< I Na Lii 2 >

1 HOOKOKOKE mai la hoi na la o Davida e make ai; a kauoha mai la oia ia Solomona i kana keiki, i mai la,
Nígbà tí ọjọ́ ikú Dafidi súnmọ́ etílé, ó pàṣẹ fún Solomoni ọmọ rẹ̀.
2 Ke hele nei au i ka aoao o ko ka honua a pau: e hooikaika oe, a e hookanaka hoi;
Ó sì wí pé, “Èmi ti fẹ́ lọ sí ọ̀nà gbogbo ayé, nítorí náà jẹ́ alágbára kí o sì fi ara rẹ hàn bí ọkùnrin,
3 A e malama oe i ke kauoha a Iehova kou Akua, e hele ma kona mau aoao, me ka malama i kona mau kapu, a me kana mau kauoha, a me kona mau kanawai, a me kana mau olelo me ia i kakauia'i ma ke kanawai ia Mose, i pomaikai oe ma na mea a pau au e hana aku ai, a i na wahi a pau e huli ae ai oe:
kí o sì wòye ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ béèrè, rìn ní ọ̀nà rẹ̀, kí o sì pa àṣẹ àti òfin rẹ̀ mọ́, àti ìdájọ́ rẹ, àti ẹ̀rí rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé òfin Mose, nítorí kí ìwọ kí ó le è máa ṣe rere ní ohun gbogbo tí ìwọ ṣe, àti ní ibikíbi tí ìwọ bá lọ,
4 I hooko iho ai o Iehova i kana olelo ana i olelo mai ai no'u, i ka i ana mai, Ina e malama kau mau keiki i ko lakou aoao, e hele imua o'u me ka oiaio, me ko lakou naau a pau, a me ko lakou uhane a pau, aole oe e nele i ke kanaka ole (wahi ana) e noho maluna o ka nohoalii o ka Iseraela.
kí Olúwa kí ó lè pa ìlérí rẹ̀ tí ó sọ nípa tèmi mọ́ pé, ‘Bí àwọn ọmọ rẹ bá kíyèsi ọ̀nà wọn, tí wọ́n bá sì fi gbogbo àyà wọn àti ọkàn wọn rìn níwájú mi ní òtítọ́, o kì yóò sì kùnà láti ní ọkùnrin kan lórí ìtẹ́ Israẹli.’
5 A ua ike no hoi oe i ka mea a Ioaba ke keiki a Zeruia i hana mai ai ia'u, a me ka mea ana i hana'ku ai i na luna elua o ka poe koa o ka Iseraela, ia Abenera ke keiki a Nera, a ia Amasa ke keiki a Ietera; ua pepehi oia ia laua, a ua hookahe oia i ke koko o ke kaua i ka wa maluhia, ua kau hoi oia i ke koko o ke kaua ma kona kaei i kaeiia'i kona puhaka, a ma kona mau kamaa i hookomoia'i kona mau wawae.
“Ìwọ pẹ̀lú sì mọ ohun tí Joabu ọmọ Seruiah ṣe sí mi àti ohun tí ó ṣe sí balógun méjì nínú àwọn ológun Israẹli, sí Abneri ọmọ Neri àti sí Amasa ọmọ Jeteri. Ó sì pa wọ́n, ó sì ta ẹ̀jẹ̀ wọn sílẹ̀ ní ìgbà àlàáfíà bí í ti ojú ogun ó sì fi ẹ̀jẹ̀ náà sí ara àmùrè rẹ̀ tí ń bẹ ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, àti sí ara sálúbàtà rẹ̀ tí ń bẹ ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
6 Nolaila e hana oe mamuli o kou akamai, i ole ai e iho maluhia kona poohina i ka luakupapau. (Sheol h7585)
Ṣe sí í gẹ́gẹ́ bí ọgbọ́n rẹ̀, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí ewú orí rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí isà òkú ní àlàáfíà. (Sheol h7585)
7 Aka, e lokomaikai aku oe i na keiki a Barezilai no Gileada, o lakou kekahi o ka poe e ai ana ma kou papaaina; no ka mea, pela lakou i hele mai ai ia'u i ko'u hee ana imua o Abesaloma kou hoahanau.
