< Thaburi 22 >

1 Thaburi ya Daudi Ngai wakwa, Ngai wakwa, ũndiganĩirie nĩkĩ? Ũndaihĩrĩirie ũguo nĩkĩ, ũkaaga kũũhonokia, ũkaraihĩrĩria ciugo cia mũcaayo wakwa?
Fún adarí orin. Tí ohùn orin “àgbọ̀nrín òwúrọ̀.” Saamu ti Dafidi. Ọlọ́run mi, Ọlọ́run mi, èéṣe tí ìwọ fi kọ̀ mí sílẹ̀? Èéṣe tí o fi jìnnà láti gbà mí là, àní sí igbe ìkérora mi?
2 Wee Ngai wakwa, ngũkayagĩra mũthenya, no ndũnjĩtĩkaga, ngũkayagĩra ũtukũ, na ndingĩkira.
Ọlọ́run mi, ní ọ̀sán gangan ni mo kígbe, ṣùgbọ́n ìwọ kò dá mi ní ohùn: àti ní òru èmi kò dákẹ́.
3 No rĩrĩ, Wee ũrĩ Mũtheru, Wee ũikarĩire gĩtĩ kĩa ũnene; Wee nĩwe ũgoocagwo nĩ Isiraeli.
Ṣùgbọ́n síbẹ̀ ẹni mímọ́ ni Ìwọ; ẹni tí ó tẹ ìyìn Israẹli dó.
4 Maithe maitũ nĩwe meehokaga; maakwĩhokire nawe ũkĩmahonokia.
Àwọn baba ńlá wa ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú rẹ; wọ́n ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ìwọ sì gbà wọ́n.
5 Maagũkaĩire nao makĩhonokio; maakwĩhokire na matiigana gũconorithio.
Ìwọ ni wọ́n sun ẹkún sí, wọ́n sì ní ìgbàlà; ìwọ ni wọ́n gbẹ́kẹ̀lé, a kò sì dójútì wọ́n.
6 No niĩ nduĩkĩte o ta kĩgunyũ, no ti ta mũndũ, nganyararwo nĩ andũ na ngamenwo nĩ kĩrĩndĩ.
Ṣùgbọ́n kòkòrò ní mo jẹ́, kì í sì í ṣe ènìyàn; mo di ẹlẹ́gàn àwọn ènìyàn, ẹlẹ́yà àwọn ènìyàn.
7 Andũ arĩa othe maanyonaga nĩmanyũrũragia; makaanuma makĩinainagia mĩtwe, makoiga atĩrĩ:
Gbogbo àwọn tí ó rí mí fi mí ṣe ẹlẹ́yà; wọ́n yọ ètè ẹ̀gàn wọn sí mi, wọ́n sì ń mi orí wọn pé.
8 “Ehokaga Jehova; Jehova nĩakĩmũhatũre. Nĩakĩmũteithũre, nĩgũkorwo nĩakenagio nĩwe.”
“Ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé Olúwa; jẹ́ kí Olúwa gbà á là. Jẹ́ kí ó gbà á là, nítorí pé, ó ní ayọ̀ nínú rẹ̀.”
9 No rĩrĩ, Wee nĩwe wandutire nda ya maitũ; watũmire ngwĩhoke ndĩ o nyondo-inĩ cia maitũ.
Síbẹ̀ ìwọ ni ó ti mú mi wá láti inú; ìwọ ni ó mú mi wà láìléwu, nígbà tí mo rọ̀ mọ́ ọmú ìyá mi.
10 Kuuma ndaaciarwo ndaikirio o harĩwe; kuuma ndoima nda ya maitũ ũkoretwo ũrĩ Mũrungu wakwa.
Ìwọ ni a fi mí lé lọ́wọ́ láti inú ìyá mi wá, nígbà tí ìyá mí sì ti bí mi, ìwọ ni Ọlọ́run mi.
11 Ndũkandaihĩrĩrie, nĩgũkorwo thĩĩna ũrĩ o hakuhĩ, na gũtirĩ mũndũ o na ũmwe wa kũndeithia.
Má ṣe jìnnà sí mi, nítorí pé ìyọnu súnmọ́ tòsí kò sì ṣí ẹnìkan tí yóò ṣe ìrànlọ́wọ́.
