< Mariko 1 >

1 Kĩambĩrĩria kĩa Ũhoro-ũrĩa-Mwega ũkoniĩ Jesũ Kristũ Mũrũ wa Ngai.
Ìbẹ̀rẹ̀ ìyìnrere nípa Jesu Kristi, Ọmọ Ọlọ́run.
2 O ta ũrĩa kwandĩkĩtwo ibuku-inĩ rĩa Isaia ũrĩa mũnabii atĩrĩ: “Nĩngũtũma mũtũmwo wakwa athiĩ mbere yaku, ũrĩa ũgũgũthondekera njĩra yaku.”
Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé wòlíì Isaiah pé, “Èmi yóò ran oníṣẹ́ mi síwájú rẹ, Ẹni tí yóò tún ọ̀nà rẹ ṣe.”
3 “Kũrĩ mũgambo wa mũndũ ũkwanĩrĩra werũ-inĩ akoiga atĩrĩ, ‘Haarĩriai njĩra ya Mwathani, rũngariai njĩra ciake.’”
“Ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù, ‘Ẹ tún ọ̀nà Olúwa ṣe, ẹ ṣe ojú ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́.’”
4 Nĩ ũndũ ũcio Johana ookire akĩhunjagia, na akĩbatithanagĩria werũ-inĩ. Aahunjagia atĩ andũ merire, nĩguo marekerwo mehia mao, nĩgeetha mabatithio.
Johanu dé, ẹni tí ó ń tẹnibọmi ní aginjù, tí ó sì ń wàásù ìtẹ̀bọmi ìrònúpìwàdà fún ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀.
5 Nao andũ othe a bũrũri wa Judea na andũ othe a Jerusalemu magĩthiĩ kũrĩ we. Moimbũraga mehia mao, nake akamabatithĩria rũũĩ-inĩ rwa Jorodani.
Gbogbo àwọn tí ń gbé ní agbègbè Judea, àti gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu jáde tọ̀ ọ́ lọ, a sì ti ọwọ́ rẹ̀ tẹ gbogbo wọn bọ omi ni odò Jordani, wọ́n ń jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
6 Johana ehumbaga nguo ciathondeketwo na guoya wa ngamĩĩra, na nĩehotoraga mũcibi wa rũũa njohero, na aarĩĩaga ngigĩ na ũũkĩ wa gĩthaka.
Johanu sì wọ aṣọ irun ìbákasẹ. Ó sì di àmùrè awọ mọ́ ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Eṣú àti oyin ìgàn sì ni oúnjẹ rẹ̀.
7 Nayo ndũmĩrĩri yake yarĩ ĩno: “Thuutha wakwa nĩgũgũũka mũndũ ũngĩ ũrĩ na hinya kũngĩra, ũrĩa niĩ itagĩrĩire kũinamĩrĩra njohore ndigi cia iraatũ ciake.
Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wàásù wí pé, “Ẹnìkan tí ó tóbi jù mí lọ ń bọ̀ lẹ́yìn mi, okùn bàtà ẹsẹ̀ ẹni tí èmi kò tó ẹni tí ń tú.
8 Niĩ ndĩmũbatithagia na maaĩ, nowe arĩmũbatithagia na Roho Mũtheru.”
Èmi ń fi omi ṣe ìtẹ̀bọmi yín, ṣùgbọ́n Òun yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ ṣe ìtẹ̀bọmi yín.”
9 Na rĩrĩ, ihinda o rĩu Jesũ agĩũka oimĩte Nazarethi kũu Galili, na akĩbatithio nĩ Johana rũũĩ-inĩ rwa Jorodani.
Ó sì ṣe ní ọjọ́ kan Jesu ti Nasareti ti Galili jáde wá, a sì ti ọwọ́ Johanu ṣe ìtẹ̀bọmi fún ní odò Jordani.
10 Na rĩrĩa Jesũ oimĩraga maaĩ-inĩ akĩona igũrũ rĩahingũka, nake Roho Mũtheru akĩmũikũrũkĩra ahaana ta ndutura.
Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ tí Jesu ń ti inú omi jáde wá, ó rí ọ̀run tí ó ṣí sílẹ̀, Ẹ̀mí Mímọ́ bí àdàbà sọ̀kalẹ̀ lé e lórí.
11 Mũgambo ũkiuma igũrũ ũkiuga atĩrĩ, “We nĩwe Mũrũ wakwa ũrĩa nyendete, na nĩngenaga mũno nĩwe.”
Ohùn kan sì ti ọ̀run wá wí pé, “Ìwọ ni àyànfẹ́ Ọmọ mi, ẹni tí inú mi dùn sí gidigidi.”
