< I Na Lii 11 >

1 U A aloha aku la o Solomona ke alii i na wahine e he nui no, me ke kaikamahine pu a Parao, na wahine o ka Moaba, a o ka Amora, a o ka Edoma, a o ko Sidona, a me ka Heta;
Solomoni ọba fẹ́ ọ̀pọ̀ àjèjì obìnrin yàtọ̀ sí ọmọbìnrin Farao, àwọn ọmọbìnrin Moabu, àti ti Ammoni, ti Edomu, ti Sidoni àti ti àwọn ọmọ Hiti.
2 O ko na lahuikanaka a Iehova i olelo mai ai i na mamo a Iseraela, Aole oukou e komo aku io lakou la, aole hoi lakou e komo mai io oukou nei, no ka mea, e hoohuli io lakou la i ko oukou naau mamuli o ko lakou mau akua; hoopili ae la o Solomona ia lakou me ke aloha.
Wọ́n wá láti orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti wí fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ fẹ́ wọn níyàwó tàbí ní ọkọ, nítorí wọn yóò yí ọkàn yín padà sí òrìṣà wọn.” Síbẹ̀síbẹ̀ Solomoni fàmọ́ wọn ní ìfẹ́.
3 A loaa ia ia ehiku haneri wahine, na wahine alii, a ekolu haneri haiawahine; a hoohuli e aku kana mau wahine i kona naau.
Ó sì ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin obìnrin, àwọn ọmọ ọba àti ọ̀ọ́dúnrún àlè, àwọn ìyàwó rẹ̀ sì yí i ní ọkàn padà.
4 O keia hoi, a elemakule ae la o Solomona, ua hoohuli ae kana mau wahine i kona naau mamuli o na akua e; aole i hemolele kona naau ia Iehova kona Akua, e like me ka naau o Davida kona makuakane.
Bí Solomoni sì ti di arúgbó, àwọn ìyàwó rẹ̀ sì yí i ní ọkàn padà sí ọlọ́run mìíràn, ọkàn rẹ̀ kò sì ṣe déédé pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọkàn Dafidi baba rẹ̀ ti ṣe.
5 No ka mea ua hahai ae la o Solomona mamuli o Aseterota ke akua wahine o ko Sidona, a mamuli o Milekoma ka mea i hoowahawahaia o ka Amona.
Solomoni tọ Aṣtoreti òrìṣà àwọn ará Sidoni lẹ́yìn, àti Moleki òrìṣà ìríra àwọn ọmọ Ammoni.
6 A hana ino ae la o Solomona ma ke alo o Iehova, aole hele okoa mamuli o Iehova, e like me Davida kona makuakane.
Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni ṣe búburú níwájú Olúwa; kò sì tọ Olúwa lẹ́yìn ní pípé, bí Dafidi baba rẹ̀ ti ṣe.
7 Alaila hana ae la o Solomona i wahi kiekie no Kemosaka mea inainaia o ka Moaba, ma ka puu mamua o Ierusalema, a no Moleka ka mea inainaia o na mamo a Amona.
Lórí òkè tí ń bẹ níwájú Jerusalẹmu, Solomoni kọ́ ibi gíga kan fún Kemoṣi, òrìṣà ìríra Moabu, àti fún Moleki, òrìṣà ìríra àwọn ọmọ Ammoni.
8 Pela ia i hana'i no na wahine e ana a pau i kukuni i ka mea ala a i kaumaha aku no ko lakou mau akua.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì ṣe bẹ́ẹ̀ fún gbogbo àwọn àjèjì obìnrin rẹ̀, ẹni tí ń sun tùràrí, tí wọ́n sì ń rú ẹbọ fún òrìṣà wọn.
9 Huhu mai la o Iehova ia Solomona, no ka huli ana'e o kona naau mai o Iehova ae ke Akua o Iseraela, ka mea i ikeia e ia i na manawa elua;
Olúwa bínú sí Solomoni nítorí ọkàn rẹ̀ ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run Israẹli, tí ó ti fi ara hàn án lẹ́ẹ̀méjì.
10 A i kauoha mai la hoi ia ia no keia mea, i ole ia e hahai mamuli o ua akua e: aka, aole oia i malama i ka mea a Iehova i kauoha mai ai ia ia.
Bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti kìlọ̀ fún Solomoni kí ó má ṣe tọ àwọn ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn, ṣùgbọ́n Solomoni kò pa àṣẹ Olúwa mọ́.
11 Nolaila i olelo mai ai o Iehova ia Solomona, No kau hana ana ia mea, aole hoi i malama mai i kuu berita, a me ko'u mau kanawai a'u i kauoha aku ai ia oe, e kaili ae auauei au i ke aupuni mai ou ae nei, a e haawi aku no ia i kau kauwa.
Nítorí náà Olúwa wí fún Solomoni pé, “Nítorí bí ìwọ ti ṣe nǹkan yìí, tí ìwọ kò sì pa májẹ̀mú mi àti àṣẹ mi mọ́, tí mo ti pàṣẹ fún ọ, dájúdájú èmi yóò fa ìjọba ya kúrò lọ́wọ́ rẹ, èmi yóò sì fi fún ẹlòmíràn.
12 Aka, i kou mau la, aole au e hana i keia no Davida kou makuakane; aka, mailoko ae o ka lima o kau koiki e kaili ae ai au ia.
Ṣùgbọ́n, nítorí Dafidi baba rẹ, Èmi kì yóò ṣe é ní ọjọ́ rẹ. Èmi yóò fà á ya kúrò lọ́wọ́ ọmọ rẹ.
13 Aole hoi au e kaili honua i ke aupuni a pau, e haawi aku no au i hookahi ohana i kau keiki no Davida ka'u kauwa, a no Ierusalema a'u i koho ai.
Síbẹ̀ èmi kì yóò fa gbogbo ìjọba náà ya, ṣùgbọ́n èmi yóò fi ẹ̀yà kan fún ọmọ rẹ nítorí Dafidi ìránṣẹ́ mi, àti nítorí Jerusalẹmu tí èmi ti yàn.”
14 Hooku mai la o Iehova i ka enemi ia Solomona, o Hadada no Edoma; no na keiki ia a ke alii ma Edoma.
Nígbà náà ni Olúwa gbé ọ̀tá kan dìde sí Solomoni, Hadadi ará Edomu ìdílé ọba ni ó ti wá ní Edomu.
15 No ka mea, o keia kekahi, i ka wa i noho ai o Davida ma Edoma, hele ae la o Ioaba ka luna o ka poe koa e kanu i ka poe i pepehiia, mahope o kona pepehi ana ae i na kane a pau ma Edoma;
Ó sì ṣe, nígbà tí Dafidi wà ní Edomu, Joabu olórí ogun sì gòkè lọ láti sin àwọn ọmọ-ogun Israẹli ti a pa lójú ogun, ó sì pa gbogbo ọkùnrin Edomu.
16 (No ka mea, ua noho o Ioaba malaila me ka Iseraela a pau i na malama eono, a oki aku oia i na kane a pau ma Edoma; )
Nítorí Joabu àti gbogbo Israẹli sì dúró níbẹ̀ fún oṣù mẹ́fà, títí wọ́n fi pa gbogbo ọkùnrin Edomu run.
17 Holo aku la o Hadada, oia me kekahi poe kanaka o Edoma pu o na kauwa o kona makuakane me ia, e hele pu i Aigupita; he keiki uuku o Hadada.
Ṣùgbọ́n Hadadi sálọ sí Ejibiti pẹ̀lú àwọn ará Edomu tí wọ́n jẹ́ ìránṣẹ́ baba rẹ̀. Hadadi sì wà ní ọmọdé nígbà náà.
18 Puka ae la lakou mailoko ae o Midiana, a hele i Parana; a lawe pu lakou i kanaka mailoko ae o Parana, a hele i Aigupita ia Parao ke alii o Aigupita, nana no i haawi i hale nona, a hooponopono i ai nana, a haawi hoi i kahi aina ia ia.
Wọ́n sì dìde kúrò ní Midiani, wọ́n sì lọ sí Parani. Nígbà náà ni wọ́n mú ènìyàn pẹ̀lú wọn láti Parani wá, wọ́n sì lọ sí Ejibiti, sọ́dọ̀ Farao ọba Ejibiti ẹni tí ó fún Hadadi ní ilé àti ilẹ̀, ó sì fún un ní oúnjẹ.
19 A loaa ia Hadada ka lokomaikai nui ia ma ke alo o Parao, a haawi oia ia ia i ka hoahanau o kana wahine iho, ka hoahanau o Tapene ke alii wahine.
