< Nehemia 6 >

1 Na rĩrĩa Sanibalati, na Tobia, na Geshemu ũrĩa Mũarabu, na thũ iria ingĩ ciitũ maakinyĩirwo nĩ ũhoro atĩ nĩnjakĩte rũthingo rĩngĩ na hatiarĩ ithenya o na rĩmwe rĩatigarĩte rũthingo-inĩ, o na gũtuĩka nginyagia ihinda rĩu ndiekĩrĩte mĩrango ya ihingo,
Nígbà tí Sanballati, Tobiah Geṣemu ará Arabia àti àwọn ọ̀tá wa tókù gbọ́ pé, mo ti tún odi náà mọ, kò sì sí àlàfo kankan tí ó ṣẹ́kù nínú rẹ̀—bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi kò ì tí ì ri àwọn ìlẹ̀kùn ibodè ní àkókò náà.
2 Sanibalati na Geshemu makĩndũmĩra ndũmĩrĩri ĩno: “Ũka, reke tũcemanie itũũra-inĩ rĩmwe werũ-inĩ wa Ono.” No rĩrĩ, maathugundaga kũnjĩka ũũru;
Sanballati àti Geṣemu rán iṣẹ́ yìí sí mi pé, “Wá jẹ́ kí a jọ pàdé pọ̀ nínú ọ̀kan lára àwọn ìletò ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Ono.” Ṣùgbọ́n wọ́n ń gbèrò láti ṣe mí ní ibi;
3 nĩ ũndũ ũcio ngĩmatũmĩra andũ mamacookerie atĩrĩ: “Ndĩ na wĩra wa bata ndĩraruta, ndingĩhota gũikũrũka njũke. Wĩra ũngĩkĩrũgamio nĩkĩ, atĩ nyambe njikũrũke kũrĩ inyuĩ?”
bẹ́ẹ̀ ni mo rán oníṣẹ́ padà pẹ̀lú èsì yìí pé, “Èmi ń ṣe iṣẹ́ ńlá kan, èmi kò le è sọ̀kalẹ̀ wá. Èéṣe tí iṣẹ́ náà yóò fi dúró, nígbà tí mo bá fi í sílẹ̀ tí mo sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ yín wá?”
4 Maandũmĩire ndũmĩrĩri ta ĩyo maita mana, na o hĩndĩ ndaacookagia icookio rĩu.
Wọ́n rán iṣẹ́ náà sí mi nígbà mẹ́rin ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀, mo sì fún wọn ní èsì bákan náà fún ìgbà kọ̀ọ̀kan.
5 Ihinda rĩa gatano Sanibalati akĩndũmĩra ndungata yake na ndũmĩrĩri o ro ĩyo, ĩkuuĩte marũa mataarĩ matume,
Ní ìgbà karùn-ún, Sanballati rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sí mi pẹ̀lú irú iṣẹ́ kan náà, lẹ́tà kan tí a kò fi sínú àpò ìwé wà ní ọwọ́ rẹ̀
6 marĩa maandĩkĩtwo ũũ: “Ũhoro nĩwarĩtio ndũrĩrĩ-inĩ, na Geshemu aroiga ũhoro ũcio nĩ wa ma, atĩ wee na Ayahudi nĩmũrathugunda kũremera mũthamaki mũmũũkĩrĩre, na nĩ ũndũ ũcio nĩmũraaka rũthingo. Ningĩ kũringana na ũhoro ũcio nĩũrenda gũtuĩka mũthamaki wao
tí a kọ sínú un rẹ̀ pé, “A ròyìn rẹ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, Geṣemu sì sọ pé, òtítọ́ ni, pé ìwọ àti àwọn Júù ń gbèrò láti ṣọ̀tẹ̀, nítorí náà ni ẹ ṣe ń mọ odi. Síwájú sí i, gẹ́gẹ́ bí ìròyìn yìí, ìwọ sì ń gbèrò láti di ọba wọn
7 na atĩ nĩ ũthuurĩte anabii a kwanĩrĩra ũhoro ũgũkoniĩ kũu Jerusalemu makiugaga atĩrĩ, ‘Juda kũrĩ na mũthamaki!’ Rĩu-rĩ, ũhoro ũcio nĩũgũkinyĩra mũthamaki; nĩ ũndũ ũcio ũka, twaranĩrie.”
