< I Samuela 1 >

1 O KEKAHI kanaka no Ramataima-Zopima, no ka mauna o Eperaima, o Elekana kona inoa, ke keiki a Ierohama, ke keiki a Elihu, ke keiki a Tohu, ke keiki a Zupa, no Eperata:
Ọkùnrin kan wà, láti Ramataimu-Sofimu, láti ìlú olókè Efraimu, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Elkana, ọmọ Jerohamu, ọmọ Elihu, ọmọ Tohu, ọmọ Sufu, ará Efrata.
2 Elua aua wahine; o Hana ka inoa o kekahi, a o Penina ka inoa o kekahi: a he mau keiki na Penina, aka, o Hana aohe ana keiki.
Ó sì ní ìyàwó méjì, orúkọ wọn ni Hana àti Penina: Penina ní ọmọ, ṣùgbọ́n Hana kò ní.
3 I kela makahiki keia makahiki, hele aku ua kanaka la mai kona kulanakauhale aku e hoomana, a e kaumaha aku ia Iehova o na lehulehu ma Silo; malaila na keiki elua a Eli, o Hopeni laua o Pinehasa, na kahuna a Iehova.
Ní ọdọọdún, ọkùnrin yìí máa ń gòkè láti ìlú rẹ̀ láti lọ sìn àti láti ṣe ìrúbọ sí Olúwa àwọn ọmọ-ogun jùlọ ní Ṣilo, níbi tí àwọn ọmọkùnrin Eli méjèèjì, Hofini àti Finehasi ti jẹ́ àlùfáà Olúwa.
4 A hiki mai ka la a Elekana i kaumaha aku ai, haawi aku la ia i na haawina na Penina, na kana wahine, a na kana mau keikikane a pau, a na kana mau kaikamahine.
Nígbàkígbà tí ó bá kan Elkana láti ṣe ìrúbọ, òun yóò bù lára ẹran fún aya rẹ̀ Penina àti fún gbogbo àwọn ọmọ ọkùnrin àti obìnrin.
5 A haawi papalua aku la ia na Hana; no ka mea, ua aloha aku oia ia Hana: aka, ua pa ia ia Iehova.
Ṣùgbọ́n ó máa ń pín ìlọ́po fun Hana nítorí pé ó fẹ́ràn rẹ̀ àti pé Olúwa ti sé e nínú.
6 Hoonaukiuki aku la kona enemi ia ia, i mea e hoonaulu aku ai ia ia; no ka mea, ua hoopaa o Iehova i kona opu.
Nítorí pé Olúwa ti sé e nínú, orogún rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí ní fín níràn láti lè mú kí ó bínú.
7 Pela kana i hana'i mai kela makahiki a keia makahiki, ia ia i pii aku ai i ka hale o Iehova, pela no ia i hoonaukiuki aku ai ia ia, a uwe iho la o Hana, aole ia i ai.
Eléyìí sì máa ń ṣẹlẹ̀ ní ọdọọdún. Nígbàkígbà tí Hana bá gòkè lọ sí ilé Olúwa, orogún rẹ̀ a máa fín níràn títí tí yóò fi máa sọkún tí kò sì ní lè jẹun.
8 Alaila ninau aku la o Elekana kana kane ia ia, E Hana, heaha kau i uwe ai? No ke aha la aole oe i ai? Heaha ka mea i kaumaha'i kou naau? Aole anei e oi aku ko'u pono ia oe imua o na keikikane he umi?
Elkana ọkọ rẹ̀ yóò sọ fún un pé, “Hana èéṣe tí ìwọ fi ń sọkún? Èéṣe tí ìwọ kò fi jẹun? Èéṣe tí ìwọ fi ń ba ọkàn jẹ́? Èmi kò ha ju ọmọ mẹ́wàá lọ fún ọ bí?”
9 Ku ae la o Hana mahope o ka lakou ai ana a me ka lakou inu ana ma Silo: a e noho ana o Eli ke kahuna maluna o ka noho ma ka lapauila o ka hale o Iehova.
Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti jẹ, tí wọ́n tún mu tán ní Ṣilo, Hana dìde wá síwájú Olúwa. Nígbà náà, Eli àlùfáà wà lórí àga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa ní ibi tí ó máa ń jókòó.