Inú Farao sì dùn sí Hadadi púpọ̀ tí ó fi fún un ní arábìnrin aya rẹ̀ ní aya, arábìnrin Tapenesi, ayaba.
20 A hanau mai la ka hoahanau o Tapene i keikikane nana, o Genubata, a na Tapene ia i ukuhi maloko o ka hale o Parao; a iloko no o Genubata o ka hale o Parao iwaena o na keiki a Parao.
Arábìnrin Tapenesi bí ọmọkùnrin kan fún un tí à ń pe orúkọ rẹ̀ ní Genubati, ẹni tí Tapenesi tọ́ dàgbà ní ààfin ọba. Níbẹ̀ ni Genubati ń gbé pẹ̀lú àwọn ọmọ Farao fúnra rẹ̀.
21 A lohe o Hadada ma Aigupita, ua hiamoe o Davida me kona mau makua, a ua make hoi o Ioaba ka luna o ka poe koa, i aku la o Hadada ia Parao, E hookuu ae ia'u e hele ae i ko'u aina,
Nígbà tí ó sì wà ní Ejibiti, Hadadi sì gbọ́ pé Dafidi ti sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, àti pé Joabu olórí ogun sì ti kú pẹ̀lú. Nígbà náà ni Hadadi wí fún Farao pé, “Jẹ́ kí n lọ, kí èmi kí ó le padà sí ìlú mi.”
22 Alaila olelo mai la o Parao ia ia, Heaha kou mea hemahema ia'u, ea, i imi ai oe e hoi aku i kou aina? I aku la oia, Aohe, aka, e hookuu wale mai oe ia'u.
Farao sì wí fún un pé, “Kí ni ìwọ ṣe aláìní níbí, tí ìwọ fi fẹ́ padà lọ sí ìlú rẹ?” Hadadi sì wí pé, “Kò sí nǹkan, ṣùgbọ́n sá à jẹ́ kí èmi kí ó lọ!”
23 A hooku mai la ke Akua i kekahi enemi, o Rezona ke keiki a Eliada, ka mea i mahuka mai kona haku aku o Hadedezera ke alii o Zoba;
Ọlọ́run sì gbé ọ̀tá mìíràn dìde sí Solomoni, Resoni ọmọ Eliada, ẹni tí ó ti sá kúrò lọ́dọ̀ Hadadeseri olúwa rẹ̀, ọba Soba.
24 Ua hoakoakoa ae la oia i kanaka io ua iho no, a lilo oia i lunakoa maluna o ka papa, i ka wa i pepehi ai o Davida ia lakou; a hele ae la lakou i Damaseko, a noho malaila, a ua alii ae la hoi ma Damaseko.
Ó sì kó ènìyàn jọ sọ́dọ̀ ara rẹ̀, ó sì di olórí ogun ẹgbẹ́ kan, nígbà tí Dafidi fi pa ogun Soba run; wọ́n sì lọ sí Damasku, wọ́n ń gbé ibẹ̀, wọ́n sì jẹ ọba ní Damasku.
25 A ua ku e mai la oia i ka Iseraela i na la a pau o Solomona, okoa ke kolohe ana o Hadada: hoowahawaha mai la o Rezona i ka Iseraela, a ua alii ae la maluna o Suria.
Resoni sì jẹ́ ọ̀tá Israẹli ní gbogbo ọjọ́ Solomoni, ó ń pa kún ibi ti Hadadi ṣe. Bẹ́ẹ̀ ni Resoni jẹ ọba ní Siria, ó sì ṣòdì sí Israẹli.
26 A o Ieroboama ke keiki a Nebata, o ka Eperaima no Zereda, o Zerua ka inoa o kona makuwahine he wahinekanemake, o ke kauwa a Solomona, oia kekahi i hapai i ka lima ku e i ke alii.
Bákan náà Jeroboamu ọmọ Nebati sì ṣọ̀tẹ̀ sí ọba. Ó sì jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ Solomoni, ará Efraimu ti Sereda, ìyá rẹ̀ sì jẹ́ opó, orúkọ rẹ̀ ni Serua.
27 Eia ka kumu i hapai ai oia i ka lima i ku e i ke alii; kukulu ae la o Solomona ia Milo, a hoopaa iho la i na wahi naha o ke kulanakauhale o Davida kona makuakane.
