< Thaburi 68 >

1 Thaburi ya Daudi Ngai nĩakĩarahũke, ahurunje thũ ciake; nao arĩa mamũthũire nĩmoore mehere mbere yake.
Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Orin. Kí Ọlọ́run kí ó dìde, kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ kí ó fọ́nká; kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ kí ó sá níwájú rẹ̀.
2 O ta ũrĩa ndogo yũmbũragwo nĩ rũhuho-rĩ, ũromombũra; o ta ũrĩa mũhũra ũringũkagio nĩ mwaki-rĩ, andũ arĩa aaganu marothira marĩ mbere ya Ngai.
Bí ìjì ti ń fẹ́ èéfín lọ, kí ó fẹ́ wọn lọ; bí ìda ti í yọ́ níwájú iná, kí olùṣe búburú ṣègbé níwájú Ọlọ́run.
3 No rĩrĩ, arĩa athingu marocanjamũka na makene marĩ mbere ya Ngai; marorũũhia nĩ gũkena.
Ṣùgbọ́n kí inú olódodo kí ó dùn kí ó sì kún fún ayọ̀ níwájú Ọlọ́run; kí inú wọn kí ó dùn, kí ó sì kún fún ayọ̀.
4 Inĩrai Ngai, mũine mũgooce rĩĩtwa rĩake, kumiai ũcio ũhaicaga matu ta mbarathi, rĩĩtwa rĩake nĩ Jehova; gĩcanjamũkei mũrĩ mbere yake.
Ẹ kọrin sí Ọlọ́run, ẹ kọrin ìyìn sí i, ẹ la ọ̀nà fún ẹni tí ń rékọjá ní aginjù. Olúwa ni orúkọ rẹ̀, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú rẹ̀.
5 Ngai ũrĩa ũikaraga gĩikaro gĩake gĩtheru-rĩ, nĩwe ithe wa ciana cia ngoriai, na mũgitĩri wa atumia a ndigwa.
Baba àwọn aláìní baba àti onídàájọ́ àwọn opó ni Ọlọ́run ní ibùgbé rẹ̀ mímọ́
6 Ngai nĩatũmaga arĩa maikaraga marĩ oiki magĩe na mĩciĩ, arĩa ohe amohorithagia na akamoimagaria; no andũ arĩa aremi matũũraga bũrũri mũũmũ.
Ọlọ́run gbé aláìlera kalẹ̀ nínú ìdílé, ó darí àwọn ẹlẹ́wọ̀n pẹ̀lú orin, ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́tẹ̀ ní ń gbé nínú ilẹ̀ gbígbẹ.
7 Wee Ngai rĩrĩa woimagarire ũrĩ mbere ya andũ aku, hĩndĩ ĩrĩa watuĩkanĩirie rũngʼũrĩ-inĩ-rĩ,
Nígbà tí ìwọ bá jáde lónìí níwájú àwọn ènìyàn rẹ, Ọlọ́run, tí ń kọjá lọ láàrín aginjù, (Sela)
8 thĩ nĩyathingithire, narĩo igũrũ rĩkiuria mbura, nĩ ũndũ wa gũũka kwa Ngai, o Ũcio Ngai wa Sinai, na nĩ ũndũ wa gũũka kwa Ngai, Ngai wa Isiraeli.
Ilẹ̀ mì títí, àwọn ọ̀run ń rọ òjò jáde, níwájú Ọlọ́run, ẹni Sinai, níwájú Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli.
9 Wee Ngai-rĩ, nĩwoiririe mbura nyingĩ, ũkĩnyootora bũrũri ũcio wa igai rĩaku ũrĩa wangʼarĩte.
Ìwọ fún wa ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ òjò, Ọlọ́run; ìwọ tu ilẹ̀ ìní rẹ̀ lára nígbà tí ó rẹ̀ ẹ́ tan.
10 Andũ aku magĩtũũra kuo, na kuumana na ũingĩ wa indo ciaku, Wee Ngai-rĩ, ũgĩtanahĩra athĩĩni acio.
Àwọn ènìyàn rẹ tẹ̀dó síbẹ̀ nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìní rẹ, Ọlọ́run, ìwọ pèsè fún àwọn aláìní.
11 Mwathani nĩaheanire ũhoro, nao arĩa maawanĩrĩire maarĩ gĩkundi kĩnene:
Olúwa ti pàṣẹ ọ̀rọ̀, púpọ̀ ní ogun àwọn ẹni tí ó ń ròyìn rẹ̀.
12 “Athamaki na mbũtũ cia ita moraga na ihenya; nakuo kambĩ-inĩ andũ magayanaga indo cia ndaho.
“Àwọn ọba àti àwọn ológun yára sálọ; obìnrin tí ó sì jókòó ni ilé ní ń pín ìkógun náà.
