< Nehemia 1 >
1 Ici nĩcio ciugo cia Nehemia mũrũ wa Hakalia: Atĩrĩrĩ, mweri-inĩ wa Kiselevu wa mwaka wa mĩrongo ĩĩrĩ, rĩrĩa ndaarĩ thĩinĩ wa nyũmba ya ũthamaki kũu Shushani-rĩ,
Ọ̀rọ̀ Nehemiah ọmọ Hakaliah. Ní oṣù Kisleu ní ogún ọdún (ìjọba Ahaswerusi ọba Persia) nígbà tí mo wà ní ààfin Susa,
2 Hanani, ũmwe wa ariũ a baba, agĩũka kuuma Juda arĩ na andũ angĩ, na ngĩmahooya ũhoro wa matigari ma Ayahudi arĩa maahonokete gũtahwo, o na ngĩmahooya ũhoro wa Jerusalemu.
Hanani, ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin mi wá láti Juda pẹ̀lú àwọn ọkùnrin kan, mo sì béèrè lọ́wọ́ wọn nípa àwọn Júù tí ó ṣẹ́kù tí wọn kò kó ní ìgbèkùn, àti nípa Jerusalẹmu.
3 Nao makĩnjookeria atĩrĩ, “Andũ arĩa maahonokire gũtahwo, o acio marĩ kũu bũrũri-inĩ, marĩ na thĩĩna mũnene na makanyararwo mũno. Rũthingo rwa Jerusalemu nĩrũmomore, na ihingo ciaruo igacinwo na mwaki.”
Wọ́n sọ fún mi pé, “Àwọn tí ó kù tí a kó ní ìgbèkùn tí wọ́n sì padà sí agbègbè ìjọba wà nínú wàhálà púpọ̀ àti ẹ̀gàn. Odi Jerusalẹmu ti wó lulẹ̀ a sì ti fi iná sun ẹnu ibodè rẹ̀.”
4 Rĩrĩa ndaiguire maũndũ macio, ngĩikara thĩ, ngĩrĩra. Ngĩikara ngĩcakayaga matukũ maigana ũna, ngĩĩhinga kũrĩa irio na ngĩhooya Ngai wa igũrũ.
Nígbà tí mo gbọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyí, mo jókòó mo sì sọkún. Mo ṣọ̀fọ̀, mo gbààwẹ̀, mo sì gbàdúrà fún ọjọ́ díẹ̀ níwájú Ọlọ́run ọ̀run.
5 Ningĩ ngiuga atĩrĩ: “Wee Jehova Ngai wa Igũrũ, wee Mũrungu mũnene na wa kũmakania, ũrĩa ũhingagia kĩrĩkanĩro gĩake kĩa wendo kũrĩ arĩa mamwendete na magaathĩkĩra maathani make,
Nígbà náà ni mo wí pé: “Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run, Ọlọ́run tí ó tóbi tí ó sì ní ẹ̀rù, tí ó ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ rẹ̀ mọ́ pẹ̀lú wọn tí ó fẹ́ ẹ tí wọ́n sì ń pa àṣẹ mọ́.
6 ndagũthaitha ũtege gũtũ gwaku, na ũhingũre maitho maku ũigue ihooya rĩrĩa ndungata yaku ĩrahooya ĩrĩ mbere yaku mũthenya na ũtukũ nĩ ũndũ wa ndungata ciaku, andũ a Isiraeli. Nĩngumbũra mehia ma andũ a Isiraeli, na makwa, na ma nyũmba ya baba, marĩa ithuĩ tũkwĩhĩirie.
Jẹ́ kí etí rẹ kí ó ṣí sílẹ̀, kí ojú ù rẹ kí ó sì ṣí sílẹ̀ láti gbọ́ àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbà ní iwájú rẹ ní ọ̀sán àti ní òru fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ènìyàn Israẹli. Mo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àwa ọmọ Israẹli àti tèmi àti ti ilé baba mi, tí a ti ṣẹ̀ sí ọ.
7 Nĩtwĩkĩte maũndũ ma waganu mũnene harĩwe. Tũtiathĩkĩire maathani na irĩra cia watho waku cia kũrũmĩrĩrwo, o na mawatho marĩa waheire Musa ndungata yaku.
Àwa ti ṣe búburú sí ọ. A kò sì pa àṣẹ ìlànà àti òfin tí ìwọ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ mọ́.
8 “Ririkana ũrutani ũrĩa waheire Musa ndungata yaku, ũkiuga atĩrĩ, ‘Mũngĩaga kwĩhokeka, nĩngamũhurunja gatagatĩ ka ndũrĩrĩ,
“Rántí ìlànà tí o fún Mose ìránṣẹ́ rẹ, wí pé, ‘Bí ìwọ bá jẹ́ aláìṣòótọ́, èmi yóò fọ́n yín ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
9 no mũngĩkanjookerera na mwathĩkĩre maathani makwa, hĩndĩ ĩyo o na andũ anyu arĩa maatahĩtwo magatwarwo ituri cia thĩ kũrĩa kũraya mũno, nĩngamacookereria ndĩmarute kuo, ndĩmarehe kũndũ kũrĩa thuurĩte gũtuĩke gĩikaro kĩa Rĩĩtwa rĩakwa.’
Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá yípadà sí mi, tí ẹ bá sì pa àṣẹ mi mọ́, nígbà náà bí àwọn ènìyàn yín tí a kó ní ìgbèkùn tilẹ̀ wà ní jìnnà réré ìpẹ̀kun ọ̀run, èmi yóò kó wọn jọ láti ibẹ̀, èmi yóò sì mú wọn wá, sí ibi tí èmi ti yàn bí i ibùgbé fún orúkọ mi.’
10 “Acio nĩ ndungata ciaku na andũ aku, arĩa wakũũrire na ũndũ wa hinya waku mũnene na guoko gwaku kũrĩ ũhoti.
“Àwọn ni ìránṣẹ́ rẹ àti ènìyàn rẹ àwọn tí ìwọ rà padà pẹ̀lú agbára ńlá rẹ àti ọwọ́ agbára ńlá rẹ.
11 Wee, Jehova, ndagũthaitha ũtege gũtũ ũigue mahooya ma ndungata ĩno yaku, o na mahooya ma ndungata ciaku iria ikenagio nĩ gwĩtigĩra rĩĩtwa rĩaku. Kĩreke ndungata yaku ĩgaacĩre ũmũthĩ na ũndũ wa gũtũma ĩtĩkĩrĩke harĩ mũndũ ũyũ.” Nĩ niĩ ndatwaragĩra mũthamaki kĩndũ gĩa kũnyua.
Olúwa, jẹ́ kí etí rẹ ṣí sílẹ̀ sí àdúrà ìránṣẹ́ rẹ yìí, àti sí àdúrà àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wọ́n ní inú dídùn láti bọ̀wọ̀ fún orúkọ rẹ. Fún ìránṣẹ́ rẹ ní àṣeyọrí lónìí kí o sì síjú àánú wò ó níwájú ọkùnrin yìí.” Nítorí tí mo jẹ́ agbọ́tí ọba nígbà náà.