< Ndari 10 >
1 Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 “Thondeka tũrumbeta twĩrĩ, ũtũthondeke na betha ndure, tũhũthagĩrwo gwĩtaga kĩrĩndĩ hamwe, o na twa gwĩta andũ moime kambĩ moimagare mathiĩ.
“Ṣe fèrè fàdákà méjì pẹ̀lú fàdákà lílù, kí o máa lò ó láti máa fi pe ìjọ ènìyàn àti láti máa fi darí ìrìnàjò lọ sí ibùdó yín.
3 Hĩndĩ ĩrĩa tũrumbeta tweerĩ twahuhwo hamwe, kĩrĩndĩ gĩothe gĩkongana harĩwe hau itoonyero-inĩ rĩa Hema-ya-Gũtũnganwo.
Nígbà tí o bá fọn méjèèjì gbogbo ìjọ ènìyàn yóò pé síwájú rẹ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
4 Angĩkorwo no karumbeta kamwe kahuhwo-rĩ, atongoria, nĩo anene a mbarĩ cia Isiraeli, nĩo marĩũnganaga harĩwe.
Bí ó bá jẹ́ ọ̀kan ni o fọn, nígbà náà ni àwọn olórí ẹ̀yà Israẹli yóò péjọ síwájú rẹ.
5 Rĩrĩa karumbeta kahuhwo na mũgambo mũnene, mĩhĩrĩga ĩrĩa ĩikarĩte mwena wa irathĩro ĩkoimagara.
Nígbà tí o bá fun ìpè ìdágìrì, àwọn ẹ̀yà tó pa ibùdó sí ìhà ìlà-oòrùn ni yóò gbéra.
6 Karumbeta ga keerĩ kahuhwo na mũgambo mũnene, andũ a kambĩ cia mwena wa gũthini makoimagara. Mũgambo ũcio mũnene nĩguo kĩmenyithia gĩa kuumagara.
Nígbà tí o bá fun ìpè ìdágìrì kejì, ibùdó tó wà ní ìhà gúúsù ni yóò gbéra. Ìpè ìdágìrì yìí ni yóò jẹ́ àmì fún gbígbéra.
7 Nĩgeetha kĩrĩndĩ kĩũngane-rĩ, huhagai tũrumbeta, no ti na mĩhuhĩre ta ĩyo ĩngĩ.
Nígbà tí o bá fẹ́ pe ìjọ ènìyàn jọ, fun fèrè nìkan, má ṣe fun ti ìdágìrì pẹ̀lú rẹ̀.
8 “Ariũ a Harũni, acio athĩnjĩri-Ngai, nĩo marĩhuhaga tũrumbeta tũu. Ũndũ ũcio ũtuĩke watho wa gũtũũrio nĩ inyuĩ na njiarwa iria igooka.
“Àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ni kí ó máa fun fèrè. Èyí yóò jẹ́ ìlànà láéláé fún yín àti fún ìran tó ń bọ̀.
9 Rĩrĩa mũgũthiĩ mbaara ĩrĩ bũrũri wanyu kĩũmbe mũkarũe na thũ iria imũhinyagĩrĩria-rĩ, huhagai tũrumbeta na mũgambo mũnene. Hĩndĩ ĩyo Jehova Ngai wanyu nĩakamũririkana na amũhonokie kuuma kũrĩ thũ cianyu.
Nígbà tí ẹ bá lọ jagun pẹ̀lú àwọn ọ̀tá tó ń ni yín lára ní ilẹ̀ yín, ẹ fun ìpè ìdágìrì pẹ̀lú fèrè. A ó sì rántí yín níwájú Olúwa, Ọlọ́run yín yóò sì gbà yín lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá yín.
10 Ningĩ mahinda manyu ma gũkena, nĩmo ma ciathĩ cianyu iria njathane, na ciathĩ cia Karũgamo ka Mweri, nĩ mũrĩhuhaga tũrumbeta nĩ ũndũ wa maruta ma njino na maruta ma ũiguano, na nĩmo magaatuĩka kĩririkano kĩanyu mbere ya Ngai wanyu. Niĩ nĩ niĩ Jehova Ngai Wanyu.”
Bẹ́ẹ̀ náà ni ní ọjọ́ ayọ̀ yín, ní gbogbo àjọ̀dún tí a yàn àti ní ìbẹ̀rẹ̀ oṣù yín, ni kí ẹ máa fun fèrè lórí ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà yín, wọn yóò sì jẹ́ ìrántí fún yín níwájú Ọlọ́run. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
11 Mũthenya wa mĩrongo ĩĩrĩ wa mweri wa keerĩ mwaka-inĩ wa ĩĩrĩ, itu nĩrĩeherire kuuma hema-inĩ ĩrĩa nyamũre ya Ũira.
Ní ogúnjọ́ oṣù kejì, ní ọdún kejì ni ìkùùkuu kúrò lórí tabanaku ẹ̀rí.
