< Thaburi 2 >

1 Nĩ kĩĩ gĩtũmaga ndũrĩrĩ iciirĩre gwĩka ũũru na andũ mathugunde maũndũ ma tũhũ?
Èéṣe tí àwọn orílẹ̀-èdè fi ń dìtẹ̀, àti tí àwọn ènìyàn ń ṣe rìkíṣí asán?
2 Athamaki a thĩ nĩmatuĩte itua, na aathani magacookania ndundu nĩguo mookĩrĩre Jehova, na mookĩrĩre Ũrĩa wake Mũitĩrĩrie Maguta.
Àwọn ọba ayé péjọpọ̀ àti àwọn ìjòyè gbìmọ̀ pọ̀ sí Olúwa àti sí ẹni àmì òróró rẹ̀.
3 Moigaga atĩrĩ, “Nĩtwĩohorei mĩnyororo yao, na mabĩngũ mao tũmate matweherere.”
Wọ́n sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí a fa ẹ̀wọ̀n wọn já, kí a sì ju ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ wọn nù.”
4 Ũrĩa ũikarĩire gĩtĩ kĩa ũnene kũu igũrũ no gũtheka aratheka; We Mwathani-rĩ, nĩkũnyũrũria aramanyũrũria.
Ẹni tí ó gúnwà lórí ìtẹ́ lọ́run rẹ́rìn-ín; Olúwa fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà.
5 Ningĩ agacooka akamakũũma arakarĩte, na akamekĩra guoya mũnene angʼũrĩkĩte akameera atĩrĩ,
Nígbà náà ni yóò bá wọn wí ní ìbínú rẹ̀ yóò sì dẹ́rùbà wọ́n ní ìrunú rẹ̀, ó wí pé,
6 “Niĩ nĩ niĩ njigĩte Mũthamaki wakwa kũu Zayuni, kĩrĩma-inĩ gĩakwa kĩrĩa kĩamũre.”
“Èmi ti fi ọba mi sí ipò lórí Sioni, òkè mímọ́ mi.”
7 Niĩ nĩngwanĩrĩra itua rĩa Jehova: Jehova aanjĩĩrire atĩrĩ, “Wee nĩwe Mũrũ wakwa, ũmũthĩ nĩndatuĩka thoguo.
Èmi yóò sì kéde ìpinnu Olúwa: Ó sọ fún mi pé, “Ìwọ ni ọmọ mi; lónìí, èmi ti di baba rẹ.
8 Hooya niĩ, na nĩngũkũhe ndũrĩrĩ ituĩke igai rĩaku, nacio ituri cia thĩ ituĩke ciaku kĩũmbe.
Béèrè lọ́wọ́ mi, Èmi yóò jẹ́ kí orílẹ̀-èdè di ìní rẹ, òpin ilé ayé yóò sì jẹ́ ogún rẹ.
9 Nĩũgaciunanga na njũgũma ya kĩgera ya ũthamaki; ũgaacihehenja ihaane ta tũcunjĩ twa nyũngũ ya rĩũmba.”
Ìwọ yóò fi ọ̀pá irin ṣe àkóso wọn ìwọ yóò sì rún wọn wómúwómú bí ìkòkò amọ̀.”
10 Nĩ ũndũ ũcio, inyuĩ athamaki ta kĩũhĩgeei, inyuĩ aathani a thĩ mũtaarĩke.
Nítorí náà, ẹ̀yin ọba, ẹ jẹ́ ọlọ́gbọ́n; ẹ gbọ́ ìkìlọ̀ ẹ̀yin alákòóso ayé.
11 Tungatĩrai Jehova mũkĩmwĩtigagĩra, na mũkene o mũkĩinainaga.
Ẹ sin Olúwa pẹ̀lú ìbẹ̀rù ẹ sì máa yọ̀ pẹ̀lú ìwárìrì.
12 Mumunyai Mũriũ, ndakae kũrakara, na inyuĩ mũniinĩrwo njĩra-inĩ, nĩgũkorwo mangʼũrĩ make maahota kũrĩrĩmbũka o rĩmwe. Kũrathimwo-rĩ, nĩ arĩa othe moragĩra harĩ we.
Fi ẹnu ko ọmọ náà ní ẹnu, kí ó má ba à bínú, kí ó má ba à pa yín run ní ọ̀nà yín, nítorí ìbínú rẹ̀ lè ru sókè ní ẹ̀ẹ̀kan. Ìbùkún ni fún gbogbo àwọn tí ó fi í ṣe ibi ìsádi wọn.

< Thaburi 2 >