< I Na Lii 21 >

1 EIA hoi kekahi mea mahope mai o ia mau mea, he malawaina ia Nabota no Iezereela, maloko ia o Iezereela, e pili ana i ka halealii o Ahaba ke alii o Samaria.
Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí Naboti ará Jesreeli sì ní ọgbà àjàrà kan ní Jesreeli, ní ẹ̀gbẹ́ ààfin Ahabu ọba Samaria.
2 Olelo mai la o Ahaba ia Nabota, i mai la, E haawi mai oe i kou malawaina, i lilo ia ia'u i mala laauikiai, no ka mea, e kokoke mai ana no ia i ko'u hale; a e haawi aku au nau i ka malawaina e oi aku kona mai kai mamua o keia: a i pono ia oe, e haawi aku au ia oe i ke kala e like kona waiwai me ia.
Ahabu sì wí fún Naboti pé, “Fún mi ní ọgbà àjàrà rẹ, kí èmi kí ó fi ṣe ọgbà-ewébẹ̀, nítorí tí ó súnmọ́ tòsí ilé mi, èmi yóò sì fún ọ ní ọgbà àjàrà tí ó sàn jù ú lọ dípò rẹ̀; tàbí bí ó bá sì dára ní ojú rẹ, èmi yóò fi iye owó rẹ̀ fún ọ.”
3 I aku la o Nabota ia Ahaba, Na Iehova wau e hoole mai, i ole e haawi au i ka hooilina o ko'u mau makua ia oe.
Ṣùgbọ́n Naboti wí fún Ahabu pé, “Olúwa má jẹ́ kí èmi fi ogún àwọn baba mi fún ọ.”
4 Hele ae la hoi o Ahaba iloko o kona hale me ke kaumaha, a me ka huhu, no ka olelo a Nabota no Iezereela i olelo aku ai ia ia; no ka mea, ua olelo oia, Aole au e haawi aku i ka hooilina o ko'u mau makua ia oe. Moe iho la oia ma kona wahi moe, haliu e aku i kona maka, aole hoi i ai i ka berena.
Ahabu sì wá sí ilé rẹ̀, ó wugbọ́, inú rẹ̀ sì bàjẹ́ nítorí ọ̀rọ̀ tí Naboti ará Jesreeli sọ fún un; nítorí tí ó wí pé, “Èmi kì yóò fún ọ ní ogún àwọn baba mi.” Ó sì dùbúlẹ̀ lórí ibùsùn rẹ̀, ó sì yí ojú rẹ̀ padà, kò sì fẹ́ jẹun.
5 Alaila hele ae la kana wahine o Iezebela io na la, ninau aku la hoi, No ke aha la e kaumaha nei kou uhane, i ole ai oe e ai i ka berena?
Jesebeli aya rẹ̀ sì tọ̀ ọ́ wá, ó sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Èéṣe tí inú rẹ fi bàjẹ́, èéṣe tí ìwọ kò sì jẹun?”
6 Hai mai la oia, No ka mea, ua olelo aku au ia Nabota no Iezereela, i ka i ana'ku ia ia, E haawi mai oe i kou malawaina ia'u no ke kala; a, ina e makemake oe, e haawi aku au ia oe i kekahi malawaina e nona; a olelo mai la oia, Aole au e haawi i kuu malawaina ia oe.
Ó sì dá a lóhùn pé, “Nítorí tí mo wí fún Naboti ará Jesreeli pé, ‘Ta ọgbà àjàrà rẹ fún mi, tàbí bí ó bá wù ọ́, èmi yóò fún ọ ní ọgbà àjàrà mìíràn ní ipò rẹ̀.’ Ṣùgbọ́n ó wí pé, ‘Èmi kì yóò fún ọ ní ọgbà àjàrà mi.’”
7 I aku la hoi o Iezebela kana wahine ia ia, Ke hoomalu nei anei oe i ke aupuni o ka Iseraela? E ala'e a e ai i ka berena, e olioli kou naau, na'u no e haawi i ka malawaina o Nabota no Iezereela ia oe.
Jesebeli aya rẹ̀ sì wí pé, “Ṣé báyìí ni ìwọ yóò ṣe ṣe bí ọba lórí Israẹli? Dìde, jẹun! Kí o sì jẹ́ kí inú rẹ̀ dùn. Èmi yóò sì fún ọ ní ọgbà àjàrà Naboti ará Jesreeli.”
8 Kakau iho la oia i na palapala ma ka inoa o Ahaba, a kau iho la i kona sila, a hoouna aku la i ua mau palapala la i na lunakahiko a me na haku na mea iloko o kona kulanakauhale, e noho ana me Nabota.
Bẹ́ẹ̀ ni ó kọ̀wé ní orúkọ Ahabu, ó sì fi èdìdì rẹ̀ dì í, ó sì fi ìwé náà ránṣẹ́ sí àwọn àgbàgbà àti àwọn ọlọ́lá tí ó ń gbé ní ìlú Naboti pẹ̀lú rẹ̀.