10 Ua kaumaha kona naau, pule aku la oia ia Iehova, a uwe nui iho la.
Pẹ̀lú ẹ̀dùn ọkàn Hana sọkún gidigidi, ó sì gbàdúrà sí Olúwa.
11 Hoohiki iho la ia i ka hoohiki ana, i aku la, E Iehova o na lehulehu, a i ike pono mai oe i ka ehaeha o kau kauwawahine, a i hoomanao mai ia'u, aole i hoopoina i kau kauwawahine, a i haawi mai hoi i keikikane no kau kauwawahine; alaila e hoolilo au ia ia no Iehova i na la a pau o kona ola ana; aole e hoopiliia mai ka pahi amu ma kona poo.
Ó sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, jùlọ tí ìwọ bá le bojú wo ìránṣẹ́bìnrin rẹ kí ìwọ sì rántí rẹ̀, tí ìwọ kò sì gbàgbé ìránṣẹ́ rẹ ṣùgbọ́n tí ìwọ yóò fún un ní ọmọkùnrin, nígbà náà èmi yóò sì fi fún Olúwa ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀ a kì yóò sì fi abẹ kàn án ní orí.”
12 A i kana pule nui ana imua o Iehova, nana aku la o Eli i kona waha.
Bí ó sì ṣe ń gbàdúrà sí Olúwa, Eli sì kíyèsi ẹnu rẹ̀.
13 Maloko o kona naau ka Hana olelo ana; akoako wale no kona lehelehe, aole i loheia kona leo: nolaila manao iho la o Eli, ua ona ia.
Hana ń gbàdúrà láti inú ọkàn rẹ̀, ṣùgbọ́n ètè rẹ̀ ni ó ń mì, a kò gbọ́ ohùn rẹ̀. Eli rò wí pé ó ti mu ọtí yó.
14 Ninau aku la o Eli ia ia, Pehea la ka loihi o kou ona ana? E hoolei oe i kou waina mai ou aku la.
Eli sì wí fún un pé, “Yóò ti pẹ́ fún ọ tó tí ìwọ yóò máa yó? Mú ọtí wáìnì rẹ̀ kúrò.”
15 Olelo aku la o Hana, i aku la, Aole, e kuu haku; he wahine ehaeha wau ma ka naau; aole au i inu i ka waina, aole i ka mea ona, aka, ua ninini aku au i kuu uhane imua o Iehova.
Hana dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, Olúwa mi, èmi ni obìnrin oníròbìnújẹ́. Èmi kò mu ọtí wáìnì tàbí ọtí líle; èmi ń tú ọkàn mi jáde sí Olúwa ni.
16 Mai manao mai oe i kau kauwawahine, he kaikamahine na ka hewa; no ka mea, no ka nui o kuu ehaeha ana, a me ke kaumaha, ua olelo iho nei au a keia wa.
Má ṣe mú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí obìnrin búburú. Èmi ti ń gbàdúrà níhìn-ín nínú ìrora ọkàn àti ìbànújẹ́ mi.”
17 Olelo aku la o Eli, i aku la. O hele oe me ke aloha: a na ke Akua o ka Israela e hooko mai kau mea au i noi aku ai ia ia.
Eli dáhùn pé, “Máa lọ ní àlàáfíà, kí Ọlọ́run Israẹli fi ohun tí ìwọ ti béèrè ní ọwọ́ rẹ̀ fún ọ.”
18 I mai la ia, I loaa i kau kauwawahine ke aloha imua o kou maka. A hele aku la ua wahine la ma kona wahi i hele ai, a ai iho la, aole minamina hou kona maka.
Ó wí pé, “Kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ rí oore-ọ̀fẹ́ lójú rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin náà bá tirẹ̀ lọ, ó sì jẹun, kò sì fa ojú ro mọ́.
19 Ala ae la lakou i kakahiaka nui, a hoomana aku la imua o Iehova, a hoi aku la a hiki i ko lakou hale ma Rama: a ike iho la o Elekana ia Hana i kana wahine; a hoomanao mai la o Iehova ia ia.
Wọ́n sì dìde ni kùtùkùtù òwúrọ̀, wọn wólẹ̀ sìn níwájú Olúwa, wọn padà wa sí ilé wọn ni Rama: Elkana si mọ Hana aya rẹ̀: Olúwa sì rántí rẹ̀.
