< I Samuela 4 >

1 A HIKI ae la ka olelo a Samuela i ka Iseraela a pau. Hele ku e aku la ka Iseraela i ko Pilisetia i ke kaua, a hoomoana iho la ma Ebenezera; a o ko Pilisetia hoomoana iho la ma Apeka.
Ọ̀rọ̀ Samuẹli tọ gbogbo àwọn ọmọ Israẹli wá. Nísinsin yìí àwọn ọmọ Israẹli jáde láti lọ bá àwọn Filistini jà. Àwọn ọmọ Israẹli sì pàgọ́ sí Ebeneseri àti àwọn Filistini ní Afeki.
2 Hoomakaukau iho ko Pilisetia ia lakou iho e ku e i ka Iseraela; a hoouka iho la, a ua lukuia o ka Iseraela imua o ko Pilisetia; a eha tausani kanaka paha i lukuia i ke kaua ana ma ke kula.
Àwọn Filistini mú ogun wọn sọ̀kalẹ̀ láti pàdé Israẹli, nígbà tí ogun náà bẹ̀rẹ̀, àwọn Filistini ṣẹ́gun Israẹli wọ́n pa ẹgbàajì ọkùnrin nínú ogun náà.
3 A hiki mai la na kanaka i kahi i hoomoana'i, i ae la na lunakahiko o ka Iseraela, No ke aha la o Iehova i luku mai ai ia kakou i keia la imua o ko Pilisetia? E lawe mai io kakou nei i ka pahuberita o Iehova mai Silo mai, a hiki mai ia iwaena o kakou, oia ka mea e hoola ia kakou mai ka lima mai o ko kakou poe enemi.
Nígbà tí àwọn ọmọ-ogun náà padà sí ibùdó, àwọn àgbàgbà Israẹli sì béèrè pé, “Èéṣe ti Olúwa fi mú kí àwọn Filistini ṣẹ́gun wa lónìí? Ẹ jẹ́ kí a gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa láti Ṣilo wá, kí ó ba à le lọ pẹ̀lú wa kí ó sì gbà wá là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa.”
4 Hoouna aku la na kanaka ma Silo e lawe mai mailaila mai i ka pahuberita o Iehova sabaota, e waiho ana mawaena o na kerubima: ilaila na keiki elua a Eli, o Hopeni a me Pinehasa me ka pahuberita o ke Akua.
Nítorí náà a rán àwọn ènìyàn lọ sí Ṣilo, wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wá, ẹni tí ń wà láàrín àwọn Kérúbù àti àwọn ọmọ Eli méjèèjì Hofini àti Finehasi wà níbẹ̀ pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run.
5 A hiki mai la ka pahuberita o Iehova iloko o kahi i hoomoana'i, hooho ae la ka Iseraela a pau me ka hooho nui, a haalulu ka honua.
Nígbà tí àpótí ẹ̀rí Olúwa wá sí ibùdó, gbogbo àwọn ọmọ Israẹli sì dìde láti kígbe tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ sì mì tìtì.
6 A lohe ae la ko Pilisetia i ka leo o ka hooho ana, i ae la lakou, No ke aha la ka leo o keia hooho nui ana ma kahi i hoomoana'i ka poe Hebera? A ike lakou, ua hiki mai ka pahu o Iehova ma kahi i hoomoana'i.
Ní ìgbà tí àwọn Filistini gbọ́ ariwo náà wọ́n béèrè pé, “Kí ni gbogbo ariwo yìí ní ibùdó Heberu?” Nígbà tí wọ́n mọ̀ wí pé àpótí ẹ̀rí Olúwa ti wá sí ibùdó,
7 Makau iho la ko Pilisetia, no ka mea, i iho la lakou, Ua hiki mai ke Akua iloko o kahi i hoomoana'i. I ae la lakou, Auwe kakou! no ka mea, aohe mea mamua e like ai me keia.