Èyí sì ni ìdí tí ó fi ṣọ̀tẹ̀ sí ọba: Solomoni kọ́ Millo, ó sì di ẹ̀yà ìlú Dafidi baba rẹ̀.
28 A o ke kanaka Ieroboama, he kanaka koa ikaika loa no ia; a ike ae la o Solomona i ua kanaka ui la e hoomau ana i ka hana, hoolilo ae la oia ia ia i luna maluna o ka ukana a pau o ka ohana o Iosepa.
Jeroboamu jẹ́ ọkùnrin alágbára, nígbà tí Solomoni sì rí bí ọ̀dọ́mọkùnrin náà ti ṣe iṣẹ́ rẹ̀ dáradára, ó fi í ṣe olórí iṣẹ́ ìrú ilé Josẹfu.
29 Eia kekahi mea ia manawa, i ka puka ana'e o Ieroboama mai Ierusalema ae, loaa oia i ke kaula ia Ahiia no Silo, ma ke alanui, a ua hoaahu oia ia ia iho me ke aahu hou; a o laua wale no ma ke kula.
Ó sì ṣe, ní àkókò náà Jeroboamu ń jáde kúrò ní Jerusalẹmu. Wòlíì Ahijah ti Ṣilo sì pàdé rẹ̀ lójú ọ̀nà, ó sì wọ agbádá tuntun. Àwọn méjèèjì nìkan ni ó sì ń bẹ ní oko,
30 Lalau iho la o Ahiia i ka aahu hou ka mea maluna iho ona, a uhae ae la ia mea i mau apana he umikumamalua.
Ahijah sì gbá agbádá tuntun tí ó wọ̀ mú, ó sì fà á ya sí ọ̀nà méjìlá.
31 A olelo mai la oia ia Ieroboama, E lawe oe i na apana he umi; no ka mea, ke i mai nei o Iehova ke Akua o Iseraela, peneia, Eia hoi, e kaili ae auanei au i ke aupuni mailoko ae o ka lima o Solomona, a e haawi au i na ohana he umi ia oe:
Nígbà náà ni ó sọ fún Jeroboamu pé, “Mú ọ̀nà mẹ́wàá fún ara rẹ, nítorí báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí pé, ‘Wò ó, èmi yóò fa ìjọba náà ya kúrò ní ọwọ́ Solomoni, èmi yóò sì fi ẹ̀yà mẹ́wàá fún ọ.
32 Aka, ia ia no ka ohana hookahi no Davida ka'u kauwa, a no Ierusalema ke kulanakauhale a'u i koho ai mailoko mai o na ohana a pau o ka Iseraela:
Ṣùgbọ́n nítorí ti Dafidi ìránṣẹ́ mi àti nítorí Jerusalẹmu, ìlú tí mo ti yàn nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli, òun yóò ní ẹ̀yà kan.
33 O No ka mea, ua haalele mai lakou ia'u, a ua hoomana ae ia Aseterota ke akua wahine o ko Sidona, ia Kemosa ke akua o ka Moaba, a ia Milekoma ke akua o na mamo a Amona, aole hoi i hele ma ko'u mau aoao, e hana i ka mea pono i ko'u mau maka, i ka malama i ko'u mau kanawai a me ko'u mau kapu, e like me Davida kona makuakane.
Èmi yóò ṣe èyí nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, wọ́n sì ti sin Aṣtoreti òrìṣà àwọn ará Sidoni, Kemoṣi òrìṣà àwọn ará Moabu, àti Moleki òrìṣà àwọn ọmọ Ammoni, wọn kò sì rìn ní ọ̀nà mi, tàbí ṣe èyí tí ó dára lójú mi, tàbí pa àṣẹ àti òfin mi mọ́ bí Dafidi baba Solomoni ti ṣe.
34 Aole nae au e kaili honua ae i ke aupuni a pau mailoko ae o kona lima; aka, e hoomau auanei au i kona alii ana i na la a pau o kona ola ana, no Davida ka'u kauwa, a'u i koho ai no kona malama ana i ka'u mau kauoha a me ko'u mau kanawai.