“Ṣùgbọ́n fi inú rere hàn sí àwọn ọmọ Barsillai, ti Gileadi, jẹ́ kí wọn wà lára àwọn tí ó ń jẹun lórí tábìlì rẹ̀. Wọ́n dúró tì mí nígbà tí mo sá kúrò níwájú Absalomu arákùnrin rẹ.
8 Aia hoi me oe o Simei ke keiki a Gera ka Beniamina no Bahurima, ua hoino wale mai oia ia'u me ka olelo hoino loa i ka la i hele aku ai au i Mahanaima; aka, ua hele ae ia e halawai me au ma Ioredane, a hoohiki aku la au nona, ma o Iehova la, i aku la, Aole au e pepehi aku ia oe me ka pahikaua.
“Àti kí o rántí, Ṣimei ọmọ Gera ẹ̀yà Benjamini tí Bahurimu wà pẹ̀lú rẹ̀, tí ó bú mi ní èébú tí ó korò ní ọjọ́ tí mo lọ sí Mahanaimu. Nígbà tí ó sọ̀kalẹ̀ wá pàdé mi ní Jordani, mo fi Olúwa búra fún un pé, ‘Èmi kì yóò fi idà pa ọ́.’
9 Ano hoi, mai hoapono oe ia ia, no ka mea, he kanaka naauao no oe, a ua ike oe i kau mea e pono ai ke hana aku ia ia; aka, e hooiho oe i kona poohina ilalo i ka luakupapau me ke koko. (Sheol h7585)
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, má ṣe kíyèsi í gẹ́gẹ́ bí aláìlẹ́ṣẹ̀, ọkùnrin ọlọ́gbọ́n ni ìwọ ṣe; ìwọ yóò mọ ohun tí ìwọ yóò ṣe sí i. Mú ewú orí rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sínú isà òkú pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀.” (Sheol h7585)
10 Alaila hiamoe iho la o Davida me kona mau makua, a ua kanuia ma ke kulanakauhale o Davida.
Nígbà náà ni Dafidi sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dafidi.
11 A o na la i alii ai o Davida maluna o ka Iseraela he kanaha mau makahiki ia; ma Heberona i alii ai oia i na makahiki ehiku, a ma Ierusalema i alii ai oia i na makahiki he kanakolukumamakolu.
Dafidi ti jẹ ọba lórí Israẹli ní ogójì ọdún, ọdún méje ni Hebroni àti ọdún mẹ́tàlélọ́gbọ̀n ní Jerusalẹmu.
12 Alaila noho iho la o Solomona maluna o ka nohoalii o kona makuakane, a ua hooku paa loa ia kona aupuni.
Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi baba rẹ̀, ìjọba rẹ̀ sì fi ìdí múlẹ̀ gidigidi.
13 Alaila hele mai la o Adoniia ke keiki a Hagita io Bateseba la ka makuwahine o Solomona. Ninau aku la oia, Ua hele mai nei anei oe me ke aloha? I mai la ia, Me ke aloha.
Wàyí, Adonijah ọmọ Haggiti tọ Batṣeba, ìyá Solomoni wá. Batṣeba sì bi í pé, “Àlàáfíà ni o bá wa bí?” Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àlàáfíà ni.”
14 A olelo mai la hoi ia, He wahi manao ka'u e olelo aku ai ia oe. A i aku la kela, E olelo mai.
Nígbà náà ni ó sì fi kún un pé, “Mo ní ohun kan láti sọ fún ọ.” Batṣeba sì wí pé, “Máa wí.”
15 Olelo mai la ia, Ua ike no oe, ia'u no ke aupuni, a ua kau na maka o ka Iseraela a pau ia'u i alii ae au; aka, ua hoohuliia ke aupuni, a ua lilo ae nei i ko'u hoahanau: no ka mea, nona no ia, mai Iehova mai.
Ó wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí o ti mọ̀, ti tèmi ni ìjọba náà. Gbogbo Israẹli ti wò mí bí ọba wọn. Ṣùgbọ́n nǹkan yípadà, ìjọba náà sì ti lọ sí ọ̀dọ̀ arákùnrin mi, nítorí ó ti wá sọ́dọ̀ rẹ̀ láti ọwọ́ Olúwa wá.