àwọn Filistini sì bẹ̀rù pé, Ọlọ́run kékeré ti wọ ibùdó, wọ́n wí pé, “A wọ wàhálà, irú èyí kò tí ì ṣẹlẹ̀ rí.
8 Auwe kakou! owai la ka mea nana kakou e hoola mai ka lima mai o keia mau Akua mana? o na Akua keia i luku ai i ka poe o Aigupita i ua ino a pau ma ka waonahele.
Àwa gbé! Ta ni yóò gbà wá kúrò lọ́wọ́ Ọlọ́run alágbára yìí? Àwọn ni Ọlọ́run tí ó fi ìpọ́njú pa àwọn ará Ejibiti pẹ̀lú gbogbo àjàkálẹ̀-ààrùn ní aginjù.
9 E ikaika oukou, e hookanaka hoi, e ko Pilisetia, i lilo ole ai oukou i kauwa na ka poe Hebera, e like me lakou na oukou: e hookanaka e kaua aku.
Ẹ jẹ́ alágbára Filistini, ẹ ṣe bí ọkùnrin, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ẹ̀yin yóò di ẹrú àwọn Heberu, bí wọ́n ti jẹ́ sí i yín. Ẹ jẹ́ alágbára ọkùnrin, kí ẹ sì jagun!”
10 A kaua aku la ko Pilisetia, a lukuia o ka Iseraela, a holo kela kanaka keia kanaka i kona halelewa; a he nui loa na mea i make, no ka mea, haule iho la o ka Iseraela, he kanakolu tausani koa hele wawae.
Nígbà náà àwọn Filistini jà, wọ́n sì ṣẹ́gun àwọn Israẹli olúkúlùkù sì sá padà sínú àgọ́ rẹ̀, wọ́n pa ọ̀pọ̀ ènìyàn, àwọn ará Israẹli tí ó kú sí ogun sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àwọn ọmọ-ogun orí ilẹ̀.
11 A ua haoia ka pahu o ke Akua; a make na keiki elua a Eli, o Hopeni a o Pinehasa.
Wọ́n gba àpótí ẹ̀rí Olúwa, àwọn ọmọkùnrin Eli méjèèjì sì kú, Hofini àti Finehasi.
12 Holo aku la kekahi kanaka no Beniamina mai ke kaua aku, a hiki ma Silo ia la hookahi, me kona kapa i haehaeia, a me ka lepo maluna o kona poo.
Lọ́jọ́ kan náà tí ará Benjamini kan sá wá láti ojú ogun tí ó sì lọ sí Ṣilo, aṣọ rẹ̀ sì fàya pẹ̀lú eruku lórí rẹ̀.
13 A hiki aku la ia, aia hoi, e noho ana o Eli maluna o ka noho ma kapa alanui, e kiai ana: no ka mea, pihoihoi kona naau no ka pahu o ke Akua. A hiki aku la ke kanaka ma ke kulanakauhale, a hai aku, auwe nui iho la ko ke kulanakauhale a pau.
Nígbà tí ó sì dé, Eli sì jókòó sórí àga rẹ̀ ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà, ó ń wò, ọkàn rẹ̀ kò balẹ̀ nítorí àpótí ẹ̀rí Olúwa. Nígbà tí ọkùnrin náà wọ ìlú tí ó sì sọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀, gbogbo ìlú bẹ̀rẹ̀ sí sọkún.
14 A lohe ae la o Eli i ka leo o ka uwe ana, i iho la ia, No ke aha la ka leo o keia haunaele? A hele koke mai ke kanaka, a hai ia Eli.
Eli gbọ́ ìró ohùn ẹkún náà ó sì béèrè pé, “Kí ni ìtumọ̀ ariwo yìí?” Ọkùnrin náà sì sáré tọ Eli wá
15 He kanaiwakumamawalu ko Eli mau makahiki, ua ku paa kona mau maka, aole ia i ike.
Eli sì di ẹni méjìdínlọ́gọ́run ọdún, tí ojú rẹ̀ di bàìbàì, kò sì ríran mọ́.
