< Thimo 3 >
1 Mũrũ wakwa, ndũkariganĩrwo nĩ ũrutani wakwa, no ngoro yaku nĩĩrũmagie maathani makwa,
Ọmọ mi, má ṣe gbàgbé ẹ̀kọ́ mi. Ṣùgbọ́n pa òfin mi mọ́ sí ọkàn rẹ.
2 nĩgũkorwo nĩmagakuongerera matukũ ũtũũre mĩaka mĩingĩ, na matũme ũgaacĩre.
Nítorí ọjọ́ gígùn, ẹ̀mí gígùn, àti àlàáfíà, ni wọn yóò fi kùn un fún ọ.
3 Ndũkanareke wendani na wĩhokeku ikweherere; cioherere ngingo yaku, ũciandĩke kĩhengere-inĩ kĩa ngoro yaku.
Má ṣe jẹ́ kí ìfẹ́ àti òtítọ́ ṣíṣe fi ọ́ sílẹ̀ láéláé so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ, kọ wọ́n sí wàláà àyà rẹ.
4 Weka ũguo nĩũgeetĩkĩrĩka, na ũgĩe na rĩĩtwa rĩega maitho-inĩ ma Ngai o na ma andũ.
Nígbà náà ni ìwọ yóò rí ojúrere àti orúkọ rere ní ojú Ọlọ́run àti lójú ènìyàn.
5 Wĩhoke Jehova na ngoro yaku yothe, na ndũkanehoke ũmenyo waku mwene;
Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ má ṣe sinmi lé òye ara à rẹ.
6 mũmenyithagie mĩthiĩre yaku yothe, na nĩarĩrũngaga njĩra ciaku.
Mọ̀ ọ́n ní gbogbo ọ̀nà rẹ òun yóò sì máa tọ́ ipa ọ̀nà rẹ.
7 Tiga kwĩonaga ũrĩ mũũgĩ maitho-inĩ maku mwene; wĩtigĩre Jehova na ũtheemage maũndũ marĩa mooru.
Má ṣe jẹ́ ọlọ́gbọ́n lójú ara à rẹ bẹ̀rù Olúwa kí o sì kórìíra ibi.
8 Ũndũ ũcio nĩũrĩkũrehagĩra ũgima wa mwĩrĩ, na mahĩndĩ maku makoragwo marĩ na hinya.
Èyí yóò mú ìlera fún ara rẹ àti okun fún àwọn egungun rẹ.
9 Tĩĩaga Jehova na ũtonga waku, ningĩ ũmũtĩĩage na maciaro mothe ma mbere ma irio ciaku cia mĩgũnda;
Fi ọrọ̀ rẹ bọ̀wọ̀ fún Olúwa, pẹ̀lú àkọ́so oko rẹ,
10 namo makũmbĩ maku nĩmakaiyũrĩrĩra, nayo mĩtũngi yaku ĩiyũrĩrĩre ndibei ya mũhihano.
nígbà náà ni àká rẹ yóò kún àkúnya àgbá rẹ yóò kún àkúnwọ́sílẹ̀ fún wáìnì tuntun.
11 Mũrũ wakwa, tiga kũnyarara ihũũra rĩa Jehova, na ndũgathũũre irũithia rĩake,
Ọmọ mi, má ṣe kẹ́gàn ìbáwí Olúwa má sì ṣe bínú nígbà tí ó bá ń bá ọ wí,
12 nĩgũkorwo Jehova arũithagia arĩa endete, o ta ũrĩa ithe wa mũndũ arũithagia mũriũ ũrĩa akenagĩra.
nítorí Olúwa a máa bá àwọn tí ó fẹ́ràn wí bí baba ti í bá ọmọ tí ó bá nínú dídùn sí wí.
13 Kũrathimwo-rĩ, nĩ mũndũ ũrĩa wonete ũũgĩ, mũndũ ũcio wĩgĩĩrĩire na ũmenyo,
Ìbùkún ni fún ẹni tí ó ní ìmọ̀, ẹni tí ó tún ní òye sí i,
14 nĩgũkorwo ũũgĩ nĩ wa bata mũno gũkĩra betha, na ũciaraga uumithio ũkĩrĩte wa thahabu.
nítorí ó ṣe èrè ju fàdákà lọ ó sì ní èrè lórí ju wúrà lọ.
15 Ũũgĩ ũrĩ goro gũkĩra ruru iria ndune; kĩrĩa gĩothe ũngĩĩrirĩria gũtirĩ kĩngĩringithanio naguo.
Ó ṣe iyebíye ju iyùn lọ; kò sí ohunkóhun tí a lè fiwé e nínú ohun gbogbo tí ìwọ fẹ́.
16 Guoko-inĩ gwake kwa ũrĩo harĩ ũingĩ wa matukũ; guoko-inĩ gwake kwa ũmotho harĩ na ũtonga na gĩtĩĩo.
Ẹ̀mí gígùn ń bẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀; ní ọwọ́ òsì rẹ sì ni ọrọ̀ àti ọlá.
17 Mĩthiĩre ya ũũgĩ nĩ mĩthiĩre ya kwendeka, na njĩra ciaguo ciothe nĩ cia thayũ.
Àwọn ọ̀nà rẹ jẹ́ ọ̀nà ìtura, òpópónà rẹ sì jẹ́ ti àlàáfíà.
18 Ũũgĩ nĩ mũtĩ wa muoyo kũrĩ arĩa maũhĩmbagĩria; arĩa megĩagĩra naguo-rĩ, nĩmarĩrathimagwo.
