< I Oihanaalii 12 >

1 A IA hoi ka poe i hele mai io Davida la ma Zikelaga, i kona manawa i noho paa ai no Saula ke keiki a Kisa; iwaena lakou o na kanaka ikaika, ka poe i kokua i ke kaua.
Àwọn wọ̀nyí ni ọkùnrin tí ó wá sí ọ̀dọ̀ Dafidi ní Siklagi, nígbà tí ó sá kúrò níwájú Saulu ọmọ Kiṣi (wọ́n wà lára àwọn jagunjagun ẹni tí ó ràn án lọ́wọ́ láti ibi ìjà.
2 Ua makaukau lakou i na kakaka, a ua hiki no ia lakou ke nou aku i na pohaku, a me ka pana pua mailoko aku o ke kakaka, me ka lima akau a me ka lima hema, no ka hanauna lakou o Saula, no ka Beniamina.
Wọ́n sì mú wọn pẹ̀lú ìtẹríba wọ́n sì lágbára láti ta ọfà tàbí láti ta kànnàkànnà òkúta ní ọwọ́ òsì tàbí ní ọwọ́ ọ̀tún, wọ́n sì jẹ́ ìbátan ọkùnrin Saulu láti ẹ̀yà Benjamini):
3 O Ahiezera ka luna, alaila o Ioasa, na keiki laua a Hasemaa no Gibea: o Ieziela hoi, a o Peleta, nakeiki a Azemavota; o Beraka hoi, a o Iehu no Anetota.
Ahieseri olórí wọn àti Joaṣi àwọn ọmọ Ṣemaah ará Gibeah: Jeṣieli àti Peleti ọmọ Asmafeti, Beraka, Jehu ará Anatoti.
4 A o Isemaia no Gibeona, he kanaka ikaika iwaena o ke kanakolu; a o Ieremia, o Iahaziela, o Iohanana, a o Iosabada, no Gederata,
Àti Iṣmaiah ará Gibeoni, ọkùnrin alágbára kan lára àwọn ọgbọ̀n ẹni tí ó jẹ́ olórí nínú àwọn ọgbọ̀n; Jeremiah, Jahasieli, Johanani, Josabadi ará Gedera,
5 O Eluzai, o Ierimota, o Bealia o Semaria, a o Sepatia no Harupa,
Elusai, Jerimoti, Bealiah, Ṣemariah àti Ṣefatia ará Harufiti;
6 O Elekana, o Iesia, o Azareela, o Ioezera, o Iasobeama, no ka Kora;
Elkana, Iṣiah, Asareeli, Joeseri àti Jaṣobeamu ará Kora;
7 O loela, o Zebadia, na keiki a Ierohama no Gedora.
àti Joẹla, àti Sebadiah àwọn ọmọ Jerohamu láti Gedori.
8 A hookaawale mai la kekahi poe Gada ia lakou iho no Davida ma kahi paa ma ka waonahele, he poe kanaka ikaika, kanaka kaua e kaua ai; e hiki ia lakou ke lawe i palekaua a me ka ihe, a o na helehelena o lakou, me he helehelena liona la, a ua like lakou me ka dia o na mauna ka mama:
Díẹ̀ lára àwọn ará Gadi yà sọ́dọ̀ Dafidi ní ibi gíga ní aginjù. Wọ́n sì jẹ́ onígboyà ológun tí ó múra fún ogun tí ó sì lágbára láti di asà àti ẹṣin mú. Ojú wọn sì dàbí ojú kìnnìún, wọ́n sì yára bí àgbọ̀nrín lórí àwọn òkè.
9 O Ezera ka mua, o Obadia ka lua, o Eliaba ke kolu,
Eseri sì jẹ́ ìjòyè, Obadiah sì jẹ́ igbákejì akọgun, Eliabu ẹlẹ́ẹ̀kẹta,
10 O Misemana ka ha, o Ieremia ka lima,
Miṣimana ẹlẹ́ẹ̀kẹrin, Jeremiah ẹlẹ́ẹ̀karùnún
11 O Atai ke ono, o Eliela ka hiku,
Attai ẹlẹ́ẹ̀kẹfà, Elieli èkeje,
12 O Iohanana ka walu, o Elezabada ka iwa,
Johanani ẹlẹ́ẹ̀kẹjọ Elsabadi ẹlẹ́ẹ̀kẹsàn-án
13 O Ieremia ka umi, a o Makebanai ka umikumamakahi.
Jeremiah ẹlẹ́ẹ̀kẹwàá àti Makbannai ẹlẹ́ẹ̀kọkànlá.
