< Thimo 1 >

1 Ici nĩ thimo cia Solomoni mũrũ wa Daudi, ũrĩa warĩ mũthamaki wa Isiraeli:
Àwọn òwe ti Solomoni, ọmọ Dafidi, ọba Israẹli.
2 nĩ thimo cia gũtũma mũndũ agĩe na ũũgĩ, na ataarĩke; nĩ cia gũtũma ahote gũtaũkĩrwo nĩ ciugo cia ũũgĩ;
Láti le ní ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́, láti ní òye àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀.
3 nĩ cia gũtũma mũndũ ataarĩke ahote kũbarĩrĩra mũtũũrĩre wake, ekage maũndũ marĩa magĩrĩire, na ma kĩhooto, na marĩa mega;
Láti gba ẹ̀kọ́ ọgbọ́n, òdodo, àti ìdájọ́, àti àìṣègbè;
4 nĩ cia gũtũma ũrĩa ũtarĩ na ũũgĩ agĩe na ũmenyo, na cia gũtũma mũndũ mwĩthĩ agĩe na ũmenyo na ũgereri:
láti fi òye fún onírẹ̀lẹ̀, ìmọ̀ àti ìṣọ́ra fún àwọn èwe.
5 arĩa oogĩ-rĩ, nĩmathikĩrĩrie na mongerere wĩruti wao, nao arĩa akũũrani maũndũ metĩkĩre gũtongorio.
Jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n tẹ́tí kí ó sì ní ìmọ̀ kún ìmọ̀, sì jẹ́ kí ẹni òye gba ìtọ́sọ́nà.
6 Ningĩ nĩ cia gũtũma mũndũ ataũkĩrwo nĩ thimo na ngerekano, na ataũkĩrwo nĩ ciugo cia andũ arĩa oogĩ, na ndaĩ ciao.
Láti mọ ìtumọ̀ òwe àti ìtán-dòwe, àwọn ọ̀rọ̀ àti àlọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n.
7 Kĩambĩrĩria kĩa ũmenyo nĩ gwĩtigĩra Jehova, no arĩa akĩĩgu nĩ mathũire ũũgĩ na ũtaaro.
Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìbẹ̀rẹ̀ ìmọ̀, ṣùgbọ́n aláìgbọ́n kẹ́gàn ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́.
8 Mũrũ wakwa, thikĩrĩria mataaro ma thoguo, na ndũgatigane na ũrutani wa maitũguo.
Tẹ́tí, ìwọ ọmọ mi sí ẹ̀kọ́ baba rẹ, má ṣe kọ ẹ̀kọ́ màmá rẹ sílẹ̀.
9 Maũndũ macio magaatuĩka ithaga rĩa kũgemia mũtwe waku, na ta mũgathĩ wa kũgemia ngingo yaku.
Wọn yóò jẹ́ òdòdó ẹ̀yẹ olóòórùn dídùn lórí rẹ àti ọ̀ṣọ́ tí ó dára yí ọrùn rẹ ká.
10 Mũrũ wakwa, ehia mangĩgakũheenereria-rĩ, ndũkanetĩkanie nao.
Ọmọ mi, bí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ bá ń tàn ọ́, má ṣe gbà fún wọn.
11 Mangĩgakwĩra atĩrĩ, “Ũka ũthiĩ hamwe na ithuĩ; reke tuoherie mũndũ tũite thakame yake, reke tũcemaceeme mũndũ o na ũtehĩtie;
Bí wọn bá wí pé, “Wá pẹ̀lú wa; jẹ́ kí á ba ní ibùba fún ẹ̀jẹ̀ ẹnìkan, jẹ́ kí á lúgọ ní ìkọ̀kọ̀ de aláìṣẹ̀ ní àìnídìí;
12 ningĩ reke tũmamerie marĩ muoyo, o ta ũrĩa mbĩrĩra ĩĩkaga, na marĩ agima, o ta arĩa maharũrũkaga irima; (Sheol h7585)
jẹ́ ká gbé wọn mì láààyè, bí ibojì òkú, àti lódidi, bí àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sínú kòtò; (Sheol h7585)
13 Na ithuĩ-rĩ, tũkĩgĩe na indo cia goro cia mĩthemba yothe, na tũiyũrie nyũmba ciitũ na indo cia ndaho;
a ó rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan tó níye lórí a ó sì fi ìkógun kún inú ilé wa,
14 rutithania wĩra na ithuĩ, tũkorwo na mũhuko ũmwe ithuothe”;
da ìpín rẹ pọ̀ mọ́ àárín wa, a ó sì jọ pawó sínú àpò kan náà,”
15 mũrũ wakwa, tiga gũtwarana nao, ndũkagerere njĩra ciao;
ọmọ mi, má ṣe bá wọn lọ, má ṣe rìn ní ojú ọ̀nà wọn.
16 nĩgũkorwo magũrũ mao mahanyũkaga mathiĩ mehia-inĩ, nao mahiũhaga magaite thakame.
Nítorí ẹsẹ̀ wọn ń sáré sí ẹ̀ṣẹ̀, wọ́n yára láti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀.
17 Kaĩ nĩ wĩra wa tũhũ kũiga gĩkerenge nyoni ciothe igĩkuonaga-ĩ!
Wàhálà asán ni kí ènìyàn máa dẹ àwọ̀n sílẹ̀, ní ojú ẹyẹ!
18 Andũ aya mohagĩria thakame yao ene; maceemaga o mĩoyo yao ene!
Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ń lúgọ fún ẹ̀jẹ̀ ara wọn. Ara wọn ni wọ́n ń dá lọ́nà.