12 Ndegwa nyingĩ nĩindigicĩirie; thiũrũrũkĩirio nĩ ndegwa irĩ hinya cia Bashani.
Ọ̀pọ̀ akọ màlúù yí mi ká; àwọn màlúù alágbára Baṣani rọ̀gbà yí mi ká.
13 Mĩrũũthi ĩkũrarama, ĩgĩtambuuranga kĩrĩa ĩgwatĩtie, ĩnjathamĩirie tũnua twayo.
Wọ́n ya ẹnu wọn sì mi bí i kìnnìún tí ń dọdẹ kiri, tí ń ké ramúramù.
14 Njitĩtwo thĩ ta maaĩ, namo mahĩndĩ makwa mothe nĩmarekanĩtie. Ngoro yakwa yororoete ta mũhũra; ĩtwekete ĩrĩ thĩinĩ wakwa.
A dà mí jáde gẹ́gẹ́ bí omi, gbogbo egungun mi ti yẹ̀ kúrò ní oríkèé rẹ̀. Ọkàn mi sì dàbí i ìda; tí ó yọ́ láàrín inú mi.
15 Hinya wakwa ũniarĩte ta rũgĩo, naruo rũrĩmĩ rwakwa rũkanyiitana na karakara nĩkũngʼara; ũngometie rũkũngũ-inĩ rwa gĩkuũ.
Agbára mí ti gbẹ bí àpáàdì, ahọ́n mí sì tilẹ̀ mọ́ párí ẹ̀rẹ̀kẹ́ ẹ mi; ìwọ ti tẹ́ mi sínú eruku ikú. (questioned)
16 Ndĩĩmũrigiicĩrie nĩ magui; ndĩĩmũthiũrũrũkĩrie nĩ gĩkundi kĩa andũ arĩa meekaga ũũru, nĩmatheecangĩte moko na magũrũ makwa.
Àwọn ajá yí mi ká; ìjọ àwọn ènìyàn ibi ti ká mi mọ́, wọ́n gún mi lọ́wọ́, wọ́n sì gún mi lẹ́sẹ̀.
17 Mahĩndĩ makwa no hote kũmatara mothe; andũ marandora na makangũũrĩra maitho.
Mo lè ka gbogbo àwọn egungun mi; àwọn tìkára wọn ń wò, wọ́n dójú lé mi.
18 Maragayana nguo ciakwa, nayo kanjũ yakwa makamĩcuukĩra mĩtĩ.
Wọ́n pín aṣọ mi láàrín ara wọn àní lórí aṣọ mi ni wọ́n ṣẹ́ gègé.
19 No rĩrĩ, Wee Jehova, ndũkandaihĩrĩrie mũno; Wee Hinya wakwa, hiũha ũũke ũndeithie.
Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, má ṣe jìnnà sí mi. Háà! Olùrànlọ́wọ́ ọ̀ mi, yára wá fún àtìlẹ́yìn mi!
20 Teithũra muoyo wakwa kuuma harĩ rũhiũ rwa njora, ũteithũre muoyo wakwa wa goro harĩ hinya wa magui.
Gba ọkàn mi sílẹ̀ lọ́wọ́ idà, àní ẹ̀mí mi lọ́wọ́ agbára àwọn ajá.
21 Thara kuuma kanua-inĩ ka mĩrũũthi; honokia kuuma hĩa-inĩ cia mbogo.
Gba ọkàn mi sílẹ̀ lọ́wọ́ kìnnìún; kí o sì gbà mí sílẹ̀ lọ́wọ́ ìwo àgbáǹréré.
22 Nĩngumbũra rĩĩtwa rĩaku kũrĩ ariũ a baba; ndĩrĩkũgoocaga ndĩ kĩũngano-inĩ.
Èmi yóò kéde orúkọ rẹ láàrín arákùnrin àti arábìnrin mi; nínú ìjọ ni èmi yóò máa yìn ọ́.