Igi ìyè ni ó jẹ́ fún gbogbo ẹni tí ó bá gbà á; àwọn tí ó bá sì dìímú yóò rí ìbùkún gbà.
19 Jehova aahandire mĩthingi ya thĩ na ũũgĩ, na akĩrũmia igũrũ na ũmenyo wake;
Nípa ọgbọ́n, Olúwa fi ìpìlẹ̀ ilẹ̀ ayé sọlẹ̀; nípa òye, ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn;
20 ũmenyo wake nĩguo wagayanirie kũrĩa kũriku, namo matu magatatagia ime.
nípa ìmọ̀ rẹ̀ ó pín ibú omi ní yà, àwọsánmọ̀ sì ń sẹ ìrì.
21 Mũrũ wakwa tũũria matua mega na ũkũũrani maũndũ, ndũkanareke ciehere maitho-inĩ maku;
Ọmọ mi, pa ọgbọ́n tí ó yè kooro àti ìmòye mọ́, má jẹ́ kí wọn lọ kúrò ní ibi tí ojú rẹ ti le tó wọn.
22 nĩcio igaagũtũũria muoyo, na nĩ ithaga rĩa kũgemagia ngingo yaku.
Wọn yóò jẹ́ ìyè fún ọ, àti ẹ̀ṣọ́ fún ọrùn rẹ.
23 Ningĩ ũrĩthiiaga na njĩra yaku ũrĩ na thayũ, na kũgũrũ gwaku gũtikahĩngwo;
Nígbà náà ni ìwọ yóò bá ọ̀nà rẹ lọ ní àìléwu, ìwọ kì yóò sì kọsẹ̀.
24 Wakoma-rĩ, ndũgetigĩra; wakoma-rĩ, ũrĩkomaga toro mwega.
Nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, ìwọ kì yóò bẹ̀rù, nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀, oorun rẹ yóò jẹ́ oorun ayọ̀.
25 Ndũgetigĩre mwanangĩko wa narua, kana kĩhuhũkanio kĩrĩa gĩkoragĩrĩra andũ arĩa aaganu,
Má ṣe bẹ̀rù ìdààmú òjijì, tàbí ti ìparun tí ó ń dé bá àwọn ènìyàn búburú.
26 nĩgũkorwo Jehova nĩwe ũgaatuĩka mwĩhoko waku, na amenyagĩrĩre kũgũrũ gwaku gũtikanyiitwo nĩ mũtego.
Nítorí Olúwa yóò jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ, kì yóò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ bọ́ sínú pàkúté.
27 Ndũkanagirĩrĩrie ũndũ mwega ũkinyĩre arĩa maagĩrĩirwo nĩgũkinyĩrĩrwo nĩguo, rĩrĩa ũrĩ na ũhoti wa kũhingia ũndũ ũcio.
Má ṣe fa ọwọ́ ìre sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ṣe tìrẹ, nígbà tí ó bá wà ní ìkápá rẹ láti ṣe ohun kan.
28 Ndũkaneere mũndũ wa itũũra rĩaku atĩrĩ, “Thiĩ ũgooka rĩngĩ; kĩu ũrenda nĩngakũhe rũciũ,” o rĩrĩa ũrĩ na kĩndũ kĩu hakuhĩ.
Má ṣe wí fún aládùúgbò rẹ pé, “Padà wá nígbà tó ṣe díẹ̀; èmi yóò fi fún ọ ní ọ̀la,” nígbà tí o ní i pẹ̀lú rẹ nísinsin yìí.
29 Ndũkanaciirĩre gwĩka mũndũ wa itũũra rĩaku ũũru, ũcio ũtũũraga hakuhĩ nawe akwĩhokete.
Má ṣe pète ohun búburú fún aládùúgbò rẹ, ti o gbé nítòsí rẹ, tí ó sì fọkàn tán ọ.
30 Ndũkanarũithie mũndũ tũhũ, rĩrĩa atarĩ ũndũ mũũru agwĩkĩte.
Má ṣe fẹ̀sùn kan ènìyàn láìnídìí, nígbà tí kò ṣe ọ́ ní ibi kankan rárá.
31 Ndũkanacumĩkĩre maũndũ ma mũndũ wa ngũĩ, kana ũthuure njĩra o na ĩmwe yake,
Má ṣe ṣe ìlara ènìyàn jàgídíjàgan tàbí kí o yàn láti rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
32 nĩgũkorwo Jehova nĩathũire mũndũ mwaganu, no nĩagĩĩaga ndundu na andũ arĩa arũngĩrĩru.
Nítorí Olúwa kórìíra ènìyàn aláyídáyidà ṣùgbọ́n a máa fọkàn tán ẹni dídúró ṣinṣin.
33 Nyũmba ya arĩa aaganu ĩtũũraga na kĩrumi kĩa Jehova, no mũciĩ wa arĩa athingu nĩaũrathimaga.
Ègún Olúwa ń bẹ lórí ilé ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n ó bùkún fún ilé olódodo.
34 Jehova nĩanyũrũragia andũ arĩa manyũrũranagia na mwĩtĩĩo, no arĩa menyiihagia nĩamaheaga wega wake.
Ó fi àwọn ẹlẹ́yà ṣe yẹ̀yẹ́, ṣùgbọ́n ó fi oore-ọ̀fẹ́ fún onírẹ̀lẹ̀.
35 Andũ arĩa oogĩ magayaga gĩtĩĩo, no andũ arĩa akĩĩgu magayaga njono.
Ọlọ́gbọ́n jogún iyì, ṣùgbọ́n àwọn aṣiwèrè ni yóò ru ìtìjú wọn.