àti pé ó ti yan àwọn wòlíì kí wọn lè kéde nípa rẹ̀ ní Jerusalẹmu: ‘Ọba kan wà ní Juda!’ Nísinsin yìí, ìròyìn yìí yóò padà sí ọ̀dọ̀ ọba; nítorí náà wá, jẹ́ kí a bá ara wa sọ̀rọ̀.”
8 Na niĩ ngĩkĩmũcookeria atĩrĩ: “Gũtirĩ ũndũ ta ũcio ũroiga ũrekĩka; nĩ gwĩthugundĩra ũrethugundĩra ũhoro ũcio meciiria-inĩ maku.”
Mo dá èsì yìí padà sí i pé, “Kò sí ohun kan nínú irú ohun tí ìwọ sọ tí ó ṣẹlẹ̀; ìwọ kàn rò wọ́n ní orí ara rẹ ni.”
9 Andũ acio maageragia ũrĩa wothe mangĩtũguoyohia, magĩĩciiria atĩrĩ, “Moko mao nĩmekwaga hinya wa kũruta wĩra, naguo wage kũrĩĩka.” No ngĩhooya Ngai, ngĩmwĩra atĩrĩ, “Rĩu ĩkĩra moko makwa hinya.”
Gbogbo wọn múra láti dẹ́rùbà wá, wọ́n ń rò ó wí pé, “Ọwọ́ wọn kò ní ran iṣẹ́ náà, àti wí pé wọn kò ní parí rẹ̀.” Ṣùgbọ́n mo gbàdúrà pé, “Nísinsin yìí Ọlọ́run fi agbára fún ọwọ́ mi.”
10 Mũthenya ũmwe nĩndathiire mũciĩ gwa Shemaia mũrũ wa Delaia, mũrũ wa Mehetabeli, ũrĩa wahingĩirwo gwake mũciĩ. Akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Nĩtũcemanie nyũmba ya Ngai, hekarũ thĩinĩ, na tũhinge mĩrango ya hekarũ, tondũ kũrĩ na andũ maroka gũkũũraga, megũka gũkũũraga ũtukũ.”
Ní ọjọ́ kan mo lọ sí ilé Ṣemaiah ọmọ Delaiah, ọmọ Mehetabeeli, ẹni tí a há mọ́ sínú ilé rẹ̀. Ó wí pé, “Jẹ́ kí a pàdé ní ilé Ọlọ́run nínú tẹmpili, kí o sì jẹ́ kí a pa àwọn ìlẹ̀kùn tẹmpili dé, nítorí àwọn ènìyàn ń bọ̀ láti pa ọ́, ní òru ni wọn yóò wá láti pa ọ́.”
11 No ngĩmũũria atĩrĩ, “Mũndũ ta niĩ nĩagĩrĩirwo nĩ kũũra? Kana mũndũ ta niĩ nĩagĩrĩirwo kwĩhitha thĩinĩ wa hekarũ ahonokie muoyo wake? Niĩ ndigũthiĩ!”
Ṣùgbọ́n mo wí pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí irú ènìyàn bí èmi sálọ? Tàbí kí ènìyàn bí èmi sálọ sínú tẹmpili láti gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là? Èmi kò ní lọ!”
12 Nĩndamenyire atĩ ti Ngai wamũtũmĩte, no aandathagĩra ũũru tondũ Tobia na Sanibalati nĩmamũrĩhĩte eke ũguo.
Èmi wòye pé Ọlọ́run kò rán an, ṣùgbọ́n ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí mi nítorí Tobiah àti Sanballati ti bẹ̀ ẹ́ ní ọ̀wẹ̀.