23 Inyuĩ andũ aya mwĩtigĩrĩte Jehova, mũgoocei! Inyuothe a njiaro cia Jakubu, mũkumiei, inyuĩ a njiaro cia Isiraeli, mũtĩĩei.
Ẹ̀yin tí ẹ bẹ̀rù Olúwa, ẹ yìn ín! Gbogbo ẹ̀yin ìran Jakọbu, ẹ fi ògo fún un! Ẹ dìde fún un tẹ̀rù tẹ̀rù, ẹ̀yin irú-ọmọ Israẹli!
24 Nĩgũkorwo we ndaamenire kana akĩnyarara gũthĩĩnĩka kwa ũrĩa mũnyamarĩku; ndaahithire ũthiũ wake kuuma kũrĩ we, no nĩathikĩrĩirie kĩrĩro gĩake.
Nítorí pé òun kò ṣátá, bẹ́ẹ̀ ni kò sì kórìíra ìpọ́njú àwọn tí a ni lára; kò sì fi ojú rẹ̀ pamọ́ fún mi ṣùgbọ́n ó gbọ́ nígbà tí mo ké pè é.
25 Gĩtũmi kĩa ngũgooce ũrĩa ngũgoocaga ndĩ kĩũngano-inĩ kĩnene kiumĩte harĩwe; niĩ nĩndĩrĩhingagia mĩĩhĩtwa yakwa ndĩ mbere ya arĩa magwĩtigĩrĩte.
Láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni ìyìn mi yóò ti wá nínú àjọ ńlá; ẹ̀jẹ́ rẹ̀ ni èmi yóò san níwájú àwọn tí o bẹ̀rù rẹ̀
26 Andũ arĩa athĩĩni marĩrĩĩaga na makahũũna, arĩa marongoragia Jehova, nĩmarĩmũgoocaga; ngoro cianyu irotũũra nginya tene.
tálákà yóò jẹ yóò sì yó; àwọn tí n wá Olúwa yóò yin jẹ́ kí ẹ̀mí rẹ̀ wà láààyè títí ayérayé!
27 Andũ arĩa othe matũũraga ituri ciothe cia thĩ nĩmakaririkana na macookerere Jehova, andũ a nyũmba ciothe cia ndũrĩrĩ nĩmakainamĩrĩra mbere yake,
Gbogbo òpin ayé ni yóò rántí wọn yóò sì yípadà sí Olúwa, àti gbogbo ìdílé orílẹ̀-èdè ni wọn yóò jọ́sìn níwájú rẹ̀,
28 nĩgũkorwo ũthamaki nĩ wa Jehova, na nĩwe wathaga ndũrĩrĩ ciothe.
nítorí ìjọba ni ti Olúwa. Òun ni ó ń pàṣẹ lórí àwọn orílẹ̀-èdè.
29 Andũ arĩa othe atongu a thĩ makaarĩa na mamũhooe; arĩa othe makuuaga magathikwo nĩmagaturia ndu mbere yake, o acio matangĩhota gwĩtũũria muoyo.
Bẹ́ẹ̀ náà ni gbogbo àwọn olówó ayé wọn yóò ṣe àsè, wọn yóò sì sìn; gbogbo àwọn tí ó wọ inú ilẹ̀ lọ yóò kúnlẹ̀ ní iwájú rẹ̀ àti ẹni tí kò lè pa ọkàn ara rẹ̀ mọ́ ni ààyè.
30 Ciana nĩikamũtungatĩra; nacio nĩikaahe njiarwa iria igooka ũhoro wa Mwathani.
Irú-ọmọ rẹ̀ yóò sìn ín; a ó sọ fún àwọn ìran tí ń bọ̀ nípa Olúwa.
31 Acio nĩmakahunjia ũthingu wake kũrĩ andũ arĩa magaaciarwo, nĩgũkorwo nĩwe wĩkĩte ũguo.
Wọn yóò polongo òdodo rẹ̀ sí àwọn ọmọ tí a kò tí ì bí, wí pé, òun ni ó ṣe èyí.

< Thaburi 22 >