani, a me na hoohololio kanaono tausani, a me na kanaka i pau ole i ka heluia ka poe i hele pu me ia mai Aigupita mai; ka Luba, a me ka Suka, a me ka Kusa.
Pẹ̀lú ẹgbàá mẹ́fà kẹ̀kẹ́ àti ọ̀kẹ́ mẹ́ta àwọn ọkùnrin ẹlẹ́ṣin àti àìníye ọ̀wọ́ ogun ti Libia, Sukki àti Kuṣi, tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ láti Ejibiti.
4 Hoopio aku la oia i na kulanakauhale i paa i ka pa ma Iuda, a hiki mai la i Ierusalema.
Ó fi agbára mú àwọn ìlú ààbò ti Juda, pẹ̀lú wá sí Jerusalẹmu bí ó ti jìnnà tó.
5 Alaila, hele mai o Semaia, ke kaula, io Rehoboama la, a i na 'lii o Iuda i hoakoakoaia ma Ierusalema mai mua mai o Sisaka, i aku la ia lakou, Penei i olelo mai ai o Iehova ia oukou, Ua haalele oukou ia'u, no ia mea, ua haalele aku au ia oukou iloko o ka lima o Sisaka.
Nígbà náà, wòlíì Ṣemaiah wá sí ọ̀dọ̀ Rehoboamu àti sí ọ̀dọ̀ àwọn olórí Juda tí wọ́n ti péjọ ní Jerusalẹmu nítorí ìbẹ̀rù Ṣiṣaki, ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ìwọ ti pa mí tì; nítorí náà èmi náà ti pa yín tì sí ọ̀dọ̀ Ṣiṣaki.”
6 Hoohaahaa iho la na kaukaualii o ka Iseraela a me ka Moi ia lakou iho, i iho la, Ua pololei o Iehova.
Àwọn olórí Israẹli àti ọba rẹ̀ ará wọn sílẹ̀, wọ́n sì wí pé, “Olódodo ni Olúwa.”
7 A ike o Iehova, ua hoohaahaa lakou ia lakou iho, hiki mai la ka olelo a Iehova ia Semaia, i mai la, Ua hoohaahaa lakou ia lakou iho; aole au e luku loa ia lakou, e haawi no au ia lakou i wahi maha iki, aole au e ninini i ko'u huhu maluna o Ierusalema ma ka lima o Sisaka.
Nígbà tí Olúwa rí i pé, wọ́n ti rẹ̀ ara wọn sílẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa yí tọ Ṣemaiah lọ pé, “Níwọ́n ìgbà tí wọ́n ti rẹ ara wọn sílẹ̀, Èmi kì yóò pa wọ́n ṣùgbọ́n, yóò fún wọn ní ìtúsílẹ̀ tó bá yá. Ìbínú mi kì yóò dà sórí Jerusalẹmu ní ipasẹ̀ Ṣiṣaki.
8 Aka, e lilo lakou i poe kauwa nana, i ike lakou i ka hookauwa ana na'u, a me ka hookauwa ana na na aupuni o na aina.
Bí ó ti wù kí ó rí, wọn yóò sìn ní abẹ́ rẹ̀, kí wọn kí ó lè mọ̀ ìyàtọ̀ láàrín sí sìn mí àti sí sin àwọn ọba ilẹ̀ mìíràn.”
9 Alaila pii mai la Sisaka ke alii o Aigupita i Ierusalema, a hao iho la i ka waiwai o ka hale o Iehova, a me ka waiwai o ka hale o ke alii, hao iho la oia i na mea a pau; a lawe no hoi i na palekaua gula a Solomona i hana'i.
Nígbà tí Ṣiṣaki ọba Ejibiti dojúkọ Jerusalẹmu, ó gbé àwọn ìṣúra ilé Olúwa, àti àwọn ìṣúra ààfin ọba. Ó gbé gbogbo rẹ̀, pẹ̀lú àwọn àpáta wúrà tí Solomoni dá.