14 O lakou he poe mamo a Gada, na luna o ka poe kaua: o kekahi mea uuku iho, maluna ia o ka haneri; a o ka mea nui loa, maluna ia o ka tausani.
Àwọn ará Gadi wọ́n sì jẹ́ olórí ogun; ẹni tí ó kéré jù sì jẹ́ àpapọ̀ ọgọ́rùn-ún, àti fún ẹni tí ó pọ̀jù fún ẹgbẹ̀rún.
15 O lakou ka poe i hele ma kela kapa o Ioredane i ka malama mua, i ka manawa i hoopiha ai ia maluna o kona mau kapa a pan: a hoopuehu aku la lakou i na mea a pau o na awawa ma ka hikina a ma ke komohana.
Àwọn ni ẹni tí ó rékọjá Jordani ní oṣù àkọ́kọ́ nígbà tí ó kún bo gbogbo bèbè rẹ̀, wọ́n sì lé gbogbo àwọn tí ó ń gbé nínú àfonífojì, lọ sí ìlà-oòrùn àti níhà ìwọ̀-oòrùn.
16 A hele mai la kekahi poe mamo a Beniamina a me Iuda i kahi paa io Davida la.
Ìyókù ará Benjamini àti àwọn díẹ̀ ọkùnrin láti Juda lọ sí ọ̀dọ̀ Dafidi ní ibi gíga.
17 Hele aku la o Davida iwaho e halawai me lakou; olelo aku la ia, i aku la ia lakou, Ina e hele aloha mai no oukou io'u nei e kokua mai ia'u, e hookahi ana ko'u naau me ko oukou: aka, ina no ka haawi aku ia'u i ko'u poe enemi, na ke Akua o ko kakou poe kupuna e nana mai, a e papa mai; no ka mea, aole i loaa ka hewa ma ko'u mau lima.
Dafidi sì lọ láti lọ pàdé wọn ó sì wí fún wọn pé, “Tí ẹ bá wá sọ́dọ̀ mi lálàáfíà, láti ràn mí lọ́wọ́ mo ṣetán láti mú un yín wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú mi ṣùgbọ́n tí ẹ bá wá láti dá mi sí fún àwọn ọ̀tá mi nígbà tí ọwọ́ mi bá mọ́ kúrò nínú ìwà agbára, kí Ọlọ́run àwọn baba wa kí ó sì ri kí ó sì ṣe ìdájọ́.”
18 Alaila kau mai la ka Uhane maluna iho o Amasai, ke pookela o na lunakoa, Nou no makou, e Davida, a ma kou aoao hoi, e ke keiki a Iese, aloha, aloha ia oe, aloha hoi i na kokua mahope ou; no ka mea, o kou Akua ke kokua mai ia oe. Alaila, hookipa ae la o Davida ia lakou, a hoonoho ia lakou i mau luna o na koa.
Nígbà náà Ẹ̀mí Mímọ́ wa sórí Amasai ìjòyè àwọn ọgbọ̀n, ó sì wí pé, “Tìrẹ ni àwa ń ṣe, ìwọ Dafidi! Àwa pẹ̀lú rẹ, ìwọ ọmọ Jese! Àlàáfíà, àlàáfíà fún ọ, àti àlàáfíà fún àwọn tí ó ràn ó lọ́wọ́, nítorí Ọlọ́run rẹ̀ yóò ràn ọ́ lọ́wọ́.” Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì gbà wọ́n ó sì mú wọn jẹ olórí ẹgbẹ́ ogun.
19 A kaana mai la kekahi poe o Manase ia Davida, ia ia i hele pu ai me ko Pilisetia i ke kaua ia Saula: aka, aole i kokua aku lakou nei mamuli o lakou, no ka mea, na na 'lii o ko Pilisetia i kukakuka pu, a hoihoi aku ia ia, me ka i ana, E kaa aku auanei ia i kona haku ia Saula, maluna o ko kakou mau poo.
Díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin Manase sì yà sí ọ̀dọ̀ Dafidi nígbà tí ó lọ pẹ̀lú àwọn ará Filistini láti bá Saulu jà. (Òun àti àwọn ọkùnrin rẹ̀ wọn kò sì ran ará Filistini lọ́wọ́ nítorí, lẹ́yìn tiwọn sọ̀rọ̀ papọ̀, àwọn olórí wọn rán wọn jáde, wọ́n sì wí pé, “Yóò jẹ́ ìparun fún wa tí ó bá padà tọ ọ̀gá rẹ̀ Saulu lọ.”)
20 I kona hele ana i Zikelaga, kaana mai la kekahi poe o ka Manase ia ia, o Adena, o Iozabada, o Iediaela, o Mikaela, o Iozabada, o Elihu, a o Ziletai, na luna tausani o ka Manase.