16 Ano la hoi, hookahi mea a'u e noi ai ia oe, mai hoole mai oe ia'u. I aku la oia ia ia, E olelo mai no.
Nísinsin yìí mo ní ìbéèrè kan láti bi ọ́, má ṣe kọ̀ fún mi.” Ó wí pé, “O lè wí.”
17 I mai la hoi oia, Ke noi aku nei au ia oe e olelo oe ia Solomona ke alii, (no ka mea aole oia e hoole ia oe, ) e haawi mai oia ia Abisaga no Sunama ia'u i wahine.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì tẹ̀síwájú pé, “Mo bẹ̀ ọ́, jọ̀wọ́ sọ fún Solomoni ọba (òun kì yóò kọ̀ fún ọ́) kí ó fún mi ní Abiṣagi ará Ṣunemu ní aya.”
18 I aku la o Bateseba, He pono, e olelo aku no wau i ke alii, nou.
Batṣeba sì dáhùn pé, “Ó dára èmi yóò bá ọba sọ̀rọ̀ nítorí rẹ̀.”
19 Hele aku la o Bateseba i ke alii ia Solomona, e i aku ia ia no Adoniia. Ku ae la hoi ke alii iluna e halawai me ia, a kulou iho la ia ia, a noho iho la ma kona nohoalii, a ua hoonoho iho i ka noho no ka makuwahine o ke alii; a noho iho oia ma kona lima akau.
Nígbà tí Batṣeba sì tọ Solomoni ọba lọ láti bá a sọ̀rọ̀ nítorí Adonijah, ọba sì dìde láti pàdé rẹ̀, ó sì tẹríba fún un, ó sì jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀. Ó sì tẹ́ ìtẹ́ kan fún ìyá ọba, ó sì jókòó lọ́wọ́ ọ̀tún rẹ̀.
20 Alaila i ae la ia, Hookahi mea iki ka'u e noi aku ai ia oe; mai hoole mai oe ia'u. A olelo ae la ke alii ia ia, E olelo mai no oe, e kuu makuwahine, no ka mea, aole au e hoole aku ia oe.
Ó sì wí pé, “Mo ní ìbéèrè kékeré kan láti béèrè lọ́wọ́ rẹ, má ṣe kọ̀ fún mi.” Ọba sì dáhùn wí pé, “Béèrè, ìyá mi; èmi kì yóò kọ̀ ọ́.”
21 I ae la kela, E haawiia'ku o Abisaga no Sunama ia Adoniia kou hoahanau i wahine.
Nígbà náà ni ó wí pé, “Jẹ́ kí a fi Abiṣagi ará Ṣunemu fún Adonijah arákùnrin rẹ ní aya.”
22 Olelo ae la ke alii Solomona, i ae la i kona makuwahine, No ke aha la oe i noi mai nei ia Abisaga no Sunama na Adoniia? E noi mai oe i ke aupuni kekahi nona, no ka mea, o ko'u kaikuaana no ia, nona hoi, a no Abiatara ke kahuna, a no Ioaba ke keiki a Zeruia.
Solomoni ọba sì dá ìyá rẹ̀ lóhùn pé, “Èéṣe tí ìwọ fi béèrè Abiṣagi ará Ṣunemu fún Adonijah! Ìwọ ìbá sì béèrè ìjọba fún un pẹ̀lú nítorí ẹ̀gbọ́n mi ní í ṣe, fún òun pàápàá àti fún Abiatari àlùfáà àti fun Joabu ọmọ Seruiah!”
23 Alaila hoohiki Solomona ke alii ma o Iehova la, i aku la, Me ia e hana mai ai ke Akua ia'u, a e hui hou, ke olelo ku e ole o Adoniia i keia olelo i kona ola iho.
Nígbà náà ni Solomoni ọba fi Olúwa búra pé, “Kí Ọlọ́run ki ó jẹ mí ní yà, àti jù bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú, bí Adonijah kò bá ní fi ẹ̀mí rẹ̀ san ìbéèrè yìí!