20 A hiki mai ka manawa mahope o ka Hana hapai ana, hanau mai la ia, he keikikane, a kapa aku la ia i kona inoa o Samuela; no ka mea, ua noi aku au ia ia ia Iehova.
Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ rẹ̀ pé, lẹ́yìn ìgbà tí Hana lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Samuẹli, pé, “Nítorí tí mo béèrè rẹ̀ lọ́wọ́ Olúwa.”
21 A o ua kanaka la, o Elekana, a me ko kona hale a pau, hele aku la e kaumaha aku ia Iehova i ka mohai makahiki, a me kona hoohiki ana.
Ọkùnrin náà Elkana, àti gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀, gòkè lọ láti rú ẹbọ ọdún sí Olúwa, àti láti sán ẹ̀jẹ́ rẹ̀.
22 Aka, aole hiki aku o Hana, no ka mea, olelo aku la ia i kana kane, Aia e ukuhiia'ku ai ke keiki, alaila lawe aku au ia ia, e ikea ia ma ke alo o Iehova, a e noho mau loa ia ilaila.
Ṣùgbọ́n Hana kò gòkè lọ; nítorí tí ó sọ fún ọkọ rẹ̀ pé, “Ó di ìgbà tí mo bá gba ọmú lẹ́nu ọmọ náà, nígbà náà ni èmi yóò mú un lọ, kí òun lè fi ara hàn níwájú Olúwa, kí ó sí máa gbé ibẹ̀ títí láé.”
23 I mai la o Elekana kana kane ia ia, E hana oe i ka pono i kou manao: e noho, a hiki mai ka manawa e ukuhi aku ai oe ia ia; e hooko mai o Iehova i kana olelo. Noho iho la ka wahine e hanai i ke keiki, a hiki i ka wa e ukuhi aku ai ia ia.
Elkana ọkọ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Ṣe èyí tí ó tọ́ lójú rẹ. Dúró títí ìwọ yóò fi gba ọmú lẹ́nu rẹ̀; ṣùgbọ́n kí Olúwa sá à mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin náà sì jókòó, ó sì fi ọmú fún ọmọ rẹ̀ títí ó fi gbà á lẹ́nu rẹ̀.
24 A i ka wa i ukuhi aku ai ia i ke keiki, lawe aku la oia ia ia me na bipikane ekolu, hookahi epa palaoa, hookahi hue waina hoi, a lawe aku la ia ia i ka hale o Iehova ma Silo: a opiopio no hoi ke keiki.
Nígbà tí ó sì gba ọmú lẹ́nu rẹ̀, ó sì mú un gòkè lọ pẹ̀lú ara rẹ̀. Pẹ̀lú ẹgbọrọ màlúù mẹ́ta, àti ìyẹ̀fun efa kan, àti ìgò ọtí wáìnì kan, ó sì mú un wá sí ilé Olúwa ní Ṣilo: ọmọ náà sì wà ní ọmọdé.
25 Pepehi iho lakou i ka bipikane, a lawe aku la i ke keiki ia Eli.
Wọ́n pa ẹgbọrọ màlúù, wọ́n sì mú ọmọ náà tọ Eli wá.
26 Olelo aku la ia, E kuu haku, ma kou ola ana, e kuu haku, owau no ka wahine i ku pu me oe maanei e pule ana ia Iehova.
Hana sì wí pé, “Olúwa mi, bí ọkàn rẹ ti wà láààyè, Olúwa mi, èmi ni obìnrin náà tí ó dúró lẹ́bàá ọ̀dọ̀ rẹ níhìn-ín tí ń tọrọ lọ́dọ̀ Olúwa.
27 O keia keiki ka'u i pule aku ai; a ua haawi mai o Iehova ia'u i ka'u noi a'u i noi aku ai ia ia.
Ọmọ yìí ni mo ń tọrọ; Olúwa sì fi ìdáhùn ìbéèrè tí mo béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀ fún mi.
28 No ia mea, ke haawi aku nei au ia ia no Iehova. I na la a pau o kona ela ana e haawiia oia no Iehova. A hoomana aku la lakou ia Iehova malaila.
Nítorí náà pẹ̀lú, èmi fi í fún Olúwa; ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀: nítorí tí mo ti béèrè rẹ̀ fún Olúwa.” Wọn si wólẹ̀ sin Olúwa níbẹ̀.

< I Samuela 1 >