19 Ũcio nĩguo mũthia wa arĩa othe magĩaga na indo na njĩra ya ungumania; indo icio iniinaga mĩoyo ya arĩa magĩaga nacio.
Báyìí ni ìgbẹ̀yìn gbogbo àwọn tí ń wá èrè àìtọ́; yóò mú ẹ̀mí gbogbo ẹni tí ó rí i lọ.
20 Ũũgĩ nĩ aretana anĩrĩire njĩra-inĩ, ningĩ agakayũrũrũka arĩ ihaaro-inĩ cia mũingĩ;
Ọgbọ́n kígbe sókè ní pópó ó gbé ohùn rẹ̀ sókè láàrín ọjà;
21 Aragũthũka na mũgambo mũnene arĩ magomano-inĩ ma njĩra kũu kũrĩ inegene, o na itoonyero rĩa itũũra inene akoria atĩrĩ:
láàrín ọjà ni ó ti kígbe jáde ní ibodè ìlú ni ó ti sọ̀rọ̀ ọ rẹ̀:
22 “Inyuĩ mũtarĩ ũũgĩ-rĩ, nĩ nginya rĩ mũgũtũũra mwendete njĩra cianyu itarĩ cia ũũgĩ? Nĩ nginya rĩ anyũrũrania megũtũũra makenagĩra kĩnyũrũri, na arĩa akĩĩgu mathũire ũmenyo?
“Yóò ha ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin aláìmọ̀kan yóò fi fẹ́ àìmọ̀kan yín tó? Yóò ha ti pẹ́ tó tí àwọn ẹlẹ́gàn yóò ṣe inú dídùn sí ìpẹ̀gàn tó? Àwọn aláìgbọ́n kórìíra ìmọ̀?
23 Korwo nĩmwetĩkĩrire kũigua ũtaaro wakwa-rĩ, nĩingĩamũhingũrĩire ngoro yakwa, ndũme mũmenye meciiria makwa.
Bí ẹ bá ti gbọ́ ìbáwí ì mi ni, ǹ bá ti tú ohun tí ó wà nínú ọkàn mi jáde fún yín kí n sì fi inú mi hàn sí i yín.
24 No tondũ nĩmwaregire kũnjigua rĩrĩa ndetanire, na gũtirĩ mũndũ werũmbũirie hĩndĩ ĩrĩa ndatambũrũkirie guoko gwakwa,
Ṣùgbọ́n níwọ̀n bí ẹ ti kọ ìpè ní ìgbà tí mo pè kò sì sí ẹni tí ó kọ ibi ara sí mi gbà tí mo na ọwọ́ sí wọn,
25 na mũkĩagĩra mataaro makwa mothe bata, na mũkĩaga gwĩtĩkĩra ikaanania rĩakwa-rĩ,
níwọ́n bí ẹ ti kọ gbogbo ìmọ̀ràn mi, tí ẹ̀yin kò sì gba ìbáwí mi,
26 niĩ na niĩ nĩngamũthekerera hĩndĩ yanyu ya mwanangĩko, na ndĩmũnyũrũrie rĩrĩa mũgaakorererwo nĩ mũtino:
Èmi pẹ̀lú yóò fi ìdààmú yín rẹ́rìn-ín; èmi yóò ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín.
27 ĩĩ hĩndĩ ĩrĩa guoya ũkaamũkorerera ta kĩhuhũkanio, rĩrĩa mwanangĩko ũkaamũhaata ta rũhuho rwa kĩhuhũkanio, rĩrĩa mũgaakinyĩrĩrwo nĩ mĩnyamaro na ruo rwa ngoro.
Nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín bí ìjì líle, nígbà tí ìdààmú bá dé bá ọ bí ààjà, nígbà tí wàhálà àti ìbànújẹ́ ọkàn bá bò ọ́ mọ́lẹ̀.
28 “Hĩndĩ ĩyo nĩmakangaĩra, no ndikametĩka; nĩmakanjetha na kĩyo, no matikanyona.
“Nígbà náà ni wọn yóò ké pè mí ṣùgbọ́n, èmi kò ní dáhùn; wọn yóò fi ara balẹ̀ wá mi ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí mi.
29 Tondũ nĩmathũũrire ũmenyo, na matiigana gũthuura gwĩtigĩra Jehova,
Níwọ́n bí wọ́n ti kórìíra ìmọ̀ tí wọ́n sì kọ̀ láti bẹ̀rù Olúwa.
30 tondũ matietĩkĩrire mataaro makwa, na nĩmamenire ikaanania rĩakwa,
Níwọ́n bí wọn kò ti gbà ìmọ̀ràn mi tí wọ́n sì kẹ́gàn ìmọ̀ràn mi,
31 makaarĩa maciaro ma mĩthiĩre yao, na mahũũnio nĩ maciaro ma mathugunda mao.
wọn yóò jẹ èrè iṣẹ́ ọwọ́ wọn wọn yóò sì jèrè èso ètè wọn ní kíkún.
32 Nĩgũkorwo ũgenyũ wa arĩa matarĩ ũũgĩ nĩũkamooraga, nakuo kwĩgangara kwa arĩa akĩĩgu nĩgũkamaniina;
Nítorí ìrìnkurìn àwọn aláìmọ̀kan ni yóò pa wọ́n ìkáwọ́gbera aláìgbọ́n ni yóò pa á run;
33 no ũrĩa wothe ũnjiguaga arĩtũũraga na thayũ, na atũũre ahooreire, atarĩ ũgwati angĩĩtigĩra.”
ṣùgbọ́n ẹnìkan tí ó bá fetí sí mi, yóò gbé láìléwu yóò sì wà nínú ìdẹ̀ra, láìsí ìbẹ̀rù ìpalára.”

< Thimo 1 >