13 O na rĩrĩa mũkomete hakuhĩ na mwaki wa gĩikaro kĩa nja, mũhaana o ta mathagu ma ndutura magemetio na betha, nacio njoya ciayo ikagemio na thahabu ĩkũhenia.”
Nígbà tí ẹ̀yin dùbúlẹ̀ láàrín agbo ẹran, nígbà náà ni ẹ̀yin ó dàbí ìyẹ́ àdàbà ti a bò ní fàdákà, àti ìyẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú wúrà pupa.”
14 Rĩrĩa Mwene-Hinya-Wothe aahurunjire athamaki bũrũri-inĩ-rĩ, kwahaanaga o ta rĩrĩa tharunji ĩgwĩte kĩrĩma-inĩ gĩa Zalimoni.
Nígbà tí Olódùmarè fọ́n àwọn ọba ká ní ilẹ̀ náà, ó dàbí òjò dídi ní Salmoni.
15 Ĩ irĩma cia Bashani ti irĩma irĩ riiri; irĩma cia Bashani irĩ tũcũmbĩrĩ tũingĩ.
Òkè Baṣani jẹ́ òkè Ọlọ́run; òkè tí ó ní orí púpọ̀ ni òkè Baṣani.
16 Inyuĩ irĩma ici irĩ tũcũmbĩrĩ tũingĩ-rĩ, mũrarora na ũiru nĩkĩ, kĩrĩma kĩrĩa Ngai athuurĩte gĩtuĩke gĩikaro gĩake, o kũrĩa Jehova we mwene egũtũũra nginya tene?
Kí ló dé tí ẹ̀yin fi ń ṣe ìlara, ẹ̀yin òkè wúwo, òkè tí Ọlọ́run ti fẹ́ láti jẹ ọba níbi tí Olúwa fúnra rẹ̀ yóò máa gbé títí láé?
17 Ngaari cia Ngai cia ita nĩ makũmi ma ngiri, na ngiri cia ngiri; Mwathani nĩokĩte arĩ gatagatĩ ga cio oimĩte Kĩrĩma gĩa Sinai, agatoonya handũ hake haamũre.
Ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ni kẹ̀kẹ́ ogun Ọlọ́run ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún; Olúwa ń bẹ láàrín wọn, ní Sinai ni ibi mímọ́ rẹ̀.
18 Rĩrĩa wambatire igũrũ, nĩwatongoririe arĩa maatahĩtwo mũtongoro-inĩ waku; nĩwamũkĩrire iheo kuuma kũrĩ andũ, o na ũgĩciamũkĩra kuuma kũrĩ andũ arĩa aremi, nĩgeetha Wee, Jehova Ngai, ũtũũre kuo.
Ìwọ ti gòkè sí ibi gíga ìwọ ti di ìgbèkùn ní ìgbèkùn lọ; ìwọ ti gba ẹ̀bùn fún ènìyàn: nítòótọ́, fún àwọn ọlọ̀tẹ̀ pẹ̀lú, kí Olúwa Ọlọ́run lè máa bá wọn gbé.
19 Goocai Mwathani, o we Mũrungu Mũhonokia witũ, o we ũkuuaga mĩrigo iitũ mũthenya o mũthenya.
Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Olùgbàlà wa, ẹni tí ó ń fi ojoojúmọ́ gba ẹrù wa rù. (Sela)
20 Ngai witũ nĩ Mũrungu ũhonokanagia; Mwathani Jehova nĩwe rĩũrĩro rĩa kuuma gĩkuũ-inĩ.
Ọlọ́run wa jẹ́ Ọlọ́run tó ń gbàlà àti sí Olúwa Olódùmarè ni ó ń gbà wá lọ́wọ́ ikú.
21 Ti-itherũ Ngai nĩakamemenda ciongo cia thũ ciake, amemende ruototia rwa arĩa mathiiaga na mbere kwĩhia.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò tẹ orí àwọn ọ̀tá rẹ̀, àti agbárí onírun àwọn tó ń tẹ̀síwájú nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn
22 Mwathani ekuuga atĩrĩ, “Nĩngaruta thũ cianyu kuuma Bashani; ndĩcirute iria-inĩ kũrĩa kũriku,
Olúwa wí pé, “Èmi ó mú wọn wá láti Baṣani; èmi ó mú wọn wá láti ibú omi Òkun,
23 nĩgeetha mũtobokie makinya manyu thakame-inĩ ya thũ cianyu, o nacio nĩmĩ cia ngui cianyu igĩe na igai rĩacio.”
kí ẹsẹ̀ rẹ kí ó le pọ́n ní inú ẹ̀jẹ̀ àwọn ọ̀tá rẹ, àti ahọ́n àwọn ajá rẹ ní ìpín tiwọn lára àwọn ọ̀tá rẹ.”
