< Ndari 3 >
1 Ũyũ nĩguo ũhoro wa njiaro cia Harũni na Musa hĩndĩ ĩrĩa Jehova aaririe na Musa Kĩrĩma-inĩ gĩa Sinai.
Ìwọ̀nyí ni ìdílé Aaroni àti Mose ní ìgbà tí Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ní òkè Sinai.
2 Marĩĩtwa ma ariũ a Harũni maarĩ Nadabu ũrĩa warĩ irigithathi, na Abihu, na Eleazaru, na Ithamaru.
Orúkọ àwọn ọmọ Aaroni nìwọ̀nyí, Nadabu ni àkọ́bí, Abihu, Eleasari àti Itamari.
3 Macio nĩmo marĩĩtwa ma ariũ a Harũni, nao maarĩ athĩnjĩri-Ngai aitĩrĩrie maguta, arĩa maamũrĩtwo matungatage marĩ athĩnjĩri-Ngai.
Orúkọ àwọn ọmọ Aaroni ni ìwọ̀nyí, àwọn àlùfáà tí a fi òróró yàn, àwọn tí a fi joyè àlùfáà láti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí àlùfáà.
4 Na rĩrĩ, Nadabu na Abihu nĩmakuire marĩ mbere ya Jehova rĩrĩa maarutaga igongona na mwaki ũtarĩ mwĩtĩkĩrie mbere yake Werũ-inĩ wa Sinai. Matiarĩ na ciana cia aanake; nĩ ũndũ ũcio, Eleazaru na Ithamaru nĩo maatungataga marĩ athĩnjĩri-Ngai hĩndĩ ĩrĩa yothe ithe wao Harũni aarĩ muoyo.
Ṣùgbọ́n Nadabu àti Abihu ti kú níwájú Olúwa nígbà tí wọ́n rú iná àjèjì níwájú Olúwa nínú ijù Sinai, àwọn méjèèjì kò sì ní ọmọ. Báyìí Eleasari àti Itamari ló ṣiṣẹ́ àlùfáà nígbà ayé Aaroni baba wọn.
5 Nake Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ,
Olúwa sọ fún Mose pé,
6 “Rehe andũ a mũhĩrĩga wa Lawi ũmaneane kũrĩ Harũni mũthĩnjĩri-Ngai, nĩguo mamũteithagie.
“Kó ẹ̀yà Lefi wá, kí o sì fà wọ́n fún Aaroni àlùfáà láti máa ràn án lọ́wọ́.
7 Marĩĩrutaga wĩra wa kũmũtungatĩra, na matungatagĩre kĩrĩndĩ kĩu gĩothe hau Hema-inĩ-ya-Gũtũnganwo na ũndũ wa kũruta wĩra wa hema ĩyo.
Wọn yóò máa ṣiṣẹ́ fún un àti fún gbogbo ìjọ ènìyàn ní àgọ́ ìpàdé bí wọ́n ti ń ṣiṣẹ́ ìsìn nínú àgọ́.
8 Nao marĩmenyagĩrĩra indo ciothe cia Hema-ya-Gũtũnganwo, mahingagie maũndũ marĩa magĩrĩire nĩ gwĩkwo nĩ andũ a Isiraeli na ũndũ wa kũruta wĩra wa hema ĩyo.
Wọn yóò máa tọ́jú gbogbo ohun èlò inú àgọ́ ìpàdé, wọn yóò sì máa ṣe ojúṣe àwọn ọmọ Israẹli nípa ṣíṣe iṣẹ́ nínú àgọ́.
9 Neana Alawii acio kũrĩ Harũni na ariũ ake; nĩo andũ a Isiraeli arĩa mekũneanwo kũrĩ we biũ.
Fi ẹ̀yà Lefi jì Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, àwọn nìkan ni a fi fún Aaroni nínú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli.
10 Amũra Harũni na ariũ ake matungatage marĩ athĩnjĩri-Ngai; mũndũ ũngĩ o wothe ũrĩa ũrĩkuhagĩrĩria harĩa haamũre no nginya ooragwo.”