9 Palapala ae la ia iloko o na palapala, i aku la, E kala aku i ka hookeai, a e hooku ia Nabota iluna imua o na kanaka;
Nínú àwọn ìwé náà, ó kọ pé, “Ẹ kéde àwẹ̀, kí ẹ sì fi Naboti sí ipò ọlá láàrín àwọn ènìyàn.
10 A e hooku hoi i na kanaka elua, i na keiki a Beliala, imua ona, e hoike ku e ia ia, e olelo ana, Ua hoi no wale oe i ke Akua a i ke alii. Alaila lawe aku ia ia mawaho, a e hailuku ia ia i make ia.
Ṣùgbọ́n kí ẹ fi ènìyàn méjì, ẹni búburú síwájú rẹ̀ láti jẹ́rìí sí i wí pé, ó bú Ọlọ́run àti ọba. Nígbà náà ni kí ẹ mú u jáde, kí ẹ sì sọ ọ́ ní òkúta pa.”
11 Hana iho la na kanaka o ke kulanakauhale, o na lunakahiko a me na haku ka poe e noho ana ma kona kulanakauhale, e like me ka Iezebela i hoouna aku ai ia lakou, a e like me ka mea i kakauia maloko o na palapala ana i hoouna aku ai ia lakou.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ọlọ́lá tí wọ́n ń ṣe ará ìlú Naboti sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ìwé tí Jesebeli kọ ránṣẹ́ sí wọn.
12 Kala ae la lakou i ka hookeai, a hooku ae la lakou ia Nabota iluna imua o na kanaka.
Wọ́n sì kéde àwẹ̀, wọ́n sì fi Naboti sí ipò ọlá láàrín àwọn ènìyàn.
13 A hele mai la na kanaka elua, na keiki a Beliala, a noho iho la imua ona: hoike ku e ae la ua mau kanaka la o Beliala ia ia, ia Nabota, ma ke alo o na kanaka, i ae la, Ua hoino wale o Nabota i ke Akua a i ke alii. Alaila lawe ae la lakou ia ia mawaho o ke kulanakauhale, a hailuku aku la lakou ia ia me na pohaku a make ia.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin méjì sì dé, àwọn ẹni búburú, wọ́n sì jókòó síwájú rẹ̀, wọ́n sì jẹ́rìí lòdì sí Naboti níwájú àwọn ènìyàn wí pé, “Naboti ti bú Ọlọ́run àti ọba.” Nígbà náà ni wọ́n mú jáde kúrò ní ìlú, wọ́n sì sọ ọ́ ní òkúta pa.
14 Alaila hoouna mai la lakou io Iezebela la, i mai la, Ua hailukuia o Nabota, a ua make.
Nígbà náà ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jesebeli wí pé, “A ti sọ Naboti ní òkúta, ó sì kú.”
15 Eia hoi kekahi, i ka lohe ana o Iezebela ua hailukuia o Nabota, a ua make, i aku la o Iezebela ia Ahaba, E eu e komo i ka malawaina o Nabota no Iezereela, ka mea ana i haawi ole ai ia oe no ke kala; no ka mea, aole e ola ana o Nabota, aka, ua make no.
Bí Jesebeli sì ti gbọ́ pé, a ti sọ Naboti ní Òkúta pa, ó sì wí fún Ahabu pé, “Dìde! Kí o sì jogún ọgbà àjàrà Naboti, ará Jesreeli, tí ó kọ̀ láti tà fún ọ kò sí láààyè mọ́, ó ti kú.”
16 Eia keia, i ka lohe ana o Ahaba, ua make o Nabota, ku ae la o Ahaba iluna e iho i ka malawaina o Nabota no Iezereela, e lawe ia nona.
Nígbà tí Ahabu sì gbọ́ pé Naboti ti kú, ó sì dìde, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún ọgbà àjàrà Naboti.
17 Hiki mai la ka olelo a Iehova ia Elia no Tiseba, i mai la,
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah ará Tiṣibi wá wí pé,
18 E eu, e iho ae oe e halawai me Ahaba ke alii o ka Iseraela, o ko Samaria; aia hoi ia maloko o ka malawaina o Nabota kahi i iho ai oia e komo.
“Sọ̀kalẹ̀ lọ láti lọ pàdé Ahabu ọba Israẹli, tí ó wà ní Samaria. Ó wà ní ọgbà àjàrà Naboti báyìí, níbi tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún rẹ̀.
19 E olelo aku hoi oe ia ia, i ka i ana aku, Ke i mai nei o Iehova, Ua pepehi ae nei anei oe, a ua lawe hoi nou? A e olelo aku oe ia ia, Ke i mai nei o Iehova penei, Ma kahi i palu ai o na ilio i ke koko o Nabota, malaila no e palu ai na ilio i kou koko, i kou ponoi no.