16 I mai la ke kanaka ia Eli, Owau no ka mea i hele mai, mai ke kaua mai, i keia la wau i holo mai nei mai ke kaua mai. Ninau aku la ia, Heaha ka olelo, e kuu keiki?
Ọkùnrin náà sọ fún Eli, “Mo ṣẹ̀ṣẹ̀ dé láti ibi ogun náà ni: mo sá láti ibi ogun náà wá lónìí.” Eli sì béèrè pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀ ọmọ mi?”
17 Olelo mai la ka elele, i mai la, Ua hee ka Iseraela imua o ko Pilisetia: a ua nui loa ka poe kanaka i pepehiia; a o kau mau keiki elua, o Hopeni a o Pinehasa, ua make laua, a ua haoia ka pahu o ke Akua.
Ọkùnrin tí ó mú ìròyìn náà wá dáhùn pé, “Israẹli sá níwájú àwọn Filistini, ìṣubú àwọn ọmọ-ogun náà sì pọ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ méjèèjì, Hofini àti Finehasi, wọ́n kú, wọ́n sì ti gba àpótí ẹ̀rí Olúwa lọ.”
18 A i kona hai ana mai i ka pahu o ke Akua, haule iho la o Eli mahope o kona noho ma ka aoao o ka ipuka, a hai kona a-i, a make iho la ia; no ka mea, he kanaka elemakule ia, ua kaumaha hoi. A ua hooponopono aku ia i ka Iseraela i na makahiki he kanaha.
Nígbà tí ó dárúkọ àpótí ẹ̀rí Olúwa, Eli sì ṣubú sẹ́yìn kúrò lórí àga ní ẹ̀gbẹ́ bodè, ọrùn rẹ̀ ṣẹ́, ó sì kú, nítorí tí ó jẹ́ arúgbó ọkùnrin, ó sì tóbi, ó ti darí àwọn Israẹli fún ogójì ọdún.
19 A o kona hunonawahine, ka wahine a Pinehasa, ua hapai, kokoke no i puni: a lohe ae la oia ia mea, i ka lilo ana o ka pahu o ke Akua, i ka make ana o kona makuahonoaikane a me kaua kane hoi, kulou iho la ia, no ka hanau ana; no ka mea, ua hiki mai kona nahunahu ia ia.
Aya ọmọ rẹ̀, ìyàwó Finehasi, ó lóyún ó súnmọ́ àkókò àti bí. Nígbà tí ó gbọ́ ìròyìn náà wí pé wọ́n ti gba àpótí ẹ̀rí Olúwa lọ àti wí pé baba ọkọ rẹ̀ àti ọkọ rẹ̀ ti kú, ó rọbí ó sì bímọ, ó sì borí ìrora ìrọbí náà.
20 A kokoke ia e make, i aku la na wahine e ku ana ia ia, Mai makau oe, no ka mea, ua hoohanau oe i keikikane. Aole ia i ekemu mai, aole hoi ia i maliu mai.
Bí ó ti ń kú lọ, obìnrin tí ó dúró tì í wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù; nítorí o ti bí ọmọ ọkùnrin.” Ṣùgbọ́n kò sọ̀rọ̀ tàbí kọ ibi ara sí i.
21 A kapa aku la ia i ka inoa o ke keiki o Ikaboda, i aku la, Ua hala aku la ka nani mai ka Iseraela aku; no ka pahu o ke Akua i laweia'ku, a no kona makuahonoaikane, a no kana kane.
Ó sì pe ọmọ náà ní Ikabodu, wí pé, “Kò sí ògo fún Israẹli mọ́,” nítorí tí wọ́n ti gba àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run àti ikú baba ọkọ rẹ̀ àti ti ọkọ rẹ̀.
22 I aku la ia, Ua hala aku la ka nani mai ka Iseraela aku: no ka mea, ua haoia ka pahu o ke Akua.
Ó si wí pé, “Ògo kò sí fún Israẹli mọ́, nítorí ti a ti gbá àpótí Ọlọ́run.”

< I Samuela 4 >