24 Ano hoi, me ke ola ana o Iehova, ka mea nana i hooku paa mai ia'u, a i hoonoho ia'u ma ka nohoalii o Davida ko'u makuakane, ka mea nana i hana i hale no'u, e like me kana olelo hoopomaikai, e make no o Adoniia i keia la.
Àti nísinsin yìí, bí ó ti dájú pé Olúwa wà láààyè, ẹni tí ó ti mú mi jókòó lórí ìtẹ́ baba mi Dafidi, àti tí ó sì ti kọ́ ilé fún mi bí ó ti ṣèlérí, lónìí ni a ó pa Adonijah!”
25 Kena ae la o Solomona ke alii ma ka lima o Benaia ke keiki a Iehoiada; lele aku la oia ia ia a make ia.
Solomoni ọba sì pàṣẹ fún Benaiah ọmọ Jehoiada, ó sì kọlu Adonijah, ó sì kú.
26 A olelo mai la ke alii ia Abiatara ke kahuna, E hele aku oe i Anatota, i kau mau mahinaai ponoi; no ka mea, he pono ke make oe: aka, aole au e pepehi aku ia oe i keia mau la, no ka mea, ua hali oe i ka pahuberita o ka Haku Iehova imua o Davida ko'u makuakane, a ua hookaumahaia oe i na mea a pau i hookaumahaia'i ko'u makuakane.
Ọba sì wí fún Abiatari àlùfáà pé, “Padà lọ sí pápá rẹ ni Anatoti, ó yẹ fún ọ láti kú, ṣùgbọ́n èmi kì yóò pa ọ́ nísinsin yìí, nítorí o ti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa Olódùmarè níwájú Dafidi baba mi, o sì ti ní ìpín nínú gbogbo ìyà tí baba mi jẹ.”
27 Pela i kipaku aku ai o Solomona ia Abiatara mai kona kahuna ana no Iehova, i hooko i ka olelo a Iehova ana i olelo ai no ka ohana a Eli ma Silo.
Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni yọ Abiatari kúrò nínú iṣẹ́ àlùfáà Olúwa, kí ó lè mú ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti sọ nípa ilé Eli ní Ṣilo ṣẹ.
28 Alaila hiki ae la ka olelo ia Ioaba; no ka mea, ua huli ae o Ioaba mamuli o Adoniia aole nae ia i huli mamuli o Abesaloma: a holo aku la o Ioaba i ka halelewa o Iehova, a lalau ae la i na pepeiaohao o ke kuahu.
Nígbà tí ìròyìn sì dé ọ̀dọ̀ Joabu, ẹni tí ó ti dìtẹ̀ pẹ̀lú Adonijah bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kò wà pẹ̀lú Absalomu, ó sì sálọ sínú àgọ́ Olúwa, ó sì di ìwo pẹpẹ mú.
29 A ua haiia'ku i ke alii ia Solomona, Ua holo aku o Ioaba i ka halelewa o Iehova, aia hoi ia ma ke kuahu. Alaila kena ae la o Solomona ia Benaia ke keiki a Iehoiada, i ae la, E hele oe e lele aku ia ia.
A sì sọ fún Solomoni ọba pé Joabu ti sálọ sínú àgọ́ Olúwa àti pé ó wà ní ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ. Nígbà náà ni Solomoni pàṣẹ fún Benaiah ọmọ Jehoiada pé, “Lọ, kí o sì kọlù ú.”
30 A hele aku la o Benaia i ka halelewa o Iehova, i aku la ia ia, Ke i mai nei ke alii, E hele mai oe. I mai kela, Aole, aka, maanei au e make ai. A hoi hoike o Benaia i ke alii, i aku la, Pela i olelo mai ai o Ioaba, a pela i hoike mai ai oia ia'u.
Benaiah sì wọ inú àgọ́ Olúwa, ó sì wí fún Joabu pé, “Ọba sọ wí pé, ‘Jáde wá.’” Ṣùgbọ́n ó dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, èmi yóò kú níhìn-ín.” Benaiah sì mú èsì fún ọba, “Báyìí ni Joabu ṣe dá mi lóhùn.”
31 A i mai la ke alii ia ia, E hana aku oe e like me kana i olelo mai ai, e lele aku ia ia a e kanu ia ia, i lawe aku oe i ke koko hala ole a Ioaba i hookahe ai, mai o'u aku nei, a mai ka ohana aku a ko'u makuakane.