Kí o sì yan Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ láti máa ṣiṣẹ́ àlùfáà; àlejò tó bá súnmọ́ ibi mímọ́ pípa ni kí ẹ pa á.”
11 Ningĩ Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ,
Olúwa tún sọ fún Mose pé,
12 “Niĩ nĩ niĩ thuurĩte Alawii kuuma kũrĩ andũ a Isiraeli ithenya rĩa marigithathi ma arũme arĩa marigithathĩtwo nĩ andũ-a-nja othe a Isiraeli. Alawii nĩ akwa,
“Báyìí èmi fúnra mi ti mú ẹ̀yà Lefi láàrín àwọn ọmọ Israẹli dípò gbogbo àkọ́bí ọkùnrin àwọn ọmọbìnrin Israẹli. Ti èmi ni àwọn ọmọ Lefi,
13 nĩgũkorwo marigithathi mothe nĩ makwa. Hĩndĩ ĩrĩa ndooragire marigithathi mothe ma Misiri, noguo ndeyamũrĩire marigithathi mothe ma Isiraeli, marĩ ma mũndũ kana ma nyamũ. Macio nĩ makwa kĩũmbe. Niĩ nĩ niĩ Jehova.”
nítorí pé ti èmi ni gbogbo àkọ́bí. Ní ọjọ́ tí mo pa gbogbo àkọ́bí ní ilẹ̀ Ejibiti ni mo ti ya gbogbo àkọ́bí sọ́tọ̀ ní Israẹli yálà ti ènìyàn tàbí ti ẹranko. Gbogbo wọn gbọdọ̀ jẹ́ ti èmi. Èmi ni Olúwa.”
14 Ningĩ Jehova akĩĩra Musa kũu Werũ-inĩ wa Sinai atĩrĩ,
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose ní aginjù Sinai pé,
15 “Tara Alawii kũringana na nyũmba ciao na mbarĩ ciao. Tara arũme othe arĩa makinyĩtie mweri ũmwe na makĩria.”
“Ka àwọn ọmọ Lefi nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn kí o ka gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ oṣù kan sókè.”
16 Nĩ ũndũ ũcio, Musa akĩmatara o ta ũrĩa aathĩtwo nĩ kiugo kĩa Jehova.
Mose sì kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa ti pa á láṣẹ fún un.
17 Maya nĩmo marĩĩtwa ma ariũ a Lawi: Nĩ Gerishoni, na Kohathu, na Merari.
Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
18 Maya nĩmo marĩĩtwa ma mbarĩ cia Agerishoni: Nĩ Libini na Shimei.
Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Gerṣoni: Libni àti Ṣimei.
19 Mbarĩ cia Akohathu ciarĩ: Amuramu, na Iziharu na Hebironi, na Uzieli.
Àwọn ìdílé Kohati ni: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli.
20 Mbarĩ cia Amerari: ciarĩ Mahali na Mushi. Ici nĩcio ciarĩ mbarĩ cia Alawii, kũringana na nyũmba ciao.
Àwọn ìdílé Merari ni: Mahili àti Muṣi. Wọ̀nyí ni ìdílé Lefi gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn.
21 Gerishoni aarĩ na mbarĩ cia Alabini na Ashimei; ici nĩcio ciarĩ mbarĩ cia Agerishoni.
Ti Gerṣoni ni ìdílé Libni àti Ṣimei; àwọn ni ìdílé Gerṣoni.
22 Arũme arĩa othe maakinyĩtie mweri ũmwe na makĩria arĩa maatarirwo maarĩ andũ 7,500.
Iye àwọn ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọ́n jẹ́ oṣù kan ó lé, jẹ́ ẹgbàata ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ.