10 A hana ke alii o Rehoboama i mea e pani ai ko laila hakahaka, i na palekaua keleawe, a haawi ia mau mea iloko o ka lima o na luna o ka poe kiai, ka poe i malama i na puka o ka hale o ke alii.
Bẹ́ẹ̀ ni, ọba Rehoboamu dá àwọn àpáta idẹ láti fi dípò wọn, ó sì fi èyí lé àwọn alákòóso àti olùṣọ́ tí ó wà ní ẹnu iṣẹ́ ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà ààfin ọba lọ́wọ́.
11 A i na wa a pau a ke alii i komo ai iloko o ka hale o Iehova, komo no ka poe kiai, a lawe mai ia mau mea, a hoihoi aku no hoi ia mau mea iloko o ke keena o ka poe kiai.
Ìgbàkígbà tí ọba bá lọ sí ilé Olúwa, àwọn olùṣọ́ n lọ pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n ń gbé àwọn àpáta náà àti lẹ́yìn, wọ́n dá wọn padà sí yàrá ìṣọ́.
12 A i kona hoohaahaa ana ia ia iho, huli ae la ka huhu o Iehova mai ona aku la, aole i pepehi ia ia a make: a ma ka aina o Iuda, ua maikai no na mea malaila.
Nítorí ti Rehoboamu rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀, ìbínú Olúwa yí padà kúrò lórí rẹ̀, a kò sì pa á run pátápátá. Nítòótọ́, ìre díẹ̀ wà ní Juda.
13 A hookupaaia ke alii ma Ierusalema, a noho alii iho la, no ka mea, he kanahakumamakahi na makahiki o Rehoboama i kona wa i hooalii'i, a noho alii ia i na makahiki he umikumamahiku, ma Ierusalema, ke kulanakauhale a Iehova i wae ai maloko o na ohana a pau o ka Iseraela, e kau mai i kona inoa malaila. A o ka inoa o kona makuwahine, o Naama no ka Amona.
Ọba Rehoboamu fi ara rẹ̀ lélẹ̀ gidigidi ní Jerusalẹmu, ó sì tẹ̀síwájú gẹ́gẹ́ bí ọba. Ó jẹ́ ẹni ọdún mọ́kànlélógójì nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba fún ọdún mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n ní Jerusalẹmu, ìlú ńlá tí Olúwa ti yàn jáde kúrò nínú gbogbo àwọn ẹ̀yà Israẹli ní èyí tí ó fẹ́ fi orúkọ rẹ̀ síbẹ̀. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Naama, ará Ammoni.
14 A hana oia i ka hewa, no ka mea, aole ia i hoomakaukau i kona naau e imi ia Iehova.
O sì ṣe búburú, nítorí tí kò múra nínú ọkàn rẹ̀ láti wá Olúwa.
15 A o na mea mua a me na mea hope a Rehoboama i hana'i, aole anei i kakauia ia mau mea ma ka palapala a Semaia ke kaula, a me Ido ka mea wanana ma ka palapala kuauhau? A he kaua ia Rehoboama, a me Ieroboama i ko laua mau la a pau loa.
Fún tí iṣẹ́ ìjọba Rehoboamu láti ìbẹ̀rẹ̀ dé ìparí, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìrántí ti Ṣemaiah wòlíì àti ti Iddo, aríran tí ó ní ṣe pẹ̀lú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá? Ìtẹ̀síwájú ogun jíjà sì wà láàrín Rehoboamu àti Jeroboamu.
16 A hiamoe iho la o Rehoboama me kona mau kupuna; a ua kanuia oia ma ke kulanakauhale o Davida. A noho alii iho la o Abiia kana keiki mahope ona.
Rehoboamu sun pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ a sin ín sínú ìlú ńlá ti Dafidi. Abijah ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.

< II Oihanaalii 12 >