24 Wee Ngai-rĩ, mũtongoro waku nĩwonekete, o mũtongoro wa Mũrungu wakwa na Mũthamaki agĩtoonya handũ-harĩa-haamũre.
Wọ́n ti rí ìrìn rẹ, Ọlọ́run, ìrìn Ọlọ́run mi àti ọba mi ní ibi mímọ́ rẹ̀.
25 Aini a nyĩmbo nĩo matongoretie, makarũmĩrĩrwo nĩ ahũũri inanda; hamwe nao nĩ airĩtu arĩa marahũũra tũhembe.
Àwọn akọrin wà ní iwájú, àwọn olórin wà lẹ́yìn; àwọn ọmọbìnrin tí ń lu ṣaworo sì wà pẹ̀lú wọn.
26 Goocai Ngai, kĩũngano-inĩ kĩrĩa kĩnene; mũgooce Jehova kĩũngano-inĩ gĩa Isiraeli.
Ẹ fi ìyìn fún Olúwa ní ẹgbẹgbẹ́; àní fún Olúwa ẹ̀yin tí ó ti orísun Israẹli wá.
27 Mũhĩrĩga ũrĩa mũnini wa Benjamini nĩguo ũcio ũmatongoretie, kĩrĩndĩ kĩnene kĩa athamaki a Juda kĩrĩ ho, na makarũmĩrĩrwo nĩ athamaki a Zebuluni na a Nafitali.
Níbẹ̀ ní ẹ̀yà kékeré Benjamini wà, tí ó ń darí wọn, níbẹ̀ ni àwọn ọmọ-aládé Juda, níbẹ̀ ni àwọn ọmọ-aládé Sebuluni àti tí Naftali.
28 Wee Ngai-rĩ, onania ũhoti waku; tuonie hinya waku, Wee Ngai, ta ũrĩa waneka.
Pàṣẹ agbára rẹ, Ọlọ́run; fi agbára rẹ hàn wá, Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe ní ìṣáájú.
29 Tondũ wa hekarũ yaku ĩrĩa ĩrĩ kũu Jerusalemu-rĩ, athamaki nĩmagakũrehagĩra iheo.
Nítorí tẹmpili rẹ ni Jerusalẹmu àwọn ọba yóò mú ẹ̀bùn wá fún ọ.
30 Rũithia nyamũ ĩrĩa ĩrĩ ithanjĩ-inĩ, ũkĩrũithie rũũru rwa ndegwa rũrĩa rũrĩ thĩinĩ wa tũcaũ twa ndũrĩrĩ. Ĩkwĩnyiihĩrie, na ĩkũrehere icunjĩ cia betha. Hurunja ndũrĩrĩ iria ikenagĩra mbaara.
Bá àwọn ẹranko búburú wí, tí ń gbé láàrín eèsún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn akọ màlúù pẹ̀lú àwọn ọmọ màlúù títí olúkúlùkù yóò fi foríbalẹ̀ pẹ̀lú ìwọ̀n fàdákà: tú àwọn ènìyàn tí ń ṣe inú dídùn sí ogun ká.
31 Abarũthi nĩmagooka moimĩte bũrũri wa Misiri; naguo bũrũri wa Kushi nĩũkenyiihĩria Ngai.
Àwọn ọmọ-aládé yóò wá láti Ejibiti; Etiopia yóò na ọwọ́ rẹ̀ sí Ọlọ́run.
32 Inĩrai Ngai, inyuĩ mothamaki ma thĩ, inai mũgooce Mwathani,
Kọrin sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ìjọba ayé, kọrin ìyìn sí Olúwa, (Sela)
33 ũcio ũthiiaga ahaicĩte matu macio ma igũrũ ma tene, ũcio ũrurumaga na mũgambo mũnene.
Sí ẹni tí ń gun ọ̀run dé ọ̀run àtijọ́ lókè, tó ń fọhùn rẹ̀, ohùn ńlá.
34 Anĩrĩrai hinya wa Ngai, we ũrĩa ũnene wake arĩ guo ũrũgamĩrĩire Isiraeli, o ũcio ũhoti wake ũrĩ kũu matu-inĩ.
Kéde agbára Ọlọ́run, ọláńlá rẹ̀ wà lórí Israẹli, tí agbára rẹ̀ wà lójú ọ̀run.
35 Wee Ngai-rĩ, ũrĩ wa gwĩtigĩrwo, ũrĩ handũ hau haku haamũre; Mũrungu wa Isiraeli nĩaheaga andũ ake ũhoti o na hinya. Ngai arogoocwo!
Ìwọ ní ẹ̀rù, Ọlọ́run, ní ibi mímọ́ rẹ; Ọlọ́run Israẹli fi agbára àti okun fún àwọn ènìyàn rẹ. Olùbùkún ní Ọlọ́run!

< Thaburi 68 >