23 Mbarĩ icio cia Agerishoni ciarĩ ciambe hema ciao mwena wa ithũĩro, thuutha wa Hema-ĩrĩa-Nyamũre.
Àwọn ìdílé Gerṣoni yóò pa ibùdó sí ìhà ìwọ̀-oòrùn lẹ́yìn àgọ́.
24 Mũtongoria wa nyũmba cia Agerishoni aarĩ Eliasafu mũrũ wa Laeli.
Olórí àwọn ìdílé Gerṣoni ni Eliasafu ọmọ Láélì.
25 Hau Hema-inĩ-ya-Gũtũnganwo-rĩ, Agerishoni nĩo maarĩ na wĩra wa kũmenyerera Hema-ĩyo-Nyamũre na hema, na ciandarũa cia kũmĩhumbĩra, na gĩtambaya gĩa gũcuurio itoonyero rĩa Hema-ya-Gũtũnganwo,
Iṣẹ́ àwọn ìdílé Gerṣoni nínú àgọ́ ìpàdé ni pé àwọn yóò máa tọ́jú àgọ́, ìbòrí àgọ́, aṣọ títa ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé,
26 na itambaya cia gũcuurio cia kũirigĩra nja, na gĩtambaya gĩa gũcuurio gĩa itoonyero rĩa nja ĩrĩa ĩthiũrũkĩirie Hema ĩyo nyamũre na kĩgongona na mĩhĩndo, na indo ciothe iria ikonainie na wĩra wacio.
aṣọ títa ti àgbàlá, aṣọ títa ti ẹnu-ọ̀nà àgbàlá tó yí àgọ́ àti pẹpẹ ká, àwọn okùn rẹ̀ àti gbogbo ohun tó jẹ mọ́ lílò wọn.
27 Kohathu aarĩ na mbarĩ cia Aamuramu, na Aiziharu, na Ahebironi, na Auzieli; icio nĩcio ciarĩ mbarĩ cia Akohathu.
Ti Kohati ní ìdílé Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli, wọ̀nyí ni ìran Kohati.
28 Arũme arĩa othe maakinyĩtie mweri ũmwe na makĩria maarĩ andũ 8,600. Wĩra wa Akohathu warĩ wa kũmenyerera harĩa haamũre.
Iye gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ọmọ oṣù kan ó lé jẹ́ ẹgbàá mẹ́rin ó lé ẹgbẹ̀ta, tí yóò máa ṣiṣẹ́ ní ibi mímọ́.
29 Mbarĩ cia Akohathu ciarĩ ciambage hema mwena wa gũthini wa Hema-ĩrĩa-Nyamũre.
Àwọn ìdílé Kohati yóò pa ibùdó wọn sí ìhà gúúsù ní ẹ̀gbẹ́ àgọ́.
30 Mũtongoria wa nyũmba cia mbarĩ cia Akohathu aarĩ Elizafani mũrũ wa Uzieli.
Olórí àwọn ìdílé Kohati ni Elisafani ọmọ Usieli.
31 Wĩra wao warĩ wa kũmenyerera ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro, na metha, na mũtĩ ũrĩa wa kũigĩrĩrwo matawa, na igongona, na indo cia gũtũmĩrwo harĩa haamũre, na gĩtambaya gĩa gũcuurio gĩa kũhakania, o na indo ciothe ciakonainie na mũhũthĩrĩre wacio.
Àwọn ni yóò máa tọ́jú àpótí ẹ̀rí, tábìlì, ọ̀pá fìtílà, àwọn pẹpẹ, gbogbo ohun èlò ibi mímọ́ tí à ń lò fún iṣẹ́ ìsìn, aṣọ títa àti gbogbo ohun tó jẹ mọ́ lílò wọn.
32 Mũtongoria mũnene wa Alawii aarĩ Eleazaru mũrũ wa Harũni, ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai. Nĩwe watuirwo mũrũgamĩrĩri wa arĩa maamenyagĩrĩra harĩa haamũre.