“‘Ṣùgbọ́n èmi kì yóò gba gbogbo ìjọba náà lọ́wọ́ Solomoni; èmi ti mú un jẹ́ olórí ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀ nítorí ti Dafidi ìránṣẹ́ mi, ẹni tí mo yàn, tí ó sì ti pa òfin mi àti àṣẹ mi mọ́.
35 Aka, e kaili ae auanei au i ke aupuni mailoko ae o ka lima o kana keiki, a e haawi au ia ia oe, i na ohana he umi.
Èmi yóò gba ìjọba náà ní ọwọ́ ọmọ rẹ̀, èmi yóò sì fi ẹ̀yà mẹ́wàá fún ọ.
36 A i kana keiki, hookahi ohana ka'u e haawi aku ai, i mau ai ke kukui no Davida ka'u kauwa, imua o ko'u alo ma Ierusalema, ke kulanakauhale a'u i koho ai no'u e waiho ai i ko'u inoa malaila.
Èmi yóò fi ẹ̀yà kan fún ọmọ rẹ kí Dafidi ìránṣẹ́ mi lè máa ní ìmọ́lẹ̀ níwájú mi nígbà gbogbo ní Jerusalẹmu, ìlú tí mo ti yàn láti fi orúkọ mi síbẹ̀.
37 A e lawe au ia oe, a e alii ae no oe mamuli o ka mea a pau a kou uhane e makemake ai, a e lilo no oe i alii no ka Iseraela.
Ṣùgbọ́n ní ti ìwọ, Èmi yóò mú ọ, ìwọ yóò sì jẹ ọba lórí ohun gbogbo tí ọkàn rẹ ń fẹ́; ìwọ yóò jẹ ọba lórí Israẹli.
38 Peneia auanei hoi, ina e hoolohe mai oe i ka mea a pau a'u e kauoha aku ai ia oe, a e hele hoi ma ko'u mau aoao, a hana hoi i ka mea pono i ko'u mau maka, i ka malama i ko'u mau kanawai, a me ka'u mau kauoha me Davida ka'u kauwa i hana'i; alaila owau pu auanei me oe, a e kukulu au i hale ku paa nou me ka'u i kukulu ai no Davida, a e haawi au i ka Iseraela ia oe.
Bí ìwọ bá ṣe gbogbo èyí tí mo pàṣẹ fún ọ, tí o sì rìn ní ọ̀nà mi, tí o sì ṣe èyí tí ó tọ́ lójú mi nípa pípa òfin àti àṣẹ mi mọ́, bí i Dafidi ìránṣẹ́ mi ti ṣe, Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ. Èmi yóò kọ́ ilé òtítọ́ fún ọ bí èyí tí mo kọ́ fún Dafidi, èmi yóò sì fi Israẹli fún ọ.
39 No keia mea, e hookaumaha ai au i na mamo a Davida, aole hoi i na la a pau loa.
Èmi yóò sì rẹ irú-ọmọ Dafidi sílẹ̀ nítorí èyí, ṣùgbọ́n kì í ṣe títí láé.’”
40 A imi iho la o Solomona e pepehi ia Ieroboama; a ku ae la o Ieroboama iluna, a holo aku la i Aigupita io Sisaka la, ke alii o Aigupita, a noho ia ma Aigupita a make o Solomona.
Solomoni wá ọ̀nà láti pa Jeroboamu, ṣùgbọ́n Jeroboamu sálọ sí Ejibiti, sọ́dọ̀ Ṣiṣaki ọba Ejibiti, ó sì wà níbẹ̀ títí Solomoni fi kú.
41 A o na hana e ae a Solomona, a me na mea a pau ana i hana'i, a me kona akamai, aole anei ia i kakauia ma ka buke o na hana a Solomona?
Ìyókù iṣẹ́ Solomoni àti gbogbo èyí tí ó ṣe, àti ọgbọ́n rẹ̀, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ìṣe Solomoni bí?
42 A o na la i alii ai o Solomona ma Ierusalema maluna o ka Iseraela a pau he kanaha mau makahiki.
Solomoni sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu lórí gbogbo Israẹli ní ogójì ọdún.
43 A hiamoe iho la o Solomona me kona mau makua, a ua kanuia ma ke kulanakauhale o Davida kona makuakane, a alii ae la o Rehoboama kana keiki ma kona hakahaka.
Nígbà náà ni Solomoni sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dafidi baba rẹ̀. Rehoboamu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.

< I Na Lii 11 >