Ọba sì pàṣẹ fún Benaiah pé, “Ṣe bí ó ti wí. Kọlù ú, kí o sì sin ín, kí o sì mú ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi àti kúrò lọ́dọ̀ ilé baba mi, tí Joabu ti ta sílẹ̀.
32 A e hoihoi aku o Iehova i kona koko maluna o ke poo ona, o ka mea i lele aku i na kanaka elua ua oi aku ko laua pono me ko laua maikai mamua o kona, a pepehi aku la ia laua me ka pahikaua, me ka ike ole o Davida ko'u makuakane, ia Abenera ke keiki a Nera, ka luna o ka poe koa o ka Iseraela, a me Amasa ke keiki a Ietera ka luna o ka poe koa o ka Iuda.
Olúwa yóò sì san ẹ̀jẹ̀ tí ó ti ta sílẹ̀ padà fún un, nítorí tí ó kọlu ọkùnrin méjì, ó sì fi idà rẹ̀ pa wọ́n, Dafidi baba mi kò sì mọ̀. Àwọn méjèèjì ni Abneri ọmọ Neri olórí ogun Israẹli, àti Amasa ọmọ Jeteri olórí ogun Juda, wọ́n jẹ́ olódodo, wọ́n sì sàn ju òun fúnra rẹ̀ lọ.
33 Nolaila e hoi ae ko laua koko maluna o ke poo o Ioaba, a maluna o kana mau keiki a mau aku; aka, maluna o Davida a me kana mau keiki, a me kana ohana, a me kona nohoalii, e kau mau loa'i ka pomaikai mai ka Haku mai.
Kí ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ wọn wá sórí Joabu àti sórí irú-ọmọ rẹ̀ títí láé. Ṣùgbọ́n sórí Dafidi àti irú-ọmọ rẹ̀, sí ilé rẹ̀ àti sí ìtẹ́ rẹ̀, ni kí àlàáfíà Olúwa wà títí láé.”
34 Hele aku la hoi o Benaia ke keiki a Iehoiada, lele aku la ia ia, a pepehi aku ia ia; a ua kanuia oia iloko o kona hale i ka waonahele.
Bẹ́ẹ̀ ni Benaiah ọmọ Jehoiada sì gòkè lọ, ó sì kọlu Joabu, ó sì pa á, a sì sin ín ní ilẹ̀ ibojì ara rẹ̀ ní aginjù.
35 A hoonoho ae la ke alii ia Benaia ke keiki a Iehoiada, iloko o kona wahi maluna o ka poe koa, a hookomo ae la ke alii ia Zadoka i ka hakahaka o Abiatara.
Ọba sì fi Benaiah ọmọ Jehoiada jẹ olórí ogun ní ipò Joabu àti Sadoku àlùfáà ní ipò Abiatari.
36 Hoouna ae la ke alii e kii ia Simei, a i ae la ia ia, E kukulu oe i hale nou ma Ierusalema, a malaila e noho ai, mai hele aku oe mai ia wahi aku.
Nígbà náà ni ọba ránṣẹ́ sí Ṣimei, ó sì wí fún un pé, “Kọ́ ilé fún ara rẹ ní Jerusalẹmu, kí o sì máa gbé ibẹ̀, ṣùgbọ́n kí o má sì ṣe lọ sí ibòmíràn.
37 No ka mea, eia, i kou la e puka aku ai maluna o ke kahawai Kederona, e ike oe he oiaio no e make io no oe, a maluna o kou poo iho kou koko.
Ọjọ́ tí ìwọ bá jáde, tí o sì kọjá àfonífojì Kidironi, kí ìwọ kí ó mọ̀ dájúdájú pé ìwọ yóò kú; ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò sì wà lórí ara rẹ.”
38 Olelo aku la hoi o Simei i ke alii, he pono ka olelo; a e like me ka olelo a kuu haku ke alii, pela no e hana aku ai kau kauwa. A noho iho la o Simei ma Ierusalema i na la he nui.