12 Na o rĩmwe Roho akĩmuoya akĩmũtwara werũ-inĩ,
Lẹ́sẹ̀kan náà, Ẹ̀mí Mímọ́ sì darí Jesu sí ijù,
13 na agĩikara kũu werũ-inĩ matukũ mĩrongo ĩna, akĩgeragio nĩ Shaitani. Nake aikaranagia na nyamũ cia gĩthaka, nao araika makamũtungatagĩra.
Ó sì wà ní ogójì ọjọ́ ní aginjù. A sì ti ọwọ́ Satani dán an wò, ó sì wà pẹ̀lú àwọn ẹranko ìgbẹ́. Àwọn angẹli sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún un.
14 Thuutha wa Johana gũikio njeera, Jesũ agĩthiĩ Galili akĩhunjagia Ũhoro-ũrĩa-Mwega wa Ngai,
Lẹ́yìn ìgbà tí ọba Herodu ti fi Johanu sínú ẹ̀wọ̀n tan, Jesu lọ sí Galili, ó ń wàásù ìyìnrere ti ìjọba Ọlọ́run.
15 akiuga atĩrĩ, “Ihinda nĩikinyu, naguo ũthamaki wa Ngai nĩũkuhĩrĩirie. Mwĩrirei mwĩtĩkie Ũhoro-ũrĩa-Mwega!”
Ó sì kéde wí pé, “Àkókò náà dé wàyí, ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀. Ẹ yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín, kí ẹ sì gba ìyìnrere yìí gbọ́.”
16 Na rĩrĩa Jesũ aathiiagĩra hũgũrũrũ-inĩ cia iria rĩa Galili, nĩonire Simoni na mũrũ wa nyina Anderea magĩikia neti ciao iria-inĩ, nĩgũkorwo maarĩ ategi a thamaki.
Ní ọjọ́ kan, bí Jesu ti ń rìn létí Òkun Galili, Ó rí Simoni àti Anderu arákùnrin rẹ̀, wọ́n ń fi àwọ̀n wọn pẹja torí pé apẹja ni wọ́n.
17 Nake Jesũ akĩmeera atĩrĩ, “Ũkai, mũnũmĩrĩre, na nĩngamũtua ategi a andũ.”
Jesu sì ké sí wọn wí pé, “Ẹ máa tọ̀ mí lẹ́yìn. Èmi yóò sì sọ yín di apẹja ènìyàn.”
18 O rĩmwe magĩtiganĩria neti ciao makĩmũrũmĩrĩra.
Ní kánkán wọ́n fi àwọ̀n wọn sílẹ̀, wọ́n sì tọ̀ Ọ́ lẹ́yìn.
19 Na aathiathia hanini, akĩona Jakubu mũrũ wa Zebedi hamwe na mũrũ wa nyina Johana marĩ gatarũ-inĩ makĩhaarĩria neti ciao.
Bí Ó sì ti rìn síwájú díẹ̀, ní etí Òkun, Ó rí Jakọbu ọmọ Sebede àti Johanu arákùnrin rẹ̀ nínú ọkọ̀, wọ́n ń tún àwọ̀n wọn ṣe.
20 O rĩmwe akĩmeeta, nao magĩtiga ithe wao Zebedi gatarũ-inĩ hamwe na aruti ake a wĩra na makĩmũrũmĩrĩra.
Ó sì ké sí àwọn náà lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, wọ́n fi Sebede baba wọn sílẹ̀ nínú ọkọ̀ pẹ̀lú àwọn alágbàṣe, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
21 Nao magĩthiĩ Kaperinaumu, na rĩrĩa mũthenya wa Thabatũ wakinyire, Jesũ agĩtoonya thunagogi na akĩambĩrĩria kũrutana.
Lẹ́yìn náà, Jesu àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wọ ìlú Kapernaumu, nígbà tí ó di òwúrọ̀ ọjọ́ ìsinmi, ó lọ sínú Sinagọgu, ó sì ń kọ́ni.
22 Na andũ makĩgegio nĩ ũrutani wake, nĩgũkorwo aamarutaga ta mũndũ warĩ na ũhoti, no ti ta arutani a watho.
Ẹnu sì ya ìjọ ènìyàn nítorí ìkọ́ni rẹ̀, nítorí pé ó ń kọ́ni bí ẹni tí ó ní àṣẹ, kì í ṣe bí àwọn olùkọ́ òfin ṣe ń kọ́ àwọn ènìyàn.
23 Na rĩrĩ, hĩndĩ o ĩyo kũu thunagogi yao, nĩ kwarĩ na mũndũ warĩ na ngoma thũku, nake akĩanĩrĩra, akiuga atĩrĩ,
Ní àsìkò náà gan an ni ọkùnrin kan tí ó wà nínú Sinagọgu wọn, tí ó ní ẹ̀mí àìmọ́, bẹ̀rẹ̀ sí í kígbe wí pé,
24 “Ũrenda atĩa na ithuĩ, wee Jesũ wa Nazarethi? Ũũkĩte gũtũniina? Nĩnjũũĩ wee nĩwe ũ! Wee nĩwe Ũrĩa-Mũtheru-wa-Ngai.”
