< Thaburi 33 >
1 Inĩrai Jehova mũkenete, inyuĩ andũ arĩa athingu; andũ arĩa arũngĩrĩru ngoro nĩo maagĩrĩirwo nĩkũmũgooca.
Ẹ yọ̀ nínú Olúwa, ẹ̀yin olódodo; ìyìn si yẹ fún ẹni dídúró ṣinṣin.
2 Goocai Jehova na kĩnanda kĩa mũgeeto; mũinĩrei na kĩnanda kĩrĩa kĩgeete na nga ikũmi.
Ẹ yin Olúwa pẹ̀lú dùùrù; ẹ máa fi ohun èlò olókùn mẹ́wàá kọrin sí i.
3 Mũinĩrei rwĩmbo rwerũ; hũũrai inanda mũrĩ na ũũgĩ, na mwanĩrĩre nĩ gũkena.
Ẹ kọ orin tuntun sí i; ẹ máa fi ọgbọọgbọ́n lu ohun èlò orin sí i, pẹ̀lú ariwo.
4 Nĩgũkorwo kiugo kĩa Jehova nĩkĩerekereru na nĩ kĩa ma; we nĩ mwĩhokeku maũndũ-inĩ mothe marĩa ekaga.
Nítorí pé ọ̀rọ̀ Olúwa dúró ṣinṣin, gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ ni à ń ṣe nínú òtítọ́.
5 Jehova nĩendete ũthingu na ciira wa kĩhooto; thĩ yothe ĩiyũrĩte wendani wake ũrĩa ũtathiraga.
Ó fẹ́ òtítọ́ àti ìdájọ́; ilé ayé kún fún ìdúró ṣinṣin àti àánú Olúwa.
6 Igũrũ rĩombirwo na ũndũ wa kiugo kĩa Jehova, mbũtũ cia igũrũ ikĩũmbwo na mĩhũmũ ya kanua gake.
Nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ṣe dá àwọn ọ̀run, àti gbogbo àwọn ẹgbẹ́ ogun wọn nípa ìmísí ẹnu rẹ̀.
7 Aacookanĩrĩirie maaĩ ma iria inene ndigithũ-inĩ; maaĩ ma kũrĩa kũriku aamaigire thĩinĩ wa makũmbĩ.
Ó kó àwọn omi òkun jọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó wà nínú ìgò; ó sì fi ibú ṣe ilé ìṣúra gbogbo.
8 Thĩ yothe nĩĩtigĩre Jehova; andũ othe a thĩ nĩmamũtĩĩe.
Jẹ́ kí gbogbo ayé kí ó bẹ̀rù Olúwa: jẹ́ kí gbogbo àwọn olùgbé ayé kí ó wà nínú ìbẹ̀rù rẹ̀.
9 Nĩgũkorwo aaririe, thĩ ĩkĩgĩa kuo; aathanire, ĩkĩĩhaanda, ĩkĩrũma wega.
Nítorí tí ó sọ̀rọ̀, ó sì ti rí bẹ́ẹ̀; ó pàṣẹ ó sì dúró ṣinṣin.
10 Jehova nĩarigiicaga mĩbango ya ndũrĩrĩ; nĩathũkagia mĩoroto ya andũ.
Olúwa ti mú ìmọ̀ràn àwọn orílẹ̀-èdè wá sí asán; ó sì mú àrékérekè àwọn ènìyàn di ṣíṣákì í.
11 No mĩbango ya Jehova ĩĩhaandaga wega nginya tene, mĩoroto ya ngoro yake ĩgakinyĩra njiarwa na njiarwa.
Ìgbìmọ̀ Olúwa dúró títí ayérayé, àní ìrò inú rẹ̀ láti ìrandíran ni.
12 Kũrathimwo-rĩ, nĩ rũrĩrĩ rũrĩa Jehova arĩ we Ngai waruo, andũ arĩa eethuurĩire matuĩke igai rĩake.
Ìbùkún ni fún orílẹ̀-èdè náà, Ọlọ́run ẹni tí Olúwa jẹ́ tirẹ̀, àti àwọn ènìyàn náà tí ó ti yàn ṣe ìní rẹ̀.
13 Jehova arĩ igũrũ aroraga thĩ akoona andũ othe;
Olúwa wò láti ọ̀run wá; Ó sì rí gbogbo ìran ènìyàn.
14 acũthagĩrĩria arĩa othe matũũraga gũkũ thĩ, arĩ o kũu gĩikaro-inĩ gĩake,
Níbi tí ó ti jókòó lórí ìtẹ́ Ó wo gbogbo àwọn olùgbé ayé
15 we nĩwe mũũmbi wa ngoro ciao othe, na nĩoĩ mawĩra mao mothe.
ẹni tí ó ṣe àyà wọn bákan náà, ó sì kíyèsi ìṣe wọn.
16 Gũtirĩ mũthamaki ũhonokagio nĩ mũigana wa ita rĩake, na gũtirĩ njamba ya ita ĩĩteithũraga nĩ ũndũ wa hinya wayo mũnene.
A kò gba ọba kan là nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọ-ogun; kò sì sí jagunjagun tí a gbà sílẹ̀ nípa agbára ńlá rẹ̀.
17 Ha ũhoro wa kũhonokania-rĩ, mbarathi cia mbaara nĩ mwĩhoko wa tũhũ; o na ĩrĩ na hinya mũingĩ ndĩngĩhonokania.
Ohun asán ni ẹṣin fún ìṣẹ́gun; bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fi agbára ńlá rẹ̀ gbani sílẹ̀.
18 No rĩrĩ, maitho ma Jehova macũthagĩrĩria andũ arĩa mamwĩtigagĩra, o acio maikaraga mehokete wendo wake ũrĩa ũtathiraga,
Wò ó, ojú Olúwa wà lára àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, àti lára àwọn tí ó ní ìrètí nínú ìfẹ́ rẹ̀ tí ó dúró ṣinṣin.
19 akamateithũra gĩkuũ-inĩ, na akamatũũria muoyo hĩndĩ ya ngʼaragu.
Láti gba ọkàn wọn kúrò lọ́wọ́ ikú àti láti pa wọ́n mọ́ láààyè lọ́wọ́ ìyàn.
20 Ithuĩ twetagĩrĩra Jehova tũrĩ na mwĩhoko; nĩwe ũteithio witũ o na ngo iitũ.
Ọkàn wa dúró de Olúwa; òun ni ìrànlọ́wọ́ wa àti asà wa.
21 Ngoro ciitũ nĩcikenete nĩ ũndũ wake, nĩgũkorwo twĩhokete rĩĩtwa rĩake itheru.
Ọkàn wa yọ̀ nínú rẹ̀, nítorí pé, àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ rẹ mímọ́.
22 Wee Jehova-rĩ, wendo waku ũrĩa ũtathiraga ũroikarania na ithuĩ, o ta ũrĩa ithuĩ tũkwĩrĩgĩrĩire.
Kí àánú rẹ, Olúwa, kí ó wà lára wa, àní gẹ́gẹ́ bí àwa ti ń ṣe ìrètí nínú rẹ.