Ṣimei sì dá ọba lóhùn pé, “Ohun tí ìwọ sọ dára. Ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe bí olúwa mi ọba ti wí.” Ṣimei sì gbé ní Jerusalẹmu fún ìgbà pípẹ́.
39 Eia kekahi, i ka pau ana o na makahiki ekolu, holo malu aku la elua o na kauwa a Simei ia Akisa ke keiki a Maaka ke alii o Gata: a olelo mai la lakou ia Simei, i mai la, Aia kau mau kauwa ma Gata.
Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ọdún mẹ́ta, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ Ṣimei méjì sì sálọ sọ́dọ̀ Akiṣi ọmọ Maaka, ọba Gati, a sì sọ fún Ṣimei pé, “Àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ méjì wà ní Gati.”
40 Ku ae la hoi o Simei, a kau aku la i ka noholio maluna o kona hoki a holo aku la i Gata, ia Akisa e imi ana i kana mau kauwa; a holo no Simei a hoihoi mai i kana mau kauwa mai Gata mai.
Fún ìdí èyí, ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ ní gàárì, ó sì lọ sọ́dọ̀ Akiṣi ní Gati láti wá àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni Ṣimei sì lọ, ó sì mú àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ padà bọ̀ láti Gati.
41 Haiia'ku la ia Solomona, ua hele aku o Simei mai Ierusalema aku i Gata, a ua hoi mai.
Nígbà tí a sì sọ fún Solomoni pé Ṣimei ti lọ láti Jerusalẹmu sí Gati, ó sì ti padà.
42 Hoouna ae ke alii e kii ia Simei, a i ae la ia ia, Aole anei na'u i hoohiki ai oe ma o Iehova la, a i olelo aku au ia oe penei, I kou la e puka aku ai a hele mawaho i kahi e, e ike oe he oiaio, e make io no oe? a olelo mai la oe ia'u, He pono ka olelo a'u e lohe nei.
Ọba pe Ṣimei lẹ́jọ́, ó wí fún un pé, “Ǹjẹ́ èmi kò ti mú ọ búra ní ti Olúwa, èmi sì ti kìlọ̀ fún ọ pé, ‘Ní ọjọ́ tí ìwọ bá kúrò láti lọ sí ibikíbi, kí o mọ̀ dájú pé ìwọ yóò kú.’ Nígbà náà ni ìwọ sì sọ fún mi pé, ‘Ohun tí ìwọ sọ dára. Èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn.’
43 No ke aha la hoi i malama ole ai oe i kau mea i hoohiki ai no Iehova, a me ke kauoha a'u i kauoha aku ai ia oe?
Èéṣe, nígbà náà tí ìwọ kò pa ìbúra Olúwa mọ́, àti kí o sì ṣe ìgbọ́ràn sí àṣẹ tí mo pa fún ọ?”
44 Olelo hou ae la ke alii ia Simei, Ua ike no oe i ka hewa a pau i maopopo i kou naau, au i hana mai ai ia Davida ko'u makuakane: nolaila e hoihoi aku o Iehova i kou hewa maluna iho o kou poo;
Ọba sì tún wí fún Ṣimei pé, “Ìwọ mọ̀ ní ọkàn rẹ gbogbo búburú tí ìwọ ti ṣe sí Dafidi baba mi. Báyìí, Olúwa yóò san gbogbo ìṣe búburú rẹ padà fún ọ.
45 A e pomaikai Solomona ke alii, a e hooku paa mau loa ia ka nohoalii o Davida ma ke alo o Iehova.
Ṣùgbọ́n a ó sì bùkún fún Solomoni ọba, ìtẹ́ Dafidi yóò sì wà láìfòyà níwájú Olúwa títí láéláé.”
46 Alaila kena ae la ke alii ia Benaia ke keiki a Iehoiada, a puka ae ia, a lele aku ia ia a make ia. A ua hoopaaia ke aupuni iloko o ka lima o Solomona.
Nígbà náà ni ọba pàṣẹ fún Benaiah ọmọ Jehoiada, ó sì jáde lọ, ó sì kọlu Ṣimei, ó sì pa á. Ìjọba náà sì wá fi ìdí múlẹ̀ ní ọwọ́ Solomoni.

< I Na Lii 2 >