“Kí ni ìwọ ń wá lọ́dọ̀ wa, Jesu ti Nasareti? Ṣé ìwọ wá láti pa wá run ni? Èmí mọ ẹni tí ìwọ í ṣe; Ìwọ ní ẹni Mímọ́ Ọlọ́run!”
25 Nake Jesũ akĩmĩkũma na hinya, akiuga atĩrĩ, “Kira na uume thĩinĩ wake!”
Jesu si bá a wí, ó wí pé, “Pa ẹnu rẹ mọ́, kí ó sì jáde kúrò lára rẹ̀.”
26 Ngoma ĩyo thũku ĩkĩmũthukathuka na hinya na ĩkiuma thĩinĩ wake ĩgĩkayaga.
Ẹ̀mí àìmọ́ náà sì gbé e ṣánlẹ̀ lógèdèǹgbé, ó ké ní ohùn rara, ó sì jáde kúrò lára ọkùnrin náà.
27 Andũ acio othe makĩgega mũno nginya makĩũrania atĩrĩ, “Ũndũ ũyũ nĩ ũrĩkũ? Ũyũ nĩ ũrutani mwerũ, wĩ na ũhoti! Nĩ araatha o na ngoma thũku na ikamwathĩkĩra.”
Ẹnu sì ya àwọn ènìyàn, tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n fi ń sọ láàrín ara wọn ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀. Wọ́n béèrè pẹ̀lú ìgbóná ara, pé, “Kí ni èyí? Irú ẹ̀kọ́ tuntun wo ni èyí? Ó ń fi agbára pàṣẹ fún àwọn ẹ̀mí àìmọ́ pàápàá wọ́n sì gbọ́ tirẹ̀.”
28 Nayo ngumo yake ĩkĩhunja na ihenya bũrũri wothe wa Galili.
Ìròyìn nípa rẹ̀ tàn ká gbogbo agbègbè Galili.
29 Na maarĩkia kuuma thunagogi, magĩthiĩ na Jakubu na Johana mũciĩ gwa Simoni na Anderea.
Nígbà tí wọn sì jáde kúrò nínú Sinagọgu, wọ́n lọ pẹ̀lú Jakọbu àti Johanu sí ilé Simoni àti Anderu.
30 Na rĩrĩ, nyina wa mũtumia wa Simoni aarĩ gĩtanda-inĩ arĩ mũrũaru mũrimũ wa kũhiũha mwĩrĩ, nao makĩĩra Jesũ ũhoro wake.
Ìyá ìyàwó Simoni tí ó dùbúlẹ̀ àìsàn ibà, wọ́n sì sọ fún Jesu nípa rẹ̀.
31 Nĩ ũndũ ũcio Jesũ agĩthiĩ harĩa aarĩ, akĩmũnyiita guoko akĩmũũkĩria. Mũrimũ ũcio wa kũhiũha mwĩrĩ ũkĩmũtiga na akĩambĩrĩria kũmatungatĩra.
Ó sì tọ̀ ọ́ lọ, ó fà á lọ́wọ́, ó sì gbé e dìde; lójúkan náà ibà náà fi sílẹ̀, ó sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún wọn.
32 Hwaĩ-inĩ ũcio thuutha wa riũa gũthũa, andũ makĩrehera Jesũ andũ arĩa othe maarĩ arũaru na arĩa maarĩ na ndaimono.
Nígbà tí ó di àṣálẹ́, tí oòrùn wọ̀, wọ́n gbé gbogbo àwọn aláìsàn àti àwọn tó ni ẹ̀mí àìmọ́ tọ̀ ọ́ wá.
33 Nao andũ a itũũra othe makĩũngana hau mũrango-inĩ wa nyũmba,
Gbogbo ìlú si péjọ ni ẹnu-ọ̀nà.
34 nake Jesũ akĩhonia andũ aingĩ arĩa maarĩ na mĩrimũ mĩthemba mĩingĩ. Ningĩ akĩingata ndaimono nyingĩ, no ndetĩkĩririe ndaimono ciarie tondũ nĩciamũũĩ.
Jesu sì wo ọ̀pọ̀ tí wọ́n ní onírúurú ààrùn sàn. Bákan náà ni ó lé ọ̀pọ̀ ẹ̀mí àìmọ́ jáde. Ṣùgbọ́n kò sì jẹ́ kí àwọn ẹ̀mí àìmọ́ náà kí ó sọ̀rọ̀, nítorí tí wọ́n mọ ẹni tí òun í ṣe.