Nígbà tí Dafidi lọ sí Siklagi, àwọn wọ̀nyí ni ọkùnrin ti Manase ẹni tí ó sì yà sọ́dọ̀ rẹ̀. Adina, Josabadi, Jediaeli, Mikaeli, Josabadi, Elihu àti Siletai, àwọn olórí ìrẹ́pọ̀ ti ẹgbẹẹgbẹ̀rún ní Manase.
21 A kokua mai la lakou mamuli o Davida me kekahi poe koa; no ka mea, he poe kanaka koa ikaika lakou a pau, a he mau luna iwaena o ka poe koa.
Wọ́n sì ran Dafidi lọ́wọ́ lórí ẹgbẹ́ ogun náà, nítorí gbogbo wọn ni akọni ènìyàn àwọn sì tún ni olórí nínú àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
22 Ia manawa no, ia la ae, ia la ae, haele mai la [na kanaka] io Davida la, a lilo ae la lakou i poe koa nui, e like me ka puali o ke Akua.
Ọjọ́ dé ọjọ́ ni àwọn ọkùnrin wá láti ran Dafidi lọ́wọ́, títí tí ó fi ní àwọn ológun ńlá, bí ogun Ọlọ́run.
23 Eia ka helu ana i na poe i makaukau no ke kaua, i hele mai io Davida la ma Heberona, e hoohuli ae i ke aupuni o Saula io na la, e like me ka olelo ana a Iehova,
Àwọn wọ̀nyí sì ni iye ọkùnrin tí ó ti di ìhámọ́ra fún ogun àwọn ẹni tí ó wá sọ́dọ̀ Dafidi ní Hebroni láti yí ìjọba Dafidi padà sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ.
24 O na mamo a Iuda i lawe i ka palekaua a me ka ihe, he eono tausani lakou a me na haneri keu ewalu, i makaukau no ke kaua.
Ọkùnrin Juda, tí o ń gbé asà àti ọ̀kọ̀, ẹgbàáta lé lẹ́gbẹ̀rin tí ó ti di ìhámọ́ra fún ogun.
25 O na mamo a Simeona, na kanaka koa ikaika no ke kaua, ehiku tausani lakou, a me ka haneri keu.
Àwọn ọkùnrin Simeoni, akọni tó mú fún ogun sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ó lé ọgọ́rùn-ún;
26 O na mamo a Levi, eha tausani a me na haneri keu eono.
àwọn ọkùnrin Lefi ẹgbàajì ó le ẹgbẹ̀ta,
27 O Iehoiada ke alakai o ka poe mamo a Aarona, a me ia pu na tausani ekolu a me na haneri keu ehiku.
pẹ̀lú Jehoiada, olórí ìdílé Aaroni pẹ̀lú ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ènìyàn,
28 A o Zadoka, he kanaka hou, he koa ikaika, a he iwakaluakumamalua na luna koa o ka ohana a kona makuakane.
àti Sadoku akọni ọ̀dọ́mọkùnrin, pẹ̀lú àwọn méjìlélógún ìjòyè láti ọ̀dọ̀ àwọn ìdílé rẹ̀;
29 A o na mamo a Beniamina, na hoahanau o Saula, ekolu tausani; no ka mea, mamua he poe kiai ka nui o lakou i ka hale o Saula.
àwọn arákùnrin Benjamini ìbátan ọkùnrin Saulu ẹgbẹ̀rún mẹ́ta, ọ̀pọ̀ nínú àwọn ẹni tí ó si kù ní olóòtítọ́ sí ilé Saulu títí di ìgbà náà;
30 A o na mamo a Eperaima, he iwakalua tausani a me na haneri keu ewalu, na kanaka koa ikaika, ua kaulana mawaena o ka ohana o ko lakou mau kupuna.
àwọn arákùnrin Efraimu, ògbójú akọni, ènìyàn Ọlọ́run ni wọ́n nílé baba wọn ogún ẹgbẹ̀rún ó le ẹgbẹ̀rin;
31 A o ka ohana hapa a Manase, he umikumamawalu tausani, i kaheaia ma ka inoa e hele mai e hooalii ia Davida.
àwọn ọkùnrin nínú ààbọ̀ ẹ̀yà Manase, tí a yàn nípa orúkọ láti wá àti láti yan Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba, ẹgbàá mẹ́sàn.
32 A o na mamo a Isakara, ka poe hoomaopopo i na ouli o na manawa, e ike ai i na mea pono a ka Iseraela e hana'i: elua haneri na pookela o lakou; a nana ae la ko lakou poe hoahanau a pau i ka lakou olelo.