12 Nao andũ a Isiraeli makiumagara kuuma Werũ wa Sinai magĩthiĩ kuuma handũ hamwe nginya harĩa hangĩ, o nginya rĩrĩa itu rĩu rĩarũgamire Werũ-inĩ wa Parani.
Àwọn ọmọ Israẹli sì gbéra kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì rin ìrìnàjò wọn káàkiri títí tí ìkùùkuu fi dúró sí aginjù Parani.
13 Nao makiumagara, arĩ riita rĩa mbere, o ta ũrĩa Jehova aathĩte Musa.
Wọ́n gbéra nígbà àkọ́kọ́ yìí nípa àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose.
14 Ikundi cia kambĩ ya Juda nĩcio cioimagarire mbere, irũmĩrĩire bendera yao. Nake Nahashoni mũrũ wa Aminadabu nĩwe warĩ mũtongoria wao.
Àwọn ìpín ti ibùdó Juda ló kọ́kọ́ gbéra tẹ̀lé wọn lábẹ́ ogun wọn Nahiṣoni ọmọ Amminadabu ni ọ̀gágun wọn.
15 Nethaneli mũrũ wa Zuaru nĩwe warĩ mũtongoria wa gĩkundi kĩa mũhĩrĩga wa Isakaru,
Netaneli ọmọ Suari ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Isakari;
16 nake Eliabu mũrũ wa Heloni nĩwe warĩ mũtongoria wa gĩkundi kĩa mũhĩrĩga wa Zebuluni.
Eliabu ọmọ Heloni ni ọ̀gágun ni ìpín ti ẹ̀yà Sebuluni.
17 Ningĩ Hema-ĩrĩa-Nyamũre ĩkĩambũrwo, nao Agerishoni na Amerari, arĩa maamĩkuuaga, makiumagara.
Nígbà náà ni wọ́n sọ tabanaku kalẹ̀ àwọn ọmọ Gerṣoni àti Merari tó gbé àgọ́ sì gbéra.
18 Nacio ikundi cia kambĩ ya Rubeni ikĩrũmĩrĩra ikundi cia Juda, irũmĩrĩire bendera yao. Elizuru mũrũ wa Shedeuru nĩwe warĩ mũtongoria wao.
Àwọn ìpín ti ibùdó ti Reubeni ló gbéra tẹ̀lé wọn, lábẹ́ ọ̀págun wọn. Elisuri ọmọ Ṣedeuri ni ọ̀gágun wọn.
19 Shelumieli mũrũ wa Zurishadai nĩwe warĩ mũtongoria wa gĩkundi kĩa mũhĩrĩga wa Simeoni,
Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Simeoni.
20 nake Eliasafu mũrũ wa Deueli nĩwe warĩ mũtongoria wa gĩkundi kĩa mũhĩrĩga wa Gadi.
Eliasafu ọmọ Deueli ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Gadi.
21 Nao Akohathu makiumagara makuuĩte indo iria nyamũre. Hema-ĩrĩa-Nyamũre yarĩ ĩkorwo yaambĩtwo matanakinya.
Nígbà náà ni àwọn ọmọ Kohati tí ń ru ohun mímọ́ náà gbéra. Àwọn ti àkọ́kọ́ yóò sì ti gbé tabanaku dúró kí wọn tó dé.
22 Nacio ikundi cia kambĩ ya Efiraimu ikĩrũmĩrĩra ikundi cia Rubeni, irũmĩrĩire bendera yao. Elishama mũrũ wa Amihudu nĩwe warĩ mũtongoria wao.
Àwọn ìpín tó wà ní ibùdó Efraimu ló tún kàn lábẹ́ ọ̀págun wọn. Eliṣama ọmọ Ammihudu ni ọ̀gágun wọn.
23 Gamalieli mũrũ wa Pedazuru nĩwe warĩ mũtongoria wa gĩkundi kĩa mũhĩrĩga wa Manase,
Gamalieli ọmọ Pedasuri ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Manase.
24 nake Abidani mũrũ wa Gideoni nĩwe warĩ mũtongoria wa gĩkundi kĩa mũhĩrĩga wa Benjamini.
Abidani ọmọ Gideoni ni ọ̀gágun ìpín ti ẹ̀yà Benjamini.
25 Kũrigĩrĩria-rĩ, ikundi cia kambĩ ya Dani ikiumagara irĩ thuutha wa icio ingĩ ciothe, ikiumagara ĩrũmĩrĩire bendera yao. Ahiezeri mũrũ wa Amishadai nĩwe warĩ mũtongoria wao.
Lákòótan, àwọn ọmọ-ogun tó ń mójútó ẹ̀yìn ló tún kàn, àwọn ni ìpín ti ibùdó Dani lábẹ́ ọ̀págun wọn. Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai ni ọ̀gágun wọn.