13 Aarĩhĩtwo nĩguo atũme ndĩtigĩre nĩgeetha ndeka ũguo njĩhie, ngĩe na rĩĩtwa rĩũru nao mone njĩra ya kũũmenithia.
Wọ́n bẹ̀ ẹ́ ní ọ̀wẹ̀ láti dẹ́rùbà mí nítorí kí èmi lè dẹ́ṣẹ̀ nípa ṣíṣe èyí, kí wọn lè bà mí lórúkọ jẹ́, kí n sì di ẹni ẹ̀gàn.
14 Wee Ngai wakwa, ririkana Tobia na Sanibalati tondũ wa ũrĩa mekĩte, na ũririkane Noadia mũnabii mũndũ-wa-nja, o na anabii arĩa angĩ makoretwo makĩgeria kũnjĩkĩra guoya.
A! Ọlọ́run mi, rántí Tobiah àti Sanballati, nítorí ohun tí wọ́n ti ṣe; kí o sì tún rántí Noadiah wòlíì obìnrin àti àwọn wòlíì tókù tí wọ́n ń gbèrò láti dẹ́rùbà mí.
15 Nĩ ũndũ ũcio, rũthingo rũu rwarĩĩkire thuutha wa mĩthenya mĩrongo ĩtano na ĩĩrĩ, mũthenya wa mĩrongo ĩĩrĩ na ĩtano, mweri-inĩ wa Eluli.
Bẹ́ẹ̀ ni a parí odi náà ní ọjọ́ kẹẹdọ́gbọ̀n oṣù Eluli, láàrín ọjọ́ méjìléláàádọ́ta.
16 Rĩrĩa thũ ciitũ ciaiguire ũhoro ũcio, ndũrĩrĩ ciothe iria ciatũthiũrũrũkĩirie igĩĩtigĩra na ikĩaga mwĩhoko, nĩ ũndũ nĩmamenyire atĩ wĩra ũcio warutĩkire na ũndũ wa ũteithio wa Ngai witũ.
Nígbà tí àwọn ọ̀tá wa gbọ́ èyí, gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká bẹ̀rù jìnnìjìnnì sì mú wọn, nítorí wọ́n wòye pé iṣẹ́ yìí di ṣíṣe pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Ọlọ́run wa.
17 Ningĩ matukũ-inĩ macio, andũ arĩa maarĩ igweta a Juda nĩmatũmagĩra Tobia marũa maingĩ, nao nĩmanyiitaga macookio kuuma kũrĩ Tobia.
Bákan náà, ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ọlọ́lá Juda ń kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ lẹ́tà ránṣẹ́ sí Tobiah, èsì láti ọ̀dọ̀ Tobiah sì ń wá sí ọ̀dọ̀ wọn.
18 Nĩgũkorwo andũ aingĩ a Juda nĩmehĩtĩte gũkorwo mwena wake, tondũ aarĩ mũthoni-we wa Shekania mũrũ wa Ara, na mũriũ wake Jehohanani aahikĩtie mwarĩ wa Meshulamu mũrũ wa Berekia.
Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn Juda ti mulẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, nítorí tí ó jẹ́ àna Ṣekaniah ọmọ Arah (Sanballati fẹ́ ọmọ Ṣekaniah), ọmọ rẹ̀ Jehohanani sì tún fẹ́ ọmọbìnrin Meṣullamu ọmọ Berekiah.
19 Na ningĩ nĩmaikaraga makĩĩheaga ũhoro wa ciĩko ciake njega magacooka makamwĩra ũrĩa na niĩ njugĩte. Nake Tobia akaandũmagĩra marũa ma gũtũma ndĩĩtigĩre.
Síwájú sí í, wọ́n túbọ̀ ń ròyìn iṣẹ́ rere rẹ̀ fún mi, wọ́n sì ń sọ ohun tí mo sọ fún un. Tobiah sì ń kọ àwọn lẹ́tà ránṣẹ́ sí mi láti dẹ́rùbà mí.

< Nehemia 6 >