Àti ní ti àwọn ọmọ Isakari, àwọn ẹni tí ó ní òye àkókò, láti mọ ohun tí Israẹli ìbá máa ṣe; olórí wọn jẹ́ ìgbà; àti gbogbo àwọn ìbátan wọn ń bẹ ní ìkáwọ́ wọn.
33 O ka Zebuluna, ka poe hele aku i ke kaua, i makaukau i ke kaua me na mea kaua a pan, he kanalima tausani o lakou i ike i ka hoouka kaua, aole he naau lua.
Àwọn ọkùnrin Sebuluni, àti àwọn jagunjagun tí ó ti nípa ogun múra fún ogun pẹ̀lú oríṣìíríṣìí ohun èlò ìjà, láti ran Dafidi lọ́wọ́ pẹ̀lú àwọn tí kò fi iyèméjì ṣe ìjólóòótọ́ wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n.
34 A o ka Napetali, hookahi tausani luna koa, a me lakou he kanakolukumamahiku tausani, me na palekaua a me na ihe.
Àwọn ọkùnrin Naftali, ẹgbẹ̀rún ìjòyè àpapọ̀ pẹ̀lú ẹgbàá méjìdínlógún. Ọkùnrin tí wọ́n gbé asà àti ọ̀kọ̀ wọn.
35 A o ka Dana i makaukau i ke kaua, he iawakaluakumamawalu tausani, a me na haneri keu eono.
Àwọn ọkùnrin Dani, tí wọ́n ṣetán fún ogun ẹgbàá mẹ́tàlá.
36 A o ka Asera, ka poe hele aku i ke kaua, i makaukau i ke kaua, he kanaha tausani.
Àwọn ọkùnrin Aṣeri, àwọn tí ó ti ní ìmọ̀ ogun múra fún ogun ọ̀kẹ́ méjì.
37 A ma kela aoao o Ioredane, o ka Reubena, a o ka Gada, a o ka ohana hapa a Manase, me na mea kaua a pau e kaua ai, he haneri a me ka iwakalua tausani.
Láti ìlà-oòrùn Jordani, ọkùnrin Reubeni, Gadi, àti ìdajì ẹ̀yà Manase, dìmọ́ra pẹ̀lú gbogbo onírúurú ohun èlò ìjà ọ̀kẹ́ mẹ́fà.
38 O keia poe kanaka kaua a pau, i ike i ka hoouka i ke kaua, i hele mai me ka naau lokahi ma Heberona, e hoalii ia Davida maluna o ka Iseraela a pau: a ua lokahi hoi ka naau o ka Iseraela a pau i koe e hoalii ia Davida.
Gbogbo èyí ni àwọn ọkùnrin ológun tí ó fi ara wọn fún ogun láti ṣe iṣẹ́ fún nínú ẹgbẹ́. Wọ́n wá sí Hebroni tí ó kún fún ìpinnu láti fi Dafidi jẹ́ ọba lórí gbogbo Israẹli. Gbogbo àwọn ìyókù lára àwọn ọmọ Israẹli sì jẹ́ onínú kan láti fi Dafidi jẹ ọba.
39 Ilaila lakou me Davida, ekolu la, e ai ana a e inu ana: no ka mea, ua hoomakaukau ko lakou poe hoahanau na lakou.
Àwọn ọkùnrin náà lo ọjọ́ mẹ́ta níbẹ̀ pẹ̀lú Dafidi, wọ́n jẹ, wọ́n sì ń mu, nítorí ìdílé wọn ti pèsè oúnjẹ fún wọn.
40 Oia hoi, o ka poe o kokoke ana me lakou, a hiki aku i ka Isakara, a i ka Zebuluna, a i ka Napetali, lawe mai la lakou i ka berena maluna o na miula, a o na kamelo, a o na hoki, a o na bipi; me ka ai a me ka palaoa, me na pai huafiku, a me na pai huawaina, me ka waina, ka aila, na bipi a me na hipa he nui loa: no ka mea, he olioli iloko o ka Iseraela.
Àwọn aládùúgbò láti ọ̀nà jíjìn gẹ́gẹ́ bí Isakari, Sebuluni àti Naftali gbé oúnjẹ wá lórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, lórí ràkunmí, àti lórí ìbáaka àti lórí màlúù, àní oúnjẹ ti ìyẹ̀fun, èso àjàrà gbígbẹ, èso ọ̀pọ̀tọ́, àkàrà dídùn, ọtí wáìnì, òróró, màlúù àti àgùntàn, nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ayọ̀ wà ní Israẹli.

< I Oihanaalii 12 >