26 Pagieli mũrũ wa Okirani nĩwe watongoragia gĩkundi kĩa mũhĩrĩga wa Asheri,
Pagieli ọmọ Okanri ni ìpín ti ẹ̀yà Aṣeri,
27 nake Ahira mũrũ wa Enani nĩwe watongoragia gĩkundi kĩa mũhĩrĩga wa Nafitali.
Ahira ọmọ Enani ni ọ̀gágun ti ẹ̀yà Naftali.
28 Ũguo nĩguo ikundi cia andũ a Isiraeli ciarũmanĩrĩire ikiumagara.
Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli ṣe tò jáde gẹ́gẹ́ bí ogun nígbà tí wọ́n bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn.
29 Na rĩrĩ, Musa akĩĩra Hobabu mũrũ wa Reueli ũrĩa Mũmidiani ũrĩa warĩ mũthoni-we atĩrĩ, “Nĩtũroimagara tũthiĩ kũrĩa Jehova aatwĩrire ũhoro wakuo atĩrĩ, ‘Nĩngamũhe kũndũ kũu.’ Ũka tũthiĩ nawe, na nĩtũgũgwĩka maũndũ mega, nĩ ũndũ Jehova nĩerĩire Isiraeli maũndũ mega.”
Mose sì sọ fún Hobabu ọmọ Reueli ará Midiani tí í ṣe àna rẹ̀ pé, “A ń gbéra láti lọ sí ibi tí Olúwa sọ pé, ‘Èmi ó fi fún un yín.’ Bá wa lọ, àwa ó ṣe ọ́ dáradára nítorí pé Olúwa ti ṣèlérí ohun rere fún Israẹli.”
30 Hobabu akĩmũcookeria atĩrĩ, “Aca, ndigũũka; no ngũcooka bũrũri witũ na kũrĩ andũ aitũ.”
Ó sì dáhùn pé, “Rárá, èmi kò ní bá yín lọ, mò ń padà lọ sí ilẹ̀ mi àti sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn mi.”
31 No Musa akĩmwĩra atĩrĩ, “Ndagũthaitha ndũgatũtige. Wee nĩũũĩ kũndũ kũrĩa tũngĩamba hema ciitũ gũkũ werũ-inĩ, na no ũtuĩke maitho maitũ.
Mose sì sọ pé, “Jọ̀wọ́ ma fi wá sílẹ̀, ìwọ mọ ibi tí a lè pa ibùdó sí nínú aginjù, ìwọ yóò sì jẹ́ ojú fún wa.
32 Ũngĩtwarana na ithuĩ-rĩ, nĩtũrĩkũgayagĩra kĩrĩa gĩothe kĩega Jehova arĩtũheaga.”
Bí o bá bá wa lọ, a ó sì pín fún ọ nínú ohun rere yówù tí Olúwa bá fún wa.”
33 Nĩ ũndũ ũcio makiumagara moimĩte hau kĩrĩma-inĩ kĩa Jehova, magĩthiĩ rũgendo rwa mĩthenya ĩtatũ. Narĩo ithandũkũ rĩa kĩrĩkanĩro kĩa Jehova rĩgĩthiĩ rĩmatongoretie mĩthenya ĩyo ĩtatũ, nĩguo rĩkamacarĩrie handũ ha kũhurũka.
Wọ́n sì gbéra láti orí òkè Olúwa ní ìrìn ọjọ́ mẹ́ta. Àpótí ẹ̀rí Olúwa ń lọ níwájú wọn fún gbogbo ọjọ́ mẹ́ta yìí láti wá ibi ìsinmi fún wọn.
34 Narĩo itu rĩa Jehova rĩakoragwo igũrũ rĩao o mũthenya makiumagara kuuma kambĩ.
Ìkùùkuu Olúwa wà lórí wọn lọ́sàn nígbà tí wọ́n gbéra kúrò ní ibùdó.
35 Hĩndĩ ĩrĩa yothe ithandũkũ rĩoimagario, Musa akoiga atĩrĩ, “Jehova, arahũka! Thũ ciaku irohurunjũka; thũ ciaku irokũũrĩra.”
Nígbàkígbà tí àpótí ẹ̀rí bá gbéra Mose yóò sì wí pé, “Dìde, Olúwa! Kí a tú àwọn ọ̀tá rẹ ká, kí àwọn tí ó kórìíra rẹ sì sálọ níwájú rẹ.”
36 Hĩndĩ ĩrĩa rĩaigwo thĩ, akoiga atĩrĩ, “Jehova cookerera ngiri ici cia Isiraeli itangĩtarĩka.”
Nígbàkígbà tí àpótí ẹ̀rí bá sinmi yóò wí pé, “Padà, Olúwa, sọ́dọ̀ àwọn àìmoye ẹgbẹẹgbẹ̀rún Israẹli.”