Sọ fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Ǹjẹ́ ìwọ kò ti pa ènìyàn, o sì ti fi agbára gba ogún rẹ̀?’ Nígbà náà ni kí o wí fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Níbi tí ajá gbé lá ẹ̀jẹ̀ Naboti, ni àwọn ajá yóò lá ẹ̀jẹ̀ rẹ, àní tìrẹ!’”
20 A olelo ae la o Ahaba ia Elia, Ua loaa anei au ia oe, e kuu enemi? I aku la o Elia, Ua loaa no ia'u, no ka mea, ua kuai lilo aku oe ia oe iho e hana ma ka hewa imua o Iehova.
Ahabu sì wí fún Elijah pé, “Ìwọ ti rí mi, ìwọ ọ̀tá mi!” Ó sì dáhùn wí pé, “Èmi ti rí ọ, nítorí tí ìwọ ti tan ara rẹ láti ṣe búburú níwájú Olúwa.
21 Eia hoi, e hoili au i ka poino maluna ou, a e kaili ae au i kou hope, a e hooki aku au i na kane mai Ahaba aku, a me ka mea paa a me ka mea paa ole iloko o ka Iseraela.
‘Èmi yóò mú ibi wá sórí rẹ. Èmi yóò sì mú ìran rẹ kúrò, èmi yóò sì ké kúrò lọ́dọ̀ Ahabu gbogbo ọmọdé ọkùnrin, àti ọmọ ọ̀dọ̀, àti òmìnira ní Israẹli.
22 A e hoohalike au i kau ohana me ka ohana a Ieroboama ke keiki a Nebata, a e like me ka ohana a Baasa ke keiki a Ahiia, no ka hoonaukiuki ana i hoohuhu mai ai oe ia'u, a i hoolilo ai hoi i ka Iseraela e lawehala.
Èmi yóò ṣe ilé rẹ bí ilé Jeroboamu, ọmọ Nebati, àti bí ilé Baaṣa, ọmọ Ahijah, nítorí ìwọ ti mú mi bínú, ìwọ sì ti mú Israẹli ṣẹ̀.’
23 A no Iezebela kekahi i olelo mai ai o Iehova, i mai la, E ai na ilio ia Iezebela ma ka pa o Iezereela.
“Àti ní ti Jesebeli pẹ̀lú Olúwa wí pé, ‘Àwọn ajá yóò jẹ Jesebeli nínú yàrá Jesreeli.’
24 A o ko Ahaba mea make maloko o ke kulanakauhale, oia ka na ilio e ai ai; a o ka mea make ma kula, oia ka na manu o ka lewa e ai ai.
“Àwọn ajá yóò jẹ ẹni Ahabu tí ó kú ní ìlú, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run yóò jẹ àwọn ẹni tí ó kú ní igbó.”
25 Aohe mea like me Ahaba, ka mea i kuai lilo aku ia ia iho e hana ma ka hewa, ma ke alo o Iehova, ka mea a Iezebela kana wahine i hooikaika aku ai.
(Kò sí ẹnìkan bí Ahabu tí ó ta ara rẹ̀ láti ṣe búburú níwájú Olúwa, ẹni tí Jesebeli aya rẹ̀ ń tì.
26 Hana hoi oia i ka mea e inaina nui ia i kona hahai ana mamuli o na akuakii, e like me ka Amora i hana'i a pau, ka poe a Iehova i kipaku aku ai imua o na mamo a Iseraela.
Ó sì ṣe ohun ìríra gidigidi ní tí tọ òrìṣà lẹ́yìn, gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí àwọn ará Amori ti ṣe, tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli.)
27 Eia hoi kekahi, i ka lohe ana o Ahaba i keia mau olelo, uhae ae la oia i kona kapa, a kau i ke kapa eleele i kona io, a hookeai iho. a moe iho la iloko o ke kapa eleele, a hele malie no hoi.
Nígbà tí Ahabu sì gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ sí ara rẹ̀, ó sì gbààwẹ̀. Ó sì dùbúlẹ̀ nínú aṣọ ọ̀fọ̀, ó sì ń lọ jẹ́ẹ́.
28 Hiki mai la ka olelo a Iehova ia Elia no Tiseba, i mai la,
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah ará Tiṣibi wá wí pé,
29 Ke ike nei anei oe i ko Ahaba hoohaahaa ana ia ia iho imua o'u? No kona hoohaahaa ana ia ia iho imua o'u, aole au e lawe mai i ka poino, i kona mau la; aka, i na la o kana keiki e hoili ai au i ka poino maluna o kana ohana.
“Ǹjẹ́ ìwọ ti rí bí Ahabu ti rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀ níwájú mi? Nítorí tí ó ti rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀, èmi kì yóò mú ibi náà wá ní ọjọ́ rẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò mú u wá sí ilé rẹ̀ ní ọjọ́ ọmọ rẹ̀.”

< I Na Lii 21 >