Eleasari ọmọ Aaroni àlùfáà ni alákòóso gbogbo àwọn olórí ìdílé Lefi. Òun ni wọ́n yàn lórí gbogbo àwọn tí yóò máa tọ́jú ibi mímọ́.
33 Merari aarĩ na mbarĩ cia Amahali na Amushi; icio nĩcio ciarĩ mbarĩ cia Merari.
Ti Merari ni ìran Mahili àti Muṣi, àwọn ni ìran Merari.
34 Arũme arĩa othe maatarirwo arĩa maakinyĩtie mweri ũmwe na makĩria maarĩ andũ 6,200.
Iye gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọ́n jẹ́ oṣù kan ó lé, èyí tí wọ́n kà jẹ́ igba mọ́kànlélọ́gbọ̀n.
35 Mũtongoria wa nyũmba cia mbarĩ ya Merari aarĩ Zurieli mũrũ wa Abihaili; nao maarĩ maambage hema mwena wa gathigathini wa Hema-ĩrĩa-Nyamũre.
Olórí àwọn ìdílé ìran Merari ni Ṣurieli ọmọ Abihaili. Wọn yóò pa ibùdó wọn sí ìhà àríwá àgọ́.
36 Amerari maamũrirwo mamenyagĩrĩre buremu ya hema ĩrĩa yaamũrĩtwo, na mĩgĩĩko yayo, na itugĩ, na itina ciacio, o na indo ciothe ciayo cia wĩra, na indo ciothe ciakonainie na mũhũthĩrĩre wacio,
Àwọn ìran Merari ni a yàn fún títọ́jú àwọn férémù àgọ́, ọ̀pá ìdábùú rẹ̀, òpó rẹ̀, ihò òpó rẹ̀ àti gbogbo ohun èlò tó jẹ mọ́ lílò wọn.
37 o na mamenyagĩrĩre itugĩ iria ciirigĩte nja yayo hamwe na itina ciacio, na higĩ cia hema na mĩhĩĩndo yayo.
Iṣẹ́ wọn tún ni títọ́jú àwọn òpó tó yí àgbàlá ká, ihò òpó rẹ̀, èèkàn àti okùn wọn.
38 Musa na Harũni na ariũ ake maarĩ mambage hema ciao mwena wa irathĩro wa Hema-ĩyo-Nyamũre, mangʼetheire irathĩro, o hau mbere ya Hema-ya-Gũtũnganwo. Wĩra wao warĩ wa kũmenyerera harĩa haamũre ithenya rĩa andũ a Isiraeli. Mũndũ ũngĩ o wothe ũngĩakuhĩrĩirie hau haamũre aarĩ ooragwo.
Mose àti Aaroni pẹ̀lú àwọn ọmọ yóò pa àgọ́ ní ìdojúkọ ìwọ̀-oòrùn níwájú àgọ́ ìpàdé. Iṣẹ́ wọn ni láti máa mójútó iṣẹ́ ìsìn ibi mímọ́ àti láti máa ṣiṣẹ́ ìsìn fún àwọn ọmọ Israẹli. Àlejò tó bá súnmọ́ ibi mímọ́ yàtọ̀ sí àwọn tí a yàn, pípa ni kí ẹ pa á.
39 Alawii arĩa othe maatarirwo ta ũrĩa Jehova aathĩte Musa na Harũni kũringana na mbarĩ ciao, hamwe na arũme othe arĩa maakinyĩtie mweri ũmwe na makĩria, maarĩ andũ 22,000.
Àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Lefi tí a kà gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose àti Aaroni gẹ́gẹ́ bí ìran wọn, pẹ̀lú gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ọmọ oṣù kan ó lé jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjìlélógún.
40 Nake Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ, “Tara marigithathi ma arũme othe ma andũ a Isiraeli arĩa makinyĩtie mweri ũmwe na makĩria, na wandĩke marĩĩtwa mao.
Olúwa sọ fún Mose pé, “Ka gbogbo àkọ́bí ọmọkùnrin Israẹli láti ọmọ oṣù kan ó lé kí o sì ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ wọn.