35 Rũciinĩ kĩroko tene kũrĩ o na nduma, Jesũ agĩũkĩra akiuma nyũmba agĩthiĩ handũ keheri-inĩ, akĩhoera ho.
Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, kí ilẹ̀ tó mọ́, Jesu nìkan jáde lọ sí aginjù kan, láti lọ gbàdúrà.
36 Nake Simoni na arĩa maarĩ nao magĩthiĩ kũmwetha,
Simoni àti àwọn ènìyàn rẹ̀ yòókù lọ láti wá a.
37 na rĩrĩa maamuonire, makĩanĩrĩra, makĩmwĩra atĩrĩ: “Andũ othe nĩwe maracaria!”
Nígbà tí wọ́n sì rí I, wọ́n sọ fún wí pé, “Gbogbo ènìyàn ń wá ọ!”
38 Jesũ akĩmacookeria atĩrĩ, “Rekei tuume gũkũ tũthiĩ kũndũ kũngĩ, matũũra-inĩ marĩa me hakuhĩ, nĩguo hunjie o nakuo. Tondũ nĩkĩo ndokire.”
Jesu sì dáhùn wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a lọ sí àwọn ìlú mìíràn, kí ń lè wàásù níbẹ̀ pẹ̀lú. Nítorí èyí ni èmi sá à ṣe wá.”
39 Nĩ ũndũ ũcio agĩthiũrũrũka Galili guothe akĩhunjagia thunagogi-inĩ ciao na akĩingataga ndaimono.
Nítorí náà, ó ń kiri gbogbo agbègbè Galili, ó ń wàásù nínú Sinagọgu. Ó sì ń lé àwọn ẹ̀mí àìmọ́ jáde.
40 Na mũndũ ũmwe warĩ na mangũ agĩũka kũrĩ we na akĩmũthaitha aturĩtie maru, akĩmwĩra atĩrĩ, “Ũngĩenda-rĩ, no ũũtherie.”
Ọkùnrin adẹ́tẹ̀ kan tọ̀ ọ́ wá, ó sì kúnlẹ̀ níwájú rẹ̀. Ó sì bẹ̀bẹ̀ fún ìmúláradá. Ó wí pé, “Bí ìwọ bá fẹ́, ìwọ lè mú mi láradá.”
41 Nake Jesũ akĩringwo nĩ tha nyingĩ, agĩtambũrũkia guoko gwake akĩhutia mũndũ ũcio. Akĩmwĩra atĩrĩ, “Nĩ ngwenda. Therio.”
Jesu kún fún àánú, ó na ọwọ́ rẹ̀, ó fi ọwọ́ rẹ̀ bà a, ó wí pé, “Èmí fẹ́. Di mímọ́.”
42 Na o hĩndĩ ĩyo mũndũ ũcio agĩthirwo nĩ mangũ, akĩhonio.
Lójúkan náà ẹ̀tẹ̀ náà fi sílẹ̀ lọ, ọkùnrin náà sì rí ìwòsàn.
43 Nake Jesũ akĩmũkaania na hinya na akĩmwĩra athiĩ,
Jesu sì kìlọ̀ fún un gidigidi
44 ningĩ akĩmwĩra atĩrĩ, “Menya ndũkeere mũndũ o na ũrĩkũ ũhoro ũyũ. No thiĩ ũkeyonanie kũrĩ mũthĩnjĩri-Ngai, na ũrute magongona marĩa Musa aathanĩte nĩ ũndũ wa gũtherio gwaku, ũtuĩke ũira kũrĩ o.”
Ó wí pé, “Lọ fi ara rẹ̀ hàn àlùfáà Júù fún àyẹ̀wò. Ṣùgbọ́n má ṣe dúró sọ ohunkóhun fún ẹnikẹ́ni ní ọ̀nà. Mú ẹ̀bùn lọ́wọ́, èyí tí Mose pàṣẹ fún adẹ́tẹ̀ tí a mú láradá. Èyí tí í ṣe ẹ̀rí pé, ó ti rí ìwòsàn.”
45 No handũ ha ũguo agĩthiĩ, akĩambĩrĩria kwaria na kũmemerekia ũhoro ũcio. Nĩ ũndũ ũcio Jesũ ndacookire kũhota gũtoonya itũũra thĩinĩ akĩonagwo nĩ andũ, no aikaraga na nja kũndũ gũtaarĩ andũ. No andũ no mookaga kũrĩ we moimĩte kũndũ guothe.
Ṣùgbọ́n ó jáde lọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí í pòkìkí, ó ń tan ìròyìn kálẹ̀. Nítorí èyí, Jesu kò sì le wọ ìlú ní gbangba mọ́, ṣùgbọ́n ó wà lẹ́yìn odi ìlú ní aginjù. Síbẹ̀, àwọn ènìyàn tọ̀ ọ́ wá láti ibi gbogbo.

< Mariko 1 >