41 Nyamũrĩra Alawii handũ ha marigithathi mothe ma andũ a Isiraeli; o naguo ũhiũ wa Alawii ũwaamũre handũ ha marigithathi mothe ma mahiũ ma andũ a Isiraeli. Niĩ nĩ niĩ Jehova.”
Kí o sì gba àwọn ọmọ Lefi dípò gbogbo àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì gba gbogbo ẹran ọ̀sìn àwọn ọmọ Lefi fún mi dípò gbogbo àkọ́bí àwọn ẹran ọ̀sìn àwọn ọmọ Israẹli. Èmi ni Olúwa.”
42 Nĩ ũndũ ũcio Musa agĩtara marigithathi mothe ma andũ a Isiraeli, o ta ũrĩa Jehova aamwathĩte.
Mose sì ka gbogbo àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún un.
43 Marigithathi mothe ma arũme arĩa maakinyĩtie mweri ũmwe na makĩria, maandĩkwo na marĩĩtwa mao, maarĩ andũ 22,273.
Àpapọ̀ iye àwọn àkọ́bí ọkùnrin láti ọmọ oṣù kan ó lé, ní àkọsílẹ̀ orúkọ wọn jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ó lé ọ̀rìnlúgba ó dín méje.
44 Ningĩ Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ,
Olúwa tún sọ fún Mose pé,
45 “Amũra Alawii handũ ha marigithathi mothe ma andũ a Isiraeli, naguo ũhiũ wa Alawii ũwaamũre handũ ha mahiũ mao. Alawii megũtuĩka akwa. Niĩ nĩ niĩ Jehova.
“Gba àwọn ọmọ Lefi dípò gbogbo àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli àti ohun ọ̀sìn àwọn ọmọ Lefi dípò ohun ọ̀sìn àwọn ọmọ Israẹli. Tèmi ni àwọn ọmọ Lefi. Èmi ni Olúwa.
46 Gũkũũra marigithathi macio 273 ma andũ a Isiraeli, acio makĩrĩte mũigana wa Alawii-rĩ,
Nísinsin yìí, láti lè ra ọ̀rìnlúgba dín méje àkọ́bí àwọn Israẹli tó ju iye àwọn ọmọ Lefi lọ,
47 oya cekeri ithano irũgamĩrĩre o mũndũ, kũringana na cekeri ya handũ-harĩa-haamũre, ĩrĩa ũritũ wayo ũrĩ gera mĩrongo ĩĩrĩ.
ìwọ yóò gba ṣékélì márùn-ún lórí ẹni kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́, èyí tí í ṣe ogún gera.
48 Mbeeca icio cia gũkũũra andũ a Isiraeli acio makĩrĩte-rĩ, cinengere Harũni na ariũ ake.”
Owó tí a fi ra àwọn àkọ́bí ọmọ Israẹli tó lé yìí, ni kí o kó fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀.”
49 Nĩ ũndũ ũcio Musa akĩũngania mbeeca cia gũkũũra andũ acio maakĩrĩte mũigana wa andũ arĩa maakũũrĩtwo nĩ Alawii.
Nígbà náà ni Mose gba owó ìràpadà àwọn ènìyàn tó ṣẹ́kù lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Lefi ti ra àwọn yòókù padà.
50 Kuuma kũrĩ marigithathi ma andũ a Isiraeli, akĩũngania betha ya ũritũ wa cekeri 1,365 kũringana na cekeri ya handũ-harĩa-haamũre.
Mose sì gba egbèje ṣékélì ó dín márùndínlógójì gẹ́gẹ́ bí iye ṣékélì ibi mímọ́ lọ́wọ́ àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli.
51 Musa akĩnengera Harũni na ariũ ake mbeeca icio ciakũũrĩte andũ, o ta ũrĩa aathĩtwo nĩ kiugo kĩa Jehova.
Mose sì kó owó ìràpadà yìí fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un.